< Genesis 14 >
1 Ní àsìkò yìí ni Amrafeli ọba Ṣinari, Arioku ọba Ellasari, Kedorlaomeri ọba Elamu àti Tidali ọba Goyimu
В дните не Сенаарския цар Амарфал, Еласарският цар Ариох, Еламският цар Ходологомор и Гоимският цар Тидал,
2 jáde lọ láti bá Bera ọba Sodomu, Birṣa ọba Gomorra, Ṣenabu ọba Adma, Ṣemeberi ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari) jagun.
тия царе отвориха война против Содомския цар Вера, Гоморския цар Верса, Адманския цар Сенав, Цевоимския цар Симовор и царя на Вала, (която е Сигор).
3 Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí ni ó kó ogun wọn jọ pọ̀ sí àfonífojì Siddimu (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀).
Всички тия се събраха в Сидимската долина (дето е сега Соленото Море).
4 Fún ọdún méjìlá gbáko ni wọ́n ti ń sin Kedorlaomeri bí ẹrú. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di ọdún kẹtàlá wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí i.
Дванадесет години бяха се подчинявали на Ходологомора, а в тринадесетата въстанаха.
5 Ní ọdún kẹrìnlá, ni Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí wọ́n ti jọ ni májẹ̀mú àṣepọ̀ wá, wọ́n ṣígun, wọ́n sì ṣẹ́gun ará Refaimu ní Aṣteroti-Karnaimu, àwọn ará Susimu ni Hamu, àwọn ará Emimu ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Kiriataimu,
В четиринадесетата година дойдоха Ходологомор и царете, които бяха с него, та поразиха рафаимите в Астарот-карнаим, зузимите в Хам, емимите в Сави-кириатаим
6 àti àwọn ará Hori ní orí òkè wọ̀n-ọn-nì Seiri, títí ó fi dé Eli-Parani ní etí ijù.
и хорейците в поляната им Сиир, до Елфаран, който е при пустинята.
7 Wọ́n sì tún yípadà lọ sí En-Miṣpati (ti o túmọ̀ sí Kadeṣi), wọ́n sì ṣẹ́gun gbogbo ilẹ̀ àwọn Amaleki, àti àwọn ará Amori tí ó tẹ̀dó sí Hasason Tamari pẹ̀lú.
А като се върнаха, дойдоха в Ен-мишнат, (който е Кадис), и поразиха цялата страна на амаликитяните, както и амореите, които живееха в Асасон-тамар.
8 Nígbà náà ni ọba Sodomu, ọba Gomorra, ọba Adma, ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari), kó àwọn ọmọ-ogun wọn, wọ́n sì pa ibùdó ogun wọn sí Àfonífojì Siddimu,
Тогава Содомският цар, Гоморският цар, Адманският цар, Цевоимският цар и царят на Вала, (която е Сигор), излязоха и се опълчиха против тях на бой в Сидимската долина:
9 láti kojú ìjà sí Kedorlaomeri ọba Elamu, Tidali ọba Goyimu, Amrafeli ọba Ṣinari àti Arioku ọba Ellasari (ọba mẹ́rin kọjú ìjà sí ọba márùn-ún).
против Еламския цар Ходологомор, Гиомския цар Тидал, Сенаарския цар Амарфал и Еласарския цар Ариох. Имаше четирима царе против петимата.
10 Àfonífojì Siddimu sì kún fún kòtò ọ̀dà ilẹ̀, nígbà tí ọba Sodomu àti ọba Gomorra sì sá, díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin ogun náà ṣubú sínú àwọn kòtò náà, àwọn tókù sì sálọ sì orí òkè.
А Сидимската долина беше пълна със смолни кладенци; и Содомският и Гоморският царе, като бягаха, паднаха в тях, а останалите избягаха на бърдото.
11 Àwọn ọba mẹ́rẹ̀ẹ̀rin náà sì kó gbogbo ẹrù Sodomu àti Gomorra àti oúnjẹ wọn; wọ́n sì lọ.
И победителите задигнаха всичкия имот на Содома и Гомора и всичката им храна и си отидоха.
12 Wọ́n sì mú Lọti ọmọ arákùnrin Abramu tí ń gbé ní Sodomu àti gbogbo ohun ìní rẹ̀.
Взеха и Аврамовия братанец Лот, който живееше в Содом, заедно с имота му и си отидоха.
13 Ẹnìkan tí ó sá àsálà sì wá ròyìn fún Abramu, ará Heberu ni. Abramu sá ti tẹ̀dó sí ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó Mamre ará Amori, arákùnrin Eṣkolu àti Aneri: àwọn ẹni tí ó ń bá Abramu ní àṣepọ̀.
А един от избавилите се дойде и извести това на евреина Аврам; той живееше при дъбовете на Амореца Мамврий, брат на Есхола и брат на Анера, които бяха Аврамови съюзници.
14 Nígbà tí Abramu gbọ́ wí pé, a di Lọti ní ìgbèkùn, ó kó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí a bí sí ilẹ̀ rẹ̀ tí ó sì ti kọ́ ni ogun jíjà jáde, wọ́n jẹ́ okòó lé lọ́ọ̀dúnrún ó dín méjì ènìyàn, ó sì lépa wọn títí dé Dani.
А като чу Аврам, че брат му бил пленен, изведе своите триста и осемнадесет обучени мъже, родени в неговия дом и гони неприятеля до Дан.
15 Ní ọ̀gànjọ́ òru, Abramu pín àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sí méjì, ó sì kọlù wọ́n, ó sì ṣẹ́gun wọn, ó sì lé wọn títí dé Hoba tí ó wà ní apá òsì Damasku.
И през нощта, той и слугите му, като се разделиха против тях, поразиха ги и ги гониха до Хова, която е от ляво на Дамаск.
16 Gbogbo ìkógun ni ó rí gbà padà àti ọmọ arákùnrin rẹ̀, Lọti pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, àti àwọn obìnrin pẹ̀lú àwọn ènìyàn tókù.
И възвърна всичкия имот, върна на брата си Лота с имота му, както и жените и людете.
17 Nígbà tí Abramu ti ṣẹ́gun Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí ó pẹ̀lú rẹ̀, ọba Sodomu lọ pàdé rẹ̀ ní àfonífojì Ṣafe (èyí ni àfonífojì Ọba).
И като се върна Аврам от поражението на Ходологомора и на царете, които бяха с него, Содомският цар излезе да го посрещне в Савинската долина, (която е Царевата долина).
18 Melkisedeki ọba Salẹmu sì mú oúnjẹ àti ọtí wáìnì jáde wá. Òun ni àlùfáà Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo.
Така Салимският цар Мелхиседек, който беше свещеник на Всемогъщия Бог, изнесе хляб и вино
19 Ó sì súre fún Abramu, wí pé, “Ìbùkún ni fún Abramu ti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, Ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
та го благослови, казвайки: Благословен да бъде Аврам от Всевишния Бог, Създател на небето и на земята;
20 Ìbùkún sì ni fún Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ, tí ó fi àwọn ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́.” Abramu sì fún un ní ìdámẹ́wàá ohun gbogbo.
благословен и Всевишният Бог, който предаде неприятелите ти в твоята ръка. И Аврам му даде десетък от всичко.
21 Ọba Sodomu sì wí fún Abramu pé, “Kó àwọn ènìyàn mi fún mi, ṣùgbọ́n mú àwọn ẹrù fún ara rẹ.”
А Содомският цар рече на Аврама: Дай ми човеците, а имота задръж за себе си.
22 Ṣùgbọ́n Abramu dá ọba Sodomu lóhùn pé, “Mo ti búra fún Olúwa, Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, tí ó dá ọ̀run àti ayé, mo sì ti gbọ́wọ́ sókè,
Но Аврам каза на Содомския цар: Аз дигнах ръката си пред Господа, Всевишния Бог, Създател на небето и земята,
23 pé, èmi kì yóò mú láti fọ́nrán òwú títí dé okùn bàtà, àti pé, èmi kí yóò mú ohun kan tí ṣe tìrẹ, kí ìwọ kí ó má ba à wí pé, ‘Mo sọ Abramu di ọlọ́rọ̀.’
и се заклех, че няма да взема нищо от твоето, ни конец ни ремък за обуща, да не би да речеш: Аз обогатих Аврама.
24 Èmi kì yóò gba ohunkóhun yàtọ̀ sí ohun tí àwọn ọkùnrin mi ti jẹ́, ṣùgbọ́n fi ìpín fún àwọn ọkùnrin tí ó bá mi lọ, Aneri, Eṣkolu àti Mamre. Jẹ́ kí wọn kí ó gba ìpín wọn.”
Приемам само онова, което изядоха момците; и дела на мъжете които отидоха с мене: Анер, Есхол и Мамври - те нека вземат дела си.