< Genesis 10 >
1 Èyí ni ìran àwọn ọmọ Noa: Ṣemu, Hamu àti Jafeti, tí àwọn náà sì bí ọmọ lẹ́yìn ìkún omi.
Et c'est ici l'histoire des fils de Noé, Sem, Cham et Japheth. Et il leur naquit des fils après le déluge.
2 Àwọn ọmọ Jafeti ni: Gomeri, Magogu, Madai, Jafani, Tubali, Meṣeki àti Tirasi.
Les fils de Japheth sont: Gomer et Magog et Madai et Javan et Thubal et Mésech et Thiras.
3 Àwọn ọmọ Gomeri ni: Aṣkenasi, Rifati àti Togarma.
Et les fils de Gomer: Askénas et Riphat et Thogarma.
4 Àwọn ọmọ Jafani ni: Eliṣa, Tarṣiṣi, Kittimu, àti Dodanimu.
Et les fils de Javan: Elisah et Tharsis, et Dodanim:
5 (Láti ọ̀dọ̀ àwọn wọ̀nyí ni àwọn tí ń gbé agbègbè tí omi wà ti tàn ká agbègbè wọn, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, ìdílé wọn ní orílẹ̀-èdè wọn, olúkúlùkù pẹ̀lú èdè tirẹ̀).
d'eux sont issus ceux qui se sont répandus sur les terres maritimes des nations dans les pays qu'ils occupent, chacun selon sa langue, sa filiation, sa nationalité.
6 Àwọn ọmọ Hamu ni: Kuṣi, Ejibiti, Puti àti Kenaani.
Et les fils de Cham: Cus et Mistraïm et Phut et Canaan.
7 Àwọn ọmọ Kuṣi ni: Seba, Hafila, Sabta, Raama, àti Sabteka. Àwọn ọmọ Raama ni: Ṣeba àti Dedani.
Et les fils de Cus: Saba et Havila et Sabtha et Rahema et Sabtcha. Et les fils de Rahemah: Séba et Dedan.
8 Kuṣi sì bí Nimrodu, ẹni tí ó di alágbára jagunjagun ní ayé.
Cus engendra Nemrod; c'est lui qui commença à être un potentat sur la terre.
9 Ó sì jẹ́ ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa; nítorí náà ni a ṣe ń wí pé, “Bí Nimrodu, ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa.”
C'est lui qui devint un puissant chasseur à la face de l'Éternel; c'est pourquoi il se dit: Comme Nemrod, puissant chasseur à la face de l'Éternel.
10 Ìjọba rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ ni Babeli, Ereki, Akkadi, Kalne, gbogbo wọn wà ní ilẹ̀ Ṣinari.
Et le commencement de son empire fut Babel et Erech et Accad et Chalneh au pays de Sinear.
11 Láti ilẹ̀ náà ni ó ti lọ sí Asiria, níbi tí ó ti tẹ ìlú Ninefe, Rehoboti àti Kala,
De ce pays-là il marcha sur Assur, et bâtit Ninive et Rechoboth-Hir et Calah
12 àti Resini, tí ó wà ní àárín Ninefe àti Kala, tí ó jẹ́ ìlú olókìkí.
et Resen entre Ninive et Calah; c'est la grande ville.
13 Ejibiti sì bí Ludimu, Anamimu, Lehabimu, Naftuhimu.
Et Mitsraïm engendra les Ludim et les Hanamin et les Lehabim et les Naphthaïm
14 Patrusimu, Kasluhimu (láti ọ̀dọ̀ ẹni tí àwọn ará Filistini ti wá) àti àwọn ará Kaftorimu.
et les Pathrusim et les Casluhim, d'où sont sortis les Philistim et les Caphthorim.
15 Kenaani sì bí Sidoni àkọ́bí rẹ̀, àti Heti.
Et Canaan engendra Sidon, son premier-né, et Heth
16 Àti àwọn ará Jebusi, àti àwọn ará Amori, àti àwọn ará Girgaṣi,
et Jebusi et Amori et Gergesi
17 àti àwọn ará Hifi, àti àwọn ará Arki, àti àwọn ará Sini,
et Hivi et Arki et Sini
18 àti àwọn ará Arfadi, àti àwọn ará Semari, àti àwọn ará Hamati. Lẹ́yìn èyí ni àwọn ẹ̀yà Kenaani tànkálẹ̀.
et Arvadi et Tsemari et Hamathi, et ensuite les familles des Cananéens s'étendirent.
19 Ààlà ilẹ̀ àwọn ará Kenaani sì dé Sidoni, lọ sí Gerari títí dé Gasa, lọ sí Sodomu, Gomorra, Adma àti Seboimu, títí dé Laṣa.
Et les limites des Cananéens furent de Sidon du côté de Gérar à Gaza, du côté de Sodome et de Gomorrhe et d'Adama et de Tseboïm à Lasah.
20 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Hamu, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, àti èdè wọn, ní ìpínlẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.
Tels sont les fils de Cham selon leurs familles, selon leurs langues, dans leurs pays, dans leurs peuplades.
21 A bí àwọn ọmọ fún Ṣemu tí Jafeti jẹ́ ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin: Ṣemu sì ni baba gbogbo àwọn ọmọ Eberi.
Et il naquit aussi des fils à Sem, père de tous les fils de Héber, frère aîné de Japheth.
22 Àwọn ọmọ Ṣemu ni: Elamu, Aṣuri, Arfakṣadi, Ludi àti Aramu.
Les fils de Sem: Heilam et Assur et Arphachsad et Lud et Aram.
23 Àwọn ọmọ Aramu ni: Usi, Huli, Geteri àti Meṣeki.
Et les fils de Aram: Uz et Hul et Gether et Mas.
24 Arfakṣadi sì bí Ṣela, Ṣela sì bí Eberi.
Et Arphachsad engendra Sélach, et Sélach engendra Héber.
25 Eberi sì bí ọmọ méjì: ọ̀kan ń jẹ́ Pelegi, nítorí ní ìgbà ọjọ́ rẹ̀ ni ilẹ̀ ya; orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Joktani.
Et à Héber il naquit deux fils: le nom de l'un était Péleg, parce que de son temps la terre fut partagée, et le nom de son frère était Joctan.
26 Joktani sì bí Almodadi, Ṣelefi, Hasarmafeti, Jera.
Et Joctan engendra Almodad et Séleph et Hatsarmaveth, et Jerach
27 Hadoramu, Usali, Dikla,
et Adoram et Uzal et Dicla
28 Obali, Abimaeli, Ṣeba.
et Hobal et Abimaël et Séba
29 Ofiri, Hafila àti Jobabu. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Joktani.
et Ophir et Havila et Jobab, tous ceux-ci fils de Joctan.
30 Agbègbè ibi tí wọn ń gbé bẹ̀rẹ̀ láti Meṣa títí dé Sefari, ní àwọn ilẹ̀ tó kún fún òkè ní ìlà-oòrùn.
Et leur habitation était depuis Mesa du côté de Sephar, la montagne de l'orient.
31 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Ṣemu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, ní èdè wọn, ní ilẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.
Ce sont là les fils de Sem selon leurs familles, selon leurs langues, dans leurs pays, selon leurs tribus.
32 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Noa gẹ́gẹ́ bí ìran wọn, ní orílẹ̀-èdè wọn. Ní ipasẹ̀ wọn ni àwọn ènìyàn ti tàn ká ilẹ̀ ayé lẹ́yìn ìkún omi.
Telles sont les familles des fils de Noé selon leurs familles, dans leurs tribus; et d'eux sont sortis les peuples qui se sont répandus sur la terre après le déluge.