< Galatians 4 >
1 Ǹjẹ́ ohun tí mo ń wí ni pé, níwọ̀n ìgbà tí àrólé náà bá wà ní èwe, kò yàtọ̀ nínú ohunkóhun sí ẹrú bí ó tilẹ̀ jẹ́ Olúwa ohun gbogbo.
Deixem-me esclarecer o que quero dizer. Um herdeiro que é menor de idade não é diferente de um escravo, embora o herdeiro possa vir a ser o dono de tudo.
2 Ṣùgbọ́n ó wà lábẹ́ olùtọ́jú àti ìríjú títí àkókò tí baba ti yàn tẹ́lẹ̀.
Um herdeiro está sujeito aos guardiões e aos administradores, até o momento determinado por seu pai.
3 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sì ni àwa, nígbà tí àwa wà ní èwe, àwa wà nínú ìdè lábẹ́ ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé.
O mesmo acontece conosco. Quando éramos crianças, estávamos sujeitos às regras básicas da lei.
4 Ṣùgbọ́n nígbà tí àkókò kíkún náà dé, Ọlọ́run rán ọmọ rẹ̀ jáde wá, ẹni tí a bí nínú obìnrin tí a bí lábẹ́ òfin.
Mas, no momento apropriado, Deus enviou o seu Filho, nascido de uma mulher e sob a regra da lei,
5 Láti ra àwọn tí ń bẹ lábẹ́ òfin padà, kí àwa lè gba ìsọdọmọ.
para que ele pudesse resgatar aqueles que eram mantidos sob o domínio da lei. Assim, pudemos nos tornar filhos adotados de Deus.
6 Àti nítorí tí ẹ̀yin jẹ́ ọmọ, Ọlọ́run sì ti rán Ẹ̀mí Ọmọ rẹ̀ wá sínú ọkàn yín, tí ń ké pé, “Ábbà, Baba.”
Deus, para lhes mostrar como vocês são filhos dele, enviou o Espírito do seu Filho para nos convencer e nos fazer chamar: “Aba”, que significa “Pai.”
7 Nítorí náà ìwọ kì í ṣe ẹrú, bí kò ṣe ọmọ; àti bí ìwọ bá ń ṣe ọmọ, ǹjẹ́ ìwọ di àrólé Ọlọ́run nípasẹ̀ Kristi.
Por isso, vocês não são mais escravos, porém, filhos. E se vocês são seus filhos, então, Deus os tornou seus herdeiros.
8 Tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀, nígbà tí ẹ̀yin kò tí i mọ Ọlọ́run, ẹ̀yin ti ṣe ẹrú fún àwọn tí kì í ṣe Ọlọ́run nípa ìṣẹ̀dá.
Na época em que vocês não conheciam a Deus, vocês eram escravizados pelos supostos “deuses” deste mundo.
9 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, nígbà tí ẹ̀yin ti mọ Ọlọ́run tan tàbí kí a sá kúkú wí pé ẹ di mímọ́ fún Ọlọ́run, èéha ti rí tí ẹ tún fi yípadà sí aláìlera àti agbára ìpilẹ̀ṣẹ̀ ẹ̀dá, lábẹ́ èyí tí ẹ̀yin tún fẹ́ padà wá ṣe ẹrú?
Mas, agora, vocês conhecem a Deus, ou melhor, são conhecidos por Deus. Então, como podem voltar para aquelas regras fracas e pobres? Vocês querem ser, mais uma vez, escravos daquelas regras?
10 Ẹ̀yin ń kíyèsi ọjọ́ àti àkókò, àti ọdún.
Por que vocês dão tanta importância a certos dias e meses, estações e anos especiais.
11 Ẹ̀rù yin ń bà mí, kí o má bà ṣe pé lásán ni mo ṣe làálàá lórí yín.
Eu estou preocupado com o fato de que tudo que eu tenha feito por vocês se perca!
12 Ará, mo bẹ̀ yín, ẹ dàbí èmi: nítorí èmi dàbí ẹ̀yin: ẹ̀yin kò ṣe mí ní ibi kan.
Meus irmãos e irmãs, eu lhes imploro: sejam como eu, pois eu me tornei como vocês. Vocês nunca me trataram mal.
13 Ẹ̀yin mọ̀ pé nínú àìlera ni mo wàásù ìyìnrere fún yín ní àkọ́kọ́.
Vocês se lembram que foi por eu estar doente que consegui anunciar-lhes o evangelho de Jesus, em minha primeira visita?
14 Èyí tí ó sì jẹ́ ìdánwò fún yín ní ara mi ni ẹ kò kẹ́gàn, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò sì kọ̀; ṣùgbọ́n ẹ̀yin gbà mí bí angẹli Ọlọ́run, àní bí Kristi Jesu.
Embora a minha saúde tenha lhes dado muito trabalho, vocês não me desprezaram e muito menos me rejeitaram. Na verdade, fui tratado por vocês como um anjo de Deus. Posso até dizer que me trataram como ao próprio Cristo Jesus.
15 Ǹjẹ́ ayọ̀ yín ìgbà náà ha dà? Nítorí mo gba ẹ̀rí yín pé, bi o bá ṣe é ṣe, ẹ̀ ò bá yọ ojú yín jáde, ẹ̀ bá sì fi wọ́n fún mi.
Então, o que aconteceu com toda aquela gratidão que vocês demonstraram? Eu lhes digo que, naquela época, se vocês pudessem tirar os seus olhos e dá-los para mim, teriam feito isso.
16 Ǹjẹ́ mo ha di ọ̀tá yín nítorí mo sọ òtítọ́ fún yín bí?
Então, o que aconteceu? Por acaso, eu me tornei inimigo de vocês, por lhes ter dito a verdade?
17 Wọ́n ń fi ìtara wá yin, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún rere; wọ́n ń fẹ́ já yin kúrò, kí ẹ̀yin lè máa wá wọn.
Essas pessoas estão interessadas em ganhar o apoio de vocês, mas não por bons motivos. Pelo contrário, elas querem mantê-los afastados de nós, para que vocês as apoiem com toda a sua disposição.
18 Ṣùgbọ́n ó dára láti máa fi ìtara wá ni fún ohun rere nígbà gbogbo, kì í sì í ṣe nígbà tí mo wà pẹ̀lú yín nìkan.
É claro que é bom querer fazer o bem. Mas isso deveria acontecer sempre, em qualquer situação, e não apenas quando estou aí com vocês!
19 Ẹ̀yin ọmọ mi kéékèèké, ẹ̀yin tí mo tún ń rọbí títí a ó fi ṣe ẹ̀dá Kristi nínú yín.
Meus queridos filhos, eu realmente quero trabalhar com vocês, até que a natureza de Cristo faça parte de vocês.
20 Ìbá wù mí láti wà lọ́dọ̀ yín nísinsin yìí, kí èmi sì yí ohùn mi padà nítorí pé mo dààmú nítorí yín.
Eu realmente desejaria poder estar com vocês neste momento, pois, assim, certamente mudaria o meu tom de voz. Eu estou muito preocupado com vocês!
21 Ẹ wí fún mi, ẹ̀yin tí ń fẹ́ wà lábẹ́ òfin, ẹ ko ha gbọ́ òfin ohun ti òfin sọ.
Respondam-me isto, vocês que desejam viver sob o domínio da lei: Vocês não ouvem o que a lei diz?
22 Nítorí a ti kọ ọ́ pé, Abrahamu ní ọmọ ọkùnrin méjì, ọ̀kan láti ọ̀dọ̀ ẹrúbìnrin, àti ọ̀kan láti ọ̀dọ̀ òmìnira obìnrin.
Como está escrito nas Sagradas Escrituras, Abraão teve dois filhos, um de uma escrava, e outro, de uma mulher livre.
23 Ṣùgbọ́n a bí èyí tí ṣe ti ẹrúbìnrin nípa ti ara, ṣùgbọ́n èyí ti òmìnira obìnrin ni a bí nípa ìlérí.
No entanto, o filho da escrava nasceu de acordo com um plano feito pela mente humana, enquanto que o filho da mulher livre nasceu como o resultado da promessa divina.
24 Nǹkan wọ̀nyí jẹ́ àpẹẹrẹ: nítorí pé àwọn obìnrin wọ̀nyí ní májẹ̀mú méjèèjì; ọ̀kan láti orí òkè Sinai wá, tí a bí lóko ẹrú, tí í ṣe Hagari.
Assim, temos uma analogia em relação a isso: essas duas mulheres representam dois acordos. Um acordo é aquele do monte Sinai, representado por Agar. Dela nasceram filhos para a escravidão.
25 Nítorí Hagari yìí ni òkè Sinai Arabia, tí ó sì dúró fún Jerusalẹmu tí ó wà nísinsin yìí, tí ó sì wà lóko ẹrú pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀.
Agar simboliza o monte Sinai, na Arábia, que corresponde à atual Jerusalém, pois ela se encontra escravizada junto com os seus filhos.
26 Ṣùgbọ́n Jerusalẹmu ti òkè jẹ́ òmìnira, èyí tí í ṣe ìyá wa.
Mas, a Jerusalém celestial é livre. Ela é a nossa mãe.
27 Nítorí a ti kọ ọ́ pé, “Máa yọ̀, ìwọ obìnrin àgàn tí kò bímọ, bú sí ayọ̀ kí o sì kígbe sókè, ìwọ tí kò rọbí rí; nítorí àwọn ọmọ obìnrin náà tí a kọ̀sílẹ̀ yóò pọ̀ ju ti obìnrin tó ní ọkọ lọ.”
Como está escrito nas Sagradas Escrituras: “Alegrem-se vocês que não têm filhos e que nunca deram à luz! Gritem de alegria, vocês que nunca entraram em trabalho de parto, pois a mulher abandonada tem mais filhos do que a mulher que mora com o marido!”
28 Ǹjẹ́ ará, ọmọ ìlérí ni àwa gẹ́gẹ́ bí Isaaki.
Agora, meus irmãos, somos os filhos da promessa, exatamente como Isaque.
29 Ṣùgbọ́n bí èyí tí a bí nípa ti ara ti ṣe inúnibíni nígbà náà sí èyí tí a bí nípa ti Ẹ̀mí, bẹ́ẹ̀ sì ni nísinsin yìí.
No entanto, assim como aquele que nasceu de acordo com um plano humano perseguiu aquele que nasceu por meio do Espírito, o mesmo acontece hoje.
30 Ṣùgbọ́n ìwé mímọ́ ha ti wí, “Lé ẹrúbìnrin yìí àti ọmọ rẹ̀ jáde, nítorí ọmọ ẹrúbìnrin kì yóò bá ọmọ òmìnira obìnrin jogún pọ̀.”
Mas, o que as Sagradas Escrituras dizem? “Mande embora a escrava e o seu filho, pois o filho da escrava não será herdeiro, ao contrário do filho da mulher livre.”
31 Nítorí náà, ará, àwa kì í ṣe ọmọ ẹrúbìnrin bí kò ṣe ti òmìnira obìnrin.
Portanto, meus amigos, nós não somos filhos de uma escrava, mas da mulher livre.