< Ezra 7 >

1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ní àkókò ìjọba ọba Artasasta ní Persia, Esra ọmọ Seraiah, ọmọ Asariah, ọmọ Hilkiah,
A po tych sprawach za królowania Artakserksesa, króla Perskiego, Ezdrasz, syn Sarajasza, syna Azaryjaszowego, syna Helkijaszowego,
2 ọmọ Ṣallumu, ọmọ Sadoku, ọmọ Ahitubu,
Syna Sallumowego, syna Sadokowego, syna Achitobowego,
3 ọmọ Amariah, ọmọ Asariah, ọmọ Meraioti,
Syna Amaryjaszowego, syna Azaryjaszowego, syna Merajotowego,
4 ọmọ Serahiah, ọmọ Ussi, ọmọ Bukki,
Syna Zerahyjaszowego, syna Uzego, syna Bukkiego,
5 ọmọ Abiṣua, ọmọ Finehasi, ọmọ Eleasari, ọmọ Aaroni olórí àlùfáà—
Syna Abisujego, syna Fineesowego, syna Eleazarowego, syna Aarona kapłana najwyższego:
6 Esra yìí sì gòkè wá láti Babeli. Olùkọ́ tí ó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nípa òfin Mose, èyí tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ti fi fún wọn. Ọba sì fi gbogbo ohun tí ó béèrè fún un, nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára rẹ̀.
Ten Ezdrasz wyszedł z Babilonu, a był człowiekiem biegłym w zakonie Mojżeszowym, który był dał Pan, Bóg Izraelski; a pozwolił mu był król według ręki Pana Boga jego nad nim, na wszystkę prośbę jego.
7 Ní ọdún keje ọba Artasasta díẹ̀ lára àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà àti àwọn tí ń ṣiṣẹ́ nínú tẹmpili náà gòkè wá sí Jerusalẹmu.
(Wyszli też niektórzy z synów Izraelskich, i z kapłanów, i z Lewitów, i śpiewaków, i z odźwiernych, i z Netynejczyków, do Jeruzalemu roku siódmego Artakserksesa króla)
8 Ní oṣù karùn-ún ọdún keje ọba yìí ni Esra dé sí Jerusalẹmu.
I przyszedł do Jeruzalemu miesiąca piątego; tenci był rok siódmy króla Daryjusza.
9 Ó bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ̀ láti Babeli ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, ó sì dé Jerusalẹmu ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run rẹ̀ wà ní ara rẹ̀.
Albowiem w pierwszy dzień miesiąca pierwszego wyszedł z Babilonu, a dnia pierwszego miesiąca piątego przyszedł do Jeruzalemu według łaskawego wspomożenia Boga swego.
10 Esra ti fi ara rẹ̀ jì fún kíkọ́ àti pípa òfin Olúwa mọ́, ó sì ń kọ́ òfin àti ìlànà Mose ní Israẹli.
Bo Ezdrasz przygotował był serce swe, aby szukał zakonu Pańskiego, i aby czynił, i nauczał w Izraelu ustaw i sądów.
11 Èyí ni ẹ̀dà lẹ́tà ti ọba Artasasta fún àlùfáà Esra olùkọ́ni, ẹni tó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nínú àkọsílẹ̀ òfin àti ìlànà Olúwa fún Israẹli.
A tenci jest przepis listu, który dał król Artakserkses Ezdraszowi, kapłanowi nauczonemu w zakonie, i biegłemu w tych rzeczach, które przykazał Pan, i w ustawach jego w Izraelu.
12 Artasasta, ọba àwọn ọba. Sí àlùfáà Esra, olùkọ́ òfin Ọlọ́run ọ̀run. Àlàáfíà.
Artakserkses, król nad królmi, Ezdraszowi, kapłanowi nauczonemu w zakonie Boga niebieskiego, mężowi doskonałemu, i Cheenetczykom.
13 Mo pàṣẹ pé ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi, ti ó wà ní abẹ́ ìṣàkóso ìjọba mi, tí ó bá fẹ́ láti bá ọ lọ sí Jerusalẹmu lè tẹ̀lé ọ lọ.
Wydany odemnie jest dekret, iż ktobykolwiek dobrowolnie w królestwie mojem z ludu Izraelskiego, i z kapłanów jego i z Lewitów chciał iść z tobą do Jeruzalemu, aby szedł.
14 Ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ̀ méjèèje rán ọ lọ láti wádìí nípa òfin Ọlọ́run rẹ tí ó wà ní ọwọ́ rẹ nípa Juda àti Jerusalẹmu.
Ponieważ od króla i od siedmiu radnych panów jego jesteś posłany, abyś dojrzał Judy i Jeruzalemu według zakonu Boga twego, który jest w rękach twoich.
15 Síwájú sí i, kí ìwọ kí ó kó fàdákà àti wúrà lọ pẹ̀lú rẹ èyí tí ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ fi tọkàntọkàn fún Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ibùjókòó rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu,
A iżbyś odniósł srebro i złoto, które król i radni panowie jego dobrowolnie ofiarowali Bogu Izraelskiemu, którego przybytek jest w Jeruzalemie.
16 pẹ̀lú gbogbo fàdákà àti wúrà tí ìwọ lè rí ní agbègbè ìjọba Babeli àti àwọn ọrẹ àtinúwá àwọn ènìyàn àti ti àwọn àlùfáà fún tẹmpili Ọlọ́run wọn ní Jerusalẹmu.
Do tego wszystko srebro i złoto, któregobyś nabył we wszystkiej krainie Babilońskiej, z dobrowolnemi darami od ludu i od kapłanów, którzyby co dobrowolnie ofiarowali na dom Boga swego, który jest w Jeruzalemie;
17 Pẹ̀lú owó yìí, rí i dájú pé ó ra àwọn akọ màlúù, àwọn àgbò àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn, pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ, àti ọrẹ ohun mímu, kí ìwọ kí ó fi wọ́n rú ẹbọ lórí pẹpẹ tẹmpili Ọlọ́run rẹ ní Jerusalẹmu.
Abyś prędko nakupił za to srebro cielców, baranów, baranków z śniednemi ofiarami ich, i z mokremi ofiarami ich, a ofiarował je na ołtarzu domu Boga waszego, który jest w Jeruzalemie;
18 Ìwọ àti àwọn Júù arákùnrin rẹ lè fi èyí tókù fàdákà àti wúrà ṣe ohunkóhun tí ó bá dára lójú yín, ní ìbámu pẹ̀lú ìfẹ́ Ọlọ́run yín.
A cokolwiek się tobie i braciom twoim będzie dobrego zdało, z ostatkiem srebra i złota uczynić, według woli Boga waszego uczyńcie.
19 Kó gbogbo ohun èlò tí a fi sí ìkáwọ́ rẹ fún Ọlọ́run Jerusalẹmu fún ìsìn nínú tẹmpili Ọlọ́run rẹ.
Naczynia też, któreć są oddane do usługi domu Boga twego, oddaj przed Bogiem w Jeruzalemie.
20 Ohunkóhun mìíràn tí o bá nílò fún tẹmpili Ọlọ́run rẹ tí ó sì ní láti pèsè, o lè mú u láti inú ìṣúra ọba.
Także i inne rzeczy, należące do domu Boga twego, i coby potrzeba dać, dasz z domu skarbów królewskich.
21 Èmi, ọba Artasasta, pàṣẹ fún gbogbo olùtọ́jú ilé ìṣúra agbègbè Eufurate láìrójú láti pèsè ohunkóhun tí àlùfáà Esra, olùkọ́ni ní òfin Ọlọ́run ọ̀run bá béèrè lọ́wọ́ yín
A ja, ja król Artakserkses, rozkazałem wszystkim podskarbim, którzyście za rzeką, aby wszystko, czegobykolwiek żądał od was Ezdrasz kapłan, nauczyciel zakonu Boga niebieskiego, prędko się stało,
22 tó ọgọ́rùn-ún kan tálẹ́ǹtì fàdákà, ọgọ́rùn-ún kan òsùwọ̀n àlìkámà, àti dé ọgọ́rùn-ún bati ọtí wáìnì, àti dé ọgọ́rùn-ún bati òróró olifi, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ iyọ̀.
Aż do sta talentów srebra i aż do sta korcy pszenicy, i aż do sta wiader wina, i aż do sta bareł oliwy, a soli bez miary.
23 Ohunkóhun tí Ọlọ́run ọ̀run bá fẹ́, jẹ́ kí ó di ṣíṣe ní pípé fún tẹmpili Ọlọ́run ọ̀run. Èéṣe tí ìbínú yóò ṣe wá sí agbègbè ọba àti sí orí àwọn ọmọ rẹ̀?
Cobykolwiek było z rozkazania Boga niebieskiego, niech będzie prędko dodane do domu Boga niebieskiego; bo przecz ma być wzruszony gniew jego przeciwko królestwu, królowi i synom jego?
24 Ìwọ sì ní láti mọ̀ pé ìwọ kò ní àṣẹ láti sọ sísan owó orí, owó òde tàbí owó bodè di dandan fún àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà, àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili tàbí àwọn òṣìṣẹ́ mìíràn nínú ilé Ọlọ́run yìí.
Także oznajmujemy wam, aby na żadnego z kapłanów, i z Lewitów, i z śpiewaków, i z odźwiernych, Netynejczyków, i innych sług domu Boga tego, cła, czynszów, i dani dorocznej żaden starosta nie wkładał.
25 Ìwọ Esra, ní ìbámu pẹ̀lú ọgbọ́n Ọlọ́run rẹ̀, èyí tí ó ní, yan àwọn adájọ́ àgbà àti àwọn onídàájọ́ láti máa ṣe ìdájọ́ fún àwọn ènìyàn agbègbè Eufurate, gbogbo àwọn tí ó mọ òfin Ọlọ́run rẹ. Ìwọ yóò sì kọ́ ẹnikẹ́ni tí kò mọ̀ àwọn òfin náà.
A ty Ezdraszu! według mądrości Boga twego, która jest w tobie, postanowisz sędziów, i w prawie biegłych, aby sądzili wszystek lud, który jest za rzeką, ze wszystkich, którzy są powiadomi zakonu Boga twego; a ktoby nie umiał, uczyć go będziecie.
26 Ẹnikẹ́ni tí kò bá ṣe ìgbọ́ràn sí òfin Ọlọ́run rẹ àti sí òfin ọba ní ó gbọdọ̀ kú tàbí kí a lé e jáde tàbí kí a gbẹ́sẹ̀ lé ẹrù rẹ̀ tàbí kí a sọ ọ́ sínú ẹ̀wọ̀n.
A ktobykolwiek nie czynił dosyć zakonowi Boga twego, i prawu królewskiemu, aby prędki dekret był o nim wyadany albo na śmierć, albo na wygnanie jego, albo na skaranie na majętności, albo na więzienie. I rzekł Ezdrasz:
27 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ẹni tí ó fi sí ọkàn ọba láti mú ọlá wá sí ilé Olúwa ní Jerusalẹmu ní ọ̀nà yìí.
Błogosławiony Pan, Bóg ojców naszych, który to dał w serce królewskie, aby uwielbił dom Pański, który jest w Jeruzalemie;
28 Ẹni tí ó jẹ́ kí ojúrere rẹ̀ tàn kàn mí níwájú ọba àti àwọn olùbádámọ̀ràn àti ní iwájú àwọn alágbára ìjòyè ọba. Nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára mi, mo mú ọkàn le, mo sì kó àwọn olórí jọ láàrín àwọn ènìyàn Israẹli láti gòkè lọ pẹ̀lú mi.
A ku mnie skłonił miłosierdzie przed królem i radą jego, i wszystkimi książętami królewskimi możnymi. Przetoż ja, będąc umocniony ręką Pana, Boga mojego, która jest nademną, zgromadziłem z Izraela przedniejszych, którzy wyszli zemną.

< Ezra 7 >