< Genesis 10 >
1 Èyí ni ìran àwọn ọmọ Noa: Ṣemu, Hamu àti Jafeti, tí àwọn náà sì bí ọmọ lẹ́yìn ìkún omi.
These are the generations of the sons of Noah: Shem, Ham, and Japheth, and of the sons who were born to them after the great flood.
2 Àwọn ọmọ Jafeti ni: Gomeri, Magogu, Madai, Jafani, Tubali, Meṣeki àti Tirasi.
The sons of Japheth were Gomer, and Magog, and Madai, and Javan, and Tubal, and Meshech, and Tiras.
3 Àwọn ọmọ Gomeri ni: Aṣkenasi, Rifati àti Togarma.
And then the sons of Gomer were Ashkenaz, and Riphath, and Togarmah.
4 Àwọn ọmọ Jafani ni: Eliṣa, Tarṣiṣi, Kittimu, àti Dodanimu.
And the sons of Javan were Elishah, and Tarshish, Kittim, and Rodanim.
5 (Láti ọ̀dọ̀ àwọn wọ̀nyí ni àwọn tí ń gbé agbègbè tí omi wà ti tàn ká agbègbè wọn, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, ìdílé wọn ní orílẹ̀-èdè wọn, olúkúlùkù pẹ̀lú èdè tirẹ̀).
The islands of the Gentiles were divided by these into their regions, each one according to his tongue, and their families in their nations.
6 Àwọn ọmọ Hamu ni: Kuṣi, Ejibiti, Puti àti Kenaani.
And the Sons of Ham were Cush, and Mizraim, and Put, and Canaan.
7 Àwọn ọmọ Kuṣi ni: Seba, Hafila, Sabta, Raama, àti Sabteka. Àwọn ọmọ Raama ni: Ṣeba àti Dedani.
And the sons of Cush were Seba, and Havilah, and Sabtah, and Raamah, and Sabteca. The sons of Raamah were Sheba and Dadan.
8 Kuṣi sì bí Nimrodu, ẹni tí ó di alágbára jagunjagun ní ayé.
And then Cush conceived Nimrod; he began to be powerful on the earth.
9 Ó sì jẹ́ ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa; nítorí náà ni a ṣe ń wí pé, “Bí Nimrodu, ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa.”
And he was an able hunter before the Lord. From this, a proverb came forth: ‘Just like Nimrod, an able hunter before the Lord.’
10 Ìjọba rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ ni Babeli, Ereki, Akkadi, Kalne, gbogbo wọn wà ní ilẹ̀ Ṣinari.
And so, the beginning of his kingdom was Babylon, and Erech, and Accad, and Chalanne, in the land of Shinar.
11 Láti ilẹ̀ náà ni ó ti lọ sí Asiria, níbi tí ó ti tẹ ìlú Ninefe, Rehoboti àti Kala,
From that land, Assur came forth, and he built Nineveh, and the streets of the city, and Calah,
12 àti Resini, tí ó wà ní àárín Ninefe àti Kala, tí ó jẹ́ ìlú olókìkí.
and also Resen, between Nineveh and Calah. This is a great city.
13 Ejibiti sì bí Ludimu, Anamimu, Lehabimu, Naftuhimu.
And truly, Mizraim conceived Ludim, and Anamim, and Lehabim, Naphtuhim,
14 Patrusimu, Kasluhimu (láti ọ̀dọ̀ ẹni tí àwọn ará Filistini ti wá) àti àwọn ará Kaftorimu.
and Pathrusim, and Casluhim, from whom came forth the Philistines and the Caphtorim.
15 Kenaani sì bí Sidoni àkọ́bí rẹ̀, àti Heti.
Then Canaan conceived Sidon his firstborn, the Hittite,
16 Àti àwọn ará Jebusi, àti àwọn ará Amori, àti àwọn ará Girgaṣi,
and the Jebusite, and the Amorite, the Girgashite,
17 àti àwọn ará Hifi, àti àwọn ará Arki, àti àwọn ará Sini,
the Hivite, and the Arkite: the Sinite,
18 àti àwọn ará Arfadi, àti àwọn ará Semari, àti àwọn ará Hamati. Lẹ́yìn èyí ni àwọn ẹ̀yà Kenaani tànkálẹ̀.
and the Arvadian, the Samarite, and the Hamathite. And after this, the peoples of the Canaanites became widespread.
19 Ààlà ilẹ̀ àwọn ará Kenaani sì dé Sidoni, lọ sí Gerari títí dé Gasa, lọ sí Sodomu, Gomorra, Adma àti Seboimu, títí dé Laṣa.
And the borders of Canaan went, as one travels, from Sidon to Gerar, even to Gaza, until one enters Sodom and Gomorrah, and from Admah and Zeboiim, even to Lesa.
20 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Hamu, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, àti èdè wọn, ní ìpínlẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.
These are the sons of Ham in their kindred, and tongues, and generations, and lands, and nations.
21 A bí àwọn ọmọ fún Ṣemu tí Jafeti jẹ́ ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin: Ṣemu sì ni baba gbogbo àwọn ọmọ Eberi.
Likewise, from Shem, the father of all the sons of Heber, the elder brother of Japheth, sons were born.
22 Àwọn ọmọ Ṣemu ni: Elamu, Aṣuri, Arfakṣadi, Ludi àti Aramu.
The sons of Shem were Elam, and Asshur, and Arphaxad, and Lud, and Aram.
23 Àwọn ọmọ Aramu ni: Usi, Huli, Geteri àti Meṣeki.
The sons of Aram were Uz, and Hul, and Gether, and Mash.
24 Arfakṣadi sì bí Ṣela, Ṣela sì bí Eberi.
But truly, Arphaxad conceived Shelah, from whom was born Eber.
25 Eberi sì bí ọmọ méjì: ọ̀kan ń jẹ́ Pelegi, nítorí ní ìgbà ọjọ́ rẹ̀ ni ilẹ̀ ya; orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Joktani.
And to Eber were born two sons: the name of the one was Peleg, for in his days the earth became divided, and his brother’s name was Joktan.
26 Joktani sì bí Almodadi, Ṣelefi, Hasarmafeti, Jera.
This Joktan conceived Almodad, and Sheleph, and Hazarmaveth, Jerah
27 Hadoramu, Usali, Dikla,
and Hadoram, and Uzal and Diklah,
28 Obali, Abimaeli, Ṣeba.
and Obal and Abimael, Sheba
29 Ofiri, Hafila àti Jobabu. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Joktani.
and Ophir, and Havilah and Jobab. All these were the sons of Joktan.
30 Agbègbè ibi tí wọn ń gbé bẹ̀rẹ̀ láti Meṣa títí dé Sefari, ní àwọn ilẹ̀ tó kún fún òkè ní ìlà-oòrùn.
And their habitation extended from Messa, as one sojourns, even to Sephar, a mountain in the east.
31 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Ṣemu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, ní èdè wọn, ní ilẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.
These are the sons of Shem according to their kindred, and tongues, and the regions within their nations.
32 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Noa gẹ́gẹ́ bí ìran wọn, ní orílẹ̀-èdè wọn. Ní ipasẹ̀ wọn ni àwọn ènìyàn ti tàn ká ilẹ̀ ayé lẹ́yìn ìkún omi.
These are the families of Noah, according to their peoples and nations. The nations became divided according to these, on the earth after the great flood.