< Genesis 12 >

1 Olúwa sì wí fún Abramu, “Jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ àti kúrò lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ, lọ sí ilẹ̀ kan tí èmi yóò fihàn ọ́.
Yahvé dit à Abram: « Quitte ton pays, ta famille et la maison de ton père, et va dans le pays que je te montrerai.
2 “Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, èmi yóò sì bùkún fún ọ; èmi yóò sọ orúkọ rẹ di ńlá, ìbùkún ni ìwọ yóò sì jásí.
Je ferai de toi une grande nation. Je te bénirai et je rendrai ton nom grand. Tu seras une bénédiction.
3 Èmi yóò bùkún fún àwọn tí ó súre fún ọ, ẹni tí ó fi ọ́ ré ni Èmi yóò fi ré; nínú rẹ ni a ó bùkún gbogbo ìdílé ayé.”
Je bénirai ceux qui te béniront, et je maudirai celui qui te traitera avec mépris. Toutes les familles de la terre seront bénies par toi. »
4 Bẹ́ẹ̀ ni Abramu lọ bí Olúwa ti sọ fún un. Lọti náà sì bá a lọ. Abramu jẹ́ ẹni àrùndínlọ́gọ́rin ọdún nígbà tí ó jáde kúrò ní Harani.
Et Abram partit, comme Yahvé le lui avait dit. Lot partit avec lui. Abram était âgé de soixante-quinze ans lorsqu'il partit de Haran.
5 Abramu sì mú Sarai aya rẹ̀, àti Lọti ọmọ arákùnrin rẹ̀: gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti kójọ àti àwọn ènìyàn tí wọ́n ní ní Harani. Wọ́n sì jáde lọ sí ilẹ̀ Kenaani. Wọ́n sì gúnlẹ̀ síbẹ̀.
Abram prit Saraï, sa femme, Lot, le fils de son frère, tous les biens qu'ils avaient rassemblés, et le peuple qu'ils avaient acquis à Haran, et ils partirent pour aller au pays de Canaan. Ils entrèrent dans le pays de Canaan.
6 Abramu sì rìn la ilẹ̀ náà já títí dé ibi igi ńlá kan tí à ń pè ni More ní Ṣekemu. Àwọn ará Kenaani sì wà ní ilẹ̀ náà.
Abram traversa le pays jusqu'au lieu-dit Sichem, au chêne de Moreh. En ce temps-là, les Cananéens étaient dans le pays.
7 Olúwa sì farahan Abramu, ó sì wí fún un pé, “Irú-ọmọ rẹ ni Èmi yóò fi ilẹ̀ yìí fún.” Abramu tẹ́ pẹpẹ kan síbẹ̀ fún Olúwa tí ó fi ara hàn án.
Yahvé apparut à Abram et dit: « Je donnerai ce pays à ta descendance. » Il y bâtit un autel à Yahvé, qui lui était apparu.
8 Ó sì kúrò níbẹ̀ lọ sí agbègbè àwọn òkè kan ní ìhà ìlà-oòrùn Beteli, ó sì pàgọ́ rẹ̀ síbẹ̀. Beteli wà ní ìwọ̀-oòrùn, Ai wà ní ìlà-oòrùn. Ó tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ fún Olúwa, ó sì ké pe orúkọ Olúwa.
Il partit de là pour aller sur la montagne à l'est de Béthel et planta sa tente, ayant Béthel à l'ouest et Aï à l'est. Là, il bâtit un autel à Yahvé et invoqua le nom de Yahvé.
9 Nígbà náà ni Abramu tẹ̀síwájú sí ìhà gúúsù.
Abram voyagea, toujours en direction du sud.
10 Ìyàn kan sì mú ní ilẹ̀ náà, Abramu sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti ṣe àtìpó níbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, nítorí ìyàn náà mú gidigidi.
Il y eut une famine dans le pays. Abram descendit en Égypte pour y vivre comme un étranger, car la famine sévissait dans le pays.
11 Bí ó ti ku díẹ̀ kí ó wọ Ejibiti, ó wí fún Sarai, aya rẹ̀ pé, “Mo mọ̀ pé arẹwà obìnrin ni ìwọ,
Lorsqu'il fut sur le point d'entrer en Égypte, il dit à Saraï, sa femme: « Voici, je sais que tu es une femme belle à regarder.
12 nígbà tí àwọn ará Ejibiti bá rí ọ, wọn yóò wí pé, ‘Aya rẹ̀ nìyí.’ Wọn yóò si pa mí, ṣùgbọ́n wọn yóò dá ọ sí.
Quand les Égyptiens te verront, ils diront: « C'est sa femme ». Ils me tueront, mais ils te laisseront la vie sauve.
13 Nítorí náà, sọ pé, arábìnrin mi ni ìwọ, wọn yóò sì ṣe mí dáradára, a ó sì dá ẹ̀mí mi sí nítorí tìrẹ.”
Dis, je t'en prie, que tu es ma sœur, afin que je sois heureux à cause de toi et que mon âme vive grâce à toi. »
14 Nígbà tí Abramu dé Ejibiti, àwọn ará Ejibiti ri i pé aya rẹ̀ rẹwà gidigidi.
Quand Abram fut arrivé en Égypte, les Égyptiens virent que la femme était très belle.
15 Nígbà tí àwọn ìjòyè Farao sì rí i, wọ́n ròyìn rẹ̀ níwájú Farao, wọ́n sì mú un lọ sí ààfin.
Les princes de Pharaon la virent et la louèrent à Pharaon; et la femme fut emmenée dans la maison de Pharaon.
16 Ó sì kẹ́ Abramu dáradára nítorí Sarai, Abramu sì ní àgùntàn àti màlúù, akọ àti abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin, pẹ̀lú ìbákasẹ.
Il traita bien Abram à cause d'elle. Il eut des moutons, du bétail, des ânes mâles, des serviteurs mâles, des servantes, des ânesses et des chameaux.
17 Olúwa sì rán àjàkálẹ̀-ààrùn búburú sí Farao àti ilé rẹ̀, nítorí Sarai aya Abramu.
Yahvé affligea Pharaon et sa maison de grandes plaies à cause de Saraï, la femme d'Abram.
18 Nítorí náà Farao ránṣẹ́ pe Abramu, ó sì wí fun pé, “Èwo ni ìwọ ṣe sí mi yìí? Kí ló dé tí ìwọ kò sọ fún mi pé aya rẹ ní í ṣe?
Pharaon appela Abram et dit: « Qu'est-ce que tu m'as fait? Pourquoi ne m'as-tu pas dit qu'elle était ta femme?
19 Èéṣe tí o fi wí pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ tí èmi sì fi fẹ́ ẹ gẹ́gẹ́ bí aya? Nítorí náà nísinsin yìí, aya rẹ náà nìyí, mú un kí o sì máa lọ.”
Pourquoi as-tu dit: « C'est ma sœur », pour que je la prenne pour femme? Maintenant donc, va voir ta femme, prends-la, et va-t'en. »
20 Nígbà náà ni Farao pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ nípa Abramu, wọ́n sì lé e jáde ti òun ti aya rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní.
Pharaon donna des ordres aux hommes à son sujet, et ils l'emmenèrent avec sa femme et tout ce qui lui appartenait.

< Genesis 12 >