< Ezra 7 >
1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ní àkókò ìjọba ọba Artasasta ní Persia, Esra ọmọ Seraiah, ọmọ Asariah, ọmọ Hilkiah,
Now after these things, in the reigne of Artahshashte King of Persia, was Ezra the sonne of Seraiah, the sonne of Azariah, the sonne of Hilkiah,
2 ọmọ Ṣallumu, ọmọ Sadoku, ọmọ Ahitubu,
The sonne of Shallum, the sonne of Zadok, the sonne of Ahitub,
3 ọmọ Amariah, ọmọ Asariah, ọmọ Meraioti,
The sonne of Amariah, the sonne of Azariah, the sonne of Meraioth,
4 ọmọ Serahiah, ọmọ Ussi, ọmọ Bukki,
The sonne of Zeraiah, the sonne of Vzzi, the sonne of Bukki,
5 ọmọ Abiṣua, ọmọ Finehasi, ọmọ Eleasari, ọmọ Aaroni olórí àlùfáà—
The sonne of Abishua, the sonne of Phinehas, the sonne of Eleazar, the sonne of Aaron, the chiefe Priest.
6 Esra yìí sì gòkè wá láti Babeli. Olùkọ́ tí ó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nípa òfin Mose, èyí tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ti fi fún wọn. Ọba sì fi gbogbo ohun tí ó béèrè fún un, nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára rẹ̀.
This Ezra came vp from Babel, and was a Scribe prompt in the Lawe of Moses, which the Lord God of Israel had giuen, and the King gaue him all his request according to the hande of the Lord his God which was vpon him.
7 Ní ọdún keje ọba Artasasta díẹ̀ lára àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà àti àwọn tí ń ṣiṣẹ́ nínú tẹmpili náà gòkè wá sí Jerusalẹmu.
And there went vp certaine of the children of Israel, and of the Priests, and the Leuites, and the singers, and the porters, and the Nethinims vnto Ierusalem, in the seuenth yere of King Artahshashte.
8 Ní oṣù karùn-ún ọdún keje ọba yìí ni Esra dé sí Jerusalẹmu.
And hee came to Ierusalem in the fift moneth, which was in the seuenth yeere of the King.
9 Ó bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ̀ láti Babeli ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, ó sì dé Jerusalẹmu ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run rẹ̀ wà ní ara rẹ̀.
For vpon the first day of the first moneth began he to goe vp from Babel, and on the first day of the fift moneth came he to Ierusalem, according to the good hande of his God that was vpon him.
10 Esra ti fi ara rẹ̀ jì fún kíkọ́ àti pípa òfin Olúwa mọ́, ó sì ń kọ́ òfin àti ìlànà Mose ní Israẹli.
For Ezra had prepared his heart to seeke the Lawe of the Lord, and to doe it, and to teach the precepts and iudgements in Israel.
11 Èyí ni ẹ̀dà lẹ́tà ti ọba Artasasta fún àlùfáà Esra olùkọ́ni, ẹni tó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nínú àkọsílẹ̀ òfin àti ìlànà Olúwa fún Israẹli.
And this is the copie of the letter that King Artahshashte gaue vnto Ezra the Priest and scribe, euen a writer of the words of the commadements of ye Lord, and of his statutes ouer Israel.
12 Artasasta, ọba àwọn ọba. Sí àlùfáà Esra, olùkọ́ òfin Ọlọ́run ọ̀run. Àlàáfíà.
ARTAHSHASHTE King of Kings to Ezra the Priest and perfite scribe of the Lawe of the God of heauen, and to Cheeneth.
13 Mo pàṣẹ pé ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi, ti ó wà ní abẹ́ ìṣàkóso ìjọba mi, tí ó bá fẹ́ láti bá ọ lọ sí Jerusalẹmu lè tẹ̀lé ọ lọ.
I haue giuen commandement, that euery one, that is willing in my kingdome of the people of Israel, and of the Priestes, and Leuites to goe to Ierusalem with thee, shall goe.
14 Ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ̀ méjèèje rán ọ lọ láti wádìí nípa òfin Ọlọ́run rẹ tí ó wà ní ọwọ́ rẹ nípa Juda àti Jerusalẹmu.
Therefore art thou sent of the King and his seuen counsellers, to enquire in Iudah and Ierusalem, according to the lawe of thy God, which is in thine hand,
15 Síwájú sí i, kí ìwọ kí ó kó fàdákà àti wúrà lọ pẹ̀lú rẹ èyí tí ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ fi tọkàntọkàn fún Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ibùjókòó rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu,
And to carry the siluer and the gold, which the King and his cousellers willingly offer vnto the God of Israel (whose habitation is in Ierusalem)
16 pẹ̀lú gbogbo fàdákà àti wúrà tí ìwọ lè rí ní agbègbè ìjọba Babeli àti àwọn ọrẹ àtinúwá àwọn ènìyàn àti ti àwọn àlùfáà fún tẹmpili Ọlọ́run wọn ní Jerusalẹmu.
And all the siluer and gold that thou canst finde in all the prouince of Babel, with the free offring of the people, and that which the Priestes offer willingly to the house of their God which is in Ierusalem,
17 Pẹ̀lú owó yìí, rí i dájú pé ó ra àwọn akọ màlúù, àwọn àgbò àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn, pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ, àti ọrẹ ohun mímu, kí ìwọ kí ó fi wọ́n rú ẹbọ lórí pẹpẹ tẹmpili Ọlọ́run rẹ ní Jerusalẹmu.
That thou mayest bye speedily with this siluer, bullocks, rammes, lambes, with their meate offrings and their drinke offrings: and thou shalt offer them vpon the altar of the house of your God, which is in Ierusalem.
18 Ìwọ àti àwọn Júù arákùnrin rẹ lè fi èyí tókù fàdákà àti wúrà ṣe ohunkóhun tí ó bá dára lójú yín, ní ìbámu pẹ̀lú ìfẹ́ Ọlọ́run yín.
And whatsoeuer it pleaseth thee and thy brethren to do with the rest of the siluer, and gold, doe ye it according to the will of your God.
19 Kó gbogbo ohun èlò tí a fi sí ìkáwọ́ rẹ fún Ọlọ́run Jerusalẹmu fún ìsìn nínú tẹmpili Ọlọ́run rẹ.
And the vessels that are giuen thee for the seruice of the house of thy God, those deliuer thou before God in Ierusalem.
20 Ohunkóhun mìíràn tí o bá nílò fún tẹmpili Ọlọ́run rẹ tí ó sì ní láti pèsè, o lè mú u láti inú ìṣúra ọba.
And the residue that shall be needeful for the house of thy God, which shall be meete for thee to bestowe, thou shalt bestowe it out of the Kings treasure house,
21 Èmi, ọba Artasasta, pàṣẹ fún gbogbo olùtọ́jú ilé ìṣúra agbègbè Eufurate láìrójú láti pèsè ohunkóhun tí àlùfáà Esra, olùkọ́ni ní òfin Ọlọ́run ọ̀run bá béèrè lọ́wọ́ yín
And I King Artahshashte haue giuen commandemet to all the treasurers which are beyond the Riuer, that whatsoeuer Ezra the Priest and Scribe of the Law of the God of heauen shall require of you, that it be done incontinently,
22 tó ọgọ́rùn-ún kan tálẹ́ǹtì fàdákà, ọgọ́rùn-ún kan òsùwọ̀n àlìkámà, àti dé ọgọ́rùn-ún bati ọtí wáìnì, àti dé ọgọ́rùn-ún bati òróró olifi, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ iyọ̀.
Vnto an hundreth talents of siluer, vnto an hundreth measures of wheate, and vnto an hundreth baths of wine, and vnto an hundreth baths of oyle, and salt without writing.
23 Ohunkóhun tí Ọlọ́run ọ̀run bá fẹ́, jẹ́ kí ó di ṣíṣe ní pípé fún tẹmpili Ọlọ́run ọ̀run. Èéṣe tí ìbínú yóò ṣe wá sí agbègbè ọba àti sí orí àwọn ọmọ rẹ̀?
Whatsoeuer is by the commandement of the God of heauen, let it be done speedily for the house of the God of heauen: for why should he be wroth against the realme of the King, and his children?
24 Ìwọ sì ní láti mọ̀ pé ìwọ kò ní àṣẹ láti sọ sísan owó orí, owó òde tàbí owó bodè di dandan fún àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà, àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili tàbí àwọn òṣìṣẹ́ mìíràn nínú ilé Ọlọ́run yìí.
And we certifie you, that vpon any of the Priestes, Leuites, singers, porters, Nethinims, or Ministers in this house of God, there shall no gouernour laye vpon them tolle, tribute nor custome.
25 Ìwọ Esra, ní ìbámu pẹ̀lú ọgbọ́n Ọlọ́run rẹ̀, èyí tí ó ní, yan àwọn adájọ́ àgbà àti àwọn onídàájọ́ láti máa ṣe ìdájọ́ fún àwọn ènìyàn agbègbè Eufurate, gbogbo àwọn tí ó mọ òfin Ọlọ́run rẹ. Ìwọ yóò sì kọ́ ẹnikẹ́ni tí kò mọ̀ àwọn òfin náà.
And thou Ezra (after the wisedome of thy God, that is in thine hand) set iudges and arbiters, which may iudge all the people that is beyond the Riuer, euen all that knowe the Lawe of thy God, and teach ye them that know it not.
26 Ẹnikẹ́ni tí kò bá ṣe ìgbọ́ràn sí òfin Ọlọ́run rẹ àti sí òfin ọba ní ó gbọdọ̀ kú tàbí kí a lé e jáde tàbí kí a gbẹ́sẹ̀ lé ẹrù rẹ̀ tàbí kí a sọ ọ́ sínú ẹ̀wọ̀n.
And whosoeuer will not doe the Lawe of thy God, and the Kings lawe, let him haue iudgement without delay, whether it be vnto death, or to banishment, or to confiscation of goods, or to imprisonment.
27 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ẹni tí ó fi sí ọkàn ọba láti mú ọlá wá sí ilé Olúwa ní Jerusalẹmu ní ọ̀nà yìí.
Blessed be the Lord God of our fathers, which so hath put in the Kings heart, to beautifie the house of the Lord that is in Ierusalem,
28 Ẹni tí ó jẹ́ kí ojúrere rẹ̀ tàn kàn mí níwájú ọba àti àwọn olùbádámọ̀ràn àti ní iwájú àwọn alágbára ìjòyè ọba. Nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára mi, mo mú ọkàn le, mo sì kó àwọn olórí jọ láàrín àwọn ènìyàn Israẹli láti gòkè lọ pẹ̀lú mi.
And hath enclined mercy toward me, before the King and his counsellers, and before all the Kings mightie Princes: and I was comforted by the hand of the Lord my God which was vpon me, and I gathered the chiefe of Israel to goe vp with me.