< Genesis 14 >

1 Ní àsìkò yìí ni Amrafeli ọba Ṣinari, Arioku ọba Ellasari, Kedorlaomeri ọba Elamu àti Tidali ọba Goyimu
And it chaunsed within a while that Amraphel kynge of Synear Arioch kynge of Ellasar Kedorlaomer kynge of Elam and Thydeall kynge of the nations:
2 jáde lọ láti bá Bera ọba Sodomu, Birṣa ọba Gomorra, Ṣenabu ọba Adma, Ṣemeberi ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari) jagun.
made warre wyth Bera kynge of Sodoh and with Birsa kynge of Gomorra. And wythe Sineab kynge of Adama and with Semeaber kynge of Zeboim and wyth the kynge of Bela Which Bela is called Zoar.
3 Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí ni ó kó ogun wọn jọ pọ̀ sí àfonífojì Siddimu (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀).
All these came together vnto the vale of siddim which is now the salt see
4 Fún ọdún méjìlá gbáko ni wọ́n ti ń sin Kedorlaomeri bí ẹrú. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di ọdún kẹtàlá wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí i.
Twelve yere were they subiecte to kinge kedorlaomer and in the. xiij. yere rebelled.
5 Ní ọdún kẹrìnlá, ni Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí wọ́n ti jọ ni májẹ̀mú àṣepọ̀ wá, wọ́n ṣígun, wọ́n sì ṣẹ́gun ará Refaimu ní Aṣteroti-Karnaimu, àwọn ará Susimu ni Hamu, àwọn ará Emimu ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Kiriataimu,
Therfore in the. xiiij. yere came kedorlaomer and the kynges that were wyth hym and smote the Raphayms in Astarath Karnaim and the Susims in Hain ad the Emyms in Sabe Kariathaim
6 àti àwọn ará Hori ní orí òkè wọ̀n-ọn-nì Seiri, títí ó fi dé Eli-Parani ní etí ijù.
and the Hozyms in their awne mounte Seir vnto the playne of Pharan which bordreth vpon the wyldernesse.
7 Wọ́n sì tún yípadà lọ sí En-Miṣpati (ti o túmọ̀ sí Kadeṣi), wọ́n sì ṣẹ́gun gbogbo ilẹ̀ àwọn Amaleki, àti àwọn ará Amori tí ó tẹ̀dó sí Hasason Tamari pẹ̀lú.
And then turned they and came to the well of iugmente which is Cades and smote all the contre of the Amalechites and also the amorytes that dwell in Hazezon Thamar.
8 Nígbà náà ni ọba Sodomu, ọba Gomorra, ọba Adma, ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari), kó àwọn ọmọ-ogun wọn, wọ́n sì pa ibùdó ogun wọn sí Àfonífojì Siddimu,
Than went out the kynge of Sodome and the kynge of Gomorra and the kinge of Adama and the kynge of Zeboijm and the kynge of Bela now called Zoar. And sette their men in aray to fyghte wyth them in the vale of siddim that is to say
9 láti kojú ìjà sí Kedorlaomeri ọba Elamu, Tidali ọba Goyimu, Amrafeli ọba Ṣinari àti Arioku ọba Ellasari (ọba mẹ́rin kọjú ìjà sí ọba márùn-ún).
wyth kedorlaomer the kynge of Elam and with Thydeall kynge of the Nations and wyth Amraphel kynge of Synear. And with Arioch kynge of Ellasar: foure kynges agenste v.
10 Àfonífojì Siddimu sì kún fún kòtò ọ̀dà ilẹ̀, nígbà tí ọba Sodomu àti ọba Gomorra sì sá, díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin ogun náà ṣubú sínú àwọn kòtò náà, àwọn tókù sì sálọ sì orí òkè.
And that vale of siddim was full of slyme pyttes. And the kynges of Sodome and Gomorra fled and fell there. And the resydue fled to the mountaynes.
11 Àwọn ọba mẹ́rẹ̀ẹ̀rin náà sì kó gbogbo ẹrù Sodomu àti Gomorra àti oúnjẹ wọn; wọ́n sì lọ.
And they toke all the goodes of Sodome and Gomorra and all their vitalles ad went their waye.
12 Wọ́n sì mú Lọti ọmọ arákùnrin Abramu tí ń gbé ní Sodomu àti gbogbo ohun ìní rẹ̀.
And they toke Lot also Abrams brothers sonne and his good (for he dwelled at Sodome) and departed:
13 Ẹnìkan tí ó sá àsálà sì wá ròyìn fún Abramu, ará Heberu ni. Abramu sá ti tẹ̀dó sí ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó Mamre ará Amori, arákùnrin Eṣkolu àti Aneri: àwọn ẹni tí ó ń bá Abramu ní àṣepọ̀.
Than came one that had escaped and tolde Abram the hebrue which dwelled in the okegrove of Mamre the Amoryte brother of Eschol and Aner: which were confederate wyth Abram.
14 Nígbà tí Abramu gbọ́ wí pé, a di Lọti ní ìgbèkùn, ó kó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí a bí sí ilẹ̀ rẹ̀ tí ó sì ti kọ́ ni ogun jíjà jáde, wọ́n jẹ́ okòó lé lọ́ọ̀dúnrún ó dín méjì ènìyàn, ó sì lépa wọn títí dé Dani.
When Abram herde that his brother was taken he harnessed his seruantes borne in his owne house. iij. hundred and. xviij. ad folowed tyll they came at Dan.
15 Ní ọ̀gànjọ́ òru, Abramu pín àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sí méjì, ó sì kọlù wọ́n, ó sì ṣẹ́gun wọn, ó sì lé wọn títí dé Hoba tí ó wà ní apá òsì Damasku.
And sette hymselfe ad his seruantes in aray and fell vpon them by nyght and smote them and chased them awaye vnto Hoba: which lyeth on the lefte hande of Damascos
16 Gbogbo ìkógun ni ó rí gbà padà àti ọmọ arákùnrin rẹ̀, Lọti pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, àti àwọn obìnrin pẹ̀lú àwọn ènìyàn tókù.
and broughte agayne all the goodes and also his brother Lot ad his goodes the weme also and the people.
17 Nígbà tí Abramu ti ṣẹ́gun Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí ó pẹ̀lú rẹ̀, ọba Sodomu lọ pàdé rẹ̀ ní àfonífojì Ṣafe (èyí ni àfonífojì Ọba).
And as he retourned agayne from the slaughter of kedorlaomer and of the kynges that were with hym than came the kynge of Sodome agaynst hym vnto the vale of Saue which now is called kynges dale.
18 Melkisedeki ọba Salẹmu sì mú oúnjẹ àti ọtí wáìnì jáde wá. Òun ni àlùfáà Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo.
Than Melchisedech kinge of Salem brought forth breed and wyne. And he beynge the prest of the most hyghest God
19 Ó sì súre fún Abramu, wí pé, “Ìbùkún ni fún Abramu ti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, Ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
blessed hym saynge. Blessed be Abram vnto the most hyghest God possessor of heauen and erth.
20 Ìbùkún sì ni fún Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ, tí ó fi àwọn ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́.” Abramu sì fún un ní ìdámẹ́wàá ohun gbogbo.
And blessed be God the most hyghest which hath delyvered thyne enimies in to thy handes. And Abra gaue hym tythes of all.
21 Ọba Sodomu sì wí fún Abramu pé, “Kó àwọn ènìyàn mi fún mi, ṣùgbọ́n mú àwọn ẹrù fún ara rẹ.”
Than sayd the kynge of Sodome vnto Abram: gyue me the soulles and take the goodes to thy selfe.
22 Ṣùgbọ́n Abramu dá ọba Sodomu lóhùn pé, “Mo ti búra fún Olúwa, Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, tí ó dá ọ̀run àti ayé, mo sì ti gbọ́wọ́ sókè,
And Abram answered the kynge of Sodome: I lyfte vpp my hande vnto the LORde God most hygh possessor of heaven ad erth
23 pé, èmi kì yóò mú láti fọ́nrán òwú títí dé okùn bàtà, àti pé, èmi kí yóò mú ohun kan tí ṣe tìrẹ, kí ìwọ kí ó má ba à wí pé, ‘Mo sọ Abramu di ọlọ́rọ̀.’
that I will not take of all yt is thyne so moch as a thred or a shoulacher lest thou shuldest saye I haue made Abra ryche.
24 Èmi kì yóò gba ohunkóhun yàtọ̀ sí ohun tí àwọn ọkùnrin mi ti jẹ́, ṣùgbọ́n fi ìpín fún àwọn ọkùnrin tí ó bá mi lọ, Aneri, Eṣkolu àti Mamre. Jẹ́ kí wọn kí ó gba ìpín wọn.”
Saue only that which the yonge men haue eaten ad the partes of the men which went wyth me. Aner Escholl and Mamre. Let them take their partes.

< Genesis 14 >