< Genesis 13 >
1 Abramu sì gòkè láti Ejibiti lọ sí ìhà gúúsù, pẹ̀lú aya rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní àti Lọti pẹ̀lú.
Xuning bilǝn Abram ayali wǝ uning barliⱪ nǝrsilirini ⱨǝmdǝ Lutni elip Misirdin qiⱪip, Ⱪanaanning jǝnubidiki Nǝgǝw yurtiƣa mangdi.
2 Abramu sì ti di ọlọ́rọ̀ gidigidi; ní ẹran ọ̀sìn, ó ní fàdákà àti wúrà.
U qaƣda Abramning mal-waran wǝ altun-kümüxliri kɵp bolup, helila bay idi.
3 Láti gúúsù, ó ń lọ láti ibìkan sí ibòmíràn títí ó fi dé ilẹ̀ Beteli, ní ibi tí àgọ́ rẹ̀ ti wà ní ìṣáájú rí, lágbedeméjì Beteli àti Ai.
U kɵqüp yürüp, jǝnubtiki Nǝgǝwdin Bǝyt-Əlgǝ, yǝni Bǝyt-Əl bilǝn Ayining otturisidiki ǝslidǝ qedir tikkǝn jayƣa,
4 Ní ibi pẹpẹ tí ó ti tẹ́ síbẹ̀ ní ìṣáájú, níbẹ̀ ni Abramu sì ń ké pe orúkọ Olúwa.
ⱪurbangaⱨ yasiƣan jayƣa ⱪaytip kǝldi. Abram xu yǝrdǝ Pǝrwǝrdigarning namini qaⱪirip ibadǝt ⱪildi.
5 Àti Lọti pẹ̀lú, tí ó ń bá Abramu rìn kiri, ní agbo ẹran, ọ̀wọ́ ẹran àti àgọ́.
Abram bilǝn billǝ mangƣan Lutningmu ⱪoy-kala padiliri wǝ qedirliri bar idi.
6 Ṣùgbọ́n ilẹ̀ náà kò le gbà wọ́n tí wọ́n bá ń gbé pọ̀, nítorí, ohun ìní wọn pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́, dé bi wí pé wọn kò le è gbé pọ̀.
Əmdi ular billǝ tursa, zemin ularni ⱪamdiyalmaytti;
7 Èdè-àìyedè sì bẹ̀rẹ̀ láàrín àwọn darandaran Abramu àti ti Lọti. Àwọn ará Kenaani àti àwọn ará Peresi sì ń gbé ní ilẹ̀ náà nígbà náà.
bu sǝwǝbtin Abramning padiqiliri bilǝn Lutning padiqilirining arisida jedǝl qiⱪti (u waⱪitta Ⱪanaaniylar bilǝn Pǝrizziylǝr xu zeminda turatti).
8 Abramu sì wí fún Lọti pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, má ṣe jẹ́ kí èdè-àìyedè kí ó wà láàrín èmi àti ìrẹ, àti láàrín àwọn darandaran wa, nítorí pé ẹbí kan ni àwa ṣe.
Xunga Abram Lutⱪa: — «Biz bolsaⱪ ⱪerindaxlarmiz, sǝn bilǝn mening aramda, mening padiqilirim bilǝn sening padiqiliring arisida talax-tartix pǝyda bolmisun.
9 Gbogbo ilẹ̀ ha kọ́ nìyí níwájú rẹ? Jẹ́ kí a pínyà. Bí ìwọ bá lọ sí apá ọ̀tún, èmi yóò lọ sí apá òsì, bí ó sì ṣe òsì ni ìwọ lọ, èmi yóò lọ sí apá ọ̀tún.”
Mana, aldingda pütkül zemin turmamdu? Əmdi sǝn mǝndin ayrilƣin; ǝgǝr sǝn sol tǝrǝpkǝ barsang, mǝn ong tǝrǝpkǝ baray; ǝgǝr sǝn ong tǝrǝpkǝ barsang, mǝn sol tǝrǝpkǝ baray», — dedi.
10 Lọti sì gbójú sókè, ó sì ri wí pé gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jordani ni omi rin dáradára bí ọgbà Olúwa, bí ilẹ̀ Ejibiti, ní ọ̀nà Soari. (Èyí ní ìṣáájú kí Olúwa tó pa Sodomu àti Gomorra run.)
U waⱪitta Lut nǝzǝr selip kɵrdiki, Iordan wadisidiki barliⱪ tüzlǝnglikning Zoar xǝⱨirigiqǝ ⱨǝmmila yǝrning süyi intayin mol idi; Pǝrwǝrdigar Sodom bilǝn Gomorrani wǝyran ⱪilixtin ilgiri bu yǝr bǝǝyni Pǝrwǝrdigarning beƣi, Misir zeminidǝk idi.
11 Nítorí náà Lọti yan gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jordani yìí fún ara rẹ̀, ó sì ń lọ sí ọ̀nà ìlà-oòrùn. Òun àti Abramu sì pínyà.
Xuning bilǝn Lut ɵzigǝ Iordan wadisidiki pütkül tüzlǝnglikni talliwaldi; andin Lut mǝxriⱪ tǝrǝpkǝ kɵqüp bardi. Xundaⱪ ⱪilip ikkiylǝn ayrildi.
12 Abramu ń gbé ni ilẹ̀ Kenaani, Lọti sì jókòó ní ìlú agbègbè àfonífojì náà, ó sì pàgọ́ rẹ̀ títí dé Sodomu.
Abram Ⱪanaan zeminida olturaⱪlaxti; Lut bolsa tüzlǝngliktiki xǝⱨǝrlǝrning arisida turdi; u bara-bara qedirlirini Sodom xǝⱨiri tǝrǝpkǝ yɵtkidi.
13 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Sodomu jẹ́ ènìyàn búburú, wọn sì ń dẹ́ṣẹ̀ gidigidi ni iwájú Olúwa.
Sodom hǝlⱪi rǝzil adǝmlǝr bolup, Pǝrwǝrdigarning nǝziridǝ tolimu eƣir gunaⱨkarlar idi.
14 Olúwa sì wí fún Abramu lẹ́yìn ìpinyà òun àti Lọti pé, “Gbé ojú rẹ sókè nísinsin yìí, kí o sì wò láti ibi tí o gbé wà a nì lọ sí ìhà àríwá àti sí ìhà gúúsù, sí ìlà-oòrùn àti sí ìwọ̀ rẹ̀.
Lut Abramdin ayrilip kǝtkǝndin keyin, Pǝrwǝrdigar Abramƣa: — Sǝn ǝmdi bexingni kɵtürüp, ɵzüng turƣan jaydin ximal wǝ jǝnubⱪa, mǝxriⱪ wǝ mǝƣrip tǝrǝpkǝ ⱪariƣin;
15 Gbogbo ilẹ̀ tí ìwọ ń wò o nì ni èmi ó fi fún ọ àti irú-ọmọ rẹ láéláé.
qünki sǝn ⱨazir kɵrüwatⱪan bu barliⱪ zeminni sanga wǝ nǝslinggǝ mǝnggülük berimǝn.
16 Èmi yóò mú kí irú-ọmọ rẹ kí ó pọ̀ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí ó bá ṣe pé ẹnikẹ́ni bá le è ka erùpẹ̀ ilẹ̀, nígbà náà ni yóò tó lè ka irú-ọmọ rẹ.
Sening nǝslingni yǝrdiki topidǝk kɵp ⱪilimǝn; xundaⱪki, ǝgǝr birsi yǝrdiki topini sanap qiⱪalisa, sening nǝslingnimu sanap qiⱪalixi mumkin bolidu.
17 Dìde, rìn òró àti ìbú ilẹ̀ náà já, nítorí ìwọ ni Èmi yóò fi fún.”
Ornungdin tur, bu zeminni uzunluⱪi wǝ kǝngliki boyiqǝ aylinip qiⱪⱪin; qünki Mǝn uni sanga ata ⱪilimǝn, — dedi.
18 Nígbà náà ni Abramu kó àgọ́ rẹ̀, ó sì wá, ó sì jókòó ní ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó Mamre, tí ó wà ní Hebroni. Níbẹ̀ ni ó gbé tẹ́ pẹpẹ kan sí fún Olúwa.
Xunga Abram qedirlirini yɵtkǝp, Ⱨebron xǝⱨirigǝ yeⱪin Mamrǝdiki dubzarliⱪning yeniƣa berip olturaⱪlaxti; u xu yǝrdǝ Pǝrwǝrdigarƣa atap bir ⱪurbangaⱨ yasidi.