< Ezra 7 >

1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ní àkókò ìjọba ọba Artasasta ní Persia, Esra ọmọ Seraiah, ọmọ Asariah, ọmọ Hilkiah,
Now, after these things, in the reign of Artaxerxes king of Persia, Ezra, —son of Seraiah, son of Azariah, son of Hilkiah;
2 ọmọ Ṣallumu, ọmọ Sadoku, ọmọ Ahitubu,
son of Shallum, son of Zadok, son of Ahitub;
3 ọmọ Amariah, ọmọ Asariah, ọmọ Meraioti,
son of Amariah, son of Azariah, son of Meraioth;
4 ọmọ Serahiah, ọmọ Ussi, ọmọ Bukki,
son of Zerahiah, son of Uzzi, son of Bukki;
5 ọmọ Abiṣua, ọmọ Finehasi, ọmọ Eleasari, ọmọ Aaroni olórí àlùfáà—
son of Abishua, son of Phinehas, son of Eliazar, son of Aaron the first priest; —
6 Esra yìí sì gòkè wá láti Babeli. Olùkọ́ tí ó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nípa òfin Mose, èyí tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ti fi fún wọn. Ọba sì fi gbogbo ohun tí ó béèrè fún un, nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára rẹ̀.
this Ezra, came up out of Babylon, he, being a ready scribe in the law of Moses, which Yahweh God of Israel had given, —and the king gave him, according to the hand of Yahweh his God upon him, all his request.
7 Ní ọdún keje ọba Artasasta díẹ̀ lára àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà àti àwọn tí ń ṣiṣẹ́ nínú tẹmpili náà gòkè wá sí Jerusalẹmu.
So then there came up some of the sons of Israel, and some of the priests and the Levites and the singers and the doorkeepers and the Nethinim, unto Jerusalem, —in the seventh year of Artaxerxes the king.
8 Ní oṣù karùn-ún ọdún keje ọba yìí ni Esra dé sí Jerusalẹmu.
And he entered Jerusalem, in the fifth month, —the same, was the seventh year of the king.
9 Ó bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ̀ láti Babeli ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, ó sì dé Jerusalẹmu ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run rẹ̀ wà ní ara rẹ̀.
For, on the first of the first month, was a beginning made of coming up from Babylon, —and, on the first of the fifth month, entered he into Jerusalem, according to the good hand of his God upon him.
10 Esra ti fi ara rẹ̀ jì fún kíkọ́ àti pípa òfin Olúwa mọ́, ó sì ń kọ́ òfin àti ìlànà Mose ní Israẹli.
For, Ezra, had settled his heart, to study the law of Yahweh, and to do [it], —and to teach in Israel, statute and regulation.
11 Èyí ni ẹ̀dà lẹ́tà ti ọba Artasasta fún àlùfáà Esra olùkọ́ni, ẹni tó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nínú àkọsílẹ̀ òfin àti ìlànà Olúwa fún Israẹli.
Now, this, is a copy of the letter which King Artaxerxes gave, to Ezra the priest the scribe, —the scribe of the words of the commandments of Yahweh, and of his statutes, for Israel: —
12 Artasasta, ọba àwọn ọba. Sí àlùfáà Esra, olùkọ́ òfin Ọlọ́run ọ̀run. Àlàáfíà.
Artaxerxes, king of kings, Unto Ezra the priest, scribe of the law of the God of the heavens—To despatch and so forth.
13 Mo pàṣẹ pé ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi, ti ó wà ní abẹ́ ìṣàkóso ìjọba mi, tí ó bá fẹ́ láti bá ọ lọ sí Jerusalẹmu lè tẹ̀lé ọ lọ.
From me, is issued an edict, that, every one in my kingdom, of the people of Israel, and of their priests and the Levites, who is minded of his own freewill to go to Jerusalem, with thee, let him go.
14 Ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ̀ méjèèje rán ọ lọ láti wádìí nípa òfin Ọlọ́run rẹ tí ó wà ní ọwọ́ rẹ nípa Juda àti Jerusalẹmu.
Forasmuch as, from before the king and his seven counselors, thou art sent, to enquire concerning Judah and as to Jerusalem, —by the law of thy God which is in thy hand;
15 Síwájú sí i, kí ìwọ kí ó kó fàdákà àti wúrà lọ pẹ̀lú rẹ èyí tí ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ fi tọkàntọkàn fún Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ibùjókòó rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu,
and to carry the silver and gold which the king and his counselors have freely offered unto the God of Israel, who, in Jerusalem, hath his habitation;
16 pẹ̀lú gbogbo fàdákà àti wúrà tí ìwọ lè rí ní agbègbè ìjọba Babeli àti àwọn ọrẹ àtinúwá àwọn ènìyàn àti ti àwọn àlùfáà fún tẹmpili Ọlọ́run wọn ní Jerusalẹmu.
and all the silver and the gold, which thou shalt find, in all the province of Babylon, —with the freewill offering of the people and of the priests offered willingly for the house of their God which is in Jerusalem,
17 Pẹ̀lú owó yìí, rí i dájú pé ó ra àwọn akọ màlúù, àwọn àgbò àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn, pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ, àti ọrẹ ohun mímu, kí ìwọ kí ó fi wọ́n rú ẹbọ lórí pẹpẹ tẹmpili Ọlọ́run rẹ ní Jerusalẹmu.
therefore, with all diligence, shalt thou buy—with this silver—bullocks, rams, lambs, with their meal-offerings, and their drink-offerings, —and shalt offer them upon the altar of the house of your God which is in Jerusalem;
18 Ìwọ àti àwọn Júù arákùnrin rẹ lè fi èyí tókù fàdákà àti wúrà ṣe ohunkóhun tí ó bá dára lójú yín, ní ìbámu pẹ̀lú ìfẹ́ Ọlọ́run yín.
and, whatsoever, unto thee and unto thy brethren, shall seem good, with the rest of the silver and the gold, to do, according to the pleasure of your God, shall ye do.
19 Kó gbogbo ohun èlò tí a fi sí ìkáwọ́ rẹ fún Ọlọ́run Jerusalẹmu fún ìsìn nínú tẹmpili Ọlọ́run rẹ.
And, the utensils which are freely given to thee for the service of the house of thy God, put thou back, before the God of Jerusalem.
20 Ohunkóhun mìíràn tí o bá nílò fún tẹmpili Ọlọ́run rẹ tí ó sì ní láti pèsè, o lè mú u láti inú ìṣúra ọba.
And, the rest of the need of the house of thy God, which it shall fall to thee to give, thou shalt give, out of the treasure-house of the king.
21 Èmi, ọba Artasasta, pàṣẹ fún gbogbo olùtọ́jú ilé ìṣúra agbègbè Eufurate láìrójú láti pèsè ohunkóhun tí àlùfáà Esra, olùkọ́ni ní òfin Ọlọ́run ọ̀run bá béèrè lọ́wọ́ yín
And, from me myself, Artaxerxes the king, issueth an edict, to all the treasurers who are Beyond the River, —that, whatsoever Ezra the priest the scribe of the law of the God of the heavens shall ask of you, with diligence, shall it be done:
22 tó ọgọ́rùn-ún kan tálẹ́ǹtì fàdákà, ọgọ́rùn-ún kan òsùwọ̀n àlìkámà, àti dé ọgọ́rùn-ún bati ọtí wáìnì, àti dé ọgọ́rùn-ún bati òróró olifi, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ iyọ̀.
unto a hundred talents of silver, and unto a hundred measures of wheat, and unto a hundred baths of wine, and unto a hundred baths of oil, —and salt without limit.
23 Ohunkóhun tí Ọlọ́run ọ̀run bá fẹ́, jẹ́ kí ó di ṣíṣe ní pípé fún tẹmpili Ọlọ́run ọ̀run. Èéṣe tí ìbínú yóò ṣe wá sí agbègbè ọba àti sí orí àwọn ọmọ rẹ̀?
Whatsoever is due to an edict of the God of the heavens, let it be done diligently, for the house of the God of the heavens, —for wherefore should there be wrath against the realm of the king and his sons?
24 Ìwọ sì ní láti mọ̀ pé ìwọ kò ní àṣẹ láti sọ sísan owó orí, owó òde tàbí owó bodè di dandan fún àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà, àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili tàbí àwọn òṣìṣẹ́ mìíràn nínú ilé Ọlọ́run yìí.
And, you, we do certify, that, as touching any of the priests or the Levites, the singers, the doorkeepers, the Nethinim, or the servitors of this house of God, tribute, excise or toll, shall it not be competent to impose upon them.
25 Ìwọ Esra, ní ìbámu pẹ̀lú ọgbọ́n Ọlọ́run rẹ̀, èyí tí ó ní, yan àwọn adájọ́ àgbà àti àwọn onídàájọ́ láti máa ṣe ìdájọ́ fún àwọn ènìyàn agbègbè Eufurate, gbogbo àwọn tí ó mọ òfin Ọlọ́run rẹ. Ìwọ yóò sì kọ́ ẹnikẹ́ni tí kò mọ̀ àwọn òfin náà.
And, thou, Ezra, according to the wisdom of thy God that is in thy hand, appoint thou judges and magistrates, who shall administer justice to all the people that are Beyond the River, to all who know the law of thy God, —and, whoso knoweth not, ye shall teach.
26 Ẹnikẹ́ni tí kò bá ṣe ìgbọ́ràn sí òfin Ọlọ́run rẹ àti sí òfin ọba ní ó gbọdọ̀ kú tàbí kí a lé e jáde tàbí kí a gbẹ́sẹ̀ lé ẹrù rẹ̀ tàbí kí a sọ ọ́ sínú ẹ̀wọ̀n.
But, whosoever shall not do the law of thy God and the law of the king, speedily, let, penalty, be exacted from him, —whether to death, or to banishment, or to confiscation of goods, or to imprisonment.
27 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ẹni tí ó fi sí ọkàn ọba láti mú ọlá wá sí ilé Olúwa ní Jerusalẹmu ní ọ̀nà yìí.
Blessed be Yahweh, God of our fathers, —who hath put the like of this into the heart of the king, to beautify the house of Yahweh, which is in Jerusalem;
28 Ẹni tí ó jẹ́ kí ojúrere rẹ̀ tàn kàn mí níwájú ọba àti àwọn olùbádámọ̀ràn àti ní iwájú àwọn alágbára ìjòyè ọba. Nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára mi, mo mú ọkàn le, mo sì kó àwọn olórí jọ láàrín àwọn ènìyàn Israẹli láti gòkè lọ pẹ̀lú mi.
and, unto me, hath extended lovingkindness, before the king and his counselors, yea all the valiant captains of the king, —I, therefore have emboldened myself, according to the hand of Yahweh my God upon me, and gathered out of Israel, chief men, to go up with me.

< Ezra 7 >