< Ezra 1 >

1 Ní ọdún kìn-ín-ní Kirusi, ọba Persia, kí a lè mú ọ̀rọ̀ Olúwa tí Jeremiah sọ ṣẹ, Olúwa ru ọkàn Kirusi ọba Persia sókè láti ṣe ìkéde jákèjádò gbogbo agbègbè ìjọba rẹ̀, kí ó sì ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ pé,
I KA makahiki akahi o Kuro ke alii o Peresia, i hookoia'i ka olelo a Iehova ma ka waha o Ieremia, hoala mai o Iehova i ka naau o Kuro ke alii o Peresia, a kukala aku ia ma kona aupuni a pau, a ma ka palapala hoi, i ka i ana'e,
2 “Èyí ni ohun tí Kirusi ọba Persia wí pé: “‘Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, ti fún mi ní gbogbo ìjọba ayé. Ó sì ti yàn mí láti kọ́ tẹmpili Olúwa fún un ní Jerusalẹmu tí ó wà ní Juda.
Peneia ka olelo a Kuro ke alii o Peresia, O Iehova ke Akua o ka lani, ua haawi mai ia no'u i na aupuni a pau o ka honua; a ua kauoha mai oia ia'u e hana i hale nona ma Ierusalema i Iuda.
3 Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ láàrín yín—kí Ọlọ́run rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀, kí ó sì gòkè lọ sí Jerusalẹmu tí ó wà ní Juda, láti kọ́ tẹmpili Olúwa Ọlọ́run Israẹli, Ọlọ́run tí ó wà ní Jerusalẹmu.
Owai la ka mea iwaena o oukou no kona poe kanaka a pau? o kona Akua kekahi me ia, a e pii aku ia ma Ierusalema i Iuda, a e hana i ka hale ma Ierusalema no Iehova ke Akua o ka laeraela, oia ke Akua.
4 Kí àwọn ènìyàn ní ibikíbi tí ẹni náà bá ń gbé kí ó fi fàdákà àti wúrà pẹ̀lú ohun tí ó dára àti ẹran ọ̀sìn, pẹ̀lú ọrẹ àtinúwá ràn án lọ́wọ́ fún tẹmpili Ọlọ́run ní Jerusalẹmu.’”
A o kela mea keia mea e noho ana ma na wahi a pau ana e noho la, e kokua mai na kanaka o kona wahi ia ia me ke kala, a me ke gula, a me ka waiwai, a me na holoholona, me ka makana no hoi no ka hale o ke Akua ma Ierusalema.
5 Nígbà náà àwọn olórí ìdílé Juda àti Benjamini àti àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi—olúkúlùkù ẹni tí Ọlọ́run ti fọwọ́ tọ́ ọkàn rẹ̀—múra láti gòkè lọ láti kọ ilé Olúwa ní Jerusalẹmu.
Alaila ku ae la ka poe koikoi o na makua no ka Iuda, a me ka Beniamina, a me na kahuna, a me na Levi, o na mea a pau a ke Akua i hoala mai ai i ko lakou mau naau e pii ae e hana i ka hale no Iehova ma Ierusalema.
6 Gbogbo àwọn aládùúgbò wọn ràn wọ́n lọ́wọ́ pẹ̀lú ohun èlò ti fàdákà àti wúrà, pẹ̀lú onírúurú ohun ìní àti ẹran ọ̀sìn àti pẹ̀lú àwọn ẹ̀bùn iyebíye, ní àfikún si gbogbo àwọn ọrẹ àtinúwá.
A kokua mai no ko lakou poe hoalauna a pau ia lakou me na kiaha kala, a me ke gula, me ka waiwai, a me na holoholona, a me na mea maikai, a he okoa hoi na mea a pau i haawi lokomaikai ia mai.
7 Ní àfikún, ọba Kirusi mú àwọn ohun èlò tí ó jẹ́ ti ilé Olúwa jáde wá, tí Nebukadnessari ti kó lọ láti Jerusalẹmu tí ó sì ti kó sí ilé òrìṣà rẹ̀.
A lawe mai la o Kuro, ke alii, i na kiaha o ka hale o Iehova, na mea a Nebukaneza i lawe ae mai Ierusalema mai, a waiho ia lakou iloko o ka hale o kona mau akua;
8 Kirusi ọba Persia pàṣẹ fún Mitredati olùṣọ́ ilé ìṣúra láti kó wọn jáde, ó sì kà wọ́n fún Ṣeṣbassari ìjòyè Juda.
Oia mau mea ka Kuro ke alii o Peresia i lawe mai ai iwaho, ma ka lima o Miteredate, ka puukukala, a helu aku la ia mau mea no Sesehazara, ka luna no ka Iuda.
9 Èyí ni iye wọn. Ọgbọ̀n àwo wúrà 30 Ẹgbẹ̀rún àwo fàdákà 1,000 Àwo ìrúbọ fàdákà mọ́kàndínlọ́gbọ̀n 29
A eia ka huina o ia mau mea; he kanakolu ipu gula, a hookahi tausani ipu kala, he iwakaluakumamaiwa pahi,
10 Ọgbọ̀n àdému wúrà 30 Irinwó ó lé mẹ́wàá oríṣìí àdému fàdákà mìíràn 410 Ẹgbẹ̀rún kan àwọn ohun èlò mìíràn 1,000
He kanakolu bola gula, eha haneri a me ka umi keu na bola kala maikai iki iho, a o na kiaha e ae hookahi tausani.
11 Gbogbo ohun èlò wúrà àti ti fàdákà ní àpapọ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún ó lé irinwó. Ṣeṣbassari kó gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí wá pẹ̀lú àwọn ìgbèkùn tí ó gòkè wá láti Babeli sí Jerusalẹmu.
O na mea gula a pau, a me ke kala, elima tausani a me na haneri eha. O keia mau mea a pau ka Sesehazara i lawe aku ai i ka pii ana o ka poe pio mai Babulona aku a Ierusalema.

< Ezra 1 >