< Ezra 8 >

1 Wọ̀nyí ni àwọn olórí ìdílé àti àwọn tí ó fi orúkọ sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn tì wọn gòkè pẹ̀lú mi láti Babeli ní àkókò ìjọba Artasasta ọba:
A oto naczelnicy rodów i rodowody tych, którzy wyruszyli ze mną z Babilonu za panowania króla Artakserksesa:
2 nínú àwọn ọmọ Finehasi: Gerṣomu; nínú àwọn ọmọ Itamari: Daniẹli; nínú àwọn ọmọ Dafidi: Hattusi,
Z synów Pinchasa – Gerszom; z synów Itamara – Daniel; z synów Dawida – Chattusz;
3 nínú àwọn ọmọ Ṣekaniah; nínú àwọn ọmọ Paroṣi: Sekariah, àti pé àádọ́jọ ọkùnrin fi orúkọ sílẹ̀ pẹ̀lú rẹ;
Z synów Szekaniasza, z synów Parosza – Zachariasz, a z nim spisanych według rodowodów było stu pięćdziesięciu mężczyzn;
4 nínú àwọn ọmọ Pahati-Moabu: Elihoenai ọmọ Serahiah àti àwọn igba ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
Z synów Pachat-Moaba – Elioenaj, syn Zerachiasza, a z nim dwustu mężczyzn;
5 nínú àwọn ọmọ Sattu: Ṣekaniah ọmọ Jahasieli àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
Z synów Szekaniasza – syn Jahaziela, a z nim trzystu mężczyzn;
6 nínú àwọn ọmọ Adini: Ebedi ọmọ Jonatani, àti àádọ́ta ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
Z synów Adina – Ebed, syn Jonatana, a z nim pięćdziesięciu mężczyzn;
7 nínú àwọn ọmọ Elamu: Jeṣaiah ọmọ Ataliah àwọn àádọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
Z synów Elama – Jeszajasz, syn Ataliasza, a z nim siedemdziesięciu mężczyzn;
8 nínú àwọn ọmọ Ṣefatia: Sebadiah ọmọ Mikaeli, àti ọgọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
Z synów Szefatiasza – Zebadiasz, syn Mikaela, a z nim osiemdziesięciu mężczyzn;
9 nínú àwọn ọmọ Joabu: Obadiah ọmọ Jehieli àti ogún ó lé nígba ó dín méjì ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
Z synów Joaba – Obadiasz, syn Jechiela, a z nim dwustu osiemnastu mężczyzn;
10 nínú àwọn ọmọ Bani: Ṣelomiti ọmọ Josafiah, àti ọgọ́jọ ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
Z synów Szelomita – syn Josifiasza, a z nim stu sześćdziesięciu mężczyzn;
11 nínú àwọn ọmọ Bebai: Sekariah ọmọ Bebai àti ọkùnrin méjìdínlọ́gbọ̀n pẹ̀lú rẹ̀;
Z synów Bebaja – Zachariasz, syn Bebaja, a z nim dwudziestu ośmiu mężczyzn;
12 nínú àwọn ọmọ Asgadi: Johanani ọmọ Hakatani, àti àádọ́fà ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
Z synów Azgada – Johanan, syn Hakkatana, a z nim stu dziesięciu mężczyzn;
13 nínú àwọn ọmọ Adonikami: àwọn ti ó gbẹ̀yìn, tì orúkọ wọn ń jẹ́ Elifaleti, Jeieli àti Ṣemaiah, àti ọgọ́ta ọkùnrin pẹ̀lú wọn;
Z synów Adonikama [wyruszyli] ostatni, a oto ich imiona: Elifelet, Jejel i Szemajasz, a z nimi sześćdziesięciu mężczyzn;
14 nínú àwọn ọmọ Bigfai: Uttai àti Sakkuri, àti àádọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú wọn.
Z synów Bigwaja – Utaj i Zabbud, a z nimi siedemdziesięciu mężczyzn.
15 Èmi kó wọn jọ pọ̀ si etí odò ti ń sàn lọ sí Ahafa, a pàgọ́ síbẹ̀ fún odidi ọjọ́ mẹ́ta, nígbà ti mo wo àárín àwọn ènìyàn àti àárín àwọn àlùfáà, ń kò rí ọmọ Lefi kankan níbẹ̀.
I zgromadziłem ich nad rzeką, która płynie do Achawy, i obozowaliśmy tam przez trzy dni. Potem dokonałem przeglądu ludu i kapłanów, a z synów Lewiego nie znalazłem tam [żadnego].
16 Nígbà náà ni mo pe Elieseri, Arieli, Ṣemaiah, Elnatani, Jaribi, Elnatani, Natani, Sekariah, àti Meṣullamu, tí wọ́n jẹ́ olórí, àti Joiaribu àti Elnatani tí wọ́n jẹ́ onímọ̀ ìjìnlẹ̀,
Posłałem więc Eliezera, Ariela, Szemajasza, Elnatana, Jariba, Elnatana, Natana, Zachariasza i Meszullama, naczelników, a także Jojariba i Elnatana, [ludzi] rozumnych;
17 mo sì rán wọn tí àwọn ti àṣẹ sí ọ̀dọ̀ Iddo, tí ó jẹ́ olórí ní ibi ti a ń pè ni Kasifia, mo sì sọ fún wọn ohun tí wọn yóò wí fun Iddo àti àwọn Lefi arákùnrin rẹ̀, tí wọ́n jẹ́ òṣìṣẹ́ tẹmpili ní Kasifia pé, kí wọn mú àwọn ìránṣẹ́ wá sí ọ̀dọ̀ wa fún ilé Ọlọ́run wa.
I dałem przez nich polecenie Iddo, przełożonemu w miejscowości Kasifia, i przekazałem im słowa, które mieli powiedzieć do niego i jego braci Netinitów w miejscowości Kasifia; poleciłem, aby nam przyprowadzili sługi dla domu naszego Boga.
18 Nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run wa wà lára wa, wọ́n sì mú Ṣerebiah wá fún wa, ẹni tí ó kún ojú òsùwọ̀n láti ìran Mahili, ọmọ Lefi, ọmọ Israẹli, àti àwọn ọmọ Ṣerebiah àti àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n jẹ́ ọkùnrin méjìdínlógún.
I ponieważ łaskawa ręka naszego Boga była nad nami, przyprowadzili do nas, człowieka rozumnego spośród synów Machliego, syna Lewiego, syna Izraela, oraz Szerebiasza wraz z jego synami i braćmi – razem osiemnaście [osób];
19 Àti Haṣabiah, pẹ̀lú Jeṣaiah láti ìran Merari, pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn ọmọ wọ́n jẹ́ ogún ọkùnrin.
I Chaszabiasza, a z nim Jeszajasz spośród synów Merariego wraz z jego braćmi i ich synów – razem dwadzieścia [osób];
20 Wọ́n sì tún mú ogún lé nígba àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili wá—àwọn ènìyàn tí Dafidi àti àwọn ìjòyè rẹ̀ gbé kalẹ̀ láti ran àwọn ọmọ Lefi lọ́wọ́. Gbogbo wọn ni a ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ wọn.
Ponadto spośród Netinitów, których Dawid i naczelnicy ustanowili do posługiwania Lewitom – dwieście dwadzieścia Netinitów. Ci wszyscy zostali imiennie wyznaczeni.
21 Níbẹ̀, ní ẹ̀bá odò Ahafa, mo kéde àwẹ̀, kí a ba à le rẹ ara wa sílẹ̀ níwájú Ọlọ́run, kí a sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ fún ìrìnàjò àìléwu fún wa àti àwọn ọmọ wa àti fún gbogbo ohun ìní wa.
Wtedy tam, nad rzeką Achawa, ogłosiłem post, abyśmy ukorzyli się przed naszym Bogiem i abyśmy uprosili u niego szczęśliwą drogę dla nas, naszych dzieci i całego naszego dobytku.
22 Mo tijú láti béèrè lọ́wọ́ ọba fún àwọn jagunjagun orí ilẹ̀, àti ti orí ẹṣin láti dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá ní ọ̀nà wa, nítorí àti sọ fún ọba pé, “Ọwọ́ àánú Ọlọ́run wà ní ara gbogbo ẹni tí ó gbé ojú sókè sí i, ṣùgbọ́n ìbínú ńlá rẹ wà lórí ẹni tó kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”
Wstydziłem się bowiem prosić króla o żołnierzy i jeźdźców, aby nas w drodze ratowali przed wrogami, ponieważ powiedzieliśmy królowi: Ręka naszego Boga [jest] nad wszystkimi, którzy go szukają, dla ich dobra, ale jego moc i gniew przeciwko wszystkim, którzy go opuszczają.
23 Bẹ́ẹ̀ ni a sì gbààwẹ̀, a sì bẹ̀bẹ̀ fún èyí lọ́dọ̀ Ọlọ́run wa, òun sì gbọ́ àdúrà wa.
Pościliśmy więc i prosiliśmy o to naszego Boga. A on nas wysłuchał.
24 Nígbà náà ni mo ya àwọn àlùfáà tó jẹ́ aṣáájú méjìlá sọ́tọ̀, pẹ̀lú Ṣerebiah, Haṣabiah àti mẹ́wàá lára àwọn arákùnrin wọn,
Wtedy spośród przedniejszych kapłanów wydzieliłem dwunastu: Szerebiasza, Chaszabiasza, a z nimi dziesięciu ich braci;
25 mo sì fi òsùwọ̀n wọn ọrẹ fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò tí ọba, àti ti àwọn ìgbìmọ̀, àti ti àwọn ìjòyè, àti ti gbogbo ọmọ Israẹli tí ó wà níbẹ̀, tí wọ́n gbe sílẹ̀ fún ilé Ọlọ́run wa.
I odważyłem im srebro, złoto i naczynia, czyli ofiarę dla domu naszego Boga, którą złożyli: król, jego doradcy, jego dostojnicy oraz cały Izrael tam obecny.
26 Mo fi òsùwọ̀n wọn ẹgbẹ̀ta lé láàádọ́ta tálẹ́ǹtì fàdákà, àti ohun èlò fàdákà tí ó wọn ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì, ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì wúrà,
Odważyłem im więc do rąk sześćset pięćdziesiąt talentów srebra, sto talentów naczyń srebrnych, sto talentów złota;
27 ogún ago wúrà tí iye rẹ̀ tó ẹgbẹ̀rún dariki, àti ohun èlò idẹ dáradára méjì ti ó ni iye lórí bí i wúrà.
Dwadzieścia złotych pucharów, [ważących] po tysiąc darejków, i dwa naczynia z wybornego mosiądzu, tak piękne jak złoto.
28 Mo wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin àti àwọn ohun èlò wọ̀nyí ni a ti yà sí mímọ́ fún Olúwa. Fàdákà àti wúrà sì jẹ́ ọrẹ àtinúwá sí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín.
Potem powiedziałem do nich: Wy jesteście poświęceni PANU, naczynia [także] są poświęcone, a to srebro i złoto [są] dobrowolnym darem dla PANA, Boga waszych ojców.
29 Ẹ máa tọ́jú wọn dáradára títí ẹ̀yin yóò fi fi òsùwọ̀n wọ̀n wọ́n jáde kúrò ni ilé Olúwa ni Jerusalẹmu ní iwájú àwọn aṣáájú, àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, àti ní iwájú olórí ìdílé gbogbo ni Israẹli.”
Pilnujcie i strzeżcie [ich], dopóki nie odważycie [ich] przed przedniejszymi kapłanami, Lewitami i naczelnikami rodów Izraela w Jerozolimie, w komnatach domu PANA.
30 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi gba fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò mímọ́ tí a ti wọ̀n jáde fún kíkó lọ sí ilé Ọlọ́run wa ní Jerusalẹmu.
Wzięli więc kapłani i Lewici odważone srebro, złoto i naczynia, aby [je] zanieść do Jerozolimy, do domu naszego Boga.
31 Ní ọjọ́ kejìlá oṣù kìn-ín-ní ni a gbéra kúrò ní ẹ̀bá odò Ahafa láti lọ sí Jerusalẹmu. Ọwọ́ Ọlọ́run wa wà lára wa, ó sì dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá àti àwọn adigunjalè ní ọ̀nà wa.
Potem wyruszyliśmy znad rzeki Achawa dwunastego [dnia] pierwszego miesiąca, aby udać się do Jerozolimy. A ręka naszego Boga była nad nami i wyrwała nas z ręki wrogów i czyhających [na nas] w drodze.
32 Bẹ́ẹ̀ ni a gúnlẹ̀ sí Jerusalẹmu, níbi tí a ti sinmi fún ọjọ́ mẹ́ta.
I przybyliśmy do Jerozolimy, i zamieszkaliśmy tam przez trzy dni.
33 Ní ọjọ́ kẹrin, a wọn ohun èlò fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò mímọ lé àlùfáà Meremoti ọmọ Uriah lọ́wọ́, láti inú ilé Ọlọ́run wa, Eleasari ọmọ Finehasi wà pẹ̀lú rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi; Josabadi ọmọ Jeṣua àti Noadiah ọmọ Binnui wà níbẹ̀ pẹ̀lú.
A czwartego dnia odważono srebro, złoto i naczynia w domu naszego Boga – do ręki Meremota, syna kapłana Uriasza, z którym był Eleazar, syn Pinchasa; z nimi też [byli] Jozabad, syn Jeszuy, i Noadiasz, syn Binnuja, Lewici;
34 Gbogbo nǹkan ni a kà, tí a sì wọ̀n, gbogbo iye ìwọ̀n ni a sì ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ sínú ìwé ní ìgbà náà.
Wszystko według liczby i wagi; i zapisano wagę tego wszystkiego w tym czasie.
35 Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn tí ó ti padà láti ilẹ̀ àjèjì rú ẹbọ sísun sí Ọlọ́run Israẹli: akọ màlúù méjìlá fún gbogbo Israẹli, àgbò mẹ́rìndínlọ́gọ́rùn-ún, ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́tàdínlọ́gọ́rin, àti òbúkọ méjìlá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. Gbogbo èyí jẹ́ ẹbọ sísun sí Olúwa.
Następnie ci, którzy zostali pojmani, a powrócili z niewoli, złożyli Bogu Izraela ofiarę całopalną: dwanaście cielców za całego Izraela, dziewięćdziesiąt sześć baranów, siedemdziesiąt siedem jagniąt i dwanaście kozłów na ofiarę za grzech, wszystko jako całopalenie PANU.
36 Wọ́n sì jíṣẹ́ àṣẹ ọba fún àwọn ìjòyè àti àwọn baálẹ̀ agbègbè Eufurate, wọ́n sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún àwọn ènìyàn àti ilé Ọlọ́run.
I przekazano rozporządzenie króla jego satrapom i namiestnikom zarzecza, a ci wspomagali lud i dom Boży.

< Ezra 8 >