< Genesis 13 >

1 Abramu sì gòkè láti Ejibiti lọ sí ìhà gúúsù, pẹ̀lú aya rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní àti Lọti pẹ̀lú.
Na ka haere mai a Aperama i Ihipa, ki te tonga, raua ko tana wahine, me ana mea katoa, me Rota hoki.
2 Abramu sì ti di ọlọ́rọ̀ gidigidi; ní ẹran ọ̀sìn, ó ní fàdákà àti wúrà.
He nui rawa hoki nga kararehe, te hiriwa me te koura ki a Aperama.
3 Láti gúúsù, ó ń lọ láti ibìkan sí ibòmíràn títí ó fi dé ilẹ̀ Beteli, ní ibi tí àgọ́ rẹ̀ ti wà ní ìṣáájú rí, lágbedeméjì Beteli àti Ai.
Na ka turia mai e ia, a ka haere i te tonga a tae noa ki Peteere, ki te wahi i oroko tu ai tona teneti, i waenganui o Peteere, o Hai,
4 Ní ibi pẹpẹ tí ó ti tẹ́ síbẹ̀ ní ìṣáájú, níbẹ̀ ni Abramu sì ń ké pe orúkọ Olúwa.
Ki te wahi i te aata i hanga e ia ki reira i te timatanga: na ka karanga a Aperama i reira ki te ingoa o Ihowa.
5 Àti Lọti pẹ̀lú, tí ó ń bá Abramu rìn kiri, ní agbo ẹran, ọ̀wọ́ ẹran àti àgọ́.
Na ko Rota, i haere tahi nei i a Aperama, he hipi ano ana, he kau, he teneti.
6 Ṣùgbọ́n ilẹ̀ náà kò le gbà wọ́n tí wọ́n bá ń gbé pọ̀, nítorí, ohun ìní wọn pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́, dé bi wí pé wọn kò le è gbé pọ̀.
A kihai i nui te whenua mo raua, hei nohoanga tahitanga mo raua: he nui hoki o raua rawa, te ahei raua te moho tahi.
7 Èdè-àìyedè sì bẹ̀rẹ̀ láàrín àwọn darandaran Abramu àti ti Lọti. Àwọn ará Kenaani àti àwọn ará Peresi sì ń gbé ní ilẹ̀ náà nígbà náà.
Na ka tautohe ki a ratou nga hepara a Aperama me nga hepara a Rota; na i taua whenua e noho ana te Kanaani me te Perihi i taua wa.
8 Abramu sì wí fún Lọti pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, má ṣe jẹ́ kí èdè-àìyedè kí ó wà láàrín èmi àti ìrẹ, àti láàrín àwọn darandaran wa, nítorí pé ẹbí kan ni àwa ṣe.
Na ka mea a Aperama ki a Rota, Kaua ra taua e whakatete ki a taua, kaua hoki a taua hepara e whakatete ki a ratou; he teina nei hoki, he tuakana taua.
9 Gbogbo ilẹ̀ ha kọ́ nìyí níwájú rẹ? Jẹ́ kí a pínyà. Bí ìwọ bá lọ sí apá ọ̀tún, èmi yóò lọ sí apá òsì, bí ó sì ṣe òsì ni ìwọ lọ, èmi yóò lọ sí apá ọ̀tún.”
Kahore ianei te whenua katoa i tou aroaro? tena, wehe atu koe i ahau: ki te anga koe ki maui, ka ahu ahau ki matau, a ki te haere koe ki matau, na ka ahu ahau ki maui.
10 Lọti sì gbójú sókè, ó sì ri wí pé gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jordani ni omi rin dáradára bí ọgbà Olúwa, bí ilẹ̀ Ejibiti, ní ọ̀nà Soari. (Èyí ní ìṣáájú kí Olúwa tó pa Sodomu àti Gomorra run.)
Na ka anga ake nga kanohi o Rota, ka titiro ki te mania katoa o Horano, he makuku katoa, i te mea kahore ano kia whakangaromia noatia a Horoma, a Komora e Ihowa, he pera ano me te kari a Ihowa, me te whenua hoki o Ihipa, i tou haerenga ki Toara.
11 Nítorí náà Lọti yan gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jordani yìí fún ara rẹ̀, ó sì ń lọ sí ọ̀nà ìlà-oòrùn. Òun àti Abramu sì pínyà.
Na ka whiriwhiria e Rota ko te mania katoa o Horano mana; na ka haere a Rota whaka te rawhiti: a ka wehe raua i a raua.
12 Abramu ń gbé ni ilẹ̀ Kenaani, Lọti sì jókòó ní ìlú agbègbè àfonífojì náà, ó sì pàgọ́ rẹ̀ títí dé Sodomu.
Ko Aperama i noho kite whenua o Kanaana, ko Rota i noho ki nga pa o te mania, a whakaturia ana e ia tona teneti ki Horoma.
13 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Sodomu jẹ́ ènìyàn búburú, wọn sì ń dẹ́ṣẹ̀ gidigidi ni iwájú Olúwa.
Na he kino nga tangata o Horoma, he hunga hara rawa ki te aroaro o Ihowa.
14 Olúwa sì wí fún Abramu lẹ́yìn ìpinyà òun àti Lọti pé, “Gbé ojú rẹ sókè nísinsin yìí, kí o sì wò láti ibi tí o gbé wà a nì lọ sí ìhà àríwá àti sí ìhà gúúsù, sí ìlà-oòrùn àti sí ìwọ̀ rẹ̀.
Na ka mea a Ihowa ki a Aperama, i muri i te wehenga atu o Rota i a ia, Anga ake ou kanohi, titiro atu hoki i te wahi e tu na koe, ki te raki, ki te tonga, ki te rawhiti, ki te hauauru:
15 Gbogbo ilẹ̀ tí ìwọ ń wò o nì ni èmi ó fi fún ọ àti irú-ọmọ rẹ láéláé.
Ko te whenua katoa hoki e kite atu na koe, ka hoatu e ahau ki a koe, ki tou uri hoki ake tonu atu.
16 Èmi yóò mú kí irú-ọmọ rẹ kí ó pọ̀ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí ó bá ṣe pé ẹnikẹ́ni bá le è ka erùpẹ̀ ilẹ̀, nígbà náà ni yóò tó lè ka irú-ọmọ rẹ.
Ka meinga hoki e ahau ou uri kia rite ki te puehu o te whenua: a ki te ahei i tetahi tangata te tatau i te puehu o te whenua, e taua ano hoki ou uri.
17 Dìde, rìn òró àti ìbú ilẹ̀ náà já, nítorí ìwọ ni Èmi yóò fi fún.”
Whakatika, haereerea te whenua, tona roa, tona whanui; no te mea ka hoatu e ahau ki a koe.
18 Nígbà náà ni Abramu kó àgọ́ rẹ̀, ó sì wá, ó sì jókòó ní ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó Mamre, tí ó wà ní Hebroni. Níbẹ̀ ni ó gbé tẹ́ pẹpẹ kan sí fún Olúwa.
Na nekehia ana tona teneti e Aperama, a haere ana, noho ana ki nga oki i Mamere, ki era i Heperona, a hanga ana e ia tetahi aata ma Ihowa ki reira.

< Genesis 13 >