< Genesis 12 >

1 Olúwa sì wí fún Abramu, “Jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ àti kúrò lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ, lọ sí ilẹ̀ kan tí èmi yóò fihàn ọ́.
Nake Jehova nĩeerĩte Aburamu atĩrĩ, “Thaama uume bũrũri wanyu na ũtige andũ anyu, na nyũmba ya thoguo, ũthiĩ bũrũri ũrĩa ngaakuonia.
2 “Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, èmi yóò sì bùkún fún ọ; èmi yóò sọ orúkọ rẹ di ńlá, ìbùkún ni ìwọ yóò sì jásí.
“Niĩ nĩngagũtua rũrĩrĩ rũnene, na nĩngakũrathima; nĩngatũma rĩĩtwa rĩaku rĩgĩe igweta, nawe nĩũgatuĩka kĩrathimo.
3 Èmi yóò bùkún fún àwọn tí ó súre fún ọ, ẹni tí ó fi ọ́ ré ni Èmi yóò fi ré; nínú rẹ ni a ó bùkún gbogbo ìdílé ayé.”
Nĩngarathima arĩa magaakũrathima, na ũrĩa o wothe ũgaakũruma na niĩ nĩngatũma anyiitwo nĩ kĩrumi; nao andũ othe a thĩ nĩmakarathimwo nĩ ũndũ waku.”
4 Bẹ́ẹ̀ ni Abramu lọ bí Olúwa ti sọ fún un. Lọti náà sì bá a lọ. Abramu jẹ́ ẹni àrùndínlọ́gọ́rin ọdún nígbà tí ó jáde kúrò ní Harani.
Nĩ ũndũ ũcio Aburamu akiumagara agĩthiĩ, o ta ũrĩa Jehova aamwathĩte; nake Loti agĩthiĩ nake. Aburamu aarĩ na mĩaka mĩrongo mũgwanja na ĩtano rĩrĩa oimire Harani.
5 Abramu sì mú Sarai aya rẹ̀, àti Lọti ọmọ arákùnrin rẹ̀: gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti kójọ àti àwọn ènìyàn tí wọ́n ní ní Harani. Wọ́n sì jáde lọ sí ilẹ̀ Kenaani. Wọ́n sì gúnlẹ̀ síbẹ̀.
Nake nĩathiire na mũtumia wake Sarai, na Loti, mũriũ wa mũrũ wa nyina, na indo ciothe iria maagĩte nacio, na andũ arĩa maagĩte nao kũu Harani, na makiumagara marorete bũrũri wa Kaanani, na magĩkinya kuo.
6 Abramu sì rìn la ilẹ̀ náà já títí dé ibi igi ńlá kan tí à ń pè ni More ní Ṣekemu. Àwọn ará Kenaani sì wà ní ilẹ̀ náà.
Aburamu agĩtuĩkanĩria bũrũri ũcio agĩkinya handũ haarĩ na mũtĩ mũnene wa More kũu Shekemu. Hĩndĩ ĩyo Akaanani nĩo maatũũraga bũrũri ũcio.
7 Olúwa sì farahan Abramu, ó sì wí fún un pé, “Irú-ọmọ rẹ ni Èmi yóò fi ilẹ̀ yìí fún.” Abramu tẹ́ pẹpẹ kan síbẹ̀ fún Olúwa tí ó fi ara hàn án.
Nake Jehova akiumĩrĩra Aburamu, akĩmwĩra atĩrĩ, “Bũrũri ũyũ nĩguo ngaahe rũciaro rwaku.” Nĩ ũndũ ũcio Aburamu agĩakĩra Jehova kĩgongona hau, o we Jehova ũcio wamuumĩrĩire.
8 Ó sì kúrò níbẹ̀ lọ sí agbègbè àwọn òkè kan ní ìhà ìlà-oòrùn Beteli, ó sì pàgọ́ rẹ̀ síbẹ̀. Beteli wà ní ìwọ̀-oòrùn, Ai wà ní ìlà-oòrùn. Ó tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ fún Olúwa, ó sì ké pe orúkọ Olúwa.
Kuuma hau agĩthiĩ erekeire irĩma iria irĩ mwena wa irathĩro wa itũũra rĩa Betheli, na akĩamba hema yake, Betheli ĩgĩkorwo ĩrĩ mwena wa ithũĩro na itũũra rĩa Ai rĩrĩ mwena wa irathĩro. Hau nĩho aakĩire Jehova kĩgongona na agĩkaĩra rĩĩtwa rĩa Jehova.
9 Nígbà náà ni Abramu tẹ̀síwájú sí ìhà gúúsù.
Thuutha-inĩ Aburamu akiumagara rĩngĩ agĩthiĩ na mbere na rũgendo arorete Negevu.
10 Ìyàn kan sì mú ní ilẹ̀ náà, Abramu sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti ṣe àtìpó níbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, nítorí ìyàn náà mú gidigidi.
Na rĩrĩ, nĩ kwagĩire ngʼaragu bũrũri ũcio, nake Aburamu agĩikũrũka athiĩ Misiri agaikare kuo kwa ihinda, tondũ ngʼaragu nĩ yarĩ nene mũno.
11 Bí ó ti ku díẹ̀ kí ó wọ Ejibiti, ó wí fún Sarai, aya rẹ̀ pé, “Mo mọ̀ pé arẹwà obìnrin ni ìwọ,
Arĩ o hakuhĩ gũtoonya Misiri-rĩ, akĩĩra mũtumia wake Sarai atĩrĩ, “Nĩnjũũĩ atĩ ũrĩ mũndũ-wa-nja kĩĩrorerwa.
12 nígbà tí àwọn ará Ejibiti bá rí ọ, wọn yóò wí pé, ‘Aya rẹ̀ nìyí.’ Wọn yóò si pa mí, ṣùgbọ́n wọn yóò dá ọ sí.
Na rĩrĩ, andũ a Misiri makuona mekuuga atĩrĩ, ‘Ũyũ nĩ mũtumia wake,’ tondũ ũcio manjũrage no wee makũreke ũtũũre muoyo, makuoe.
13 Nítorí náà, sọ pé, arábìnrin mi ni ìwọ, wọn yóò sì ṣe mí dáradára, a ó sì dá ẹ̀mí mi sí nítorí tìrẹ.”
Nĩ ũndũ ũcio wee uga atĩ ũrĩ mwarĩ wa baba, nĩgeetha ũhonokie muoyo wakwa na manjĩke wega nĩ ũndũ waku.”
14 Nígbà tí Abramu dé Ejibiti, àwọn ará Ejibiti ri i pé aya rẹ̀ rẹwà gidigidi.
Rĩrĩa Aburamu aakinyire Misiri, andũ a Misiri makĩona atĩ mũtumia wake aarĩ kĩĩrorerwa biũ.
15 Nígbà tí àwọn ìjòyè Farao sì rí i, wọ́n ròyìn rẹ̀ níwájú Farao, wọ́n sì mú un lọ sí ààfin.
Nao anene a Firaũni mamuona, makĩmũgaathĩrĩria kũrĩ Firaũni, na makĩmuoya makĩmũtwara nyũmba-inĩ yake ya ũthamaki.
16 Ó sì kẹ́ Abramu dáradára nítorí Sarai, Abramu sì ní àgùntàn àti màlúù, akọ àti abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin, pẹ̀lú ìbákasẹ.
Nake Firaũni agĩtuga Aburamu nĩ ũndũ wa Sarai, na Aburamu akĩgĩa na mbũri na ngʼombe, na ndigiri cia njamba na cia nga, ndungata cia arũme na cia airĩtu, na ngamĩĩra.
17 Olúwa sì rán àjàkálẹ̀-ààrùn búburú sí Farao àti ilé rẹ̀, nítorí Sarai aya Abramu.
No Jehova akĩnyamaria Firaũni na nyũmba yake na mĩrimũ mĩũru nĩ ũndũ wa Sarai, mũtumia wa Aburamu.
18 Nítorí náà Farao ránṣẹ́ pe Abramu, ó sì wí fun pé, “Èwo ni ìwọ ṣe sí mi yìí? Kí ló dé tí ìwọ kò sọ fún mi pé aya rẹ ní í ṣe?
Nĩ ũndũ ũcio Firaũni agĩtũmanĩra Aburamu akĩmũũria atĩrĩ, “Nĩ atĩa ũũ ũnjĩkĩte? Nĩ kĩĩ kĩagiririe ũnjĩĩre atĩ ũyũ nĩ mũtumia waku?
19 Èéṣe tí o fi wí pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ tí èmi sì fi fẹ́ ẹ gẹ́gẹ́ bí aya? Nítorí náà nísinsin yìí, aya rẹ náà nìyí, mú un kí o sì máa lọ.”
Nĩ kĩĩ gĩatũmire uuge, ‘Ũyũ nĩ mwarĩ wa baba,’ na nĩkĩo ndaamuoire atuĩke mũtumia wakwa? Mũtumia waku nĩwe ũyũ! Muoye mũthiĩ!”
20 Nígbà náà ni Farao pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ nípa Abramu, wọ́n sì lé e jáde ti òun ti aya rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní.
Hĩndĩ ĩyo Firaũni agĩathana akĩĩra andũ ake ũrĩa megwĩka Aburamu, nao makĩmumagaria arĩ na mũtumia wake na indo ciothe iria aarĩ nacio.

< Genesis 12 >