< Genesis 12 >

1 Olúwa sì wí fún Abramu, “Jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ àti kúrò lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ, lọ sí ilẹ̀ kan tí èmi yóò fihàn ọ́.
Og Herren sa til Abram: Dra bort fra ditt land og fra din slekt og fra din fars hus til det land som jeg vil vise dig!
2 “Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, èmi yóò sì bùkún fún ọ; èmi yóò sọ orúkọ rẹ di ńlá, ìbùkún ni ìwọ yóò sì jásí.
Og jeg vil gjøre dig til et stort folk; jeg vil velsigne dig og gjøre ditt navn stort, og du skal bli en velsignelse!
3 Èmi yóò bùkún fún àwọn tí ó súre fún ọ, ẹni tí ó fi ọ́ ré ni Èmi yóò fi ré; nínú rẹ ni a ó bùkún gbogbo ìdílé ayé.”
Og jeg vil velsigne dem som velsigner dig, og den som forbanner dig, vil jeg forbanne; og i dig skal alle jordens slekter velsignes
4 Bẹ́ẹ̀ ni Abramu lọ bí Olúwa ti sọ fún un. Lọti náà sì bá a lọ. Abramu jẹ́ ẹni àrùndínlọ́gọ́rin ọdún nígbà tí ó jáde kúrò ní Harani.
Så drog Abram bort som Herren hadde sagt til ham, og Lot drog med ham. Og Abram var fem og sytti år gammel da han drog ut fra Karan.
5 Abramu sì mú Sarai aya rẹ̀, àti Lọti ọmọ arákùnrin rẹ̀: gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti kójọ àti àwọn ènìyàn tí wọ́n ní ní Harani. Wọ́n sì jáde lọ sí ilẹ̀ Kenaani. Wọ́n sì gúnlẹ̀ síbẹ̀.
Og Abram tok med sig Sarai, sin hustru, og Lot, sin brorsønn, og all deres eiendom som de hadde vunnet, og de folk som de hadde fått i Karan; og de drog ut for å reise til Kana'ans land, og de kom til Kana'ans land.
6 Abramu sì rìn la ilẹ̀ náà já títí dé ibi igi ńlá kan tí à ń pè ni More ní Ṣekemu. Àwọn ará Kenaani sì wà ní ilẹ̀ náà.
Og Abram drog gjennem landet til Sikem-bygden, til Mores terebintelund; og kana'anittene bodde dengang der i landet.
7 Olúwa sì farahan Abramu, ó sì wí fún un pé, “Irú-ọmọ rẹ ni Èmi yóò fi ilẹ̀ yìí fún.” Abramu tẹ́ pẹpẹ kan síbẹ̀ fún Olúwa tí ó fi ara hàn án.
Da åpenbarte Herren sig for Abram og sa: Din ætt vil jeg gi dette land. Og han bygget der et alter for Herren, som hadde åpenbaret sig for ham.
8 Ó sì kúrò níbẹ̀ lọ sí agbègbè àwọn òkè kan ní ìhà ìlà-oòrùn Beteli, ó sì pàgọ́ rẹ̀ síbẹ̀. Beteli wà ní ìwọ̀-oòrùn, Ai wà ní ìlà-oòrùn. Ó tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ fún Olúwa, ó sì ké pe orúkọ Olúwa.
Derfra flyttet han til fjellene østenfor Betel og slo op sitt telt med Betel i vest og Ai i øst; og han bygget der et alter for Herren og påkalte Herrens navn.
9 Nígbà náà ni Abramu tẹ̀síwájú sí ìhà gúúsù.
Og Abram drog efter hvert videre til sydlandet.
10 Ìyàn kan sì mú ní ilẹ̀ náà, Abramu sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti ṣe àtìpó níbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, nítorí ìyàn náà mú gidigidi.
Så blev det hungersnød i landet; og Abram drog ned til Egypten for å opholde sig der, for hungersnøden var stor i landet.
11 Bí ó ti ku díẹ̀ kí ó wọ Ejibiti, ó wí fún Sarai, aya rẹ̀ pé, “Mo mọ̀ pé arẹwà obìnrin ni ìwọ,
Og da han ikke hadde langt igjen til Egypten, sa han til Sarai, sin hustru: Jeg vet jo at du er en vakker kvinne.
12 nígbà tí àwọn ará Ejibiti bá rí ọ, wọn yóò wí pé, ‘Aya rẹ̀ nìyí.’ Wọn yóò si pa mí, ṣùgbọ́n wọn yóò dá ọ sí.
Når nu egypterne får se dig, vil de si: Dette er hans hustru, og så slår de mig ihjel og lar dig leve.
13 Nítorí náà, sọ pé, arábìnrin mi ni ìwọ, wọn yóò sì ṣe mí dáradára, a ó sì dá ẹ̀mí mi sí nítorí tìrẹ.”
Kjære, si at du er min søster, så det kan gå mig vel, og mitt liv kan bli spart for din skyld!
14 Nígbà tí Abramu dé Ejibiti, àwọn ará Ejibiti ri i pé aya rẹ̀ rẹwà gidigidi.
Da nu Abram kom til Egypten, så egypterne at kvinnen var meget vakker.
15 Nígbà tí àwọn ìjòyè Farao sì rí i, wọ́n ròyìn rẹ̀ níwájú Farao, wọ́n sì mú un lọ sí ààfin.
Også Faraos høvdinger så henne og roste henne for Farao, og så blev kvinnen hentet til Faraos hus.
16 Ó sì kẹ́ Abramu dáradára nítorí Sarai, Abramu sì ní àgùntàn àti màlúù, akọ àti abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin, pẹ̀lú ìbákasẹ.
Og han gjorde vel imot Abram for hennes skyld, og han fikk både småfe og storfe og asener og træler og trælkvinner og aseninner og kameler.
17 Olúwa sì rán àjàkálẹ̀-ààrùn búburú sí Farao àti ilé rẹ̀, nítorí Sarai aya Abramu.
Men Herren hjemsøkte Farao og hans hus med store plager for Abrams hustru Sarais skyld.
18 Nítorí náà Farao ránṣẹ́ pe Abramu, ó sì wí fun pé, “Èwo ni ìwọ ṣe sí mi yìí? Kí ló dé tí ìwọ kò sọ fún mi pé aya rẹ ní í ṣe?
Da kalte Farao Abram til sig og sa: Hvad er det du har gjort imot mig? Hvorfor lot du mig ikke vite at hun er din hustru?
19 Èéṣe tí o fi wí pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ tí èmi sì fi fẹ́ ẹ gẹ́gẹ́ bí aya? Nítorí náà nísinsin yìí, aya rẹ náà nìyí, mú un kí o sì máa lọ.”
Hvorfor sa du: Hun er min søster, så jeg tok henne til hustru? Se, her har du din hustru, ta henne og gå!
20 Nígbà náà ni Farao pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ nípa Abramu, wọ́n sì lé e jáde ti òun ti aya rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní.
Og Farao gav nogen menn befaling til å følge ham på veien med hans hustru og alt det han eide.

< Genesis 12 >