< Galatians 4 >
1 Ǹjẹ́ ohun tí mo ń wí ni pé, níwọ̀n ìgbà tí àrólé náà bá wà ní èwe, kò yàtọ̀ nínú ohunkóhun sí ẹrú bí ó tilẹ̀ jẹ́ Olúwa ohun gbogbo.
Mówię tedy: (bracia!) Pokąd dziedzic jest dziecięciem, nic nie jest różny od sługi, panem będąc wszystkiego;
2 Ṣùgbọ́n ó wà lábẹ́ olùtọ́jú àti ìríjú títí àkókò tí baba ti yàn tẹ́lẹ̀.
Ale jest pod opiekunami i dozorcami aż do czasu zamierzenia ojcowskiego.
3 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sì ni àwa, nígbà tí àwa wà ní èwe, àwa wà nínú ìdè lábẹ́ ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé.
Także i my, gdyśmy byli dziećmi, pod żywioły świata byliśmy zniewoleni.
4 Ṣùgbọ́n nígbà tí àkókò kíkún náà dé, Ọlọ́run rán ọmọ rẹ̀ jáde wá, ẹni tí a bí nínú obìnrin tí a bí lábẹ́ òfin.
Lecz gdy przyszło wypełnienie czasu, posłał Bóg onego Syna swego, który się urodził z niewiasty, który się stał pod zakonem,
5 Láti ra àwọn tí ń bẹ lábẹ́ òfin padà, kí àwa lè gba ìsọdọmọ.
Aby tych, którzy pod zakonem byli, wykupił, żebyśmy prawa przysposobienia za synów dostąpili.
6 Àti nítorí tí ẹ̀yin jẹ́ ọmọ, Ọlọ́run sì ti rán Ẹ̀mí Ọmọ rẹ̀ wá sínú ọkàn yín, tí ń ké pé, “Ábbà, Baba.”
A iżeście synowie, przetoż posłał Bóg Ducha Syna swego w serca wasze, wołającego Abba, to jest Ojcze.
7 Nítorí náà ìwọ kì í ṣe ẹrú, bí kò ṣe ọmọ; àti bí ìwọ bá ń ṣe ọmọ, ǹjẹ́ ìwọ di àrólé Ọlọ́run nípasẹ̀ Kristi.
A tak już więcej nie jesteś niewolnikiem, ale synem; a ponieważ synem, tedy i dziedzicem Bożym przez Chrystusa.
8 Tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀, nígbà tí ẹ̀yin kò tí i mọ Ọlọ́run, ẹ̀yin ti ṣe ẹrú fún àwọn tí kì í ṣe Ọlọ́run nípa ìṣẹ̀dá.
Aleć naonczas nie znając Boga, służyliście tym, którzy z przyrodzenia nie są bogowie.
9 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, nígbà tí ẹ̀yin ti mọ Ọlọ́run tan tàbí kí a sá kúkú wí pé ẹ di mímọ́ fún Ọlọ́run, èéha ti rí tí ẹ tún fi yípadà sí aláìlera àti agbára ìpilẹ̀ṣẹ̀ ẹ̀dá, lábẹ́ èyí tí ẹ̀yin tún fẹ́ padà wá ṣe ẹrú?
A teraz poznawszy Boga, owszem i poznani będąc od Boga, jakoż się zaś nazad wracacie ku żywiołom mdłym i mizernym, którym zasię znowu służyć chcecie?
10 Ẹ̀yin ń kíyèsi ọjọ́ àti àkókò, àti ọdún.
Przestrzegacie dni i miesiące, i czasy, i lata.
11 Ẹ̀rù yin ń bà mí, kí o má bà ṣe pé lásán ni mo ṣe làálàá lórí yín.
Boję się o was, bym snać darmo nie pracował około was.
12 Ará, mo bẹ̀ yín, ẹ dàbí èmi: nítorí èmi dàbí ẹ̀yin: ẹ̀yin kò ṣe mí ní ibi kan.
Bądźcie jako ja, gdyżem i ja jest jako wy, bracia! proszę was. W niczemeście mnie nie ukrzywdzili.
13 Ẹ̀yin mọ̀ pé nínú àìlera ni mo wàásù ìyìnrere fún yín ní àkọ́kọ́.
Bo wiecie, żem w słabości ciała wam z przodku Ewangieliję opowiadał.
14 Èyí tí ó sì jẹ́ ìdánwò fún yín ní ara mi ni ẹ kò kẹ́gàn, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò sì kọ̀; ṣùgbọ́n ẹ̀yin gbà mí bí angẹli Ọlọ́run, àní bí Kristi Jesu.
A pokuszenia mego, które było w ciele mojem, sobie nie lekceważyliście, aniście niem gardzili, aleście mię jako Anioła Bożego przyjęli i jako Chrystusa Jezusa.
15 Ǹjẹ́ ayọ̀ yín ìgbà náà ha dà? Nítorí mo gba ẹ̀rí yín pé, bi o bá ṣe é ṣe, ẹ̀ ò bá yọ ojú yín jáde, ẹ̀ bá sì fi wọ́n fún mi.
Jakież tedy było błogosławieństwo wasze? albowiem wam daję świadectwo, iż, by była rzecz można, dalibyście mi byli wyłupiwszy oczy wasze.
16 Ǹjẹ́ mo ha di ọ̀tá yín nítorí mo sọ òtítọ́ fún yín bí?
Takżem się stał nieprzyjacielem waszym, prawdę wam mówiąc?
17 Wọ́n ń fi ìtara wá yin, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún rere; wọ́n ń fẹ́ já yin kúrò, kí ẹ̀yin lè máa wá wọn.
Pałają ku wam miłością nie dobrze, owszem chcą was odstrychnąć, abyście ich miłowali.
18 Ṣùgbọ́n ó dára láti máa fi ìtara wá ni fún ohun rere nígbà gbogbo, kì í sì í ṣe nígbà tí mo wà pẹ̀lú yín nìkan.
A dobrać rzecz, pałać miłością w dobrem zawsze, a nie tylko, gdym jest obecnym u was.
19 Ẹ̀yin ọmọ mi kéékèèké, ẹ̀yin tí mo tún ń rọbí títí a ó fi ṣe ẹ̀dá Kristi nínú yín.
Dziatki moje! (które znowu z boleścią rodzę, ażby Chrystus był wykształtowany w was),
20 Ìbá wù mí láti wà lọ́dọ̀ yín nísinsin yìí, kí èmi sì yí ohùn mi padà nítorí pé mo dààmú nítorí yín.
Chciałbym teraz być u was i odmienić głos mój, ponieważ wątpię o was.
21 Ẹ wí fún mi, ẹ̀yin tí ń fẹ́ wà lábẹ́ òfin, ẹ ko ha gbọ́ òfin ohun ti òfin sọ.
Powiedzcie mi, którzy pod zakonem chcecie być, nie słuchacież zakonu?
22 Nítorí a ti kọ ọ́ pé, Abrahamu ní ọmọ ọkùnrin méjì, ọ̀kan láti ọ̀dọ̀ ẹrúbìnrin, àti ọ̀kan láti ọ̀dọ̀ òmìnira obìnrin.
Albowiem napisane, iż Abraham miał dwóch synów, jednego z niewolnicy, a drugiego z wolnej.
23 Ṣùgbọ́n a bí èyí tí ṣe ti ẹrúbìnrin nípa ti ara, ṣùgbọ́n èyí ti òmìnira obìnrin ni a bí nípa ìlérí.
Lecz ten, który był z niewolnicy, według ciała się urodził, a który z wolnej, według obietnicy.
24 Nǹkan wọ̀nyí jẹ́ àpẹẹrẹ: nítorí pé àwọn obìnrin wọ̀nyí ní májẹ̀mú méjèèjì; ọ̀kan láti orí òkè Sinai wá, tí a bí lóko ẹrú, tí í ṣe Hagari.
Przez co znaczą się insze rzeczy; albowiem te są one dwa testamenty; jeden z góry Synajskiej, który rodzi w niewolę; a ten jest jako Agar.
25 Nítorí Hagari yìí ni òkè Sinai Arabia, tí ó sì dúró fún Jerusalẹmu tí ó wà nísinsin yìí, tí ó sì wà lóko ẹrú pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀.
Albowiem Agar jest góra Synaj w Arabii, a stosuje się do niej teraźniejsze Jeruzalem; bo jest w niewoli z dziatkami swojemi.
26 Ṣùgbọ́n Jerusalẹmu ti òkè jẹ́ òmìnira, èyí tí í ṣe ìyá wa.
Lecz ono górne Jeruzalem wolne jest, które jest matką wszystkich nas.
27 Nítorí a ti kọ ọ́ pé, “Máa yọ̀, ìwọ obìnrin àgàn tí kò bímọ, bú sí ayọ̀ kí o sì kígbe sókè, ìwọ tí kò rọbí rí; nítorí àwọn ọmọ obìnrin náà tí a kọ̀sílẹ̀ yóò pọ̀ ju ti obìnrin tó ní ọkọ lọ.”
Albowiem napisano: Rozwesel się niepłodna, która nie rodzisz; porwij się, a zawołaj, która nie pracujesz w porodzeniu; bo ta opuszczona wiele ma dziatek, więcej niż ta, która ma męża.
28 Ǹjẹ́ ará, ọmọ ìlérí ni àwa gẹ́gẹ́ bí Isaaki.
My tedy, bracia! tak jako Izaak, jesteśmy dziatkami obietnicy.
29 Ṣùgbọ́n bí èyí tí a bí nípa ti ara ti ṣe inúnibíni nígbà náà sí èyí tí a bí nípa ti Ẹ̀mí, bẹ́ẹ̀ sì ni nísinsin yìí.
Ale jako na on czas ten, który się był urodził według ciała, prześladował tego, który się był urodził według ducha, tak się dzieje i teraz.
30 Ṣùgbọ́n ìwé mímọ́ ha ti wí, “Lé ẹrúbìnrin yìí àti ọmọ rẹ̀ jáde, nítorí ọmọ ẹrúbìnrin kì yóò bá ọmọ òmìnira obìnrin jogún pọ̀.”
Ale co mówi Pismo? Wyrzuć niewolnicę i syna jej; albowiem nie będzie dziedziczył syn niewolnicy z synem wolnej,
31 Nítorí náà, ará, àwa kì í ṣe ọmọ ẹrúbìnrin bí kò ṣe ti òmìnira obìnrin.
A tak, bracia! nie jesteśmy dziećmi niewolnicy, ale wolnej.