< Genesis 10 >

1 Èyí ni ìran àwọn ọmọ Noa: Ṣemu, Hamu àti Jafeti, tí àwọn náà sì bí ọmọ lẹ́yìn ìkún omi.
Voici l'histoire des générations des fils de Noé, de Sem, de Cham et de Japhet. Des fils leur sont nés après le déluge.
2 Àwọn ọmọ Jafeti ni: Gomeri, Magogu, Madai, Jafani, Tubali, Meṣeki àti Tirasi.
Les fils de Japhet étaient: Gomer, Magog, Madai, Javan, Tubal, Meshech et Tiras.
3 Àwọn ọmọ Gomeri ni: Aṣkenasi, Rifati àti Togarma.
Les fils de Gomer étaient: Ashkenaz, Riphath et Togarmah.
4 Àwọn ọmọ Jafani ni: Eliṣa, Tarṣiṣi, Kittimu, àti Dodanimu.
Les fils de Javan étaient: Élischa, Tarsis, Kittim et Dodanim.
5 (Láti ọ̀dọ̀ àwọn wọ̀nyí ni àwọn tí ń gbé agbègbè tí omi wà ti tàn ká agbègbè wọn, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, ìdílé wọn ní orílẹ̀-èdè wọn, olúkúlùkù pẹ̀lú èdè tirẹ̀).
C'est de là que datent les îles des nations, réparties selon leurs terres, chacun selon sa langue, selon ses familles, selon ses nations.
6 Àwọn ọmọ Hamu ni: Kuṣi, Ejibiti, Puti àti Kenaani.
Les fils de Cham étaient: Cush, Mizraïm, Put et Canaan.
7 Àwọn ọmọ Kuṣi ni: Seba, Hafila, Sabta, Raama, àti Sabteka. Àwọn ọmọ Raama ni: Ṣeba àti Dedani.
Les fils de Cush étaient: Seba, Havilah, Sabtah, Raamah et Sabteca. Les fils de Raama étaient: Saba et Dedan.
8 Kuṣi sì bí Nimrodu, ẹni tí ó di alágbára jagunjagun ní ayé.
Cush fut le père de Nimrod. Celui-ci commença à être puissant sur la terre.
9 Ó sì jẹ́ ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa; nítorí náà ni a ṣe ń wí pé, “Bí Nimrodu, ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa.”
Il fut un puissant chasseur devant Yahvé. C'est pourquoi on dit: « comme Nimrod, un puissant chasseur devant Yahvé ».
10 Ìjọba rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ ni Babeli, Ereki, Akkadi, Kalne, gbogbo wọn wà ní ilẹ̀ Ṣinari.
Le commencement de son royaume était Babel, Erech, Accad et Calneh, dans le pays de Shinar.
11 Láti ilẹ̀ náà ni ó ti lọ sí Asiria, níbi tí ó ti tẹ ìlú Ninefe, Rehoboti àti Kala,
De ce pays, il alla en Assyrie, et bâtit Ninive, Rehoboth Ir, Calah,
12 àti Resini, tí ó wà ní àárín Ninefe àti Kala, tí ó jẹ́ ìlú olókìkí.
et Resen entre Ninive et la grande ville de Calah.
13 Ejibiti sì bí Ludimu, Anamimu, Lehabimu, Naftuhimu.
Mizraïm engendra Ludim, Anamim, Lehabim, Naphtuhim,
14 Patrusimu, Kasluhimu (láti ọ̀dọ̀ ẹni tí àwọn ará Filistini ti wá) àti àwọn ará Kaftorimu.
Pathrusim, Casluhim (dont descendent les Philistins) et Caphtorim.
15 Kenaani sì bí Sidoni àkọ́bí rẹ̀, àti Heti.
Canaan engendra Sidon, son premier-né, Heth,
16 Àti àwọn ará Jebusi, àti àwọn ará Amori, àti àwọn ará Girgaṣi,
les Jébusiens, les Amorites, les Girgashites,
17 àti àwọn ará Hifi, àti àwọn ará Arki, àti àwọn ará Sini,
les Hivites, les Arkites, les Sinites,
18 àti àwọn ará Arfadi, àti àwọn ará Semari, àti àwọn ará Hamati. Lẹ́yìn èyí ni àwọn ẹ̀yà Kenaani tànkálẹ̀.
les Arvadites, les Zemarites et les Hamathites. Par la suite, les familles des Cananéens se sont dispersées.
19 Ààlà ilẹ̀ àwọn ará Kenaani sì dé Sidoni, lọ sí Gerari títí dé Gasa, lọ sí Sodomu, Gomorra, Adma àti Seboimu, títí dé Laṣa.
La frontière des Cananéens s'étendait de Sidon, en allant vers Gerar, à Gaza, en allant vers Sodome, Gomorrhe, Adma et Zéboïm, à Lasha.
20 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Hamu, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, àti èdè wọn, ní ìpínlẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.
Voici les fils de Cham, selon leurs familles, selon leurs langues, dans leurs pays et leurs nations.
21 A bí àwọn ọmọ fún Ṣemu tí Jafeti jẹ́ ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin: Ṣemu sì ni baba gbogbo àwọn ọmọ Eberi.
Des enfants naquirent aussi à Sem (frère aîné de Japhet), père de tous les enfants d'Eber.
22 Àwọn ọmọ Ṣemu ni: Elamu, Aṣuri, Arfakṣadi, Ludi àti Aramu.
Les fils de Sem furent: Élam, Asshur, Arpachshad, Lud et Aram.
23 Àwọn ọmọ Aramu ni: Usi, Huli, Geteri àti Meṣeki.
Les fils d'Aram étaient: Uz, Hul, Gether et Mash.
24 Arfakṣadi sì bí Ṣela, Ṣela sì bí Eberi.
Arpacshad engendra Shéla. Schéla engendra Eber.
25 Eberi sì bí ọmọ méjì: ọ̀kan ń jẹ́ Pelegi, nítorí ní ìgbà ọjọ́ rẹ̀ ni ilẹ̀ ya; orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Joktani.
A Eber naquirent deux fils. Le nom de l'un était Peleg, car en son temps la terre fut divisée. Le nom de son frère était Joktan.
26 Joktani sì bí Almodadi, Ṣelefi, Hasarmafeti, Jera.
Joktan engendra Almodad, Sheleph, Hazarmaveth, Jerah,
27 Hadoramu, Usali, Dikla,
Hadoram, Uzal, Diklah,
28 Obali, Abimaeli, Ṣeba.
Obal, Abimael, Sheba,
29 Ofiri, Hafila àti Jobabu. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Joktani.
Ophir, Havilah et Jobab. Tous ceux-là étaient fils de Joktan.
30 Agbègbè ibi tí wọn ń gbé bẹ̀rẹ̀ láti Meṣa títí dé Sefari, ní àwọn ilẹ̀ tó kún fún òkè ní ìlà-oòrùn.
Leur demeure s'étendait depuis Mesha, en allant vers Séphar, la montagne de l'orient.
31 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Ṣemu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, ní èdè wọn, ní ilẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.
Ce sont là les fils de Sem, selon leurs familles, selon leurs langues, leurs terres et leurs nations.
32 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Noa gẹ́gẹ́ bí ìran wọn, ní orílẹ̀-èdè wọn. Ní ipasẹ̀ wọn ni àwọn ènìyàn ti tàn ká ilẹ̀ ayé lẹ́yìn ìkún omi.
Ce sont là les familles des fils de Noé, selon leurs générations, en fonction de leurs nations. Les nations se sont divisées à partir de celles-ci sur la terre après le déluge.

< Genesis 10 >