< Ezra 9 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí a ti ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí tán, àwọn olórí tọ̀ mí wá, wọ́n sì wí pé, “Àwọn ènìyàn Israẹli, tí ó fi mọ́ àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, kò tì í ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn agbègbè tí wọ́n ń ṣe ohun ìríra bí i ti àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti, àwọn ará Peresi, àwọn ará Jebusi, àwọn ará Ammoni, àwọn ará Moabu, àwọn ará Ejibiti àti ti àwọn ará Amori.
“Sa dihang nahuman na kining mga butanga, miduol kanako ang mga opisyal ug miingon, 'Ang katawhan sa Israel, ang mga pari ug ang mga Levita wala mibulag sa ilang mga kaugalingon gikan sa katawhan sa ubang mga nasod ug gikan sa ilang mga kalaw-ayan: mga Canaanhon, mga Hetihanon, mga Perisihanon, mga Jebusihanon, mga Amorihanon, mga Moabihanon, mga Ehiptohanon, ug mga Amorihanon.
2 Wọ́n ti fẹ́ lára àwọn ọmọbìnrin wọn fún ara wọn àti fún àwọn ọmọkùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí aya, wọ́n ti da irú-ọmọ ìran mímọ́ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn ti ó wà ní àyíká wọn. Àwọn olórí àti àwọn ìjòyè ta àwọn ènìyàn tókù yọ nínú híhu ìwà àìṣòótọ́.”
Tungod kay giminyoan nila ang pipila sa ilang mga anak nga babaye ug mga anak nga lalaki, ug nasagolan ang balaang katawhan sa mga tawo sa ubang mga nasod. Ug ang mga opisyal ug mga pangulo mao ang nagsugod sa pagka dili matinumanon.'
3 Nígbà tí mo gbọ́ èyí, mo fa àwọ̀tẹ́lẹ̀ àti agbádá mi ya, mo tu irun orí àti irùngbọ̀n mi, mo sì jókòó ní ìjayà.
Sa pagkadungog nako niini, gigisi ko ang akong bisti ug kupo ug gilabnot ang buhok gikan sa akong ulo ug bungot, ug milingkod ako nga nasubo.
4 Nígbà náà ni gbogbo àwọn tí ó wárìrì sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Israẹli kó ara wọn jọ yí mi ká nítorí àìṣòótọ́ àwọn ìgbèkùn yìí. Èmi sì jókòó níbẹ̀ ní ìjayà títí di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́.
Kadtong tanan nga nangalisang sa mga pulong sa Dios sa Israel mahitungod niining pagkadili matinumanon miduol kanako samtang nagalingkod ako sa kaulawan hangtod sa pagkagabii nga paghalad.
5 Ní ìgbà tí ó di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́, mo dìde kúrò nínú ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn mi, pẹ̀lú àwọ̀tẹ́lẹ̀ àti agbádá mi yíya ní ọrùn mi, mo kúnlẹ̀ lórí eékún mi méjèèjì, mo sì tẹ́ ọwọ́ mi méjèèjì sí Olúwa Ọlọ́run mi.
Apan sa gabii nga paghalad mitindog ako sa akong nahimutangan sa kaulawan sa nagisi kong mga bisti ug kupo, ug miluhod ug gidupa ko ang akong mga kamot ngadto kang Yahweh nga akong Dios.
6 Mo sì gbàdúrà: “Ojú tì mí gidigidi, tí n kò fi lè gbé ojú mi sókè sí ọ̀dọ̀ rẹ, Ọlọ́run mi, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wá di púpọ̀ ní orí wa, ẹ̀bi wa sì ga kan àwọn ọ̀run.
Miingon ako, “Dios ko, naulaw ako ug makauulaw nga iyahat ang akong panagway nganha kanimo, tungod sa among kasaypanan nga milapaw na sa among mga ulo, ug ang among mga sala misangko na ngadto sa kalangitan.
7 Láti ọjọ́ àwọn baba wá ni ẹ̀bi wa ti pọ̀ jọjọ títí di ìsinsin yìí. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa, àwa àti àwọn ọba wa àti àwọn àlùfáà wa ni a ti sọ di ẹni idà, ẹni ìgbèkùn, ìkógun àti ẹni ẹ̀sín lọ́wọ́ àwọn àjèjì ọba, bí ó ti rí lónìí.
Sukad pa sa mga adlaw sa among katigulangan hangtod karon anaa na kami sa dakong pagpakasala. Sa among mga kasaypanan kami, ang among mga hari, ug ang among mga pari gitugyan ngadto sa kamot sa mga hari niining kalibotana, ngadto sa espada, ngadto sa pagkaulipon, ug ngadto sa mga tulisan ug ngadto sa kaulawan, sama kanamo niining panahona.
8 “Ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí, fún ìgbà díẹ̀, ni a ti fi oore-ọ̀fẹ́ fún wa láti ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa wá láti sálà, àti láti fi èèkàn fún wa ni ibi mímọ́ rẹ̀, nítorí kí Ọlọ́run kí ó lè mú ojú wa mọ́lẹ̀, kí ó sì tún wa gbé dìde díẹ̀ kúrò nínú ìgbèkùn wa.
Apan karon sa hamubo nga panahon, miabot ang kaluoy gikan kang Yahweh nga among Dios aron adunay mahibilin pa nga diyutay kanamo ug aron hatagan kami ug tumbanan sa iyang balaang dapit. Alang kini sa among Dios aron malamdagan ang among mga panan-aw ug aron hatagan kami ug diyutay nga tabang sa among pagkaulipon.
9 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwa jẹ́ ẹrú, Ọlọ́run wa kò fi wa sílẹ̀ nínú ìgbèkùn wa. Ó ti fi àánú hàn fún wa ni iwájú àwọn ọba Persia: Ó ti fún wa ní ìgbé ayé tuntun láti tún odi ilé Ọlọ́run wa mọ, kí a sì tún àwókù rẹ̀ ṣe, ó sì fi odi ààbò fún wa ní Juda àti ní Jerusalẹmu.
Sanglit mga ulipon kami, apan ang among Dios wala malimot kanamo kondili iyang gipakita ang matinud-anong saad nganhi kanamo. Gipakita niya kini ngadto sa hari sa Persia aron sa paghatag kanamo ug bag-ong kusog, aron among tukoron pag-usab ang balay sa Dios ug pabarogon ang mga naguba. Gibuhat niya kini aron nga hatagan kami ug luwas nga pader didto sa Juda ug sa Jerusalem.
10 “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, Ọlọ́run wa, kí ni àwa yóò wí lẹ́yìn èyí? Nítorí tí àwa kọ àṣẹ rẹ sílẹ̀
Apan karon, among Dios, unsa man ang among ikasulti human niini? Gikalimtan namo ang imong mga mando,
11 èyí tí ìwọ ti pa fún wa láti ẹnu àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ, nígbà ti ìwọ wí pé, ‘Ilẹ̀ náà ti ẹ̀yin ń wọ̀ lọ láti gbà n nì jẹ́ ilẹ̀ aláìmọ́ tó kún fún ẹ̀gbin àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, nípa ṣíṣe ohun ìríra àti híhu ìwà èérí ti kún ún láti ìkángun kan dé èkejì.
ang mga mando nga imong gihatag sa imong mga alagad nga mga propeta, sa dihang miingon ka nga, “Kining yuta nga inyong adtoan aron panag-iyahon usa ka yuta nga mahugaw. Nahugawan kini pinaagi sa pagkamalaw-ay sa katawhan sa maong dapit. Gilukop nila kini sa ilang kahugawan gikan sa usa ka bahin hangtod sa pikas bahin.
12 Nítorí náà, ẹ má ṣe fi àwọn ọmọbìnrin yín fún àwọn ọmọkùnrin wọn ní ìyàwó tàbí kí ẹ fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin yín ní ìyàwó. Ẹ má ṣe dá májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú wọn nígbàkígbà kí ẹ̀yin kí ó sì le lágbára, kí ẹ sì le máa jẹ ire ilẹ̀ náà, kí ẹ sì le fi í sílẹ̀ fún àwọn ọmọ yín gẹ́gẹ́ bí ogún ayérayé.’
Busa karon, ayaw ihatag ngadto kanila ang inyong mga anak nga babaye ngadto sa ilang mga anak nga lalaki; ayaw kuhaa ang ilang mga anak nga babaye alang sa inyong mga anak nga lalaki, ug ayaw tinguhaa ang padayon nilang kalinaw ug kauswagan, aron mahimo kamong kusgan ug makakaon sa abot sa yuta, aron nga makapanunod niini ang inyong mga anak sa tanang panahon.”
13 “Ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wa jẹ́ àyọríṣí iṣẹ́ búburú wa àti ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ńlá wa, síbẹ̀, Ọlọ́run wa, ìjìyà ti ìwọ fún wa kéré si ìjìyà tí ó yẹ fún ẹ̀ṣẹ̀ ti a dá, ìwọ sì fún wa ní àwọn ènìyàn tó ṣẹ́kù bí èyí.
Apan human sa tanang butang nga nahitabo kanamo tungod sa among daotang binuhatan ug sa dako namong sala—sanglit ikaw, among Dios, nagpugong kung unsa ang angay sa among kasaypanan ug gibilin nga buhi—
14 Ǹjẹ́ ó yẹ kí àwa tún yẹ̀ kúrò nínú àṣẹ rẹ, kí a sì máa ṣe ìgbéyàwó papọ̀ pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí wọn ti ṣe onírúurú ohun ìríra báyìí? Ṣe ìwọ kò ní bínú sí wa láti pa wá run tí kì yóò sẹ́ ku ẹnikẹ́ni tí yóò là?
supakon ba namo pag-usab ang imong mga mando ug makigminyo niining mga tawong daotan? Dili ka ba diay masuko ug molaglag kanamo aron nga wala nay bisan usa nga mahibilin kanamo, walay bisan usa nga makaikyas?
15 Ìwọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ìwọ jẹ́ olódodo! Àwa ìgbèkùn tí ó ṣẹ́kù bí ó ti rí lónìí. Àwa dúró níwájú rẹ nínú ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ wa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé nítorí èyí ẹnikẹ́ni nínú wa kò lè dúró níwájú rẹ”.
Yahweh, Dios sa Israel, matarong ka, kay ang pipila kanamo nahibilin nga buhi hangtod niining adlawa. Tan-awa! Ania kami dinhi sa imong atubangan uban sa among mga sala, kay walay si bisan kinsa ang makabarog sa imong atubangan tungod niini.”

< Ezra 9 >