< Ezra 7 >

1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ní àkókò ìjọba ọba Artasasta ní Persia, Esra ọmọ Seraiah, ọmọ Asariah, ọmọ Hilkiah,
Torej po teh stvareh, v kraljevanju perzijskega kralja Artakserksa, je Ezra, sin Serajája, sinú Azarjája, sinú Hilkijája,
2 ọmọ Ṣallumu, ọmọ Sadoku, ọmọ Ahitubu,
sinú Šalúma, sinú Cadóka, sinú Ahitúba,
3 ọmọ Amariah, ọmọ Asariah, ọmọ Meraioti,
sinú Amarjája, sinú Azarjája, sinú Merajóta,
4 ọmọ Serahiah, ọmọ Ussi, ọmọ Bukki,
sinú Zerahjája, sinú Uzíja, sinú Bukíja,
5 ọmọ Abiṣua, ọmọ Finehasi, ọmọ Eleasari, ọmọ Aaroni olórí àlùfáà—
sinú Abišúa, sinú Pinhása, sinú Eleazarja, sinú Arona, vélikega duhovnika;
6 Esra yìí sì gòkè wá láti Babeli. Olùkọ́ tí ó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nípa òfin Mose, èyí tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ti fi fún wọn. Ọba sì fi gbogbo ohun tí ó béèrè fún un, nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára rẹ̀.
ta Ezra odšel gor iz Babilona. Ta je bil vešč pisar v Mojzesovi postavi, ki jo je dal Gospod, Izraelov Bog. In kralj mu je zagotovil vse njegove zahteve, glede na roko Gospoda, njegovega Boga, nad njim.
7 Ní ọdún keje ọba Artasasta díẹ̀ lára àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà àti àwọn tí ń ṣiṣẹ́ nínú tẹmpili náà gòkè wá sí Jerusalẹmu.
In tam so šli gor nekateri izmed Izraelovih otrok in izmed duhovnikov, Lévijevcev, pevcev, vratarjev in Netinimcev v Jeruzalem, v sedmem letu kralja Artakserksa.
8 Ní oṣù karùn-ún ọdún keje ọba yìí ni Esra dé sí Jerusalẹmu.
V petem mesecu je ta prišel v Jeruzalem, kar je bilo v sedmem letu kralja.
9 Ó bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ̀ láti Babeli ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, ó sì dé Jerusalẹmu ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run rẹ̀ wà ní ara rẹ̀.
Kajti na prvi dan prvega meseca je začel iti gor iz Babilona, in na prvi dan petega meseca je prišel v Jeruzalem, glede na dobro roko njegovega Boga nad njim.
10 Esra ti fi ara rẹ̀ jì fún kíkọ́ àti pípa òfin Olúwa mọ́, ó sì ń kọ́ òfin àti ìlànà Mose ní Israẹli.
Kajti Ezra je pripravil svoje srce, da išče Gospodovo postavo in da jo izpolnjuje in da v Izraelu uči zakone in sodbe.
11 Èyí ni ẹ̀dà lẹ́tà ti ọba Artasasta fún àlùfáà Esra olùkọ́ni, ẹni tó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nínú àkọsílẹ̀ òfin àti ìlànà Olúwa fún Israẹli.
Torej to je kopija pisma, ki ga je kralj Artakserks izročil Ezru, duhovniku, pisarju, celó pisarju besed Gospodovih zapovedi in njegovih zakonov Izraelu.
12 Artasasta, ọba àwọn ọba. Sí àlùfáà Esra, olùkọ́ òfin Ọlọ́run ọ̀run. Àlàáfíà.
›Artakserks, kralj kraljev, duhovniku Ezru, pisarju postave Boga iz nebes, popoln mir itd.
13 Mo pàṣẹ pé ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi, ti ó wà ní abẹ́ ìṣàkóso ìjọba mi, tí ó bá fẹ́ láti bá ọ lọ sí Jerusalẹmu lè tẹ̀lé ọ lọ.
Izdajam odlok, da vsi izmed Izraelovega ljudstva in izmed njegovih duhovnikov in Lévijevcev v mojem območju, ki so voljni po svoji lastni svobodni volji, da gredo gor v Jeruzalem, gredo s teboj.
14 Ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ̀ méjèèje rán ọ lọ láti wádìí nípa òfin Ọlọ́run rẹ tí ó wà ní ọwọ́ rẹ nípa Juda àti Jerusalẹmu.
Ker si poslan od kralja in od njegovih sedmih svetovalcev, da poizveš glede Juda in Jeruzalema, glede na postavo svojega Boga, ki je v tvoji roki
15 Síwájú sí i, kí ìwọ kí ó kó fàdákà àti wúrà lọ pẹ̀lú rẹ èyí tí ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ fi tọkàntọkàn fún Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ibùjókòó rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu,
in da odneseš srebro in zlato, ki so ga kralj in njegovi svetovalci velikodušno darovali Izraelovemu Bogu, katerega prebivališče je v Jeruzalemu
16 pẹ̀lú gbogbo fàdákà àti wúrà tí ìwọ lè rí ní agbègbè ìjọba Babeli àti àwọn ọrẹ àtinúwá àwọn ènìyàn àti ti àwọn àlùfáà fún tẹmpili Ọlọ́run wọn ní Jerusalẹmu.
in vse srebro in zlato, ki ga lahko najdeš po vsej babilonski provinci s prostovoljnimi daritvami ljudstva in duhovnikov, prostovoljno darovanega za hišo njihovega Boga, ki je v Jeruzalemu,
17 Pẹ̀lú owó yìí, rí i dájú pé ó ra àwọn akọ màlúù, àwọn àgbò àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn, pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ, àti ọrẹ ohun mímu, kí ìwọ kí ó fi wọ́n rú ẹbọ lórí pẹpẹ tẹmpili Ọlọ́run rẹ ní Jerusalẹmu.
da boš s tem denarjem lahko naglo kupil bikce, ovne, jagnjeta, z njihovimi jedilnimi daritvami in njihovimi pitnimi daritvami in jih daroval na oltarju hiše svojega Boga, ki je v Jeruzalemu.
18 Ìwọ àti àwọn Júù arákùnrin rẹ lè fi èyí tókù fàdákà àti wúrà ṣe ohunkóhun tí ó bá dára lójú yín, ní ìbámu pẹ̀lú ìfẹ́ Ọlọ́run yín.
In karkoli se bo zdelo dobro tebi in tvojim bratom, da storite s preostankom srebra in zlata, to storite po volji svojega Boga.
19 Kó gbogbo ohun èlò tí a fi sí ìkáwọ́ rẹ fún Ọlọ́run Jerusalẹmu fún ìsìn nínú tẹmpili Ọlọ́run rẹ.
Tudi posode, ki so ti dane za službo hiše svojega Boga, te izroči pred Bogom Jeruzalema.
20 Ohunkóhun mìíràn tí o bá nílò fún tẹmpili Ọlọ́run rẹ tí ó sì ní láti pèsè, o lè mú u láti inú ìṣúra ọba.
Karkoli več bo treba za hišo tvojega Boga, kar boš imel priložnost dati, daj to iz kraljeve zakladne hiše.
21 Èmi, ọba Artasasta, pàṣẹ fún gbogbo olùtọ́jú ilé ìṣúra agbègbè Eufurate láìrójú láti pèsè ohunkóhun tí àlùfáà Esra, olùkọ́ni ní òfin Ọlọ́run ọ̀run bá béèrè lọ́wọ́ yín
Jaz, torej jaz, kralj Artakserks, izdajam odlok vsem zakladnikom, ki so onkraj reke, da karkoli bo duhovnik Ezra, pisar postave nebeškega Boga, zahteval od vas, naj bo to naglo storjeno,
22 tó ọgọ́rùn-ún kan tálẹ́ǹtì fàdákà, ọgọ́rùn-ún kan òsùwọ̀n àlìkámà, àti dé ọgọ́rùn-ún bati ọtí wáìnì, àti dé ọgọ́rùn-ún bati òróró olifi, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ iyọ̀.
do sto talentov srebra in do sto mer pšenice in do sto čebrov vina in do sto kadi olja, soli pa brez predpisa.
23 Ohunkóhun tí Ọlọ́run ọ̀run bá fẹ́, jẹ́ kí ó di ṣíṣe ní pípé fún tẹmpili Ọlọ́run ọ̀run. Èéṣe tí ìbínú yóò ṣe wá sí agbègbè ọba àti sí orí àwọn ọmọ rẹ̀?
Karkoli je zapovedano od Boga iz nebes, naj bo to marljivo storjeno za hišo Boga iz nebes, kajti zakaj bi bil bes zoper kraljestvo kralja in njegovih sinov?
24 Ìwọ sì ní láti mọ̀ pé ìwọ kò ní àṣẹ láti sọ sísan owó orí, owó òde tàbí owó bodè di dandan fún àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà, àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili tàbí àwọn òṣìṣẹ́ mìíràn nínú ilé Ọlọ́run yìí.
Prav tako vam potrjujemo, da glede kateregakoli izmed duhovnikov in Lévijevcev, pevcev, vratarjev, Netinimcev ali služabnikov te Božje hiše, to ne bo zakonito, da bi nanje naložili pristojbino, davek in carino.
25 Ìwọ Esra, ní ìbámu pẹ̀lú ọgbọ́n Ọlọ́run rẹ̀, èyí tí ó ní, yan àwọn adájọ́ àgbà àti àwọn onídàájọ́ láti máa ṣe ìdájọ́ fún àwọn ènìyàn agbègbè Eufurate, gbogbo àwọn tí ó mọ òfin Ọlọ́run rẹ. Ìwọ yóò sì kọ́ ẹnikẹ́ni tí kò mọ̀ àwọn òfin náà.
Ti pa Ezra, po modrosti svojega Boga, ki je v tvoji roki, postavi oblastnike in sodnike, ki bodo lahko sodili vse ljudstvo, ki je onkraj reke [Evfrat], vse takšne, ki poznajo zakone tvojega Boga; in učite tiste, ki jih ne poznajo.
26 Ẹnikẹ́ni tí kò bá ṣe ìgbọ́ràn sí òfin Ọlọ́run rẹ àti sí òfin ọba ní ó gbọdọ̀ kú tàbí kí a lé e jáde tàbí kí a gbẹ́sẹ̀ lé ẹrù rẹ̀ tàbí kí a sọ ọ́ sínú ẹ̀wọ̀n.
Kdorkoli pa ne bo izpolnjeval postave tvojega Boga in kraljeve postave, naj bo nad njim naglo izvršena sodba, bodisi je to s smrtjo ali izgnanstvom ali zaplembo dobrin ali z ujetništvom.‹
27 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ẹni tí ó fi sí ọkàn ọba láti mú ọlá wá sí ilé Olúwa ní Jerusalẹmu ní ọ̀nà yìí.
Blagoslovljen bodi Gospod, Bog naših očetov, ki je takšno stvar, kot je ta, položil na kraljevo srce, da olepša Gospodovo hišo, ki je v Jeruzalemu
28 Ẹni tí ó jẹ́ kí ojúrere rẹ̀ tàn kàn mí níwájú ọba àti àwọn olùbádámọ̀ràn àti ní iwájú àwọn alágbára ìjòyè ọba. Nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára mi, mo mú ọkàn le, mo sì kó àwọn olórí jọ láàrín àwọn ènìyàn Israẹli láti gòkè lọ pẹ̀lú mi.
in mi razširil usmiljenje pred kraljem in njegovimi svetovalci in pred vsemi mogočnimi kraljevimi princi. In okrepljen sem bil, ko je bila roka Gospoda, mojega Boga, nad menoj in iz Izraela sem zbral skupaj vodilne može, da gredo gor z menoj.

< Ezra 7 >