< Galatians 1 >

1 Paulu, aposteli tí a rán kì í ṣe láti ọ̀dọ̀ ènìyàn wá, tàbí nípa ènìyàn, ṣùgbọ́n nípa Jesu Kristi àti Ọlọ́run Baba, ẹni tí ó jí i dìde kúrò nínú òkú.
Paweł, apostoł nie od ludzi ani przez człowieka, ale przez Jezusa Chrystusa i Boga Ojca, który go wskrzesił z martwych;
2 Àti gbogbo àwọn arákùnrin tí ó wà pẹ̀lú mi, Sí àwọn ìjọ ní Galatia:
I wszyscy bracia, którzy są ze mną, do kościołów Galacji:
3 Oore-ọ̀fẹ́ sí yín àti àlàáfíà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wá àti Jesu Kristi Olúwa,
Łaska wam i pokój od Boga Ojca i naszego Pana Jezusa Chrystusa;
4 ẹni tí ó fi òun tìkára rẹ̀ dípò ẹ̀ṣẹ̀ wa, kí ó lè gbà wá kúrò nínú ayé búburú ìsinsin yìí, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ Ọlọ́run àti Baba wa, (aiōn g165)
Który wydał samego siebie za nasze grzechy, aby nas wyrwać z obecnego złego świata według woli Boga i Ojca naszego; (aiōn g165)
5 ẹni tí ògo wà fún láé àti láéláé. Àmín. (aiōn g165)
Któremu chwała na wieki wieków. Amen. (aiōn g165)
6 Ó yà mi lẹ́nu pé ẹ tètè yapa kúrò lọ́dọ̀ ẹni tí ó pè yín sínú oore-ọ̀fẹ́ Kristi, sí ìyìnrere mìíràn.
Dziwię się, że tak szybko dajecie się odwieść od tego, który was powołał ku łasce Chrystusa, do innej ewangelii;
7 Nítòótọ́, kò sí ìyìnrere mìíràn bí ó tilẹ̀ ṣe pé àwọn kan wà, tí ń yọ yín lẹ́nu, tí wọ́n sì ń fẹ́ yí ìyìnrere Kristi padà.
Która nie jest inną; są tylko pewni [ludzie], którzy was niepokoją i chcą wypaczyć ewangelię Chrystusa.
8 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe àwa ni tàbí angẹli kan láti ọ̀run wá, ni ó bá wàásù ìyìnrere mìíràn fún yín ju èyí tí a tí wàásù rẹ̀ fún yín lọ, jẹ́ kí ó di ẹni ìfibú títí láéláé!
Lecz choćbyśmy nawet my albo anioł z nieba głosił wam ewangelię [inną] od tej, którą wam głosiliśmy, niech będzie przeklęty.
9 Bí àwa ti wí ṣáájú, bẹ́ẹ̀ ni mo sì tún wí nísinsin yìí pé, bí ẹnìkan bá wàásù ìyìnrere mìíràn fún yín ju èyí tí ẹ̀yin tí gbà lọ, jẹ́ kí ó di ẹni ìfibú títí láéláé!
Jak powiedzieliśmy przedtem, tak i teraz znowu mówię: Gdyby wam ktoś głosił ewangelię [inną] od tej, którą przyjęliście, niech będzie przeklęty.
10 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ènìyàn ni èmi ń wá ojúrere rẹ̀ ní tàbí Ọlọ́run? Tàbí ènìyàn ni èmi ń fẹ́ láti wù bí? Bí èmi bá ń fẹ́ láti wu ènìyàn, èmi kò lè jẹ́ ìránṣẹ́ Kristi.
Czy teraz bowiem chcę pozyskać ludzi, czy Boga? Albo czy staram się przypodobać ludziom? Gdybym nadal ludziom chciał się przypodobać, nie byłbym sługą Chrystusa.
11 Mo fẹ́ kí ẹ mọ̀, ará, pé ìyìnrere tí mo tí wàásù kì í ṣe láti ipa ènìyàn.
A oznajmiam wam, bracia, że głoszona przeze mnie ewangelia nie jest według człowieka.
12 N kò gbà á lọ́wọ́ ènìyàn kankan, bẹ́ẹ̀ ni a kò fi kọ́ mi, ṣùgbọ́n mo gbà á nípa ìfihàn láti ọ̀dọ̀ Jesu Kristi.
Nie otrzymałem jej bowiem ani nie nauczyłem się jej od człowieka, ale przez objawienie Jezusa Chrystusa.
13 Nítorí ẹ̀yin ti gbúròó ìgbé ayé mi nígbà àtijọ́ nínú ìsìn àwọn Júù, bí mo tí ṣe inúnibíni sí ìjọ ènìyàn Ọlọ́run rékọjá ààlà, tí mo sì lépa láti bà á jẹ́.
Słyszeliście bowiem o moim dawniejszym postępowaniu w judaizmie, że ponad miarę prześladowałem kościół Boży i niszczyłem go;
14 Mo sì ta ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ẹlẹgbẹ́ mi yọ nínú ìsìn àwọn Júù láàrín àwọn ìran mi, mo sì ni ìtara lọ́pọ̀lọ́pọ̀ sì òfin àtọwọ́dọ́wọ́ àwọn baba mi.
I wyprzedzałem w judaizmie wielu moich rówieśników z mojego narodu, będąc bardzo gorliwym zwolennikiem moich ojczystych tradycji.
15 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó wú Ọlọ́run ẹni tí ó yà mí sọ́tọ̀ láti inú ìyá mi wá, tí ó sì pé mi nípa oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀.
Lecz gdy upodobało się Bogu, który mnie odłączył w łonie mojej matki i powołał swoją łaską;
16 Láti fi ọmọ rẹ̀ hàn nínú mi, kì èmi lè máa wàásù ìyìnrere rẹ̀ láàrín àwọn aláìkọlà; èmi kò wá ìmọ̀ lọ sọ́dọ̀ ẹnikẹ́ni,
Aby objawić swego Syna we mnie, abym głosił go wśród pogan, natychmiast, nie radząc się ciała i krwi;
17 bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gòkè lọ sì Jerusalẹmu tọ àwọn tí í ṣe aposteli ṣáájú mi, ṣùgbọ́n mo lọ sí Arabia, mo sì tún padà wá sí Damasku.
Ani nie udając się do Jerozolimy, do tych, którzy przede mną byli apostołami, poszedłem do Arabii, po czym znowu wróciłem do Damaszku.
18 Lẹ́yìn ọdún mẹ́ta, nígbà náà ni mo gòkè lọ sì Jerusalẹmu láti lọ kì Peteru, mo sì gbé ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní ìjọ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún,
Potem, trzy lata później, udałem się do Jerozolimy, aby zobaczyć się z Piotrem, u którego przebywałem piętnaście dni.
19 èmi kò ri ẹlòmíràn nínú àwọn tí ó jẹ́ aposteli, bí kò ṣe Jakọbu arákùnrin Olúwa.
A spośród apostołów nie widziałem żadnego innego poza Jakubem, bratem Pana.
20 Nǹkan tí èmi ń kọ̀wé sí yín yìí, kíyèsi i, níwájú Ọlọ́run èmi kò ṣèké.
[Oświadczam] przed Bogiem, że w tym, co do was piszę, nie kłamię.
21 Lẹ́yìn náà mo sì wá sí agbègbè Siria àti ti Kilikia.
Potem udałem się w okolice Syrii i Cylicji;
22 Mo sì jẹ́ ẹni tí a kò mọ̀ lójú fún àwọn ìjọ tí ó wà nínú Kristi ni Judea.
A nie byłem osobiście znany kościołom Judei, które są w Chrystusie.
23 Wọ́n kàn gbọ́ ìròyìn wí pé, “Ẹni tí ó tí ń ṣe inúnibíni sí wa rí, ní ìsinsin yìí ti ń wàásù ìgbàgbọ́ náà tí ó ti gbìyànjú láti bàjẹ́ nígbà kan rí.”
Słyszeli tylko: ten, który kiedyś nas prześladował, teraz głosi wiarę, którą przedtem niszczył.
24 Wọ́n sì yin Ọlọ́run lógo nítorí mi.
I chwalili Boga z mojego powodu.

< Galatians 1 >