< Genesis 11 >
1 Lẹ́yìn náà, gbogbo àgbáyé sì ń sọ èdè kan ṣoṣo.
Toda la tierra tenía una misma lengua y un mismo lenguaje.
2 Bí àwọn ènìyàn ṣe ń tẹ̀síwájú lọ sí ìhà ìlà-oòrùn, wọ́n rí pẹ̀tẹ́lẹ̀ kan ní ilẹ̀ Ṣinari, wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
Mientras viajaban hacia el este, encontraron una llanura en la tierra de Sinar, y allí vivieron.
3 Wọ́n sì wí fún ara wọn pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a mọ bíríkì kí a sì sún wọ́n jìnà.” Bíríkì ni wọ́n ń lò ní ipò òkúta, àti ọ̀dà ilẹ̀ tí wọn ń lò láti mú wọn papọ̀ dípò ẹfun (òkúta láìmù tí wọ́n fi ń ṣe símẹ́ńtì àti omi).
Se dijeron unos a otros: “Venid, hagamos ladrillos y quemémoslos bien”. Tenían ladrillos por piedra, y usaban alquitrán como mortero.
4 Nígbà náà ni wọ́n wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a tẹ ìlú kan dó fún ara wa, kí a sì kọ́ ilé ìṣọ́ kan tí yóò kan ọ̀run, kí a ba à lè ní orúkọ, kí a má sì tú káàkiri sórí gbogbo ilẹ̀ ayé.”
Dijeron: “Vengan, construyamos una ciudad y una torre cuya cima llegue al cielo, y hagamos un nombre para nosotros, no sea que nos dispersemos por la superficie de toda la tierra.”
5 Ṣùgbọ́n, Olúwa sọ̀kalẹ̀ láti wo ìlú àti ilé ìṣọ́ tí àwọn ènìyàn náà ń kọ́.
Yahvé bajó a ver la ciudad y la torre que los hijos de los hombres construyeron.
6 Olúwa wí pé, “Bí àwọn ènìyàn bá ń jẹ́ ọ̀kan àti èdè kan tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe iṣẹ́ yìí, kò sí ohun tí wọ́n gbèrò tí wọn kò ní le ṣe yọrí.
Yahvé dijo: “He aquí que son un solo pueblo, y todos tienen una sola lengua, y esto es lo que comienzan a hacer. Ahora no se les impedirá nada de lo que pretenden hacer.
7 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a sọ̀kalẹ̀ lọ, kí a da èdè wọn rú kí èdè wọn má ba à yé ara wọn mọ́.”
Vamos, bajemos y confundamos allí su lengua, para que no entiendan el habla de los demás.”
8 Olúwa sì tú wọn ká sórí ilẹ̀ gbogbo, wọ́n sì ṣíwọ́ ìlú náà tí wọn ń tẹ̀dó.
Así que el Señor los dispersó desde allí por la superficie de toda la tierra. Dejaron de construir la ciudad.
9 Ìdí èyí ni a fi pè é ní Babeli nítorí ní ibẹ̀ ni Olúwa ti da èdè gbogbo ayé rú. Olúwa tí sì tú àwọn ènìyàn ká sí gbogbo orí ilẹ̀ ayé.
Por eso su nombre fue llamado Babel, porque allí Yahvé confundió el lenguaje de toda la tierra. Desde allí, Yahvé los dispersó por la superficie de toda la tierra.
10 Wọ̀nyí ni ìran Ṣemu. Ọdún méjì lẹ́yìn ìkún omi, tí Ṣemu pé ọgọ́rùn-ún ọdún ni ó bí Arfakṣadi.
Esta es la historia de las generaciones de Sem: Sem tenía cien años cuando fue padre de Arpachshad dos años después del diluvio.
11 Lẹ́yìn tí ó bí Arfakṣadi, Ṣemu tún wà láààyè fún ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ọdún, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
Sem vivió quinientos años después de ser padre de Arfaxad, y fue padre de más hijos e hijas.
12 Nígbà tí Arfakṣadi pé ọdún márùndínlógójì ni ó bí Ṣela.
Arfaxad vivió treinta y cinco años y llegó a ser el padre de Sala.
13 Arfakṣadi sì wà láààyè fún ọdún mẹ́tàlénírinwó lẹ́yìn tí ó bí Ṣela, ó sì bí àwọn ọmọbìnrin àti àwọn ọmọkùnrin mìíràn.
Arfaxad vivió cuatrocientos tres años después de ser el padre de Shelah, y llegó a ser el padre de más hijos e hijas.
14 Nígbà tí Ṣela pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Eberi.
Sala vivió treinta años y fue padre de Heber.
15 Ṣela sì wà láààyè fún ọdún mẹ́tàlénírinwó lẹ́yìn tí ó bí Eberi tán, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
Sala vivió cuatrocientos tres años después de ser padre de Heber, y fue padre de más hijos e hijas.
16 Eberi sì jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n, ó sì bí Pelegi.
Heber vivió treinta y cuatro años y fue padre de Peleg.
17 Eberi sì wà láààyè fún irinwó ọdún ó lé ọgbọ̀n lẹ́yìn tí ó bí Pelegi, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
Heber vivió cuatrocientos treinta años después de ser padre de Peleg, y fue padre de más hijos e hijas.
18 Nígbà tí Pelegi pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Reu.
Peleg vivió treinta años y fue padre de Reu.
19 Pelegi sì tún wà láààyè fún igba ọdún ó lé mẹ́sàn-án lẹ́yìn tí ó bí Reu, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
Peleg vivió doscientos nueve años después de ser padre de Reu, y fue padre de más hijos e hijas.
20 Nígbà tí Reu pé ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ni ó bí Serugu.
Reu vivió treinta y dos años, y llegó a ser el padre de Serug.
21 Reu tún wà láààyè lẹ́yìn tí ó bí Serugu fún igba ọdún ó lé méje, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin mìíràn.
Reu vivió doscientos siete años después de ser padre de Serug, y fue padre de más hijos e hijas.
22 Nígbà tí Serugu pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Nahori.
Serug vivió treinta años y llegó a ser padre de Nacor.
23 Serugu sì wà láààyè fún igba ọdún lẹ́yìn tí ó bí Nahori, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
Serug vivió doscientos años después de ser padre de Nacor, y llegó a ser padre de más hijos e hijas.
24 Nígbà tí Nahori pé ọmọ ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n, ó bí Tẹra.
Nacor vivió veintinueve años, y llegó a ser padre de Taré.
25 Nahori sì wà láààyè fún ọdún mọ́kàn dín lọ́gọ́fà lẹ́yìn ìbí Tẹra, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
Nacor vivió ciento diecinueve años después de ser padre de Taré, y llegó a ser padre de más hijos e hijas.
26 Lẹ́yìn tí Tẹra pé ọmọ àádọ́rin ọdún ó bí Abramu, Nahori àti Harani.
Taré vivió setenta años y fue padre de Abram, Nacor y Harán.
27 Wọ̀nyí ni ìran Tẹra. Tẹra ni baba Abramu, Nahori àti Harani. Harani sì bí Lọti.
Esta es la historia de las generaciones de Taré. Taré fue el padre de Abram, Nacor y Harán. Harán fue el padre de Lot.
28 Harani sì kú ṣáájú Tẹra baba rẹ̀ ní ilẹ̀ ìbí rẹ̀ ní Uri ti ilẹ̀ Kaldea.
Harán murió en su tierra natal, en Ur de los Caldeos, mientras su padre Taré aún vivía.
29 Abramu àti Nahori sì gbéyàwó. Orúkọ aya Abramu ni Sarai, nígbà tí aya Nahori ń jẹ́ Milka, tí ṣe ọmọ Harani. Harani ni ó bí Milka àti Iska.
Abram y Nacor se casaron con esposas. El nombre de la esposa de Abram era Sarai, y el nombre de la esposa de Nacor era Milca, hija de Harán, quien también era el padre de Isca.
30 Sarai sì yàgàn, kò sì bímọ.
Sarai era estéril. No tuvo ningún hijo.
31 Tẹra sì mú ọmọ rẹ̀ Abramu àti Lọti ọmọ Harani, ọmọ ọmọ rẹ̀, ó sì mú Sarai tí i ṣe aya ọmọ rẹ̀. Abramu pẹ̀lú gbogbo wọn sì jáde kúrò ní Uri ti Kaldea láti lọ sí ilẹ̀ Kenaani. Ṣùgbọ́n nígbà tí wọn dé Harani wọ́n tẹ̀dó síbẹ̀.
Taré tomó a Abram, su hijo, a Lot, hijo de Harán, y a Sarai, su nuera, esposa de su hijo Abram. Salieron de Ur de los Caldeos para ir a la tierra de Canaán. Llegaron a Harán y vivieron allí.
32 Nígbà tí Tẹra pé ọmọ igba ọdún ó lé márùn-ún ni ó kú ní Harani.
Los días de Taré fueron doscientos cinco años. Taré murió en Harán.