< Genesis 12 >

1 Olúwa sì wí fún Abramu, “Jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ àti kúrò lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ, lọ sí ilẹ̀ kan tí èmi yóò fihàn ọ́.
I rzekł Pan do Abrama: Wynijdź z ziemi twej, i od rodziny twojej, i z domu ojca twego, do ziemi, którąć pokażę.
2 “Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, èmi yóò sì bùkún fún ọ; èmi yóò sọ orúkọ rẹ di ńlá, ìbùkún ni ìwọ yóò sì jásí.
A uczynię cię w naród wielki, i będęć błogosławił, i uwielbię imię twoje, i będziesz błogosławieństwem.
3 Èmi yóò bùkún fún àwọn tí ó súre fún ọ, ẹni tí ó fi ọ́ ré ni Èmi yóò fi ré; nínú rẹ ni a ó bùkún gbogbo ìdílé ayé.”
I będę błogosławił błogosławiącym tobie; a przeklinające cię przeklinać będę: i będą błogosławione w tobie wszystkie narody ziemi.
4 Bẹ́ẹ̀ ni Abramu lọ bí Olúwa ti sọ fún un. Lọti náà sì bá a lọ. Abramu jẹ́ ẹni àrùndínlọ́gọ́rin ọdún nígbà tí ó jáde kúrò ní Harani.
Tedy wyszedł Abram, jako mu rozkazał Pan. Poszedł też z nim i Lot. A było Abramowi siedmdziesiąt lat i pięć lat, gdy wyszedł z Haran.
5 Abramu sì mú Sarai aya rẹ̀, àti Lọti ọmọ arákùnrin rẹ̀: gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti kójọ àti àwọn ènìyàn tí wọ́n ní ní Harani. Wọ́n sì jáde lọ sí ilẹ̀ Kenaani. Wọ́n sì gúnlẹ̀ síbẹ̀.
Wziął też Abram Saraj żonę swoję, i Lota syna brata swego, i wszystkę swą majętność, której nabyli, i dusze, których nabyli w Haranie, i wyszli, aby szli do ziemi Chananejskiej; i przyszli do ziemi Chananejskiej.
6 Abramu sì rìn la ilẹ̀ náà já títí dé ibi igi ńlá kan tí à ń pè ni More ní Ṣekemu. Àwọn ará Kenaani sì wà ní ilẹ̀ náà.
Tedy przeszedł Abram ziemię onę aż do miejsca Sychem, i aż do równiny Morech; a Chananejczyk na ten czas był w onej ziemi.
7 Olúwa sì farahan Abramu, ó sì wí fún un pé, “Irú-ọmọ rẹ ni Èmi yóò fi ilẹ̀ yìí fún.” Abramu tẹ́ pẹpẹ kan síbẹ̀ fún Olúwa tí ó fi ara hàn án.
I ukazał się Pan Abramowi, i rzekł: Nasieniu twemu dam ziemię tę; i zbudował tam ołtarz Panu, który mu się ukazał.
8 Ó sì kúrò níbẹ̀ lọ sí agbègbè àwọn òkè kan ní ìhà ìlà-oòrùn Beteli, ó sì pàgọ́ rẹ̀ síbẹ̀. Beteli wà ní ìwọ̀-oòrùn, Ai wà ní ìlà-oòrùn. Ó tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ fún Olúwa, ó sì ké pe orúkọ Olúwa.
A przeszedł stamtąd do góry na wschód Betela, i rozbił tam namiot swój, mając Betel od zachodu, a Haj od wschodu; i zbudował tam ołtarz Panu, i wzywał imienia Pańskiego.
9 Nígbà náà ni Abramu tẹ̀síwájú sí ìhà gúúsù.
Potem ruszył się Abram idąc, i ciągnąc ku południu.
10 Ìyàn kan sì mú ní ilẹ̀ náà, Abramu sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti ṣe àtìpó níbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, nítorí ìyàn náà mú gidigidi.
A był głód w ziemi onej: przeto zstąpił Abram do Egiptu, aby tam był gościem do czasu, ciężki bowiem był głód w ziemi.
11 Bí ó ti ku díẹ̀ kí ó wọ Ejibiti, ó wí fún Sarai, aya rẹ̀ pé, “Mo mọ̀ pé arẹwà obìnrin ni ìwọ,
I stało się, gdy już blisko był, aby wszedł do Egiptu, rzekł do Sarai, żony swej: Oto teraz wiem, żeś niewiasta piękna na wejrzeniu.
12 nígbà tí àwọn ará Ejibiti bá rí ọ, wọn yóò wí pé, ‘Aya rẹ̀ nìyí.’ Wọn yóò si pa mí, ṣùgbọ́n wọn yóò dá ọ sí.
I stanie się, że gdy cię obaczą Egipczanie, rzeką: Żona to jego; i zabiją mię, a ciebie żywo zostawią.
13 Nítorí náà, sọ pé, arábìnrin mi ni ìwọ, wọn yóò sì ṣe mí dáradára, a ó sì dá ẹ̀mí mi sí nítorí tìrẹ.”
Mów, proszę, żeś jest siostrą moją, aby mi dobrze było dla ciebie, i żywa została dla ciebie dusza moja.
14 Nígbà tí Abramu dé Ejibiti, àwọn ará Ejibiti ri i pé aya rẹ̀ rẹwà gidigidi.
I stało się, gdy wszedł Abram do Egiptu, ujrzeli Egipczanie niewiastę onę, iż była bardzo piękną.
15 Nígbà tí àwọn ìjòyè Farao sì rí i, wọ́n ròyìn rẹ̀ níwájú Farao, wọ́n sì mú un lọ sí ààfin.
Widzieli ją też książęta Faraonowe, i chwalili ją przed nim; i wzięto onę niewiastę do domu Faraonowego.
16 Ó sì kẹ́ Abramu dáradára nítorí Sarai, Abramu sì ní àgùntàn àti màlúù, akọ àti abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin, pẹ̀lú ìbákasẹ.
Który Abramowi dobrze czynił dla niej; i miał Abram owce, i woły, i osły i sługi, i służebnice, i oślice, i wielbłądy.
17 Olúwa sì rán àjàkálẹ̀-ààrùn búburú sí Farao àti ilé rẹ̀, nítorí Sarai aya Abramu.
Ale uderzył Pan Faraona plagami wielkiemi, i dom jego dla Sarai, żony Abramowej.
18 Nítorí náà Farao ránṣẹ́ pe Abramu, ó sì wí fun pé, “Èwo ni ìwọ ṣe sí mi yìí? Kí ló dé tí ìwọ kò sọ fún mi pé aya rẹ ní í ṣe?
Przetoż wezwał Farao Abrama, i rzekł: Cóżeś mi to uczynił? czemuś mi nie oznajmił, że to żona twoja?
19 Èéṣe tí o fi wí pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ tí èmi sì fi fẹ́ ẹ gẹ́gẹ́ bí aya? Nítorí náà nísinsin yìí, aya rẹ náà nìyí, mú un kí o sì máa lọ.”
Przeczżeś powiedział, siostra to moja? i wziąłem ją sobie za żonę; a teraz, oto żona twoja, weźmijże ją, a idź.
20 Nígbà náà ni Farao pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ nípa Abramu, wọ́n sì lé e jáde ti òun ti aya rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní.
I przykazał o nim Farao mężom, i puścili go wolno i żonę jego, i wszystko, co było jego.

< Genesis 12 >