< Ezra 8 >
1 Wọ̀nyí ni àwọn olórí ìdílé àti àwọn tí ó fi orúkọ sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn tì wọn gòkè pẹ̀lú mi láti Babeli ní àkókò ìjọba Artasasta ọba:
Voici, d’après leur filiation, les chefs des familles qui, sous le règne du roi Artahchasta, partirent avec moi de Babylone:
2 nínú àwọn ọmọ Finehasi: Gerṣomu; nínú àwọn ọmọ Itamari: Daniẹli; nínú àwọn ọmọ Dafidi: Hattusi,
parmi les enfants de Phinéas, Gersom; parmi les enfants d’lthamar, Daniel; parmi les enfants de David, Hattouch,
3 nínú àwọn ọmọ Ṣekaniah; nínú àwọn ọmọ Paroṣi: Sekariah, àti pé àádọ́jọ ọkùnrin fi orúkọ sílẹ̀ pẹ̀lú rẹ;
un des descendants de Chekhania; parmi les enfants de Paroch, Zacharie, et à lui se rattachaient, par leur filiation, cent cinquante mâles;
4 nínú àwọn ọmọ Pahati-Moabu: Elihoenai ọmọ Serahiah àti àwọn igba ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
parmi les enfants de Pahat-Moab, Elyehoènaï, fils de Zerahia, et avec lui deux cents mâles;
5 nínú àwọn ọmọ Sattu: Ṣekaniah ọmọ Jahasieli àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
parmi les enfants de Chekhania, était le fils de Yahaziël, et avec lui trois cents mâles;
6 nínú àwọn ọmọ Adini: Ebedi ọmọ Jonatani, àti àádọ́ta ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
parmi les enfants d’Adïn, Ebed, fils de Jonathan, et avec lui cinquante mâles;
7 nínú àwọn ọmọ Elamu: Jeṣaiah ọmọ Ataliah àwọn àádọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
parmi les enfants d’Elam, Isaïe, fils d’Atalia, et avec lui soixante-dix mâles;
8 nínú àwọn ọmọ Ṣefatia: Sebadiah ọmọ Mikaeli, àti ọgọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
parmi les enfants de Chefatia; Zebadia, fils de Mikhaël, et avec lui quatre-vingts mâles;
9 nínú àwọn ọmọ Joabu: Obadiah ọmọ Jehieli àti ogún ó lé nígba ó dín méjì ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
parmi les enfants de Joab, Obadia, fils de Yehiël, et avec lui deux cent dix-huit mâles;
10 nínú àwọn ọmọ Bani: Ṣelomiti ọmọ Josafiah, àti ọgọ́jọ ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
parmi les enfants de Chelomit était le fils de Yosifia, et avec lui cent soixante mâles;
11 nínú àwọn ọmọ Bebai: Sekariah ọmọ Bebai àti ọkùnrin méjìdínlọ́gbọ̀n pẹ̀lú rẹ̀;
parmi les enfants de Bêbai, Zacharie, fils de Bêbaï, et avec lui vingt-huit mâles;
12 nínú àwọn ọmọ Asgadi: Johanani ọmọ Hakatani, àti àádọ́fà ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
parmi les enfants d’Azgad, Johanan, fils de Hakatân, et avec lui cent dix mâles;
13 nínú àwọn ọmọ Adonikami: àwọn ti ó gbẹ̀yìn, tì orúkọ wọn ń jẹ́ Elifaleti, Jeieli àti Ṣemaiah, àti ọgọ́ta ọkùnrin pẹ̀lú wọn;
parmi les enfants d’Adonikâm, les derniers venus, dont voici les noms: Elifélet, Yeiêl et Chemaïa, et avec eux soixante mâles;
14 nínú àwọn ọmọ Bigfai: Uttai àti Sakkuri, àti àádọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú wọn.
et parmi les enfants de Bigvaï, Outaï et Zabboud, et avec eux soixante-dix mâles.
15 Èmi kó wọn jọ pọ̀ si etí odò ti ń sàn lọ sí Ahafa, a pàgọ́ síbẹ̀ fún odidi ọjọ́ mẹ́ta, nígbà ti mo wo àárín àwọn ènìyàn àti àárín àwọn àlùfáà, ń kò rí ọmọ Lefi kankan níbẹ̀.
Je les rassemblai près du fleuve qui se dirige vers Ahava, où nous campâmes trois jours. Je passai en revue le peuple et les prêtres et n’y trouvai point de Lévites.
16 Nígbà náà ni mo pe Elieseri, Arieli, Ṣemaiah, Elnatani, Jaribi, Elnatani, Natani, Sekariah, àti Meṣullamu, tí wọ́n jẹ́ olórí, àti Joiaribu àti Elnatani tí wọ́n jẹ́ onímọ̀ ìjìnlẹ̀,
Je dépêchai donc Eliézer, Ariël, Chemaïa, Elnatân, Yarib, Elnatân, Natân, Zacharie, Mechoullâm, tous chefs, et Yoyarib et Elnatân, instructeurs,
17 mo sì rán wọn tí àwọn ti àṣẹ sí ọ̀dọ̀ Iddo, tí ó jẹ́ olórí ní ibi ti a ń pè ni Kasifia, mo sì sọ fún wọn ohun tí wọn yóò wí fun Iddo àti àwọn Lefi arákùnrin rẹ̀, tí wọ́n jẹ́ òṣìṣẹ́ tẹmpili ní Kasifia pé, kí wọn mú àwọn ìránṣẹ́ wá sí ọ̀dọ̀ wa fún ilé Ọlọ́run wa.
et je leur fis des recommandations pour Iddo, chef dans la localité de Kassifia; je leur dictai les paroles qu’ils devaient dire à Iddo, à l’adresse de ses frères, les serviteurs du temple fixés à Kassifia, afin qu’on nous amenât des fonctionnaires pour le temple de notre Dieu.
18 Nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run wa wà lára wa, wọ́n sì mú Ṣerebiah wá fún wa, ẹni tí ó kún ojú òsùwọ̀n láti ìran Mahili, ọmọ Lefi, ọmọ Israẹli, àti àwọn ọmọ Ṣerebiah àti àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n jẹ́ ọkùnrin méjìdínlógún.
Ils nous amenèrent, grâce à la protection de Dieu étendue sur nous, un homme intelligent, choisi parmi les descendants de Mahli, fils de Lévi, fils d’Israël, ainsi que Chèrèbia, ses fils et ses frères, au nombre de dix-huit personnes;
19 Àti Haṣabiah, pẹ̀lú Jeṣaiah láti ìran Merari, pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn ọmọ wọ́n jẹ́ ogún ọkùnrin.
de plus, Hachabia, et avec lui Isaïe, un des descendants de Merari, avec ses frères et leurs fils, au nombre de vingt personnes.
20 Wọ́n sì tún mú ogún lé nígba àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili wá—àwọn ènìyàn tí Dafidi àti àwọn ìjòyè rẹ̀ gbé kalẹ̀ láti ran àwọn ọmọ Lefi lọ́wọ́. Gbogbo wọn ni a ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ wọn.
Enfin, d’entre les serviteurs du temple que David et les princes avaient affectés au service des Lévites, deux cent vingt individus, tous nominativement désignés.
21 Níbẹ̀, ní ẹ̀bá odò Ahafa, mo kéde àwẹ̀, kí a ba à le rẹ ara wa sílẹ̀ níwájú Ọlọ́run, kí a sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ fún ìrìnàjò àìléwu fún wa àti àwọn ọmọ wa àti fún gbogbo ohun ìní wa.
Je proclamai là, près du fleuve d’Ahava, un jeûne à l’effet de nous mortifier devant notre Dieu et de lui demander un voyage heureux pour nous, pour nos familles et tous nos biens;
22 Mo tijú láti béèrè lọ́wọ́ ọba fún àwọn jagunjagun orí ilẹ̀, àti ti orí ẹṣin láti dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá ní ọ̀nà wa, nítorí àti sọ fún ọba pé, “Ọwọ́ àánú Ọlọ́run wà ní ara gbogbo ẹni tí ó gbé ojú sókè sí i, ṣùgbọ́n ìbínú ńlá rẹ wà lórí ẹni tó kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”
car j’avais honte de solliciter du roi des troupes et des cavaliers pour nous secourir contre les ennemis pendant le trajet; nous avions dit, en effet, au roi: "La main de notre Dieu protège, pour leur bonheur, tous ceux qui le recherchent, tandis que sa force et sa colère pèsent sur ceux qui le délaissent."
23 Bẹ́ẹ̀ ni a sì gbààwẹ̀, a sì bẹ̀bẹ̀ fún èyí lọ́dọ̀ Ọlọ́run wa, òun sì gbọ́ àdúrà wa.
Nous jeunâmes donc et implorâmes de notre Dieu cette faveur, et il accueillit notre prière.
24 Nígbà náà ni mo ya àwọn àlùfáà tó jẹ́ aṣáájú méjìlá sọ́tọ̀, pẹ̀lú Ṣerebiah, Haṣabiah àti mẹ́wàá lára àwọn arákùnrin wọn,
Puis, je choisis parmi les chefs des prêtres une douzaine, dont Chèrèbia, Hachabia, avec dix de leurs frères;
25 mo sì fi òsùwọ̀n wọn ọrẹ fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò tí ọba, àti ti àwọn ìgbìmọ̀, àti ti àwọn ìjòyè, àti ti gbogbo ọmọ Israẹli tí ó wà níbẹ̀, tí wọ́n gbe sílẹ̀ fún ilé Ọlọ́run wa.
et je leur versai l’argent, l’or et les ustensiles, offrandes pour le temple de notre Dieu, qu’avaient prélevées le roi, ses conseillers, ses seigneurs, et tous les Israélites existants.
26 Mo fi òsùwọ̀n wọn ẹgbẹ̀ta lé láàádọ́ta tálẹ́ǹtì fàdákà, àti ohun èlò fàdákà tí ó wọn ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì, ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì wúrà,
Je leur versai aussi six cent cinquante talents d’argent, en fait d’ustensiles en argent cent talents, cent talents d’or,
27 ogún ago wúrà tí iye rẹ̀ tó ẹgbẹ̀rún dariki, àti ohun èlò idẹ dáradára méjì ti ó ni iye lórí bí i wúrà.
vingt écuelles en or valant mille dariques et deux magnifiques vases de cuivre jaune, précieux comme l’or.
28 Mo wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin àti àwọn ohun èlò wọ̀nyí ni a ti yà sí mímọ́ fún Olúwa. Fàdákà àti wúrà sì jẹ́ ọrẹ àtinúwá sí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín.
Je leur dis: "Vous êtes vous-mêmes consacrés à l’Eternel, et ces ustensiles sont consacrés; l’argent et l’or sont des dons volontaires offerts à l’Eternel, Dieu de vos pères.
29 Ẹ máa tọ́jú wọn dáradára títí ẹ̀yin yóò fi fi òsùwọ̀n wọ̀n wọ́n jáde kúrò ni ilé Olúwa ni Jerusalẹmu ní iwájú àwọn aṣáájú, àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, àti ní iwájú olórí ìdílé gbogbo ni Israẹli.”
Conservez-les avec soin jusqu’au moment où vous les verserez, en présence des chefs des prêtres, des Lévites et des chefs de famille d’Israël, à Jérusalem, dans les salles du temple de l’Eternel.
30 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi gba fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò mímọ́ tí a ti wọ̀n jáde fún kíkó lọ sí ilé Ọlọ́run wa ní Jerusalẹmu.
Les prêtres et les Lévites prirent en charge cette quantité d’argent, d’or et d’ustensiles, pour les transporter à Jérusalem, dans le temple de notre Dieu.
31 Ní ọjọ́ kejìlá oṣù kìn-ín-ní ni a gbéra kúrò ní ẹ̀bá odò Ahafa láti lọ sí Jerusalẹmu. Ọwọ́ Ọlọ́run wa wà lára wa, ó sì dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá àti àwọn adigunjalè ní ọ̀nà wa.
Nous partîmes du fleuve d’Ahava le douzième jour du premier mois pour nous diriger vers Jérusalem; la protection de notre Dieu nous couvrit et nous préserva de la main des ennemis et des dresseurs d’embûches, au cours de notre voyage.
32 Bẹ́ẹ̀ ni a gúnlẹ̀ sí Jerusalẹmu, níbi tí a ti sinmi fún ọjọ́ mẹ́ta.
Nous arrivâmes à Jérusalem et y prîmes trois jours de repos.
33 Ní ọjọ́ kẹrin, a wọn ohun èlò fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò mímọ lé àlùfáà Meremoti ọmọ Uriah lọ́wọ́, láti inú ilé Ọlọ́run wa, Eleasari ọmọ Finehasi wà pẹ̀lú rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi; Josabadi ọmọ Jeṣua àti Noadiah ọmọ Binnui wà níbẹ̀ pẹ̀lú.
Le quatrième jour, l’argent, l’or et les ustensiles furent versés dans le temple de notre Dieu, entre les mains de Merêmot, fils du prêtre Urie, assisté d’Eléazar, fils de Phinéas; avec eux se trouvaient Yozabad, fils de Yêchoua, et Noadia, fils de Binnoui, les Lévites.
34 Gbogbo nǹkan ni a kà, tí a sì wọ̀n, gbogbo iye ìwọ̀n ni a sì ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ sínú ìwé ní ìgbà náà.
Le tout fut compté et pesé, et à ce moment on en dressa un état exact.
35 Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn tí ó ti padà láti ilẹ̀ àjèjì rú ẹbọ sísun sí Ọlọ́run Israẹli: akọ màlúù méjìlá fún gbogbo Israẹli, àgbò mẹ́rìndínlọ́gọ́rùn-ún, ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́tàdínlọ́gọ́rin, àti òbúkọ méjìlá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. Gbogbo èyí jẹ́ ẹbọ sísun sí Olúwa.
Ceux qui étaient revenus de la captivité, les anciens exilés, offrirent comme holocaustes au Dieu d’Israël douze taureaux à l’intention de tout Israël, quatre-vingt-seize béliers, soixante-dix-sept brebis, et douze boucs comme sacrifice expiatoire: le tout présenté en holocauste à l’Eternel.
36 Wọ́n sì jíṣẹ́ àṣẹ ọba fún àwọn ìjòyè àti àwọn baálẹ̀ agbègbè Eufurate, wọ́n sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún àwọn ènìyàn àti ilé Ọlọ́run.
Ils remirent aussi les instructions royales aux satrapes du roi et aux préfets de ce côté du fleuve; et ceux-ci prêtèrent leur concours au peuple et au temple de Dieu.