< Genesis 14 >
1 Ní àsìkò yìí ni Amrafeli ọba Ṣinari, Arioku ọba Ellasari, Kedorlaomeri ọba Elamu àti Tidali ọba Goyimu
In a region to the east, there were four kings [who were friends/allies]. They were King Amraphel of Babylonia, King Arioch of Ellasar, King Chedorlaomer of Elam, and King Tidal of Goiim.
2 jáde lọ láti bá Bera ọba Sodomu, Birṣa ọba Gomorra, Ṣenabu ọba Adma, Ṣemeberi ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari) jagun.
In an area to the west, there were five other kings. They were King Bera of Sodom, King Birsha of Gomorrah, King Shinab of Admah, King Shemeber of Zeboiim, and the king of Bela, the city that is now called Zoar.
3 Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí ni ó kó ogun wọn jọ pọ̀ sí àfonífojì Siddimu (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀).
Those five kings and their armies gathered together in Siddim Valley, which is also called the Dead Sea [Valley], to fight against the four kings and their armies. King Chedorlaomer and his army [conquered the armies of those five kings, and demanded that those kings pay him tribute money each year].
4 Fún ọdún méjìlá gbáko ni wọ́n ti ń sin Kedorlaomeri bí ẹrú. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di ọdún kẹtàlá wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí i.
For twelve years he ruled them. But during the thirteenth year they rebelled [and refused to keep giving him tribute money].
5 Ní ọdún kẹrìnlá, ni Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí wọ́n ti jọ ni májẹ̀mú àṣepọ̀ wá, wọ́n ṣígun, wọ́n sì ṣẹ́gun ará Refaimu ní Aṣteroti-Karnaimu, àwọn ará Susimu ni Hamu, àwọn ará Emimu ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Kiriataimu,
The next year, King Chedorlaomer and the other kings that were his allies took their armies and defeated the Repha people-group in Ashteroth-Karnaim and the Zuz people-group in Ham, and the Emi people-group in Shaveh-Kiriathaim.
6 àti àwọn ará Hori ní orí òkè wọ̀n-ọn-nì Seiri, títí ó fi dé Eli-Parani ní etí ijù.
They also defeated the Hor people-group in the hilly area of Seir as far as El-Paran near the desert.
7 Wọ́n sì tún yípadà lọ sí En-Miṣpati (ti o túmọ̀ sí Kadeṣi), wọ́n sì ṣẹ́gun gbogbo ilẹ̀ àwọn Amaleki, àti àwọn ará Amori tí ó tẹ̀dó sí Hasason Tamari pẹ̀lú.
Then they turned back and went to Mishpat [city], which is now called Kadesh. They conquered all the land belonging to the Amalek people-group and the Amor people-group who were living in Hazazon-Tamar [town].
8 Nígbà náà ni ọba Sodomu, ọba Gomorra, ọba Adma, ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari), kó àwọn ọmọ-ogun wọn, wọ́n sì pa ibùdó ogun wọn sí Àfonífojì Siddimu,
Then the armies of the kings of Sodom, Gomorrah, Admah, Zeboiim and Bela marched out to fight the armies of the other four kings in Siddim Valley. That valley is close to the Salt/Dead Sea.
9 láti kojú ìjà sí Kedorlaomeri ọba Elamu, Tidali ọba Goyimu, Amrafeli ọba Ṣinari àti Arioku ọba Ellasari (ọba mẹ́rin kọjú ìjà sí ọba márùn-ún).
They fought against the armies of Chedorlaomer the king of Elam, Tidal the king of Goiim, Amraphel the king of Shinar, and Arioch the king of Ellasar. The armies of four kings were fighting against the armies of five kings.
10 Àfonífojì Siddimu sì kún fún kòtò ọ̀dà ilẹ̀, nígbà tí ọba Sodomu àti ọba Gomorra sì sá, díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin ogun náà ṣubú sínú àwọn kòtò náà, àwọn tókù sì sálọ sì orí òkè.
The Siddim Valley was full of tar pits. So when the armies of the kings of Sodom and Gomorrah tried to run away, many of the men fell into the tar pits. The others escaped and ran away to the hills.
11 Àwọn ọba mẹ́rẹ̀ẹ̀rin náà sì kó gbogbo ẹrù Sodomu àti Gomorra àti oúnjẹ wọn; wọ́n sì lọ.
As [the armies of the five kings] fled, [the armies of the four kings] seized all of the valuable things in Sodom and Gomorrah, including all the food.
12 Wọ́n sì mú Lọti ọmọ arákùnrin Abramu tí ń gbé ní Sodomu àti gbogbo ohun ìní rẹ̀.
They also captured Abram’s nephew Lot and his possessions, since he was living in Sodom at that time.
13 Ẹnìkan tí ó sá àsálà sì wá ròyìn fún Abramu, ará Heberu ni. Abramu sá ti tẹ̀dó sí ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó Mamre ará Amori, arákùnrin Eṣkolu àti Aneri: àwọn ẹni tí ó ń bá Abramu ní àṣepọ̀.
Abram was living near the big trees near Mamre, who belonged to the Amor people-group. Abram had made an agreement with Mamre and his two brothers, Eshcol and Aner, [that they would help each other if there was a war].
14 Nígbà tí Abramu gbọ́ wí pé, a di Lọti ní ìgbèkùn, ó kó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí a bí sí ilẹ̀ rẹ̀ tí ó sì ti kọ́ ni ogun jíjà jáde, wọ́n jẹ́ okòó lé lọ́ọ̀dúnrún ó dín méjì ènìyàn, ó sì lépa wọn títí dé Dani.
One of the men who escaped from the battle told Abram what had happened and that his nephew Lot had been captured and taken away. So Abram summoned 318 men who were his servants, men who had been with Abram since they were born. They all went together and pursued their enemies as far north as Dan [city].
15 Ní ọ̀gànjọ́ òru, Abramu pín àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sí méjì, ó sì kọlù wọ́n, ó sì ṣẹ́gun wọn, ó sì lé wọn títí dé Hoba tí ó wà ní apá òsì Damasku.
During the night, Abram divided the men into several groups, and they attacked their enemies from various directions and defeated them. They pursued them as far as Hobah, which was north of Damascus [city].
16 Gbogbo ìkógun ni ó rí gbà padà àti ọmọ arákùnrin rẹ̀, Lọti pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, àti àwọn obìnrin pẹ̀lú àwọn ènìyàn tókù.
Abram’s men recovered all of the goods that had been taken. They also rescued Lot and all his possessions and also the women and others who had been captured by their enemies.
17 Nígbà tí Abramu ti ṣẹ́gun Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí ó pẹ̀lú rẹ̀, ọba Sodomu lọ pàdé rẹ̀ ní àfonífojì Ṣafe (èyí ni àfonífojì Ọba).
As Abram was returning home after he and his men had defeated the armies of King Chedorlaomer and the other kings who had fought alongside him, the king of Sodom went north to meet him in Shaveh Valley, which people call the King’s Valley.
18 Melkisedeki ọba Salẹmu sì mú oúnjẹ àti ọtí wáìnì jáde wá. Òun ni àlùfáà Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo.
The king of Salem [city], whose name was Melchizedek, was also a priest who offered sacrifices to the Supreme God. He brought some bread and wine to Abram.
19 Ó sì súre fún Abramu, wí pé, “Ìbùkún ni fún Abramu ti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, Ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
Then he blessed Abram, saying “I ask the Supreme God, the one who created heaven and earth, to bless you.
20 Ìbùkún sì ni fún Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ, tí ó fi àwọn ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́.” Abramu sì fún un ní ìdámẹ́wàá ohun gbogbo.
The Supreme God has enabled you to defeat [MTY] your enemies, so we should praise/thank him.” Then Abram gave to Melchizedek a tenth part of all the things he had captured.
21 Ọba Sodomu sì wí fún Abramu pé, “Kó àwọn ènìyàn mi fún mi, ṣùgbọ́n mú àwọn ẹrù fún ara rẹ.”
The king of Sodom said to Abram, “You can keep all the goods you recovered. Just let me take back the people from my city whom you rescued.”
22 Ṣùgbọ́n Abramu dá ọba Sodomu lóhùn pé, “Mo ti búra fún Olúwa, Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, tí ó dá ọ̀run àti ayé, mo sì ti gbọ́wọ́ sókè,
But Abram said to the king of Sodom, “I have solemnly promised [MTY] to Yahweh, the Supreme God, the one who created heaven and earth,
23 pé, èmi kì yóò mú láti fọ́nrán òwú títí dé okùn bàtà, àti pé, èmi kí yóò mú ohun kan tí ṣe tìrẹ, kí ìwọ kí ó má ba à wí pé, ‘Mo sọ Abramu di ọlọ́rọ̀.’
that I will not accept even one thread or a thong of a sandal from anything that belongs to you. As a result, you will never be able to say, ‘I caused Abram to become rich.’
24 Èmi kì yóò gba ohunkóhun yàtọ̀ sí ohun tí àwọn ọkùnrin mi ti jẹ́, ṣùgbọ́n fi ìpín fún àwọn ọkùnrin tí ó bá mi lọ, Aneri, Eṣkolu àti Mamre. Jẹ́ kí wọn kí ó gba ìpín wọn.”
The only thing I will accept is the food that my men have eaten. But Aner, Eshcol, and Mamre went with me and fought alongside me, so let them also have a share of the goods we brought back.” [So the king of Sodom agreed to what he said].