< Ezra 8 >
1 Wọ̀nyí ni àwọn olórí ìdílé àti àwọn tí ó fi orúkọ sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn tì wọn gòkè pẹ̀lú mi láti Babeli ní àkókò ìjọba Artasasta ọba:
Now estes são os chefes de família de seus pais, e esta é a genealogia daqueles que subiram comigo da Babilônia, no reinado de Artaxerxes, o rei:
2 nínú àwọn ọmọ Finehasi: Gerṣomu; nínú àwọn ọmọ Itamari: Daniẹli; nínú àwọn ọmọ Dafidi: Hattusi,
Dos filhos de Phinehas, Gershom. Dos filhos de Ithamar, Daniel. Dos filhos de David, Hattush.
3 nínú àwọn ọmọ Ṣekaniah; nínú àwọn ọmọ Paroṣi: Sekariah, àti pé àádọ́jọ ọkùnrin fi orúkọ sílẹ̀ pẹ̀lú rẹ;
Dos filhos de Shecaniah, dos filhos de Parosh, Zacarias; e com ele foram listados por genealogia dos homens cento e cinqüenta.
4 nínú àwọn ọmọ Pahati-Moabu: Elihoenai ọmọ Serahiah àti àwọn igba ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
Dos filhos de Pahathmoab, Eliehoenai o filho de Zerahiah; e com ele duzentos homens.
5 nínú àwọn ọmọ Sattu: Ṣekaniah ọmọ Jahasieli àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
Dos filhos de Shecaniah, o filho de Jahaziel; e com ele trezentos homens.
6 nínú àwọn ọmọ Adini: Ebedi ọmọ Jonatani, àti àádọ́ta ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
Dos filhos de Adin, Ebed o filho de Jonathan; e com ele cinqüenta homens.
7 nínú àwọn ọmọ Elamu: Jeṣaiah ọmọ Ataliah àwọn àádọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
Dos filhos de Elão, Jesaías o filho de Atalia; e com ele setenta homens.
8 nínú àwọn ọmọ Ṣefatia: Sebadiah ọmọ Mikaeli, àti ọgọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
Dos filhos de Shephatiah, Zebadiah o filho de Michael; e com ele oitenta homens.
9 nínú àwọn ọmọ Joabu: Obadiah ọmọ Jehieli àti ogún ó lé nígba ó dín méjì ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
Dos filhos de Joab, Obadiah o filho de Jehiel; e com ele duzentos e dezoito homens.
10 nínú àwọn ọmọ Bani: Ṣelomiti ọmọ Josafiah, àti ọgọ́jọ ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
Dos filhos de Shelomith, o filho de Josiphiah; e com ele cento e sessenta homens.
11 nínú àwọn ọmọ Bebai: Sekariah ọmọ Bebai àti ọkùnrin méjìdínlọ́gbọ̀n pẹ̀lú rẹ̀;
Dos filhos de Bebai, Zacarias o filho de Bebai; e com ele vinte e oito homens.
12 nínú àwọn ọmọ Asgadi: Johanani ọmọ Hakatani, àti àádọ́fà ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
Dos filhos de Azgad, Johanan o filho de Hakkatan; e com ele cento e dez homens.
13 nínú àwọn ọmọ Adonikami: àwọn ti ó gbẹ̀yìn, tì orúkọ wọn ń jẹ́ Elifaleti, Jeieli àti Ṣemaiah, àti ọgọ́ta ọkùnrin pẹ̀lú wọn;
Dos filhos de Adonikam, que foram os últimos, seus nomes são: Eliphelet, Jeuel e Semaías; e com eles sessenta homens.
14 nínú àwọn ọmọ Bigfai: Uttai àti Sakkuri, àti àádọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú wọn.
Dos filhos de Bigvai, Uthai e Zabbud; e com eles setenta homens.
15 Èmi kó wọn jọ pọ̀ si etí odò ti ń sàn lọ sí Ahafa, a pàgọ́ síbẹ̀ fún odidi ọjọ́ mẹ́ta, nígbà ti mo wo àárín àwọn ènìyàn àti àárín àwọn àlùfáà, ń kò rí ọmọ Lefi kankan níbẹ̀.
Eu os reuni no rio que corre para o Ahava; e lá ficamos acampados três dias. Depois olhei em volta para o povo e para os sacerdotes, e descobri que não havia nenhum dos filhos de Levi.
16 Nígbà náà ni mo pe Elieseri, Arieli, Ṣemaiah, Elnatani, Jaribi, Elnatani, Natani, Sekariah, àti Meṣullamu, tí wọ́n jẹ́ olórí, àti Joiaribu àti Elnatani tí wọ́n jẹ́ onímọ̀ ìjìnlẹ̀,
Então mandei buscar Eliezer, Ariel, Semaías, Elnatã, Jaribe, Elnatã, Nathan, Zacarias e Meshullam, chefes; também Joiaribe e Elnatã, que eram professores.
17 mo sì rán wọn tí àwọn ti àṣẹ sí ọ̀dọ̀ Iddo, tí ó jẹ́ olórí ní ibi ti a ń pè ni Kasifia, mo sì sọ fún wọn ohun tí wọn yóò wí fun Iddo àti àwọn Lefi arákùnrin rẹ̀, tí wọ́n jẹ́ òṣìṣẹ́ tẹmpili ní Kasifia pé, kí wọn mú àwọn ìránṣẹ́ wá sí ọ̀dọ̀ wa fún ilé Ọlọ́run wa.
Enviei-os à Iddo, o chefe do lugar Casiphia; e lhes disse o que deveriam dizer à Iddo e seus irmãos, os servos do templo no lugar Casiphia, que deveriam trazer-nos ministros para a casa de nosso Deus.
18 Nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run wa wà lára wa, wọ́n sì mú Ṣerebiah wá fún wa, ẹni tí ó kún ojú òsùwọ̀n láti ìran Mahili, ọmọ Lefi, ọmọ Israẹli, àti àwọn ọmọ Ṣerebiah àti àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n jẹ́ ọkùnrin méjìdínlógún.
De acordo com a boa mão do nosso Deus sobre nós, eles nos trouxeram um homem de discrição, dos filhos de Mali, filho de Levi, filho de Israel, ou seja, Serebias, com seus filhos e seus irmãos, dezoito;
19 Àti Haṣabiah, pẹ̀lú Jeṣaiah láti ìran Merari, pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn ọmọ wọ́n jẹ́ ogún ọkùnrin.
e Hasabias, e com ele Jesaías dos filhos de Merari, seus irmãos e seus filhos, vinte;
20 Wọ́n sì tún mú ogún lé nígba àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili wá—àwọn ènìyàn tí Dafidi àti àwọn ìjòyè rẹ̀ gbé kalẹ̀ láti ran àwọn ọmọ Lefi lọ́wọ́. Gbogbo wọn ni a ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ wọn.
e dos servos do templo, que Davi e os príncipes tinham dado para o serviço dos levitas, duzentos e vinte servos do templo. Todos eles foram mencionados pelo nome.
21 Níbẹ̀, ní ẹ̀bá odò Ahafa, mo kéde àwẹ̀, kí a ba à le rẹ ara wa sílẹ̀ níwájú Ọlọ́run, kí a sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ fún ìrìnàjò àìléwu fún wa àti àwọn ọmọ wa àti fún gbogbo ohun ìní wa.
Então proclamei um jejum lá no rio Ahava, para que nos humilhássemos diante de nosso Deus, para buscar dele um caminho reto para nós, para nossos pequenos e para todos os nossos bens.
22 Mo tijú láti béèrè lọ́wọ́ ọba fún àwọn jagunjagun orí ilẹ̀, àti ti orí ẹṣin láti dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá ní ọ̀nà wa, nítorí àti sọ fún ọba pé, “Ọwọ́ àánú Ọlọ́run wà ní ara gbogbo ẹni tí ó gbé ojú sókè sí i, ṣùgbọ́n ìbínú ńlá rẹ wà lórí ẹni tó kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”
Pois tive vergonha de pedir ao rei um bando de soldados e cavaleiros para nos ajudar contra o inimigo no caminho, porque tínhamos falado com o rei, dizendo: “A mão de nosso Deus está sobre todos aqueles que o buscam, para o bem; mas seu poder e sua ira estão contra todos aqueles que o abandonam”.
23 Bẹ́ẹ̀ ni a sì gbààwẹ̀, a sì bẹ̀bẹ̀ fún èyí lọ́dọ̀ Ọlọ́run wa, òun sì gbọ́ àdúrà wa.
Portanto, jejuamos e imploramos a nosso Deus por isso, e ele atendeu nosso pedido.
24 Nígbà náà ni mo ya àwọn àlùfáà tó jẹ́ aṣáájú méjìlá sọ́tọ̀, pẹ̀lú Ṣerebiah, Haṣabiah àti mẹ́wàá lára àwọn arákùnrin wọn,
Então separei doze dos chefes dos sacerdotes, até mesmo Serebias, Hasabias e dez de seus irmãos com eles,
25 mo sì fi òsùwọ̀n wọn ọrẹ fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò tí ọba, àti ti àwọn ìgbìmọ̀, àti ti àwọn ìjòyè, àti ti gbogbo ọmọ Israẹli tí ó wà níbẹ̀, tí wọ́n gbe sílẹ̀ fún ilé Ọlọ́run wa.
e pesei-lhes a prata, o ouro e os vasos, até mesmo a oferta pela casa de nosso Deus, que o rei, seus conselheiros, seus príncipes e todo o Israel ali presente, haviam oferecido.
26 Mo fi òsùwọ̀n wọn ẹgbẹ̀ta lé láàádọ́ta tálẹ́ǹtì fàdákà, àti ohun èlò fàdákà tí ó wọn ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì, ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì wúrà,
pesei na mão deles seiscentos e cinqüenta talentos de prata, cem talentos de vasos de prata, cem talentos de ouro,
27 ogún ago wúrà tí iye rẹ̀ tó ẹgbẹ̀rún dariki, àti ohun èlò idẹ dáradára méjì ti ó ni iye lórí bí i wúrà.
vinte taças de ouro pesando mil dracmas, e dois vasos de bronze fino e brilhante, preciosos como o ouro.
28 Mo wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin àti àwọn ohun èlò wọ̀nyí ni a ti yà sí mímọ́ fún Olúwa. Fàdákà àti wúrà sì jẹ́ ọrẹ àtinúwá sí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín.
Eu lhes disse: “Vocês são santos para Yahweh, e os vasos são santos. A prata e o ouro são uma oferta de livre vontade a Iavé, o Deus de seus pais”.
29 Ẹ máa tọ́jú wọn dáradára títí ẹ̀yin yóò fi fi òsùwọ̀n wọ̀n wọ́n jáde kúrò ni ilé Olúwa ni Jerusalẹmu ní iwájú àwọn aṣáájú, àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, àti ní iwájú olórí ìdílé gbogbo ni Israẹli.”
Vigie-os e guarde-os até pesá-los diante dos chefes dos sacerdotes, dos levitas e dos príncipes das casas dos pais de Israel em Jerusalém, nos quartos da casa de Iavé”.
30 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi gba fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò mímọ́ tí a ti wọ̀n jáde fún kíkó lọ sí ilé Ọlọ́run wa ní Jerusalẹmu.
Assim, os sacerdotes e os levitas receberam o peso da prata, do ouro e dos vasos, para levá-los a Jerusalém para a casa de nosso Deus.
31 Ní ọjọ́ kejìlá oṣù kìn-ín-ní ni a gbéra kúrò ní ẹ̀bá odò Ahafa láti lọ sí Jerusalẹmu. Ọwọ́ Ọlọ́run wa wà lára wa, ó sì dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá àti àwọn adigunjalè ní ọ̀nà wa.
Então partimos do rio Ahava no décimo segundo dia do primeiro mês, para ir a Jerusalém. A mão de nosso Deus estava sobre nós, e ele nos livrou da mão do inimigo e dos bandidos, a propósito.
32 Bẹ́ẹ̀ ni a gúnlẹ̀ sí Jerusalẹmu, níbi tí a ti sinmi fún ọjọ́ mẹ́ta.
Viemos a Jerusalém, e lá ficamos três dias.
33 Ní ọjọ́ kẹrin, a wọn ohun èlò fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò mímọ lé àlùfáà Meremoti ọmọ Uriah lọ́wọ́, láti inú ilé Ọlọ́run wa, Eleasari ọmọ Finehasi wà pẹ̀lú rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi; Josabadi ọmọ Jeṣua àti Noadiah ọmọ Binnui wà níbẹ̀ pẹ̀lú.
No quarto dia a prata, o ouro e os vasos foram pesados na casa de nosso Deus na mão de Meremoth, filho de Uriah, o sacerdote; e com ele Eleazar, filho de Finéias; e com eles Jozabad, filho de Jeshua, e Noadiah, filho de Binnui, os levitas.
34 Gbogbo nǹkan ni a kà, tí a sì wọ̀n, gbogbo iye ìwọ̀n ni a sì ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ sínú ìwé ní ìgbà náà.
Tudo foi contado e pesado; e todo o peso foi escrito naquela época.
35 Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn tí ó ti padà láti ilẹ̀ àjèjì rú ẹbọ sísun sí Ọlọ́run Israẹli: akọ màlúù méjìlá fún gbogbo Israẹli, àgbò mẹ́rìndínlọ́gọ́rùn-ún, ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́tàdínlọ́gọ́rin, àti òbúkọ méjìlá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. Gbogbo èyí jẹ́ ẹbọ sísun sí Olúwa.
As crianças do cativeiro, que haviam saído do exílio, ofereceram holocaustos ao Deus de Israel: doze touros para todo Israel, noventa e seis carneiros, setenta e sete cordeiros e doze bodes para uma oferta pelo pecado. Tudo isso era um holocausto para Iavé.
36 Wọ́n sì jíṣẹ́ àṣẹ ọba fún àwọn ìjòyè àti àwọn baálẹ̀ agbègbè Eufurate, wọ́n sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún àwọn ènìyàn àti ilé Ọlọ́run.
Eles entregaram as comissões do rei para os governadores locais do rei e para os governadores além do rio. Então eles apoiaram o povo e a casa de Deus.