< Ezra 8 >

1 Wọ̀nyí ni àwọn olórí ìdílé àti àwọn tí ó fi orúkọ sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn tì wọn gòkè pẹ̀lú mi láti Babeli ní àkókò ìjọba Artasasta ọba:
EIA ka poe koikoi o na makua, a me ke kuauhau o lakou, ka poe i pii pu me au, mai Babulona aku, i ke au ia Aretasaseta ke alii.
2 nínú àwọn ọmọ Finehasi: Gerṣomu; nínú àwọn ọmọ Itamari: Daniẹli; nínú àwọn ọmọ Dafidi: Hattusi,
No na mamo a Pinehasa; o Geresoma; no na mamo a Itamara; o Daniela; no na mamo a Davida; o Hatusa;
3 nínú àwọn ọmọ Ṣekaniah; nínú àwọn ọmọ Paroṣi: Sekariah, àti pé àádọ́jọ ọkùnrin fi orúkọ sílẹ̀ pẹ̀lú rẹ;
No na mamo a Sekania, no na mamo a Parosa; o Zekaria: a me ia ua heluia ma ke kuauhau o na kane, hookahi haneri a me kanalima.
4 nínú àwọn ọmọ Pahati-Moabu: Elihoenai ọmọ Serahiah àti àwọn igba ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
No na mamo a Panatamoaba; o Elihoenai ke keiki a Zerahia, a me ia no elua haneri kane.
5 nínú àwọn ọmọ Sattu: Ṣekaniah ọmọ Jahasieli àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
No na mamo a Sekania; o ke keiki a Iahaziela, a me ia no ekolu haneri kane.
6 nínú àwọn ọmọ Adini: Ebedi ọmọ Jonatani, àti àádọ́ta ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
No na mamo a Adina; o Ebeda, ke keiki a Ionatana, a me ia no he kanalima kane.
7 nínú àwọn ọmọ Elamu: Jeṣaiah ọmọ Ataliah àwọn àádọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
No na mamo a Elama; o Iesaia, ke keiki a Atalia, a me ia no he kanahiku kane.
8 nínú àwọn ọmọ Ṣefatia: Sebadiah ọmọ Mikaeli, àti ọgọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
No na mamo a Sepatia; o Zebadia ke keiki a Mikaela, a me ia no he kanawalu kane.
9 nínú àwọn ọmọ Joabu: Obadiah ọmọ Jehieli àti ogún ó lé nígba ó dín méjì ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
No na mamo a Ioaba; o Obadia ke keiki a Iehiela, a me ia no elua haneri a me ka umikumamawalu kane.
10 nínú àwọn ọmọ Bani: Ṣelomiti ọmọ Josafiah, àti ọgọ́jọ ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
O na mamo a Selomita; o ke keiki a Iosipia, a me ia no hookahi haneri a me kanaono kane.
11 nínú àwọn ọmọ Bebai: Sekariah ọmọ Bebai àti ọkùnrin méjìdínlọ́gbọ̀n pẹ̀lú rẹ̀;
No na mamo a Bebai; o Zekaria ke keiki a Bebai, a'me ia no he iwakalua a me kumamawalu kane.
12 nínú àwọn ọmọ Asgadi: Johanani ọmọ Hakatani, àti àádọ́fà ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
No na mamo a Azegada; o Iohanana ke keiki a Hakatana, a me ia no hookahi haneri a me ka umi na kane.
13 nínú àwọn ọmọ Adonikami: àwọn ti ó gbẹ̀yìn, tì orúkọ wọn ń jẹ́ Elifaleti, Jeieli àti Ṣemaiah, àti ọgọ́ta ọkùnrin pẹ̀lú wọn;
No na mamo hope a Adonikama, a eia ka inoa o lakou, o Elipeleta, o Ieiela, a me Semaia, a me lakou no he kanaono kane.
14 nínú àwọn ọmọ Bigfai: Uttai àti Sakkuri, àti àádọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú wọn.
A no na mamo hoi a Bigevai; o Utai, a o Zabuda, a me laua no he kanahiku na kane.
15 Èmi kó wọn jọ pọ̀ si etí odò ti ń sàn lọ sí Ahafa, a pàgọ́ síbẹ̀ fún odidi ọjọ́ mẹ́ta, nígbà ti mo wo àárín àwọn ènìyàn àti àárín àwọn àlùfáà, ń kò rí ọmọ Lefi kankan níbẹ̀.
A hoakoakoa ae la au ia lakou ma ka muliwai e kahe ana i Ahava, a malaila makou i hoomoana'i i na ia ekolu: a nana aku la au i na kanaka, a me na kahuna, aole i lona malaila kekahi o na mamo a Levi.
16 Nígbà náà ni mo pe Elieseri, Arieli, Ṣemaiah, Elnatani, Jaribi, Elnatani, Natani, Sekariah, àti Meṣullamu, tí wọ́n jẹ́ olórí, àti Joiaribu àti Elnatani tí wọ́n jẹ́ onímọ̀ ìjìnlẹ̀,
Alaila kii aku la au ia Eliezera, a ia Ariela, a ia Simaia, a ia Elenatana, a ia Iariba, a ia Elenatana, a ia Nataua, a ia Zekaria, a me Mesulama, he mau mea koikoi; a ia Ioiariba, a ia Elenatana, he mau mea naauao.
17 mo sì rán wọn tí àwọn ti àṣẹ sí ọ̀dọ̀ Iddo, tí ó jẹ́ olórí ní ibi ti a ń pè ni Kasifia, mo sì sọ fún wọn ohun tí wọn yóò wí fun Iddo àti àwọn Lefi arákùnrin rẹ̀, tí wọ́n jẹ́ òṣìṣẹ́ tẹmpili ní Kasifia pé, kí wọn mú àwọn ìránṣẹ́ wá sí ọ̀dọ̀ wa fún ilé Ọlọ́run wa.
A hoouna aku au ia lakou e kauoha ia Ido, i ka luna ma ke kauwahi i Kasipia, a hai aku au ia lakou i na mea a lakou e olelo aku ai ia Ido, a me kona mau houhanau, ka poe Netini ma ke kauwahi i Kaeipia, e lawe mai lakou na makou i mea lawelawe no ka hale o ko kakou Akua.
18 Nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run wa wà lára wa, wọ́n sì mú Ṣerebiah wá fún wa, ẹni tí ó kún ojú òsùwọ̀n láti ìran Mahili, ọmọ Lefi, ọmọ Israẹli, àti àwọn ọmọ Ṣerebiah àti àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n jẹ́ ọkùnrin méjìdínlógún.
A ma ka lima o ke Akua maluna o makou e pono ai, lawe mai lakou no makou i kekahi kanaka naauao no na keiki a Maheli, ka mamo a Levi, ke keiki a Iseraela; a ia Serebia, me kana mau keiki, a me kona mau hoahanau he umikumamawalu;
19 Àti Haṣabiah, pẹ̀lú Jeṣaiah láti ìran Merari, pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn ọmọ wọ́n jẹ́ ogún ọkùnrin.
A me Hasabia, a me ia no o Iesaia, no na mamo a Merari, kona mau hoahanau, a me ka lakou mau keiki, he iwakalua;
20 Wọ́n sì tún mú ogún lé nígba àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili wá—àwọn ènìyàn tí Dafidi àti àwọn ìjòyè rẹ̀ gbé kalẹ̀ láti ran àwọn ọmọ Lefi lọ́wọ́. Gbogbo wọn ni a ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ wọn.
A no ka poe Netini, na mea a Davida, a me na luna i hoonoho ai no ka oihana Levi, elua haneri a me ka iwakalua Netini: ua kaheaia lakou a pau ma ka inoa.
21 Níbẹ̀, ní ẹ̀bá odò Ahafa, mo kéde àwẹ̀, kí a ba à le rẹ ara wa sílẹ̀ níwájú Ọlọ́run, kí a sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ fún ìrìnàjò àìléwu fún wa àti àwọn ọmọ wa àti fún gbogbo ohun ìní wa.
Alaila kukala aku au i hookeai malaila ma ka muliwai o Ahava, i hoohaahaa iho ai makou ia makou iho imua o ko kakou Akua, e imi aku ia ia i aoao pono no makou, a no ka makou kamalii, a no ka makou waiwai a pau.
22 Mo tijú láti béèrè lọ́wọ́ ọba fún àwọn jagunjagun orí ilẹ̀, àti ti orí ẹṣin láti dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá ní ọ̀nà wa, nítorí àti sọ fún ọba pé, “Ọwọ́ àánú Ọlọ́run wà ní ara gbogbo ẹni tí ó gbé ojú sókè sí i, ṣùgbọ́n ìbínú ńlá rẹ wà lórí ẹni tó kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”
No ka mea ua hilahila no wau e noi aku i ke alii i poe koa, a me na holohololio, e kokua ia makou no na enemi ma ke ala: no ka mea, ua olelo makou i ke alii, i ka i ana'ku, O ka lima o ko kakou Akua maluna o lakou a pau e pono ai, o ka poe e imi ana ia ia; aka, ua ku e mai kona mana a me kona huhu i ka poe a pau e haalele ia ia.
23 Bẹ́ẹ̀ ni a sì gbààwẹ̀, a sì bẹ̀bẹ̀ fún èyí lọ́dọ̀ Ọlọ́run wa, òun sì gbọ́ àdúrà wa.
A hookeai iho la makou, n nonoi aku i ko kakou Akua no keia mea; a hoolohe mai no ia ia makou.
24 Nígbà náà ni mo ya àwọn àlùfáà tó jẹ́ aṣáájú méjìlá sọ́tọ̀, pẹ̀lú Ṣerebiah, Haṣabiah àti mẹ́wàá lára àwọn arákùnrin wọn,
Alaila hookaawale au i na luna kahuna he umikumamalua. o Serebia, o Hasabia, a ho umi o ko laua mau hoahanau me laua;
25 mo sì fi òsùwọ̀n wọn ọrẹ fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò tí ọba, àti ti àwọn ìgbìmọ̀, àti ti àwọn ìjòyè, àti ti gbogbo ọmọ Israẹli tí ó wà níbẹ̀, tí wọ́n gbe sílẹ̀ fún ilé Ọlọ́run wa.
A kaupaona iho la au no lakou i ke kala, a i ke gula, a me na kiaha, ka manawalea no ka hale o ko kakou Akua, a ke alii, a me kona poe kakaolelo, a me kona poe luna, a me ka Iseraela a pau e noho ana, i haawi mai ai:
26 Mo fi òsùwọ̀n wọn ẹgbẹ̀ta lé láàádọ́ta tálẹ́ǹtì fàdákà, àti ohun èlò fàdákà tí ó wọn ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì, ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì wúrà,
Kaupaona aku la nu no ko lakou lima i eono haneri a mo kanalima talena kala, a me na kiaha kala hookahi haneri talena, a me ke gula hookahi haneri talena;
27 ogún ago wúrà tí iye rẹ̀ tó ẹgbẹ̀rún dariki, àti ohun èlò idẹ dáradára méjì ti ó ni iye lórí bí i wúrà.
A he iwakalua bola gula, hookahi tausani derama; a elua kiaha keleawe melemele maikai, he nui ke kumukuai, e like me ke gula.
28 Mo wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin àti àwọn ohun èlò wọ̀nyí ni a ti yà sí mímọ́ fún Olúwa. Fàdákà àti wúrà sì jẹ́ ọrẹ àtinúwá sí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín.
A i aku la au ia lakou, Ua hoolaaia oukou no Iehova: ua hoolaaia no hoi na kiaha; a o ke kala a me ke gula, he makana wale no Iehova ke Akua o ko oukou poe kupuna.
29 Ẹ máa tọ́jú wọn dáradára títí ẹ̀yin yóò fi fi òsùwọ̀n wọ̀n wọ́n jáde kúrò ni ilé Olúwa ni Jerusalẹmu ní iwájú àwọn aṣáájú, àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, àti ní iwájú olórí ìdílé gbogbo ni Israẹli.”
E makaala oukou, a e malama hoi, a kaupaona oukou ia mea imua o na luna kahuna a me na Levi, a me na mea koikoi o na makua o ka Iseraela ma Ierusalema, iloko o na keena ma ka hale o Iehova.
30 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi gba fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò mímọ́ tí a ti wọ̀n jáde fún kíkó lọ sí ilé Ọlọ́run wa ní Jerusalẹmu.
A lawe ae la na kahuna a me na Levi i ke kala, a me ke gula, a me na kiaha i kaupaonaia, e hali aku i Ierusalema ma ka hale o ko kakou Akua.
31 Ní ọjọ́ kejìlá oṣù kìn-ín-ní ni a gbéra kúrò ní ẹ̀bá odò Ahafa láti lọ sí Jerusalẹmu. Ọwọ́ Ọlọ́run wa wà lára wa, ó sì dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá àti àwọn adigunjalè ní ọ̀nà wa.
A haalele makou i ka muliwai o Ahava, i ka la umikumamalua o ka malama mua, e hele i Ierusalema; a maluna o makou ka lima o ko makou Akua, a hoopakele no oia ia makou i ka lima o ka enemi, a me ka poe hoohalua ma ke ala.
32 Bẹ́ẹ̀ ni a gúnlẹ̀ sí Jerusalẹmu, níbi tí a ti sinmi fún ọjọ́ mẹ́ta.
A hele mai makou i Ierusalema, a noho malaila i na la ekolu.
33 Ní ọjọ́ kẹrin, a wọn ohun èlò fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò mímọ lé àlùfáà Meremoti ọmọ Uriah lọ́wọ́, láti inú ilé Ọlọ́run wa, Eleasari ọmọ Finehasi wà pẹ̀lú rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi; Josabadi ọmọ Jeṣua àti Noadiah ọmọ Binnui wà níbẹ̀ pẹ̀lú.
A i ka ha o ka la, kaupaonaia ke kala, a me ke gula, a me na kiaha, iloko o ka hale o ko kakou Akua, ma ka lima o Meremota, ke keiki a Uria ke kahana; a me ia no o Eleazara, ke keiki a Pioehasa; a me lakou no o Iozabada, ke keiki a Iesua, a o Noadia, ke keiki a Binui, no na Levi;
34 Gbogbo nǹkan ni a kà, tí a sì wọ̀n, gbogbo iye ìwọ̀n ni a sì ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ sínú ìwé ní ìgbà náà.
Ma ka helu ana, a me ke kaupaona ana, o na mea a pau: a o na paona a pau, ua kakauia i kela manawa.
35 Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn tí ó ti padà láti ilẹ̀ àjèjì rú ẹbọ sísun sí Ọlọ́run Israẹli: akọ màlúù méjìlá fún gbogbo Israẹli, àgbò mẹ́rìndínlọ́gọ́rùn-ún, ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́tàdínlọ́gọ́rin, àti òbúkọ méjìlá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. Gbogbo èyí jẹ́ ẹbọ sísun sí Olúwa.
A o na keiki a ka poe pio i hoi hou mai, kaumaha aku lakou i na mohaikuni i ke Akua o ka Iseraela, he umikumamalua na bipikane no ka Iseraela a pau, a he kanaiwakumamaono na hipakane, a he kauahikukumamahiku na keikihipa, he umikumamalua na kaokane, i mohai hala: oia mea a pau i mohaikuni ia Iehova.
36 Wọ́n sì jíṣẹ́ àṣẹ ọba fún àwọn ìjòyè àti àwọn baálẹ̀ agbègbè Eufurate, wọ́n sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún àwọn ènìyàn àti ilé Ọlọ́run.
A haawi aku lakou i na kauoha a ke alii, i na kiaaina, a me na'lii aimoku o ke alii ma keia aoao o ka muliwai; a kokua lakou i na kauaka, a me ka hale o ke Akua.

< Ezra 8 >