< Galatians 1 >

1 Paulu, aposteli tí a rán kì í ṣe láti ọ̀dọ̀ ènìyàn wá, tàbí nípa ènìyàn, ṣùgbọ́n nípa Jesu Kristi àti Ọlọ́run Baba, ẹni tí ó jí i dìde kúrò nínú òkú.
[I], Paul, [write this letter to you. I remind you that I am] an apostle. That is not because a group of people [appointed me], nor because a human being [sent me to be an apostle]. Instead, Jesus Christ and God [our heavenly] Father, who caused Jesus to become alive again after he died, have [appointed and] sent [me to be an apostle].
2 Àti gbogbo àwọn arákùnrin tí ó wà pẹ̀lú mi, Sí àwọn ìjọ ní Galatia:
All the fellow believers [who are here] with me [approve of this message that I am writing. I am sending this letter] to the congregations that [are] in Galatia [province].
3 Oore-ọ̀fẹ́ sí yín àti àlàáfíà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wá àti Jesu Kristi Olúwa,
[I pray that] God, our Father, and the Lord Jesus Christ will kindly [help] you and enable [you to have inner] peace.
4 ẹni tí ó fi òun tìkára rẹ̀ dípò ẹ̀ṣẹ̀ wa, kí ó lè gbà wá kúrò nínú ayé búburú ìsinsin yìí, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ Ọlọ́run àti Baba wa, (aiōn g165)
Christ offered himself [as a sacrifice] in order that [he might remove the guilt for] our sins. He did that in order that he might enable us to not [do the evil things that people who do not know him] do. [He did this] because God, who is our Father, wanted it. (aiōn g165)
5 ẹni tí ògo wà fún láé àti láéláé. Àmín. (aiōn g165)
[I pray that people will] praise God forever. (May it be so!/Amen!) (aiōn g165)
6 Ó yà mi lẹ́nu pé ẹ tètè yapa kúrò lọ́dọ̀ ẹni tí ó pè yín sínú oore-ọ̀fẹ́ Kristi, sí ìyìnrere mìíràn.
I am very disappointed [IRO] that so soon [after you trusted in Christ] you have turned away from [God]. He chose you in order that [you might have what] Christ freely/kindly gives. I am also disappointed that so soon you are believing a different [message which some say is] “good news.”
7 Nítòótọ́, kò sí ìyìnrere mìíràn bí ó tilẹ̀ ṣe pé àwọn kan wà, tí ń yọ yín lẹ́nu, tí wọ́n sì ń fẹ́ yí ìyìnrere Kristi padà.
Their message is not a true message. [What is happening is that] certain persons are confusing your [minds]. They are desiring to change the good message (that Christ [revealed/about] Christ) [and are creating another message].
8 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe àwa ni tàbí angẹli kan láti ọ̀run wá, ni ó bá wàásù ìyìnrere mìíràn fún yín ju èyí tí a tí wàásù rẹ̀ fún yín lọ, jẹ́ kí ó di ẹni ìfibú títí láéláé!
But even if we [(exc) apostles] or an angel from heaven would tell you a message that is different from the good message that we told you [before], I [appeal to God] that [he] punish such a person [forever].
9 Bí àwa ti wí ṣáájú, bẹ́ẹ̀ ni mo sì tún wí nísinsin yìí pé, bí ẹnìkan bá wàásù ìyìnrere mìíràn fún yín ju èyí tí ẹ̀yin tí gbà lọ, jẹ́ kí ó di ẹni ìfibú títí láéláé!
As I told you previously, so now I tell you this once more: Someone is telling you [what he says is] a good message, but it is a message that is different from [the good message] that I gave you. So I [appeal to God] that [he] severely punish that person.
10 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ènìyàn ni èmi ń wá ojúrere rẹ̀ ní tàbí Ọlọ́run? Tàbí ènìyàn ni èmi ń fẹ́ láti wù bí? Bí èmi bá ń fẹ́ láti wu ènìyàn, èmi kò lè jẹ́ ìránṣẹ́ Kristi.
[I said that] because [RHQ] I do not desire that people approve me, [contrary to what some have said about me]. It is God whom I desire to approve me. [Specifically, I do not say and do] [RHQ] things just to please people. If it were still people whom I was trying to please, then I would not be one who [willingly and completely] serves Christ.
11 Mo fẹ́ kí ẹ mọ̀, ará, pé ìyìnrere tí mo tí wàásù kì í ṣe láti ipa ènìyàn.
My fellow believers, I want you to know that the message about Christ that I proclaim to people is not one that some person [created/thought up].
12 N kò gbà á lọ́wọ́ ènìyàn kankan, bẹ́ẹ̀ ni a kò fi kọ́ mi, ṣùgbọ́n mo gbà á nípa ìfihàn láti ọ̀dọ̀ Jesu Kristi.
I did not receive this message from a human [messenger], and no [human being] taught it to me. Instead, Jesus Christ revealed it to me.
13 Nítorí ẹ̀yin ti gbúròó ìgbé ayé mi nígbà àtijọ́ nínú ìsìn àwọn Júù, bí mo tí ṣe inúnibíni sí ìjọ ènìyàn Ọlọ́run rékọjá ààlà, tí mo sì lépa láti bà á jẹ́.
People have told you how I used to behave when [I practiced] the Jewish religion. They told you that I continually did very harmful things to the groups of believers that God [established], and they told you that I tried to get rid of those people.
14 Mo sì ta ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ẹlẹgbẹ́ mi yọ nínú ìsìn àwọn Júù láàrín àwọn ìran mi, mo sì ni ìtara lọ́pọ̀lọ́pọ̀ sì òfin àtọwọ́dọ́wọ́ àwọn baba mi.
I practiced the Jewish religion more thoroughly than many [other Jews] who were my age practiced it. I much more enthusiastically tried to get others to obey the traditions that my ancestors [kept].
15 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó wú Ọlọ́run ẹni tí ó yà mí sọ́tọ̀ láti inú ìyá mi wá, tí ó sì pé mi nípa oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀.
Nevertheless, before I was born, [God] (set me apart/selected me). He chose me [to live eternally], something that I did not deserve.
16 Láti fi ọmọ rẹ̀ hàn nínú mi, kì èmi lè máa wàásù ìyìnrere rẹ̀ láàrín àwọn aláìkọlà; èmi kò wá ìmọ̀ lọ sọ́dọ̀ ẹnikẹ́ni,
He wanted me to know that Jesus is (his Son/the man who is also God), so that I would tell others the message about him in regions where non-Jews live. But I did not immediately go to any human beings [SYN] in order to gain [an understanding of that message. I received it directly from Christ!]!
17 bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gòkè lọ sì Jerusalẹmu tọ àwọn tí í ṣe aposteli ṣáájú mi, ṣùgbọ́n mo lọ sí Arabia, mo sì tún padà wá sí Damasku.
I did not [immediately] leave Damascus and go to Jerusalem [for that purpose] to those who were apostles before I was. Instead, I went away to Arabia [region, a desert area]. Later I returned once more to Damascus [city].
18 Lẹ́yìn ọdún mẹ́ta, nígbà náà ni mo gòkè lọ sì Jerusalẹmu láti lọ kì Peteru, mo sì gbé ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní ìjọ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún,
Then three years after [God revealed this good message to me], I went up to Jerusalem in order that I might meet Peter. But I stayed with him for [only] 15 days, [which was not long enough for him to teach me thoroughly about Christ].
19 èmi kò ri ẹlòmíràn nínú àwọn tí ó jẹ́ aposteli, bí kò ṣe Jakọbu arákùnrin Olúwa.
I also saw James, the brother of our Lord [Jesus and the leader of the believers there, but] I did not see any other apostle.
20 Nǹkan tí èmi ń kọ̀wé sí yín yìí, kíyèsi i, níwájú Ọlọ́run èmi kò ṣèké.
God knows that what I am writing to you is completely true [LIT]!
21 Lẹ́yìn náà mo sì wá sí agbègbè Siria àti ti Kilikia.
After [I left Jerusalem], I went to [the regions of] Syria and Cilicia.
22 Mo sì jẹ́ ẹni tí a kò mọ̀ lójú fún àwọn ìjọ tí ó wà nínú Kristi ni Judea.
[At that time, people in] the Christian congregations that are in Judea [province] still had not met me [SYN] personally.
23 Wọ́n kàn gbọ́ ìròyìn wí pé, “Ẹni tí ó tí ń ṣe inúnibíni sí wa rí, ní ìsinsin yìí ti ń wàásù ìgbàgbọ́ náà tí ó ti gbìyànjú láti bàjẹ́ nígbà kan rí.”
They only heard [others say about me] repeatedly, “[Paul], the one who was formerly doing harmful things to us, is now telling the [same message] which we believe and which formerly he was trying (to destroy/to cause people to stop believing)!”
24 Wọ́n sì yin Ọlọ́run lógo nítorí mi.
And they praised God because of [what had happened to] me.

< Galatians 1 >