< Ezra 9 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí a ti ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí tán, àwọn olórí tọ̀ mí wá, wọ́n sì wí pé, “Àwọn ènìyàn Israẹli, tí ó fi mọ́ àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, kò tì í ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn agbègbè tí wọ́n ń ṣe ohun ìríra bí i ti àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti, àwọn ará Peresi, àwọn ará Jebusi, àwọn ará Ammoni, àwọn ará Moabu, àwọn ará Ejibiti àti ti àwọn ará Amori.
Kuin nämät kaikki olivat päätetyt, niin tulivat päämiehet minun tyköni ja sanoivat: Israelin kansa ja papit ja Leviläiset ei ole erinneet maan kansain, Kanaanealaisten, Hetiläisten, Pheresiläisten, Jebusilaisten, Ammonilaisten, Moabilaisten, Egyptiläisten ja Amorilaisten kauhistuksesta.
2 Wọ́n ti fẹ́ lára àwọn ọmọbìnrin wọn fún ara wọn àti fún àwọn ọmọkùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí aya, wọ́n ti da irú-ọmọ ìran mímọ́ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn ti ó wà ní àyíká wọn. Àwọn olórí àti àwọn ìjòyè ta àwọn ènìyàn tókù yọ nínú híhu ìwà àìṣòótọ́.”
Sillä he ovat ottaneet heidän tyttäriänsä itsellensä ja pojillensa ja ovat sekoittaneet pyhän siemenen maan kansain kanssa; ja heidän päämiehensä ja esivaltansa ovat kaikkein ensimäiset siinä pahassa teossa.
3 Nígbà tí mo gbọ́ èyí, mo fa àwọ̀tẹ́lẹ̀ àti agbádá mi ya, mo tu irun orí àti irùngbọ̀n mi, mo sì jókòó ní ìjayà.
Kuin minä sen kuulin, repäisin minä vaatteeni ja hameeni, ja repelin hiuksiani päästäni ja partaani ja istuin hämmästyksissä.
4 Nígbà náà ni gbogbo àwọn tí ó wárìrì sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Israẹli kó ara wọn jọ yí mi ká nítorí àìṣòótọ́ àwọn ìgbèkùn yìí. Èmi sì jókòó níbẹ̀ ní ìjayà títí di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́.
Ja kaikki, jotka pelkäsivät Herran Israelin Jumalan sanaa, tulivat kokoon minun tyköni, jälleen tulleiden synnin tähden; ja minä istuin hämmästyksissä hamaan ehtoouhriin asti.
5 Ní ìgbà tí ó di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́, mo dìde kúrò nínú ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn mi, pẹ̀lú àwọ̀tẹ́lẹ̀ àti agbádá mi yíya ní ọrùn mi, mo kúnlẹ̀ lórí eékún mi méjèèjì, mo sì tẹ́ ọwọ́ mi méjèèjì sí Olúwa Ọlọ́run mi.
Ja ehtoouhrin aikana nousin minä surkeudestani; ja kuin minä repäisin vaatteeni ja hameeni, lankesin minä polvilleni ja hajoitin käteni Herran minun Jumalani tykö,
6 Mo sì gbàdúrà: “Ojú tì mí gidigidi, tí n kò fi lè gbé ojú mi sókè sí ọ̀dọ̀ rẹ, Ọlọ́run mi, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wá di púpọ̀ ní orí wa, ẹ̀bi wa sì ga kan àwọn ọ̀run.
Ja sanoin: minun Jumalani! minä häpeen ja en kehtaa silmiäni nostaa sinun tykös, minun Jumalani; sillä meidän syntimme ovat enentyneet päämme ylitse ja meidän pahat tekomme ovat kasvaneet hamaan taivaaseen asti.
7 Láti ọjọ́ àwọn baba wá ni ẹ̀bi wa ti pọ̀ jọjọ títí di ìsinsin yìí. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa, àwa àti àwọn ọba wa àti àwọn àlùfáà wa ni a ti sọ di ẹni idà, ẹni ìgbèkùn, ìkógun àti ẹni ẹ̀sín lọ́wọ́ àwọn àjèjì ọba, bí ó ti rí lónìí.
Hamasta isäimme ajasta niin tähän päivään saakka olemme me olleet suurissa synneissä; ja meidän pahain töidemme tähden olemme me ja meidän kuninkaamme ja pappimme annetut maan kuningasten käsiin, ja miekkaan, ja vankeuteen ja ryöstöksi, ja meidän kasvomme häpiään, niinkuin tänäkin päivänä.
8 “Ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí, fún ìgbà díẹ̀, ni a ti fi oore-ọ̀fẹ́ fún wa láti ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa wá láti sálà, àti láti fi èèkàn fún wa ni ibi mímọ́ rẹ̀, nítorí kí Ọlọ́run kí ó lè mú ojú wa mọ́lẹ̀, kí ó sì tún wa gbé dìde díẹ̀ kúrò nínú ìgbèkùn wa.
Mutta nyt vähällä ajan rahdulla on meille armo tapahtunut Herralta meidän Jumalaltamme, että vielä on muutamia meistä jäljellä ja päässeitä, että hän antoi vielä vaarnan meille pyhään siaansa, että meidän Jumalamme valistais silmämme ja antais meille vähän virvoituksen orjuudessamme.
9 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwa jẹ́ ẹrú, Ọlọ́run wa kò fi wa sílẹ̀ nínú ìgbèkùn wa. Ó ti fi àánú hàn fún wa ni iwájú àwọn ọba Persia: Ó ti fún wa ní ìgbé ayé tuntun láti tún odi ilé Ọlọ́run wa mọ, kí a sì tún àwókù rẹ̀ ṣe, ó sì fi odi ààbò fún wa ní Juda àti ní Jerusalẹmu.
Sillä me olemme orjat; ja orjuudessamme ei hyljännyt meitä meidän Jumalamme; ja hän on kääntänyt laupiuden meidän tykömme Persian kuningasten edessä, että he antoivat meidän elää, ja korottaa meidän Jumalamme huoneen, ja korjata jaonneet paikat, ja antoi meille aidan Juudassa ja Jerusalemissa.
10 “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, Ọlọ́run wa, kí ni àwa yóò wí lẹ́yìn èyí? Nítorí tí àwa kọ àṣẹ rẹ sílẹ̀
Mitä me siis sanomme, meidän Jumalamme, tästälähin? että me olemme hyljänneet sinun käskys,
11 èyí tí ìwọ ti pa fún wa láti ẹnu àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ, nígbà ti ìwọ wí pé, ‘Ilẹ̀ náà ti ẹ̀yin ń wọ̀ lọ láti gbà n nì jẹ́ ilẹ̀ aláìmọ́ tó kún fún ẹ̀gbin àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, nípa ṣíṣe ohun ìríra àti híhu ìwà èérí ti kún ún láti ìkángun kan dé èkejì.
Joita sinä olet käskenyt palveliais prohetain kautta, sanoen: maa, johon te menette omistamaan sitä, on saastainen maa, maan kansain saastaisuuden tähden, niiden kauhistusten tähden, joilla he ovat sen täyttäneet saastaisuudellansa, sekä siellä että täällä.
12 Nítorí náà, ẹ má ṣe fi àwọn ọmọbìnrin yín fún àwọn ọmọkùnrin wọn ní ìyàwó tàbí kí ẹ fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin yín ní ìyàwó. Ẹ má ṣe dá májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú wọn nígbàkígbà kí ẹ̀yin kí ó sì le lágbára, kí ẹ sì le máa jẹ ire ilẹ̀ náà, kí ẹ sì le fi í sílẹ̀ fún àwọn ọmọ yín gẹ́gẹ́ bí ogún ayérayé.’
Niin ei teidän pidä nyt antaman tyttäriänne heidän pojillensa, ja ei teidän pidä ottaman heidän tyttäriänsä pojillenne; älkäät myös etsikö heidän rauhaansa ja hyväänsä ijankaikkisesti, että vahvistuisitte, ja söisitte maan hyvyyttä, ja saisitte antaa sen teidän lapsillenne ijankaikkiseksi perimiseksi.
13 “Ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wa jẹ́ àyọríṣí iṣẹ́ búburú wa àti ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ńlá wa, síbẹ̀, Ọlọ́run wa, ìjìyà ti ìwọ fún wa kéré si ìjìyà tí ó yẹ fún ẹ̀ṣẹ̀ ti a dá, ìwọ sì fún wa ní àwọn ènìyàn tó ṣẹ́kù bí èyí.
Ja niiden kaikkein jälkeen mitkä meidän päällemme tulleet ovat, pahain tekoimme tähden ja suurten synteimme tähden, niin olet sinä meidän Jumalamme säästänyt meidän pahoja töitämme ja antanut meille vapahduksen, niinkuin nyt on.
14 Ǹjẹ́ ó yẹ kí àwa tún yẹ̀ kúrò nínú àṣẹ rẹ, kí a sì máa ṣe ìgbéyàwó papọ̀ pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí wọn ti ṣe onírúurú ohun ìríra báyìí? Ṣe ìwọ kò ní bínú sí wa láti pa wá run tí kì yóò sẹ́ ku ẹnikẹ́ni tí yóò là?
Pitäiskö meidän taas sinun käskys käymän ylitse ja tekemän lankoutta tämän ilkiän kansan kanssa? Etkös mahda vihastua meidän päällemme, siihenasti että peräti hukutat, ettei ketään jää, eikä ole pääsemystä?
15 Ìwọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ìwọ jẹ́ olódodo! Àwa ìgbèkùn tí ó ṣẹ́kù bí ó ti rí lónìí. Àwa dúró níwájú rẹ nínú ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ wa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé nítorí èyí ẹnikẹ́ni nínú wa kò lè dúró níwájú rẹ”.
Herra Israelin Jumala! sinä olet vanhurskas. Sillä me olemme jääneet vapahdettaa, niinkuin se tänäpänä on. Katso, me olemme sinun edessäs synneissämme; sentähden ei kenkään voi edessäs pysyä.

< Ezra 9 >