< Ezra 7 >
1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ní àkókò ìjọba ọba Artasasta ní Persia, Esra ọmọ Seraiah, ọmọ Asariah, ọmọ Hilkiah,
Po tych wydarzeniach, za panowania Artakserksesa, króla Persji, Ezdrasz, syn Serajasza, syna Azariasza, syna Chilkiasza;
2 ọmọ Ṣallumu, ọmọ Sadoku, ọmọ Ahitubu,
Syna Szalluma, syna Sadoka, syna Achituba;
3 ọmọ Amariah, ọmọ Asariah, ọmọ Meraioti,
Syna Amariasza, syna Azariasza, syna Merajota;
4 ọmọ Serahiah, ọmọ Ussi, ọmọ Bukki,
Syna Zerachiasza, syna Uzziego, syna Bukkiego;
5 ọmọ Abiṣua, ọmọ Finehasi, ọmọ Eleasari, ọmọ Aaroni olórí àlùfáà—
Syna Abiszui, syna Pinchasa, syna Eleazara, syna Aarona, najwyższego kapłana;
6 Esra yìí sì gòkè wá láti Babeli. Olùkọ́ tí ó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nípa òfin Mose, èyí tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ti fi fún wọn. Ọba sì fi gbogbo ohun tí ó béèrè fún un, nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára rẹ̀.
Tenże Ezdrasz wyruszył z Babilonu, a był człowiekiem uczonym w prawie Mojżesza, które dał PAN, Bóg Izraela. A król spełnił wszystkie jego prośby, gdyż ręka PANA, jego Boga, była nad nim.
7 Ní ọdún keje ọba Artasasta díẹ̀ lára àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà àti àwọn tí ń ṣiṣẹ́ nínú tẹmpili náà gòkè wá sí Jerusalẹmu.
Wyruszyli też [niektórzy] z synów Izraela oraz z kapłanów, Lewitów, śpiewaków, odźwiernych i z Netinitów do Jerozolimy w siódmym roku króla Artakserksesa.
8 Ní oṣù karùn-ún ọdún keje ọba yìí ni Esra dé sí Jerusalẹmu.
[Ezdrasz] przybył do Jerozolimy w piątym miesiącu – było to w siódmym roku króla.
9 Ó bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ̀ láti Babeli ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, ó sì dé Jerusalẹmu ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run rẹ̀ wà ní ara rẹ̀.
Wyruszył z Babilonu w pierwszym [dniu] pierwszego miesiąca, a do Jerozolimy przybył w pierwszym [dniu] piątego miesiąca, ponieważ była nad nim łaskawa ręka jego Boga.
10 Esra ti fi ara rẹ̀ jì fún kíkọ́ àti pípa òfin Olúwa mọ́, ó sì ń kọ́ òfin àti ìlànà Mose ní Israẹli.
Ezdrasz bowiem przygotował swoje serce, aby szukać prawa PANA i wykonywać je, a także by nauczać w Izraelu ustaw i sądów.
11 Èyí ni ẹ̀dà lẹ́tà ti ọba Artasasta fún àlùfáà Esra olùkọ́ni, ẹni tó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nínú àkọsílẹ̀ òfin àti ìlànà Olúwa fún Israẹli.
A oto odpis listu, który król Artakserkses dał Ezdraszowi, kapłanowi i uczonemu, biegłemu w słowach przykazań PANA i w jego ustawach w Izraelu:
12 Artasasta, ọba àwọn ọba. Sí àlùfáà Esra, olùkọ́ òfin Ọlọ́run ọ̀run. Àlàáfíà.
Artakserkses, król królów, Ezdraszowi, kapłanowi, uczonemu w prawie Boga niebios, [mężowi] doskonałemu, otóż;
13 Mo pàṣẹ pé ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi, ti ó wà ní abẹ́ ìṣàkóso ìjọba mi, tí ó bá fẹ́ láti bá ọ lọ sí Jerusalẹmu lè tẹ̀lé ọ lọ.
Wydaję dekret [o tym], że każdy z ludu Izraela, spośród jego kapłanów i Lewitów w moim państwie, kto dobrowolnie pragnie udać się do Jerozolimy, może iść z tobą.
14 Ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ̀ méjèèje rán ọ lọ láti wádìí nípa òfin Ọlọ́run rẹ tí ó wà ní ọwọ́ rẹ nípa Juda àti Jerusalẹmu.
Ty bowiem zostałeś wysłany przez króla i jego siedmiu doradców, abyś według prawa swego Boga, które masz w swoim ręku, zbadał sprawy w Judei i Jerozolimie;
15 Síwájú sí i, kí ìwọ kí ó kó fàdákà àti wúrà lọ pẹ̀lú rẹ èyí tí ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ fi tọkàntọkàn fún Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ibùjókòó rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu,
I abyś zaniósł srebro i złoto, które król i jego doradcy dobrowolnie ofiarowali Bogu Izraela, którego przybytek [jest] w Jerozolimie;
16 pẹ̀lú gbogbo fàdákà àti wúrà tí ìwọ lè rí ní agbègbè ìjọba Babeli àti àwọn ọrẹ àtinúwá àwọn ènìyàn àti ti àwọn àlùfáà fún tẹmpili Ọlọ́run wọn ní Jerusalẹmu.
Oraz całe srebro i złoto, które otrzymasz w całej prowincji Babilonu wraz z dobrowolnymi darami od ludu i kapłanów, które dobrowolnie ofiarują na dom swego Boga w Jerozolimie;
17 Pẹ̀lú owó yìí, rí i dájú pé ó ra àwọn akọ màlúù, àwọn àgbò àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn, pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ, àti ọrẹ ohun mímu, kí ìwọ kí ó fi wọ́n rú ẹbọ lórí pẹpẹ tẹmpili Ọlọ́run rẹ ní Jerusalẹmu.
Abyś za te pieniądze bezzwłocznie kupił cielce, barany, jagnięta wraz z przynależnymi do nich ofiarami z pokarmów i płynów i złożył je na ołtarzu domu waszego Boga w Jerozolimie;
18 Ìwọ àti àwọn Júù arákùnrin rẹ lè fi èyí tókù fàdákà àti wúrà ṣe ohunkóhun tí ó bá dára lójú yín, ní ìbámu pẹ̀lú ìfẹ́ Ọlọ́run yín.
Z pozostałym srebrem i złotem uczyńcie zaś to, co ty i twoi bracia uznacie za słuszne, tak czyńcie, według woli waszego Boga.
19 Kó gbogbo ohun èlò tí a fi sí ìkáwọ́ rẹ fún Ọlọ́run Jerusalẹmu fún ìsìn nínú tẹmpili Ọlọ́run rẹ.
Naczynia też, które zostały ci dane do służby w domu twojego Boga, oddaj przed Bogiem w Jerozolimie;
20 Ohunkóhun mìíràn tí o bá nílò fún tẹmpili Ọlọ́run rẹ tí ó sì ní láti pèsè, o lè mú u láti inú ìṣúra ọba.
Także i inne potrzeby do domu twojego Boga, za które przyjdzie ci zapłacić, opłać ze skarbca królewskiego.
21 Èmi, ọba Artasasta, pàṣẹ fún gbogbo olùtọ́jú ilé ìṣúra agbègbè Eufurate láìrójú láti pèsè ohunkóhun tí àlùfáà Esra, olùkọ́ni ní òfin Ọlọ́run ọ̀run bá béèrè lọ́wọ́ yín
A ja, król Artakserkses, wydaję wszystkim podskarbim zarzecza rozkaz o tym, że wszystko, czegokolwiek zażąda od was kapłan Ezdrasz, uczony w prawie Boga niebios, ma być bezzwłocznie wykonane;
22 tó ọgọ́rùn-ún kan tálẹ́ǹtì fàdákà, ọgọ́rùn-ún kan òsùwọ̀n àlìkámà, àti dé ọgọ́rùn-ún bati ọtí wáìnì, àti dé ọgọ́rùn-ún bati òróró olifi, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ iyọ̀.
Aż do stu talentów srebra, stu kor pszenicy, stu bat wina, stu bat oliwy, a soli bez ograniczenia.
23 Ohunkóhun tí Ọlọ́run ọ̀run bá fẹ́, jẹ́ kí ó di ṣíṣe ní pípé fún tẹmpili Ọlọ́run ọ̀run. Èéṣe tí ìbínú yóò ṣe wá sí agbègbè ọba àti sí orí àwọn ọmọ rẹ̀?
Wszystko, co nakazuje Bóg niebios, ma być wykonane starannie dla domu Boga niebios, bo dlaczego ma być wzbudzony jego gniew przeciwko państwu króla i jego synów?
24 Ìwọ sì ní láti mọ̀ pé ìwọ kò ní àṣẹ láti sọ sísan owó orí, owó òde tàbí owó bodè di dandan fún àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà, àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili tàbí àwọn òṣìṣẹ́ mìíràn nínú ilé Ọlọ́run yìí.
Zawiadamiamy was również, że na żadnego z kapłanów, Lewitów, śpiewaków, odźwiernych, Netinitów oraz [pozostałych] sług tego domu Boga nie wolno nakładać podatku, danin ani cła.
25 Ìwọ Esra, ní ìbámu pẹ̀lú ọgbọ́n Ọlọ́run rẹ̀, èyí tí ó ní, yan àwọn adájọ́ àgbà àti àwọn onídàájọ́ láti máa ṣe ìdájọ́ fún àwọn ènìyàn agbègbè Eufurate, gbogbo àwọn tí ó mọ òfin Ọlọ́run rẹ. Ìwọ yóò sì kọ́ ẹnikẹ́ni tí kò mọ̀ àwọn òfin náà.
A ty, Ezdraszu, według mądrości swego Boga, która jest w tobie, ustanów urzędników i sędziów, którzy będą sądzić cały lud zarzecza, wszystkich, którzy znają prawo twego Boga; a tych, którzy go nie znają, macie uczyć.
26 Ẹnikẹ́ni tí kò bá ṣe ìgbọ́ràn sí òfin Ọlọ́run rẹ àti sí òfin ọba ní ó gbọdọ̀ kú tàbí kí a lé e jáde tàbí kí a gbẹ́sẹ̀ lé ẹrù rẹ̀ tàbí kí a sọ ọ́ sínú ẹ̀wọ̀n.
Na każdego, kto nie wykona prawa twego Boga i prawa króla, niech bezzwłocznie będzie wydany wyrok – albo śmierci, albo wygnania, albo przepadku mienia, albo więzienia.
27 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ẹni tí ó fi sí ọkàn ọba láti mú ọlá wá sí ilé Olúwa ní Jerusalẹmu ní ọ̀nà yìí.
[Ezdrasz powiedział]: Błogosławiony niech będzie PAN, Bóg naszych ojców, który włożył w serce króla [pragnienie], aby ozdobić dom PANA, który [jest] w Jerozolimie;
28 Ẹni tí ó jẹ́ kí ojúrere rẹ̀ tàn kàn mí níwájú ọba àti àwọn olùbádámọ̀ràn àti ní iwájú àwọn alágbára ìjòyè ọba. Nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára mi, mo mú ọkàn le, mo sì kó àwọn olórí jọ láàrín àwọn ènìyàn Israẹli láti gòkè lọ pẹ̀lú mi.
A mnie okazał łaskę wobec króla i jego doradców oraz wszystkich możnych dostojników króla. A ja, będąc wzmocniony ręką PANA, swego Boga, [która była] nade mną, zgromadziłem naczelników z Izraela, aby wyruszyli ze mną.