< Ezra 7 >

1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ní àkókò ìjọba ọba Artasasta ní Persia, Esra ọmọ Seraiah, ọmọ Asariah, ọmọ Hilkiah,
És ezek után Artaxerxes persa király uralkodásakor Ezsdrás, a Serája fia, ki Azariás fia, ki Hilkiás fia,
2 ọmọ Ṣallumu, ọmọ Sadoku, ọmọ Ahitubu,
Ki Sallum fia, ki Sádók fia, ki Ahitub fia,
3 ọmọ Amariah, ọmọ Asariah, ọmọ Meraioti,
Ki Amária fia, ki Azariás fia, ki Mérájóth fia,
4 ọmọ Serahiah, ọmọ Ussi, ọmọ Bukki,
Ki Zerahja fia, ki Uzzi fia, ki Bukki fia,
5 ọmọ Abiṣua, ọmọ Finehasi, ọmọ Eleasari, ọmọ Aaroni olórí àlùfáà—
Ki Abisua fia, ki Fineás fia, ki Eleázár fia, ki pedig Áronnak, a főpapnak fia volt.
6 Esra yìí sì gòkè wá láti Babeli. Olùkọ́ tí ó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nípa òfin Mose, èyí tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ti fi fún wọn. Ọba sì fi gbogbo ohun tí ó béèrè fún un, nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára rẹ̀.
Ez az Ezsdrás feljöve Babilóniából, (ő, a ki bölcs írástudó vala a Mózes törvényében, melyet az Úr, Izráel Istene adott vala) és megadá néki a király az Úrnak, az ő Istenének rajta nyugovó kegyelme szerint minden kérését.
7 Ní ọdún keje ọba Artasasta díẹ̀ lára àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà àti àwọn tí ń ṣiṣẹ́ nínú tẹmpili náà gòkè wá sí Jerusalẹmu.
Feljövének pedig az Izráel fiai, a papok, a Léviták, az énekesek, a kapunállók és a Léviták szolgái közül többen Jeruzsálembe Artaxerxes király hetedik esztendejében.
8 Ní oṣù karùn-ún ọdún keje ọba yìí ni Esra dé sí Jerusalẹmu.
És Ezsdrás megérkezék velök Jeruzsálembe az ötödik hónapban, a király hetedik esztendejében.
9 Ó bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ̀ láti Babeli ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, ó sì dé Jerusalẹmu ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run rẹ̀ wà ní ara rẹ̀.
Ugyanis az első hónak első napján határozá el a Babilóniából való feljövetelt, és az ötödik hó első napján érkezett Jeruzsálembe, az ő Istenének rajta nyugvó jó kegyelme szerint;
10 Esra ti fi ara rẹ̀ jì fún kíkọ́ àti pípa òfin Olúwa mọ́, ó sì ń kọ́ òfin àti ìlànà Mose ní Israẹli.
Mert Ezsdrás erős szívvel törekedett keresni és cselekedni az Úr törvényét, és tanítani Izráelben a rendeléseket és ítéleteket.
11 Èyí ni ẹ̀dà lẹ́tà ti ọba Artasasta fún àlùfáà Esra olùkọ́ni, ẹni tó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nínú àkọsílẹ̀ òfin àti ìlànà Olúwa fún Israẹli.
És ez mássa a levélnek, melyet adott vala Artaxerxes király Ezsdrásnak, az írástudó papnak, a ki írástudó vala az Úr parancsolatainak beszédiben, Izráelnek adott rendeléseiben:
12 Artasasta, ọba àwọn ọba. Sí àlùfáà Esra, olùkọ́ òfin Ọlọ́run ọ̀run. Àlàáfíà.
„Artaxerxes, a királyok királya Ezsdrás papnak, ki a menny Istenének törvényében bölcs írástudó és a többi.
13 Mo pàṣẹ pé ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi, ti ó wà ní abẹ́ ìṣàkóso ìjọba mi, tí ó bá fẹ́ láti bá ọ lọ sí Jerusalẹmu lè tẹ̀lé ọ lọ.
Szabadságot adok, hogy valaki országomban Izráel népe, papjai és a Léviták közül Jeruzsálembe akar menni, veled elmehet.
14 Ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ̀ méjèèje rán ọ lọ láti wádìí nípa òfin Ọlọ́run rẹ tí ó wà ní ọwọ́ rẹ nípa Juda àti Jerusalẹmu.
Minthogy te elbocsáttatol a királytól és hét tanácsosától, hogy utána nézz Júdának és Jeruzsálemnek, a te Istened törvénye szerint, mely kezedben van,
15 Síwájú sí i, kí ìwọ kí ó kó fàdákà àti wúrà lọ pẹ̀lú rẹ èyí tí ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ fi tọkàntọkàn fún Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ibùjókòó rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu,
És hogy elvigyed az ezüstöt és aranyat, melyet a király és tanácsosai önkénytesen ajándékoznak Izráel Istenének, kinek hajléka Jeruzsálemben van,
16 pẹ̀lú gbogbo fàdákà àti wúrà tí ìwọ lè rí ní agbègbè ìjọba Babeli àti àwọn ọrẹ àtinúwá àwọn ènìyàn àti ti àwọn àlùfáà fún tẹmpili Ọlọ́run wọn ní Jerusalẹmu.
És mindazt az ezüstöt és aranyat, melyet kapni fogsz Babilónia egész tartományában, együtt a nép és a papok önkénytes ajándékával, mit ezek önkénytesen ajándékoznak az ő Istenök házának, mely Jeruzsálemben van.
17 Pẹ̀lú owó yìí, rí i dájú pé ó ra àwọn akọ màlúù, àwọn àgbò àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn, pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ, àti ọrẹ ohun mímu, kí ìwọ kí ó fi wọ́n rú ẹbọ lórí pẹpẹ tẹmpili Ọlọ́run rẹ ní Jerusalẹmu.
Annálfogva gondosan végy e pénzen bikákat, kosokat és bárányokat s hozzájok való étel- és italáldozatokat, s áldozd meg azokat Istenetek házának oltárán, mely Jeruzsálemben van:
18 Ìwọ àti àwọn Júù arákùnrin rẹ lè fi èyí tókù fàdákà àti wúrà ṣe ohunkóhun tí ó bá dára lójú yín, ní ìbámu pẹ̀lú ìfẹ́ Ọlọ́run yín.
A megmaradott ezüsttel és arannyal pedig, a mit jónak láttok cselekedni te és atyádfiai, Istenetek akaratja szerint, azt cselekedjétek.
19 Kó gbogbo ohun èlò tí a fi sí ìkáwọ́ rẹ fún Ọlọ́run Jerusalẹmu fún ìsìn nínú tẹmpili Ọlọ́run rẹ.
És az edényekkel, melyek néked adattak át a te Istened házának szolgálatára, számolj be Isten előtt Jeruzsálemben.
20 Ohunkóhun mìíràn tí o bá nílò fún tẹmpili Ọlọ́run rẹ tí ó sì ní láti pèsè, o lè mú u láti inú ìṣúra ọba.
Egyéb szükségét pedig Istened házának, mit csak teljesítened kell, teljesítsd a király kincstartó házából.
21 Èmi, ọba Artasasta, pàṣẹ fún gbogbo olùtọ́jú ilé ìṣúra agbègbè Eufurate láìrójú láti pèsè ohunkóhun tí àlùfáà Esra, olùkọ́ni ní òfin Ọlọ́run ọ̀run bá béèrè lọ́wọ́ yín
És én, Artaxerxes, a király, parancsolom minden a folyóvizen túl lakó kincstartóimnak, hogy minden, a mit csak kérend tőletek Ezsdrás pap, ki a menny Istenének törvényében írástudó, pontosan teljesíttessék,
22 tó ọgọ́rùn-ún kan tálẹ́ǹtì fàdákà, ọgọ́rùn-ún kan òsùwọ̀n àlìkámà, àti dé ọgọ́rùn-ún bati ọtí wáìnì, àti dé ọgọ́rùn-ún bati òróró olifi, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ iyọ̀.
És pedig száz tálentom ezüstig, száz kór búzáig, száz báth borig, száz báth olajig és sóban, a mennyi elég.
23 Ohunkóhun tí Ọlọ́run ọ̀run bá fẹ́, jẹ́ kí ó di ṣíṣe ní pípé fún tẹmpili Ọlọ́run ọ̀run. Èéṣe tí ìbínú yóò ṣe wá sí agbègbè ọba àti sí orí àwọn ọmọ rẹ̀?
Minden, mi a menny Istenének akaratja szerint való, pontosan teljesíttessék a menny Istenének házáért, hogy meg ne haragudjék a királynak és fiainak országára.
24 Ìwọ sì ní láti mọ̀ pé ìwọ kò ní àṣẹ láti sọ sísan owó orí, owó òde tàbí owó bodè di dandan fún àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà, àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili tàbí àwọn òṣìṣẹ́ mìíràn nínú ilé Ọlọ́run yìí.
Veletek pedig tudatjuk, hogy sem a papokra, sem a Lévitákra, sem az énekesekre, sem a kapunállókra, sem a Léviták szolgáira, sem Isten e háza szolgáira, adót, rovást és úti vámot senkinek vetni nem szabad.
25 Ìwọ Esra, ní ìbámu pẹ̀lú ọgbọ́n Ọlọ́run rẹ̀, èyí tí ó ní, yan àwọn adájọ́ àgbà àti àwọn onídàájọ́ láti máa ṣe ìdájọ́ fún àwọn ènìyàn agbègbè Eufurate, gbogbo àwọn tí ó mọ òfin Ọlọ́run rẹ. Ìwọ yóò sì kọ́ ẹnikẹ́ni tí kò mọ̀ àwọn òfin náà.
És te Ezsdrás, a te Istened bölcs törvénye szerint, a mely kezedben van, rendelj ítélőket és birákat, a kik törvényt tegyenek minden a folyóvizen túl lakó nép között, mindazok között, a kik tudják Istenednek törvényeit, és a kik nem tudják, azokat tanítsátok!
26 Ẹnikẹ́ni tí kò bá ṣe ìgbọ́ràn sí òfin Ọlọ́run rẹ àti sí òfin ọba ní ó gbọdọ̀ kú tàbí kí a lé e jáde tàbí kí a gbẹ́sẹ̀ lé ẹrù rẹ̀ tàbí kí a sọ ọ́ sínú ẹ̀wọ̀n.
Valaki pedig nem fogja cselekedni a te Istenednek törvényét és a király törvényét, ítélet hozassék felette pontosan, vagy halálra, vagy számkivetésre, vagy jószágvesztésre, vagy fogságra.”
27 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ẹni tí ó fi sí ọkàn ọba láti mú ọlá wá sí ilé Olúwa ní Jerusalẹmu ní ọ̀nà yìí.
Áldott az Úr, atyáink Istene, a ki erre indítá a király szívét, hogy megékesítse az Úr házát, mely Jeruzsálemben van.
28 Ẹni tí ó jẹ́ kí ojúrere rẹ̀ tàn kàn mí níwájú ọba àti àwọn olùbádámọ̀ràn àti ní iwájú àwọn alágbára ìjòyè ọba. Nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára mi, mo mú ọkàn le, mo sì kó àwọn olórí jọ láàrín àwọn ènìyàn Israẹli láti gòkè lọ pẹ̀lú mi.
És a ki hozzám fordítá irgalmasságát a király előtt és tanácsosai előtt és a király minden hatalmas fejedelmei előtt! És én megerősödvén az Úrnak az én Istenemnek rajtam nyugovó kegyelme által, családfőket gyűjték össze Izráelből, hogy feljönnének velem.

< Ezra 7 >