< Genesis 10 >
1 Èyí ni ìran àwọn ọmọ Noa: Ṣemu, Hamu àti Jafeti, tí àwọn náà sì bí ọmọ lẹ́yìn ìkún omi.
Now these are the generations of the sons of Noah, of Shem, Ham, and Japheth. And sons were born to them after the flood.
2 Àwọn ọmọ Jafeti ni: Gomeri, Magogu, Madai, Jafani, Tubali, Meṣeki àti Tirasi.
The sons of Japheth: Gomer, and Magog, and Madai, and Javan, and Tubal, and Meshech, and Tiras.
3 Àwọn ọmọ Gomeri ni: Aṣkenasi, Rifati àti Togarma.
And the sons of Gomer: Ashkenaz, and Riphath, and Togarmah.
4 Àwọn ọmọ Jafani ni: Eliṣa, Tarṣiṣi, Kittimu, àti Dodanimu.
And the sons of Javan: Elishah, and Tarshish, Kittim, and Dodanim.
5 (Láti ọ̀dọ̀ àwọn wọ̀nyí ni àwọn tí ń gbé agbègbè tí omi wà ti tàn ká agbègbè wọn, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, ìdílé wọn ní orílẹ̀-èdè wọn, olúkúlùkù pẹ̀lú èdè tirẹ̀).
From these were the islands of the nations divided in their lands, every man according to his tongue, according to their families, in their nations.
6 Àwọn ọmọ Hamu ni: Kuṣi, Ejibiti, Puti àti Kenaani.
And the sons of Ham: Cush, and Mizraim, and Put, and Canaan.
7 Àwọn ọmọ Kuṣi ni: Seba, Hafila, Sabta, Raama, àti Sabteka. Àwọn ọmọ Raama ni: Ṣeba àti Dedani.
And the sons of Cush: Seba, and Havilah, and Sabtah, and Raamah, and Sabteca. And the sons of Raamah: Sheba, and Dedan.
8 Kuṣi sì bí Nimrodu, ẹni tí ó di alágbára jagunjagun ní ayé.
And Cush begot Nimrod. He began to be a mighty man on the earth.
9 Ó sì jẹ́ ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa; nítorí náà ni a ṣe ń wí pé, “Bí Nimrodu, ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa.”
He was a mighty hunter before Jehovah. Therefore it is said, Like Nimrod a mighty hunter before Jehovah.
10 Ìjọba rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ ni Babeli, Ereki, Akkadi, Kalne, gbogbo wọn wà ní ilẹ̀ Ṣinari.
And the beginning of his kingdom was Babel, and Erech, and Accad, and Calneh, in the land of Shinar.
11 Láti ilẹ̀ náà ni ó ti lọ sí Asiria, níbi tí ó ti tẹ ìlú Ninefe, Rehoboti àti Kala,
He went forth out of that land into Assyria, and built Nineveh, and Rehoboth-ir, and Calah,
12 àti Resini, tí ó wà ní àárín Ninefe àti Kala, tí ó jẹ́ ìlú olókìkí.
and Resen between Nineveh and Calah (the same is the great city).
13 Ejibiti sì bí Ludimu, Anamimu, Lehabimu, Naftuhimu.
And Mizraim begot Ludim, and Anamim, and Lehabim, and Naphtuhim,
14 Patrusimu, Kasluhimu (láti ọ̀dọ̀ ẹni tí àwọn ará Filistini ti wá) àti àwọn ará Kaftorimu.
and Pathrusim, and Casluhim (from where the Philistines went forth), and Caphtorim.
15 Kenaani sì bí Sidoni àkọ́bí rẹ̀, àti Heti.
And Canaan begot Sidon his firstborn, and Heth,
16 Àti àwọn ará Jebusi, àti àwọn ará Amori, àti àwọn ará Girgaṣi,
and the Jebusite, and the Amorite, and the Girgashite,
17 àti àwọn ará Hifi, àti àwọn ará Arki, àti àwọn ará Sini,
and the Hivite, and the Arkite, and the Sinite,
18 àti àwọn ará Arfadi, àti àwọn ará Semari, àti àwọn ará Hamati. Lẹ́yìn èyí ni àwọn ẹ̀yà Kenaani tànkálẹ̀.
and the Arvadite, and the Zemarite, and the Hamathite. And afterward the families of the Canaanite were spread abroad.
19 Ààlà ilẹ̀ àwọn ará Kenaani sì dé Sidoni, lọ sí Gerari títí dé Gasa, lọ sí Sodomu, Gomorra, Adma àti Seboimu, títí dé Laṣa.
And the border of the Canaanite was from Sidon, as thou go toward Gerar, to Gaza, as thou go toward Sodom and Gomorrah and Admah and Zeboiim, to Lasha.
20 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Hamu, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, àti èdè wọn, ní ìpínlẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.
These are the sons of Ham, according to their families, according to their tongues, in their lands, in their nations.
21 A bí àwọn ọmọ fún Ṣemu tí Jafeti jẹ́ ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin: Ṣemu sì ni baba gbogbo àwọn ọmọ Eberi.
And to Shem, the father of all the sons of Eber, the elder brother of Japheth, sons were also born to him.
22 Àwọn ọmọ Ṣemu ni: Elamu, Aṣuri, Arfakṣadi, Ludi àti Aramu.
The sons of Shem: Elam, and Asshur, and Arphaxad, and Lud, and Aram.
23 Àwọn ọmọ Aramu ni: Usi, Huli, Geteri àti Meṣeki.
And the sons of Aram: Uz, and Hul, and Gether, and Mash.
24 Arfakṣadi sì bí Ṣela, Ṣela sì bí Eberi.
And Arphaxad begot Shelah, and Shelah begot Eber.
25 Eberi sì bí ọmọ méjì: ọ̀kan ń jẹ́ Pelegi, nítorí ní ìgbà ọjọ́ rẹ̀ ni ilẹ̀ ya; orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Joktani.
And to Eber were born two sons. The name of the one was Peleg. For in his days the earth was divided. And his brother's name was Joktan.
26 Joktani sì bí Almodadi, Ṣelefi, Hasarmafeti, Jera.
And Joktan begot Almodad, and Sheleph, and Hazarmaveth, and Jerah,
27 Hadoramu, Usali, Dikla,
and Hadoram, and Uzal, and Diklah,
28 Obali, Abimaeli, Ṣeba.
and Obal, and Abimael, and Sheba,
29 Ofiri, Hafila àti Jobabu. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Joktani.
and Ophir, and Havilah, and Jobab. All these were the sons of Joktan.
30 Agbègbè ibi tí wọn ń gbé bẹ̀rẹ̀ láti Meṣa títí dé Sefari, ní àwọn ilẹ̀ tó kún fún òkè ní ìlà-oòrùn.
And their dwelling was from Mesha, as thou go toward Sephar, the mountain of the east.
31 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Ṣemu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, ní èdè wọn, ní ilẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.
These are the sons of Shem, according to their families, according to their tongues, in their lands, according to their nations.
32 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Noa gẹ́gẹ́ bí ìran wọn, ní orílẹ̀-èdè wọn. Ní ipasẹ̀ wọn ni àwọn ènìyàn ti tàn ká ilẹ̀ ayé lẹ́yìn ìkún omi.
These are the families of the sons of Noah, according to their generations, in their nations. And from these the nations were divided on the earth after the flood.