< Ezra 6 >

1 Nígbà náà ni ọba Dariusi pàṣẹ, wọ́n sì wá inú ilé ìfí nǹkan pamọ́ sí ní ilé ìṣúra ní Babeli.
Då befallde Konung Darios, att man söka skulle i cancelliet, uti Konungens skatthus, som i Babel låg.
2 A rí ìwé kíká kan ní Ekbatana ibi kíkó ìwé sí ní ilé olódi agbègbè Media, wọ̀nyí ni ohun tí a kọ sínú rẹ̀. Ìwé ìrántí.
Då fann man i Ahmeta, på det slottet som i Meden ligger, ena bok, och derutinnan var ett sådana ärende beskrifvet:
3 Ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba ọba Kirusi, ọba pa àṣẹ kan nípa tẹmpili Ọlọ́run ní Jerusalẹmu. Jẹ́ kí a tún tẹmpili ibi tí a ti ń rú onírúurú ẹbọ kọ́, kí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ ni gíga àti fífẹ̀ rẹ̀ jẹ́ àádọ́rùn-ún ẹsẹ̀ bàtà,
Uti första årena Konungs Cores befallde Konung Cores uppbygga Guds hus i Jerusalem, på det rum der man offrar, och grundval lägga, till sextio alnars höjd, till bredden ock sextio alnar;
4 pẹ̀lú ipele òkúta ńlá ńlá mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ àti ipele pákó kan, kí a san owó rẹ̀ láti inú ilé ìṣúra ọba.
Och tre väggar af allahanda stenar, och en vägg af trä; och kosten skall gifven varda utaf Konungshuset.
5 Sì jẹ́ kí wúrà àti àwọn ohun èlò fàdákà ti ilé Ọlọ́run, tí Nebukadnessari kó láti ilé Olúwa ní Jerusalẹmu tí ó sì kó lọ sí Babeli, di dídápadà sí ààyè wọn nínú tẹmpili ní Jerusalẹmu; kí a kó wọn sí inú ilé Ọlọ́run.
Dertill de Guds hus gyldene och silfvertyg, som NebucadNezar uti templet i Jerusalem tagit, och till Babel fört hade, skall man igengifva, så att de skola igenförde varda uti templet i Jerusalem, i sitt rum, i Guds hus.
6 Nítorí náà, kí ìwọ, Tatenai baálẹ̀ agbègbè Eufurate àti Ṣetar-bosnai àti àwọn ẹlẹgbẹ́ yín, àwọn ìjòyè ti agbègbè náà kúrò níbẹ̀.
Så farer nu långt ifrå dem, du Thathnai, landshöfdinge hinsidon vid älfven, och SetharBosnai, och deras Råd af Apharsach, som hinsidon älfven ären.
7 Ẹ fi iṣẹ́ ilé Ọlọ́run yìí lọ́rùn sílẹ̀ láì dí i lọ́wọ́. Ẹ jẹ́ kí baálẹ̀ àwọn Júù àti àwọn àgbàgbà Júù tún ilé Ọlọ́run yín kọ́ sí ipò rẹ̀.
Låter dem arbeta på Guds hus, så att Judarnas höfvitsman och deras äldsta måga bygga Guds hus på sitt rum.
8 Síwájú sí i, mo pàṣẹ ohun tí ẹ gbọdọ̀ ṣe fún àwọn àgbàgbà Júù wọ̀nyí lórí kíkọ́ ilé Ọlọ́run yìí. Gbogbo ìnáwó àwọn ọkùnrin yìí ni kí ẹ san lẹ́kùnrẹ́rẹ́ lára ìṣúra ti ọba, láti ibi àkójọpọ̀ owó ìlú ti agbègbè Eufurate kí iṣẹ́ náà má bà dúró.
Är också af mig befaldt, hvad man de äldsta i Juda utfå skall, till att bygga Guds hus, nämliga att man skall fliteliga taga utaf Konungens drätsel, det är, af den ränto hinsidon älfven, och gifva männerna, och att man icke förhindrar dem.
9 Ohunkóhun tí wọ́n bá fẹ́—àwọn ọ̀dọ́ akọ màlúù, àwọn àgbò, ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun sí Ọlọ́run ọ̀run, àti jéró, iyọ̀, wáìnì àti òróró, bí àwọn àlùfáà ní Jerusalẹmu ti béèrè ni ẹ gbọdọ̀ fún wọn lójoojúmọ́ láìyẹ̀.
Och om de behöfva kalfvar, lamb, eller bockar, till bränneoffer till himmelens Gud, hvete, salt, vin och oljo, efter Presternas sed i Jerusalem, skall man dem gifva dagliga hvad de behöfva; och att detta sker oförsummeliga;
10 Kí wọn lè rú àwọn ẹbọ tí ó tẹ́ Ọlọ́run ọ̀run lọ́rùn kí wọ́n sì gbàdúrà fún àlàáfíà ọba àti àwọn ọmọ rẹ̀.
Att de måga offra till en söt lukt Gudi i himmelen, och bedja för Konungens lif, och hans barnas.
11 Síwájú sí i, mo pàṣẹ pé tí ẹnikẹ́ni bá yí àṣẹ yìí padà, kí fa igi àjà ilé rẹ̀ yọ jáde, kí a sì gbe dúró, kí a sì fi òun náà kọ́ sí orí rẹ̀ kí ó wo ilé rẹ̀ palẹ̀ a ó sì sọ ọ́ di ààtàn.
Af mig är denna befallning gifven; och hvilken menniska denna orden förvänder, utaf hans hus skall man taga en bjelka, och resa honom upp, och hängan deruti, och hans hus skall skamliga förstördt varda för den gernings skull.
12 Kí Ọlọ́run, tí ó ti jẹ́ kí orúkọ rẹ̀ máa gbé ibẹ̀, kí ó pa gbogbo ọba àti orílẹ̀-èdè rún tí ó bá gbé ọwọ́ sókè láti yí àṣẹ yìí padà tàbí láti wó tẹmpili yìí tí ó wà ní Jerusalẹmu run. Èmi Dariusi n pàṣẹ rẹ̀, jẹ́ kí ó di mímúṣẹ láìyí ohunkóhun padà.
Och Gud, som hafver låtit sitt namn bo der, förstöre alla Konungar, och folk, som sina hand uträcka, till att förstöra och nederslå Guds hus i Jerusalem; jag Darios hafver detta befallt, att detta skall ock så alldeles fullföljdt varda.
13 Nígbà náà, nítorí àṣẹ tí ọba Dariusi pa, Tatenai, baálẹ̀ ti agbègbè Eufurate, àti Ṣetar-bosnai pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn pa á mọ́ láìyí ọ̀kan padà.
Då gjorde det Thathnai landshöfdingen hinsidon älfven, och SetharBosnai med deras Råd, till hvilka Konung Darios sändt hade, fliteliga.
14 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbàgbà Júù tẹ̀síwájú wọ́n sì ń gbèrú sí i lábẹ́ ìwàásù wòlíì Hagai àti wòlíì Sekariah, ìran Iddo. Wọ́n parí kíkọ́ ilé Olúwa gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Ọlọ́run Israẹli àti àwọn àṣẹ Kirusi, Dariusi àti Artasasta àwọn ọba Persia pọ̀.
Och Judarnas äldste byggde, och det gick för handena, efter den Prophetens Haggai och Zacharia, Iddo sons, Prophetia. Och de byggde, och uppsatte, efter Israels Guds befallning, och efter Cores, Darios och Arthahsasta, Konungarnas i Persien, befallning;
15 A parí ilé Olúwa ní ọjọ́ kẹta, oṣù Addari tí í se oṣù kejì ní ọdún kẹfà ti ìjọba ọba Dariusi.
Och fullkomnade huset, intill tredje dagen i dem månadenom Adar, det var sjette året af Konung Darios rike.
16 Nígbà náà ni àwọn ènìyàn Israẹli—àwọn àlùfáà, àwọn Lefi àti àwọn ìgbèkùn tí ó padà, ṣe ayẹyẹ yíya ilé Ọlọ́run sí mímọ́ pẹ̀lú ayọ̀.
Och Israels barn, Presterna, Leviterna, och de andre fängelsens barnen, höllo Guds hus vigning med glädje;
17 Fún yíya ilé Ọlọ́run yìí sí mímọ́, wọ́n pa ọgọ́rùn-ún akọ màlúù, igba àgbò àti irinwó akọ ọ̀dọ́-àgùntàn, àti gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo Israẹli, àgbò méjìlá, ọ̀kọ̀ọ̀kan fún olúkúlùkù àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Och offrade i Guds hus vigning hundrade kalfvar, tuhundrad lamb, fyrahundrad bockar; och till syndoffer för hela Israel, tolf getabockar, efter slägternas tal i Israel.
18 Wọ́n sì fi àwọn àlùfáà sí àwọn ìpín wọ́n àti àwọn Lefi sì ẹgbẹẹgbẹ́ wọn fún ìsin ti Ọlọ́run ní Jerusalẹmu, gẹ́gẹ́ bí ohun tí a kọ sínú ìwé Mose.
Och de satte Presterna i deras ordning, och Leviterna i deras vakt, till att tjena Gudi, som i Jerusalem är; såsom skrifvet står i Mose bok.
19 Ní ọjọ́ kẹrìnlá ti oṣù Nisani, àwọn tí a kó ní ìgbèkùn ṣe ayẹyẹ àjọ ìrékọjá.
Och fängelsens barn höllo Passah på fjortonde dagen i dem första månadenom.
20 Àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì jẹ́ mímọ́. Àwọn ará Lefi pa ọ̀dọ́-àgùntàn ti àjọ ìrékọjá fún gbogbo àwọn tí a kó ní ìgbèkùn, fún àwọn àlùfáà arákùnrin wọn àti fún ara wọn.
Ty Presterna och Leviterna hade renat sig, så att de alle rene voro, såsom en man; och de slagtade Passah för all fängelsens barn, och för deras bröder Presterna, och för sig.
21 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Israẹli tí ó ti dé láti ìgbèkùn jẹ ẹ́ lápapọ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó ti ya ara wọn kúrò nínú gbogbo iṣẹ́ àìmọ́ ti àwọn kèfèrí aládùúgbò wọn láti wá Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
Och Israels barn, som af fängelsen voro igenkomne, och alle de som sig till dem afskiljt hade ifrå Hedningarnas orenhet i landena, till att söka Herran Israels Gud, åto;
22 Fún ọjọ́ méje, wọ́n ṣe ayẹyẹ àkàrà àìwú pẹ̀lú àjẹtì àkàrà. Nítorí tí Olúwa ti kún wọn pẹ̀lú ayọ̀ nípa yíyí ọkàn ọba Asiria padà, tí ó fi ràn wọ́n lọ́wọ́ lórí iṣẹ́ ilé Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli.
Och höllo osyrade bröds högtid i sju dagar med glädje; förty Herren hade gjort dem glada, och vändt Konungens hjerta af Assur till dem, så att deras händer styrkta vordo i verket på Guds hus, den Israels Gud är.

< Ezra 6 >