+ Genesis 1 >

1 Ní ìbẹ̀rẹ̀ ohun gbogbo Ọlọ́run dá àwọn ọ̀run àti ayé.
Muⱪǝddǝmdǝ Huda asmanlar bilǝn zeminni yaratti.
2 Ayé sì wà ní rúdurùdu, ó sì ṣófo, òkùnkùn sì wà lójú ibú omi, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì ń rábàbà lójú omi.
U qaƣda yǝr bolsa xǝkilsiz wǝ ⱪupⱪuruⱪ ⱨalǝttǝ boldi; ⱪarangƣuluⱪ qongⱪur sularning yüzini ⱪaplidi; Hudaning Roⱨi qongⱪur sular üstidǝ lǝrzan pǝrwaz ⱪilatti.
3 Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí ìmọ́lẹ̀ kí ó wà,” ìmọ́lẹ̀ sì wà.
Huda: «Yoruⱪluⱪ bolsun!» dewidi, yoruⱪluⱪ pǝyda boldi.
4 Ọlọ́run rí i pé ìmọ́lẹ̀ náà dára, ó sì ya ìmọ́lẹ̀ náà sọ́tọ̀ kúrò lára òkùnkùn.
Huda yoruⱪluⱪning yahxi ikǝnlikini kɵrdi; Huda yoruⱪluⱪ bilǝn ⱪarangƣuluⱪni ayridi.
5 Ọlọ́run sì pe ìmọ́lẹ̀ náà ní “ọ̀sán,” àti òkùnkùn ní “òru.” Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kìn-ín-ní.
Huda yoruⱪluⱪni «kündüz», ⱪarangƣuluⱪni «keqǝ» dǝp atidi. Xu tǝriⱪidǝ kǝq bilǝn sǝⱨǝr ɵtti, bu tunji kün boldi.
6 Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí òfúrufú kí ó wà ní àárín àwọn omi, láti pààlà sí àárín àwọn omi.”
Andin Huda: — Sularning ariliⱪida bir boxluⱪ bolsun wǝ sular [yuⱪiri-tɵwǝn] ikkigǝ ayrilip tursun, dedi.
7 Ọlọ́run sì dá òfúrufú láti ya omi tí ó wà ní òkè òfúrufú kúrò lára omi tí ó wà ní orí ilẹ̀. Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
Xuning bilǝn Huda bir boxluⱪ ⱨasil ⱪilip, sularni boxluⱪning astiƣa wǝ boxluⱪning üstigǝ ayriwǝtti; ix ǝnǝ xundaⱪ boldi.
8 Ọlọ́run sì pe òfúrufú ní “ọ̀run.” Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kejì.
Huda bu boxluⱪni «asman» dǝp atidi. Xu tǝriⱪidǝ kǝq bilǝn sǝⱨǝr ɵtti, bu ikkinqi kün boldi.
9 Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí omi abẹ́ ọ̀run wọ́ papọ̀ sí ojú kan, kí ilẹ̀ gbígbẹ sì farahàn.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
Andin Huda: «Asmanning astidiki sular bir yǝrgǝ yiƣilsun, ⱪuruⱪ tupraⱪ kɵrünsun!» dewidi, dǝl xundaⱪ boldi.
10 Ọlọ́run sì pe ilẹ̀ gbígbẹ náà ní “ilẹ̀,” àti àpapọ̀ omi ní “òkun.” Ọlọ́run sì rí i wí pé ó dára.
Huda ⱪuruⱪ tupraⱪni «yǝr», yiƣilƣan sularni bolsa «dengizlar» dǝp atidi. Huda bularning yahxi bolƣanliⱪini kɵrdi.
11 Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó hu ọ̀gbìn: ewéko ti yóò máa mú èso wá àti igi tí yóò máa so èso ní irú tirẹ̀, tí ó ní irúgbìn nínú.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
Andin Huda yǝnǝ: «Yǝr ⱨǝrhil ɵsümlüklǝrni, uruⱪluⱪ otyaxlarni, mewǝ beridiƣan dǝrǝhlǝrni türliri boyiqǝ ɵzidǝ ündürsun! Mewilǝrning iqidǝ uruⱪliri bolsun!» dewidi, dǝl xundaⱪ boldi;
12 Ilẹ̀ sì hù ọ̀gbìn: ewéko tí ó ń so èso ní irú tirẹ̀, àti igi tí ń so èso, tí ó ní irúgbìn nínú ní irú tirẹ̀. Ọlọ́run sì ri pé ó dára.
yǝrdiki ɵsümlüklǝrni, yǝni uruⱪ qiⱪidiƣan otyaxlarni ɵz türliri boyiqǝ, mewǝ beridiƣan, yǝni mewilirining iqidǝ uruⱪliri bolƣan dǝrǝhlǝrni ɵz türliri boyiqǝ ündürdi. Huda bularning yahxi bolƣanliⱪini kɵrdi.
13 Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kẹta.
Xu tǝriⱪidǝ kǝq bilǝn sǝⱨǝr ɵtti, bu üqinqi kün boldi.
14 Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí ìmọ́lẹ̀ kí ó wà ní ojú ọ̀run, láti pààlà sí àárín ọ̀sán àti òru, kí wọn ó sì máa wà fún àmì láti mọ àwọn àsìkò, àti àwọn ọjọ́ àti àwọn ọdún.
Huda yǝnǝ: «Kündüz bilǝn keqini ayrip berix üqün asmanlarda yoruⱪluⱪ jisimlar bolsun. Ular künlǝr, pǝsillar wǝ yillarni ayrip turuxⱪa bǝlgǝ bolsun;
15 Kí wọn ó jẹ́ ìmọ́lẹ̀ ní ojú ọ̀run láti tan ìmọ́lẹ̀ sí orí ilẹ̀.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
ular asmanlarda turup nur qiⱪarƣuqi bolup, yǝr yüzigǝ yoruⱪluⱪ bǝrsun!» dewidi, dǝl xundaⱪ boldi.
16 Ọlọ́run dá ìmọ́lẹ̀ ńlá ńlá méjì, ìmọ́lẹ̀ tí ó tóbi láti ṣe àkóso ọ̀sán àti ìmọ́lẹ̀ tí ó kéré láti ṣe àkóso òru. Ó sì dá àwọn ìràwọ̀ pẹ̀lú.
Huda ikki qong nur qiⱪarƣuqi jisimni yaratti; qong nur qiⱪarƣuqini kündüzni baxⱪuridiƣan, kiqik nur qiⱪarƣuqni keqini baxⱪuridiƣan ⱪildi. Ⱨǝmdǝ yǝnǝ yultuzlarnimu yaratti.
17 Ọlọ́run sì ṣe wọ́n lọ́jọ̀ sí ojú ọ̀run láti máa tan ìmọ́lẹ̀ si orí ilẹ̀,
Huda bularni yǝrgǝ yoruⱪluⱪ berip, kündüz bilǝn keqini baxⱪurup, yoruⱪluⱪ bilǝn ⱪarangƣuluⱪni ayrisun dǝp asmanlarning gümbizigǝ orunlaxturdi. Huda buning yahxi bolƣanliⱪini kɵrdi.
18 láti ṣàkóso ọ̀sán àti òru àti láti pààlà sí àárín ìmọ́lẹ̀ àti òkùnkùn. Ọlọ́run sì rí i pé ó dára.
19 Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kẹrin.
Xu tǝriⱪidǝ kǝq bilǝn sǝⱨǝr ɵtti, bu tɵtinqi kün boldi.
20 Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí omi kí ó kún fún àwọn ohun alààyè, kí àwọn ẹyẹ kí ó sì máa fò ní òfúrufú.”
Huda yǝnǝ: «Sularda miƣ-miƣ janiwarlar bolsun, uqar-ⱪanatlar yǝrning üstidǝ, asman boxluⱪida uqsun» dedi.
21 Nítorí náà Ọlọ́run dá àwọn ẹ̀dá alààyè ńlá ńlá sí inú òkun, àwọn ohun ẹlẹ́mìí àti àwọn ohun tí ń rìn ní onírúurú tiwọn, àti àwọn ẹyẹ abìyẹ́ ní onírúurú tiwọn. Ọlọ́run sì rí i pé ó dára.
Xundaⱪ ⱪilip Huda sudiki qong-qong mǝhluⱪlarni, xundaⱪla sularda miƣ-miƣ janiwarlarni ɵz türliri boyiqǝ wǝ ⱨǝrhil uqar-ⱪanatlarni ɵz türliri boyiqǝ yaratti. Huda buning yahxi bolƣanliⱪini kɵrdi.
22 Ọlọ́run súre fún wọn, ó sì wí pé, “Ẹ máa bí sí i, ẹ sì máa pọ̀ sí i, ẹ kún inú omi òkun, kí àwọn ẹyẹ náà sì máa pọ̀ sí i ní orí ilẹ̀.”
Huda bu janliⱪlarƣa bǝht-bǝrikǝt ata ⱪilip: «Nǝsillinip, kɵpiyip, dengiz sulirini toldurunglar, uqar-ⱪanatlarmu yǝr yüzidǝ awusun» dedi.
23 Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ karùn-ún.
Xu tǝriⱪidǝ kǝq bilǝn sǝⱨǝr ɵtti, bu bǝxinqi kün boldi.
24 Ọlọ́run sì wí pé, “Kí ilẹ̀ kí ó mú ohun alààyè jáde ní onírúurú wọn: ẹran ọ̀sìn, àwọn ohun afàyàfà àti àwọn ẹran inú igbó, ọ̀kọ̀ọ̀kan ní irú tirẹ̀.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
Huda yǝnǝ: «Yǝr janiwarlarni ɵz türliri boyiqǝ qiⱪarsun — mal-qarwilarni, ɵmüligüqi janiwarlarni wǝ yawayi ⱨaywanlarni ɵz türliri boyiqǝ apiridǝ ⱪilsun» — dewidi, dǝl xundaⱪ boldi.
25 Ọlọ́run sì dá ẹranko inú igbó àti ẹran ọ̀sìn gbogbo ní irú tirẹ̀ àti gbogbo ohun alààyè tí ń rìn ní ilẹ̀ ní irú tirẹ̀. Ọlọ́run sì rí i pé ó dára.
Xundaⱪ ⱪilip Huda yǝrdiki yawayi ⱨaywanlarni ɵz türliri boyiqǝ, mal-qarwilarni ɵz türliri boyiqǝ wǝ yǝr yüzidǝ ɵmüligüqi barliⱪ janiwarlarni ɵz türliri boyiqǝ yaratti. Huda buning yahxi bolƣanliⱪini kɵrdi.
26 Lẹ́yìn náà ni Ọlọ́run wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a dá ènìyàn ní àwòrán ara wa, gẹ́gẹ́ bí àwa ti rí, kí wọn kí ó jẹ ọba lórí ẹja òkun, ẹyẹ ojú ọ̀run, ẹran ọ̀sìn, gbogbo ilẹ̀ àti lórí ohun gbogbo tí ń rìn lórí ilẹ̀.”
Andin Huda: «Ɵz sürǝt-obrazimizda, Bizgǝ ohxaydiƣan ⱪilip insanni yaritayli. Ular dengizdiki beliⱪlarƣa, asmandiki uqar-ⱪanatlarƣa, barliⱪ mal-qarwilarƣa, pütkül yǝr yüzigǝ wǝ yǝr yüzidiki barliⱪ ɵmiligüqi janiwarlarƣa igidarqiliⱪ ⱪilsun» dedi.
27 Nítorí náà, Ọlọ́run dá ènìyàn ní àwòrán ara rẹ̀, ní àwòrán Ọlọ́run ni ó dá a, akọ àti abo ni ó dá wọn.
Xundaⱪ ⱪilip, Huda insanni Ɵz sürǝt-obrazida yaratti; Uni Ɵzining süritidǝ yaratti; Ularni ǝrkǝk-qixi ⱪilip yaratti.
28 Ọlọ́run sì súre fún wọn, Ọlọ́run sì wí fún wọn pé, “Ẹ máa bí sí i, kí ẹ sì máa pọ̀ sí i, kí ẹ sì gbilẹ̀, kí ẹ ṣe ìkápá ayé. Ẹ ṣe àkóso àwọn ẹja inú òkun, ẹyẹ ojú ọ̀run àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó ń rìn ní orí ilẹ̀.”
Huda ularƣa bǝht-bǝrikǝt ata ⱪilip: «Silǝr nǝsillinip, kɵpiyip, yǝr yüzini toldurup boysundurunglar; dengizdiki beliⱪlar, asmandiki uqar-ⱪanatlarƣa, xuningdǝk yǝr yüzidǝ yüridiƣan ⱨǝrbir ⱨaywanlarƣa igidarqiliⱪ ⱪilinglar» dedi.
29 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí pé, “Mo fi gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ń so èso fún un yín bí oúnjẹ àti àwọn igi eléso pẹ̀lú. Gbogbo rẹ̀ yóò jẹ́ oúnjẹ fún un yín.
Andin Huda yǝnǝ: «Mana, Mǝn pütkül yǝr yüzidiki uruⱪluⱪ otyaxlar bilǝn uruⱪluⱪ mewǝ beridiƣan ⱨǝrbir dǝrǝhlǝrni silǝrgǝ ozuⱪluⱪ bolsun dǝp bǝrdim;
30 Àti fún àwọn ẹranko inú igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ohun afàyàfà, gbogbo ohun tó ní èémí ìyè nínú ni mo fi ewéko fún bí oúnjẹ.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
xundaⱪla yǝrdiki barliⱪ janiwarlar bilǝn asmandiki barliⱪ uqar-ⱪanatlar wǝ yǝr yüzidǝ barliⱪ ɵmiligüqilǝrgǝ, yǝni barliⱪ jan-janiwarlarƣa ozuⱪluⱪ bolsun dǝp barliⱪ gül-giyaⱨlarni bǝrdim» dewidi, dǝl xundaⱪ boldi.
31 Ọlọ́run sì rí àwọn ohun gbogbo tí ó dá, ó dára gidigidi. Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kẹfà.
Huda yaratⱪanlirining ⱨǝmmisigǝ sǝpselip ⱪaridi, wǝ mana bularning ⱨǝmmisi naⱨayiti yahxi bolƣanidi. Xu tǝriⱪidǝ kǝq bilǝn sǝⱨǝr ɵtti, bu altinqi kün boldi.

+ Genesis 1 >