< Genesis 10 >

1 Èyí ni ìran àwọn ọmọ Noa: Ṣemu, Hamu àti Jafeti, tí àwọn náà sì bí ọmọ lẹ́yìn ìkún omi.
Voici la descendance des fils de Noé, Sem, Cham et Japhet, à qui des enfants naquirent après le Déluge.
2 Àwọn ọmọ Jafeti ni: Gomeri, Magogu, Madai, Jafani, Tubali, Meṣeki àti Tirasi.
Enfants de Japhet Gourer, Magog, Madaï, Yavân, Toubal, Méchec et Tiràs.
3 Àwọn ọmọ Gomeri ni: Aṣkenasi, Rifati àti Togarma.
Enfants de Gourer: Achkenaz, Rifath et Togarma.
4 Àwọn ọmọ Jafani ni: Eliṣa, Tarṣiṣi, Kittimu, àti Dodanimu.
Enfants de Yavân: Elicha, Tharsis, Kittim et Dodanim.
5 (Láti ọ̀dọ̀ àwọn wọ̀nyí ni àwọn tí ń gbé agbègbè tí omi wà ti tàn ká agbègbè wọn, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, ìdílé wọn ní orílẹ̀-èdè wọn, olúkúlùkù pẹ̀lú èdè tirẹ̀).
De ceux-là se formèrent les colonies de peuples répandues dans divers pays, chacune selon sa langue, selon sa tribu, selon son peuple.
6 Àwọn ọmọ Hamu ni: Kuṣi, Ejibiti, Puti àti Kenaani.
Enfants de Cham: Kouch, Misraïm, Pont et Canaan.
7 Àwọn ọmọ Kuṣi ni: Seba, Hafila, Sabta, Raama, àti Sabteka. Àwọn ọmọ Raama ni: Ṣeba àti Dedani.
Enfants de Kouch: Seba et Havila, Sabta, Râma et Sabteea; enfants de Râma: Cheba et Dedân.
8 Kuṣi sì bí Nimrodu, ẹni tí ó di alágbára jagunjagun ní ayé.
Kouch engendra aussi Nemrod, celui qui le premier fut puissant sur la terre.
9 Ó sì jẹ́ ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa; nítorí náà ni a ṣe ń wí pé, “Bí Nimrodu, ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa.”
Il fut un puissant ravisseur devant l’Éternel; c’est pourquoi on dit: "Tel que Nemrod, un puissant ravisseur devant l’Éternel!"
10 Ìjọba rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ ni Babeli, Ereki, Akkadi, Kalne, gbogbo wọn wà ní ilẹ̀ Ṣinari.
Le commencement de sa domination fut Babel; puis Érec, Akkad et Kalné, dans le pays de Sennaar.
11 Láti ilẹ̀ náà ni ó ti lọ sí Asiria, níbi tí ó ti tẹ ìlú Ninefe, Rehoboti àti Kala,
De cette contrée il s’en alla en Assur, où il bâtit Ninive, Rehoboth Ir et Kélah;
12 àti Resini, tí ó wà ní àárín Ninefe àti Kala, tí ó jẹ́ ìlú olókìkí.
puis Résèn, entre Ninive et Kélah, cette grande cité.
13 Ejibiti sì bí Ludimu, Anamimu, Lehabimu, Naftuhimu.
Misraim fut la souche des Loudim, des Anamim, des Lehabim, des Naftouhim;
14 Patrusimu, Kasluhimu (láti ọ̀dọ̀ ẹni tí àwọn ará Filistini ti wá) àti àwọn ará Kaftorimu.
des Pathrousim, des Kaslouhim (d’où sortirent les Philistins) et des Kaftorim.
15 Kenaani sì bí Sidoni àkọ́bí rẹ̀, àti Heti.
Canaan engendra Sidon, son premier-né, puis Heth
16 Àti àwọn ará Jebusi, àti àwọn ará Amori, àti àwọn ará Girgaṣi,
puis le Jebuséen, l’Amorréen, le Ghirgachéen,
17 àti àwọn ará Hifi, àti àwọn ará Arki, àti àwọn ará Sini,
le Hévéen, l’Arkéen, le Sinéen,
18 àti àwọn ará Arfadi, àti àwọn ará Semari, àti àwọn ará Hamati. Lẹ́yìn èyí ni àwọn ẹ̀yà Kenaani tànkálẹ̀.
Arvadéen, le Cemaréen et le Hamathéen. Depuis, les familles des Cananéens se développèrent.
19 Ààlà ilẹ̀ àwọn ará Kenaani sì dé Sidoni, lọ sí Gerari títí dé Gasa, lọ sí Sodomu, Gomorra, Adma àti Seboimu, títí dé Laṣa.
Le territoire du peuple cananéen s’étendait depuis Sidon jusqu’à Gaza dans la direction de Gherar; jusqu’à Lécha, dans la direction de Sodome, Gomorrhe, Adma et Ceboïm.
20 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Hamu, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, àti èdè wọn, ní ìpínlẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.
Tels sont les enfants de Cham, selon leurs familles et leur langage, selon leurs territoires et leurs peuplades.
21 A bí àwọn ọmọ fún Ṣemu tí Jafeti jẹ́ ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin: Ṣemu sì ni baba gbogbo àwọn ọmọ Eberi.
Des enfants naquirent aussi à Sem, le père de toute la race d’Héber, le frère de Japhet, l’aîné.
22 Àwọn ọmọ Ṣemu ni: Elamu, Aṣuri, Arfakṣadi, Ludi àti Aramu.
Enfants de Sem: Élam, Assur, Arphaxad, Loud et Aram.
23 Àwọn ọmọ Aramu ni: Usi, Huli, Geteri àti Meṣeki.
Enfants d’Aram: Ouy, Houl, Ghéther et Mach.
24 Arfakṣadi sì bí Ṣela, Ṣela sì bí Eberi.
Arphaxad engendra Chélah, et Chélah engendra Héber.
25 Eberi sì bí ọmọ méjì: ọ̀kan ń jẹ́ Pelegi, nítorí ní ìgbà ọjọ́ rẹ̀ ni ilẹ̀ ya; orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Joktani.
A Héber il naquit deux fils. Le nom de l’un: Péleg, parce que de son temps la terre fut partagée; et le nom de son frère: Yoktân.
26 Joktani sì bí Almodadi, Ṣelefi, Hasarmafeti, Jera.
Yoktân engendra Almodad, Chélef, Haçarmaveth, Yérah.
27 Hadoramu, Usali, Dikla,
Hadoram, Ouzal, Dikla;
28 Obali, Abimaeli, Ṣeba.
Obal, Abimaêl, Cheba;
29 Ofiri, Hafila àti Jobabu. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Joktani.
Ophir, Havila et Yobab. Tous ceux-là furent enfants de Yoktân.
30 Agbègbè ibi tí wọn ń gbé bẹ̀rẹ̀ láti Meṣa títí dé Sefari, ní àwọn ilẹ̀ tó kún fún òkè ní ìlà-oòrùn.
Leurs établissements s’étendirent depuis Mécha jusqu’à la montagne Orientale, dans la direction de Sefar.
31 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Ṣemu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, ní èdè wọn, ní ilẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.
Tels sont les descendants de Sem, selon leurs familles et leurs langages, selon leurs territoires et leurs peuplades.
32 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Noa gẹ́gẹ́ bí ìran wọn, ní orílẹ̀-èdè wọn. Ní ipasẹ̀ wọn ni àwọn ènìyàn ti tàn ká ilẹ̀ ayé lẹ́yìn ìkún omi.
Ce sont là les familles des fils de Noé, selon leur filiation et leurs peuplades; et c’est de là que les nations se sont distribuées sur la terre après le Déluge.

< Genesis 10 >