< Genesis 11 >

1 Lẹ́yìn náà, gbogbo àgbáyé sì ń sọ èdè kan ṣoṣo.
And it was all the earth language one and words one.
2 Bí àwọn ènìyàn ṣe ń tẹ̀síwájú lọ sí ìhà ìlà-oòrùn, wọ́n rí pẹ̀tẹ́lẹ̀ kan ní ilẹ̀ Ṣinari, wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
And it was when set out they from [the] east and they found a plain in [the] land of Shinar and they dwelt there.
3 Wọ́n sì wí fún ara wọn pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a mọ bíríkì kí a sì sún wọ́n jìnà.” Bíríkì ni wọ́n ń lò ní ipò òkúta, àti ọ̀dà ilẹ̀ tí wọn ń lò láti mú wọn papọ̀ dípò ẹfun (òkúta láìmù tí wọ́n fi ń ṣe símẹ́ńtì àti omi).
And they said each to neighbor his give! let us make bricks bricks and let us burn [them] to burning and became for them brick to stone and bitumen became for them to mortar.
4 Nígbà náà ni wọ́n wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a tẹ ìlú kan dó fún ara wa, kí a sì kọ́ ilé ìṣọ́ kan tí yóò kan ọ̀run, kí a ba à lè ní orúkọ, kí a má sì tú káàkiri sórí gbogbo ilẹ̀ ayé.”
And they said give! - let us build for ourselves a city and a tower and top its [will be] in the heavens and we may make for ourselves a name lest we should be scattered over [the] surface of all the earth.
5 Ṣùgbọ́n, Olúwa sọ̀kalẹ̀ láti wo ìlú àti ilé ìṣọ́ tí àwọn ènìyàn náà ń kọ́.
And he came down Yahweh to see the city and the tower which they had built [the] children of humankind.
6 Olúwa wí pé, “Bí àwọn ènìyàn bá ń jẹ́ ọ̀kan àti èdè kan tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe iṣẹ́ yìí, kò sí ohun tí wọ́n gbèrò tí wọn kò ní le ṣe yọrí.
And he said Yahweh here! a people one and a language one [belongs] to all of them and this [is] beginning they to do and now not it will be withheld from them all that they will plan to do.
7 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a sọ̀kalẹ̀ lọ, kí a da èdè wọn rú kí èdè wọn má ba à yé ara wọn mọ́.”
Give! let us go down and let us confuse there language their that not they will hear each [the] language of neighbor his.
8 Olúwa sì tú wọn ká sórí ilẹ̀ gbogbo, wọ́n sì ṣíwọ́ ìlú náà tí wọn ń tẹ̀dó.
And he scattered Yahweh them from there over [the] surface of all the earth and they ceased to build the city.
9 Ìdí èyí ni a fi pè é ní Babeli nítorí ní ibẹ̀ ni Olúwa ti da èdè gbogbo ayé rú. Olúwa tí sì tú àwọn ènìyàn ká sí gbogbo orí ilẹ̀ ayé.
There-fore someone called name its Babel for there he confused Yahweh [the] language of all the earth and from there he scattered them Yahweh over [the] surface of all the earth.
10 Wọ̀nyí ni ìran Ṣemu. Ọdún méjì lẹ́yìn ìkún omi, tí Ṣemu pé ọgọ́rùn-ún ọdún ni ó bí Arfakṣadi.
These [are] [the] accounts of Shem Shem [was] a son of one hundred year[s] and he fathered Arphaxad two years after the flood.
11 Lẹ́yìn tí ó bí Arfakṣadi, Ṣemu tún wà láààyè fún ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ọdún, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
And he lived Shem after fathered he Arphaxad five hundred year[s] and he fathered sons and daughters.
12 Nígbà tí Arfakṣadi pé ọdún márùndínlógójì ni ó bí Ṣela.
And Arphaxad he lived five and thirty year[s] and he fathered Shelah.
13 Arfakṣadi sì wà láààyè fún ọdún mẹ́tàlénírinwó lẹ́yìn tí ó bí Ṣela, ó sì bí àwọn ọmọbìnrin àti àwọn ọmọkùnrin mìíràn.
And he lived Arphaxad after fathered he Shelah three years and four hundred year[s] and he fathered sons and daughters.
14 Nígbà tí Ṣela pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Eberi.
And Shelah he lived thirty year[s] and he fathered Eber.
15 Ṣela sì wà láààyè fún ọdún mẹ́tàlénírinwó lẹ́yìn tí ó bí Eberi tán, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
And he lived Shelah after fathered he Eber three years and four hundred year[s] and he fathered sons and daughters.
16 Eberi sì jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n, ó sì bí Pelegi.
And he lived Eber four and thirty year[s] and he fathered Peleg.
17 Eberi sì wà láààyè fún irinwó ọdún ó lé ọgbọ̀n lẹ́yìn tí ó bí Pelegi, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
And he lived Eber after fathered he Peleg thirty year[s] and four hundred year[s] and he fathered sons and daughters.
18 Nígbà tí Pelegi pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Reu.
And he lived Peleg thirty year[s] and he fathered Reu.
19 Pelegi sì tún wà láààyè fún igba ọdún ó lé mẹ́sàn-án lẹ́yìn tí ó bí Reu, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
And he lived Peleg after fathered he Reu nine years and two hundred year[s] and he fathered sons and daughters.
20 Nígbà tí Reu pé ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ni ó bí Serugu.
And he lived Reu two and thirty year[s] and he fathered Serug.
21 Reu tún wà láààyè lẹ́yìn tí ó bí Serugu fún igba ọdún ó lé méje, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin mìíràn.
And he lived Reu after fathered he Serug seven years and two hundred year[s] and he fathered sons and daughters.
22 Nígbà tí Serugu pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Nahori.
And he lived Serug thirty year[s] and he fathered Nahor.
23 Serugu sì wà láààyè fún igba ọdún lẹ́yìn tí ó bí Nahori, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
And he lived Serug after fathered he Nahor two hundred year[s] and he fathered sons and daughters.
24 Nígbà tí Nahori pé ọmọ ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n, ó bí Tẹra.
And he lived Nahor nine and twenty year[s] and he fathered Terah.
25 Nahori sì wà láààyè fún ọdún mọ́kàn dín lọ́gọ́fà lẹ́yìn ìbí Tẹra, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
And he lived Nahor after fathered he Terah nine-teen year[s] and one hundred year[s] and he fathered sons and daughters.
26 Lẹ́yìn tí Tẹra pé ọmọ àádọ́rin ọdún ó bí Abramu, Nahori àti Harani.
And he lived Terah seventy year[s] and he fathered Abram Nahor and Haran.
27 Wọ̀nyí ni ìran Tẹra. Tẹra ni baba Abramu, Nahori àti Harani. Harani sì bí Lọti.
And these [are] [the] accounts of Terah Terah he fathered Abram Nahor and Haran and Haran he fathered Lot.
28 Harani sì kú ṣáájú Tẹra baba rẹ̀ ní ilẹ̀ ìbí rẹ̀ ní Uri ti ilẹ̀ Kaldea.
And he died Haran on [the] face of Terah father his in [the] land of kindred his in Ur of [the] Chaldeans.
29 Abramu àti Nahori sì gbéyàwó. Orúkọ aya Abramu ni Sarai, nígbà tí aya Nahori ń jẹ́ Milka, tí ṣe ọmọ Harani. Harani ni ó bí Milka àti Iska.
And he took Abram and Nahor for themselves wives [the] name of [the] wife of Abram [was] Sarai and [the] name of [the] wife of Nahor [was] Milcah [the] daughter of Haran [the] father of Milcah and [the] father of Iscah.
30 Sarai sì yàgàn, kò sì bímọ.
And she was Sarai barren not [belonged] to her a child.
31 Tẹra sì mú ọmọ rẹ̀ Abramu àti Lọti ọmọ Harani, ọmọ ọmọ rẹ̀, ó sì mú Sarai tí i ṣe aya ọmọ rẹ̀. Abramu pẹ̀lú gbogbo wọn sì jáde kúrò ní Uri ti Kaldea láti lọ sí ilẹ̀ Kenaani. Ṣùgbọ́n nígbà tí wọn dé Harani wọ́n tẹ̀dó síbẹ̀.
And he took Terah Abram son his and Lot [the] son of Haran [the] son of son his and Sarai daughter-in-law his [the] wife of Abram son his and they went out with them from Ur of [the] Chaldeans to go [the] land of towards Canaan and they came to Haran and they dwelt there.
32 Nígbà tí Tẹra pé ọmọ igba ọdún ó lé márùn-ún ni ó kú ní Harani.
And they were [the] days of Terah five years and two hundred year[s] and he died Terah in Haran.

< Genesis 11 >