< Ezra 6 >

1 Nígbà náà ni ọba Dariusi pàṣẹ, wọ́n sì wá inú ilé ìfí nǹkan pamọ́ sí ní ilé ìṣúra ní Babeli.
Tedy král Darius rozkázal, aby hledali v bibliotéce, mezi poklady složenými v Babyloně.
2 A rí ìwé kíká kan ní Ekbatana ibi kíkó ìwé sí ní ilé olódi agbègbè Media, wọ̀nyí ni ohun tí a kọ sínú rẹ̀. Ìwé ìrántí.
I nalezena jest v Achmeta na hradě, kterýž jest v Médské krajině, jedna kniha, a takto zapsána byla v ní pamět:
3 Ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba ọba Kirusi, ọba pa àṣẹ kan nípa tẹmpili Ọlọ́run ní Jerusalẹmu. Jẹ́ kí a tún tẹmpili ibi tí a ti ń rú onírúurú ẹbọ kọ́, kí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ ni gíga àti fífẹ̀ rẹ̀ jẹ́ àádọ́rùn-ún ẹsẹ̀ bàtà,
Léta prvního Cýra krále Cýrus král rozkázal: Dům Boží, kterýž byl v Jeruzalémě, ať jest v městě staven na místě, kdež se obětují oběti, a grunty jeho ať vzhůru ženou, zvýší loktů šedesáti, a zšíří loktů šedesáti,
4 pẹ̀lú ipele òkúta ńlá ńlá mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ àti ipele pákó kan, kí a san owó rẹ̀ láti inú ilé ìṣúra ọba.
Třmi řady z kamení velikého, a řad z dříví nového, náklad pak z domu královského bude dáván.
5 Sì jẹ́ kí wúrà àti àwọn ohun èlò fàdákà ti ilé Ọlọ́run, tí Nebukadnessari kó láti ilé Olúwa ní Jerusalẹmu tí ó sì kó lọ sí Babeli, di dídápadà sí ààyè wọn nínú tẹmpili ní Jerusalẹmu; kí a kó wọn sí inú ilé Ọlọ́run.
Nadto nádobí domu Božího zlaté i stříbrné, kteréž Nabuchodonozor byl pobral z chrámu, jenž byl v Jeruzalémě, a byl je přenesl do Babylona, ať zase navrátí, aby se dostalo do chrámu Jeruzalémského na místo své, a složeno bylo v domě Božím.
6 Nítorí náà, kí ìwọ, Tatenai baálẹ̀ agbègbè Eufurate àti Ṣetar-bosnai àti àwọn ẹlẹgbẹ́ yín, àwọn ìjòyè ti agbègbè náà kúrò níbẹ̀.
Protož nyní, ty Tattenai, vývodo za řekou, Setarbozenai s tovaryši svými, i Afarsechaiští, kteříž jste za řekou, ustupte odtud.
7 Ẹ fi iṣẹ́ ilé Ọlọ́run yìí lọ́rùn sílẹ̀ láì dí i lọ́wọ́. Ẹ jẹ́ kí baálẹ̀ àwọn Júù àti àwọn àgbàgbà Júù tún ilé Ọlọ́run yín kọ́ sí ipò rẹ̀.
Nechte jich při díle toho domu Božího. Vůdce Židovský a starší jejich nechať ten dům Boží stavějí na místě jeho.
8 Síwájú sí i, mo pàṣẹ ohun tí ẹ gbọdọ̀ ṣe fún àwọn àgbàgbà Júù wọ̀nyí lórí kíkọ́ ilé Ọlọ́run yìí. Gbogbo ìnáwó àwọn ọkùnrin yìí ni kí ẹ san lẹ́kùnrẹ́rẹ́ lára ìṣúra ti ọba, láti ibi àkójọpọ̀ owó ìlú ti agbègbè Eufurate kí iṣẹ́ náà má bà dúró.
Ode mne také poručeno jest o tom, co byste měli činiti s staršími Židovskými při stavení toho domu Božího, totiž, aby z zboží královského, z důchodů, jenž jsou za řekou, bez meškání náklad dáván byl mužům těm, aby dílo nemělo překážky.
9 Ohunkóhun tí wọ́n bá fẹ́—àwọn ọ̀dọ́ akọ màlúù, àwọn àgbò, ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun sí Ọlọ́run ọ̀run, àti jéró, iyọ̀, wáìnì àti òróró, bí àwọn àlùfáà ní Jerusalẹmu ti béèrè ni ẹ gbọdọ̀ fún wọn lójoojúmọ́ láìyẹ̀.
A to, čehož by bylo potřebí, buď volků aneb skopců i beránků k zápalným obětem Boha nebeského, obilé, soli, vína i oleje, jakž by rozkázali kněží Jeruzalémští, nechť se jim dává na každý den, a to beze všeho podvodu,
10 Kí wọn lè rú àwọn ẹbọ tí ó tẹ́ Ọlọ́run ọ̀run lọ́rùn kí wọ́n sì gbàdúrà fún àlàáfíà ọba àti àwọn ọmọ rẹ̀.
Aby měli z čeho obětovati vůni příjemnou Bohu nebeskému, a aby se modlili za život krále i za syny jeho.
11 Síwájú sí i, mo pàṣẹ pé tí ẹnikẹ́ni bá yí àṣẹ yìí padà, kí fa igi àjà ilé rẹ̀ yọ jáde, kí a sì gbe dúró, kí a sì fi òun náà kọ́ sí orí rẹ̀ kí ó wo ilé rẹ̀ palẹ̀ a ó sì sọ ọ́ di ààtàn.
Nadto ode mne jest rozkázáno: Kdož by koli zrušil přikázaní toto, aby vybořeno bylo z domu jeho dřevo, a zdviženo bylo, na němž by oběšen byl, a dům jeho ať jest hnojištěm pro takovou věc.
12 Kí Ọlọ́run, tí ó ti jẹ́ kí orúkọ rẹ̀ máa gbé ibẹ̀, kí ó pa gbogbo ọba àti orílẹ̀-èdè rún tí ó bá gbé ọwọ́ sókè láti yí àṣẹ yìí padà tàbí láti wó tẹmpili yìí tí ó wà ní Jerusalẹmu run. Èmi Dariusi n pàṣẹ rẹ̀, jẹ́ kí ó di mímúṣẹ láìyí ohunkóhun padà.
Bůh pak, jehož jméno tam přebývá, zkaziž všelikého krále i lid, kterýž by vztáhl ruku svou k změnění toho, a zkáze toho domu Božího, jenž jest v Jeruzalémě. Já Darius přikazuji sám, bez meškání ať se stane.
13 Nígbà náà, nítorí àṣẹ tí ọba Dariusi pa, Tatenai, baálẹ̀ ti agbègbè Eufurate, àti Ṣetar-bosnai pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn pa á mọ́ láìyí ọ̀kan padà.
Tedy Tattenai, vývoda za řekou, a Setarbozenai s tovaryši svými vedlé toho, jakž rozkázal Darius král, tak učinili bez meškání.
14 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbàgbà Júù tẹ̀síwájú wọ́n sì ń gbèrú sí i lábẹ́ ìwàásù wòlíì Hagai àti wòlíì Sekariah, ìran Iddo. Wọ́n parí kíkọ́ ilé Olúwa gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Ọlọ́run Israẹli àti àwọn àṣẹ Kirusi, Dariusi àti Artasasta àwọn ọba Persia pọ̀.
I stavěli starší Židovští, a šťastně se jim vedlo vedlé proroctví Aggea proroka, a Zachariáše syna Iddova. Stavěli tedy a dokonali z rozkázaní Boha Izraelského, a z rozkázaní Cýra a Daria, a Artaxerxa krále Perského.
15 A parí ilé Olúwa ní ọjọ́ kẹta, oṣù Addari tí í se oṣù kejì ní ọdún kẹfà ti ìjọba ọba Dariusi.
A dokonán jest ten dům k třetímu dni měsíce Adar, a ten byl rok šestý kralování Daria krále.
16 Nígbà náà ni àwọn ènìyàn Israẹli—àwọn àlùfáà, àwọn Lefi àti àwọn ìgbèkùn tí ó padà, ṣe ayẹyẹ yíya ilé Ọlọ́run sí mímọ́ pẹ̀lú ayọ̀.
Tedy synové Izraelští, kněží a Levítové, i jiní, kteříž byli přišli z převedení, posvětili toho domu Božího s radostí.
17 Fún yíya ilé Ọlọ́run yìí sí mímọ́, wọ́n pa ọgọ́rùn-ún akọ màlúù, igba àgbò àti irinwó akọ ọ̀dọ́-àgùntàn, àti gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo Israẹli, àgbò méjìlá, ọ̀kọ̀ọ̀kan fún olúkúlùkù àwọn ẹ̀yà Israẹli.
A obětovali při posvěcení toho Božího domu sto telat, skopců dvě stě, beránků čtyři sta, a kozlů k oběti za hřích za všecken Izrael dvanáct, vedlé počtu pokolení Izraelského.
18 Wọ́n sì fi àwọn àlùfáà sí àwọn ìpín wọ́n àti àwọn Lefi sì ẹgbẹẹgbẹ́ wọn fún ìsin ti Ọlọ́run ní Jerusalẹmu, gẹ́gẹ́ bí ohun tí a kọ sínú ìwé Mose.
I postavili kněží v třídách jejich, a Levíty v pořádcích jejich při službě Boží v Jeruzalémě, jakož psáno jest v knize Mojžíšově.
19 Ní ọjọ́ kẹrìnlá ti oṣù Nisani, àwọn tí a kó ní ìgbèkùn ṣe ayẹyẹ àjọ ìrékọjá.
Slavili také ti, kteříž se vrátili z přestěhování, velikunoc čtrnáctého dne měsíce prvního.
20 Àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì jẹ́ mímọ́. Àwọn ará Lefi pa ọ̀dọ́-àgùntàn ti àjọ ìrékọjá fún gbogbo àwọn tí a kó ní ìgbèkùn, fún àwọn àlùfáà arákùnrin wọn àti fún ara wọn.
Nebo očistili se byli kněží a Levítové jednomyslně. Všickni čistí byli, a obětovali beránka velikonočního za všecky, jenž zajati byli, i za bratří své kněží, i sami za sebe.
21 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Israẹli tí ó ti dé láti ìgbèkùn jẹ ẹ́ lápapọ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó ti ya ara wọn kúrò nínú gbogbo iṣẹ́ àìmọ́ ti àwọn kèfèrí aládùúgbò wọn láti wá Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
A jedli synové Izraelští, kteříž se byli navrátili z přestěhování, i každý, kdož odděliv se od poškvrnění pohanů země, připojil se k nim, aby hledal Hospodina Boha Izraelského.
22 Fún ọjọ́ méje, wọ́n ṣe ayẹyẹ àkàrà àìwú pẹ̀lú àjẹtì àkàrà. Nítorí tí Olúwa ti kún wọn pẹ̀lú ayọ̀ nípa yíyí ọkàn ọba Asiria padà, tí ó fi ràn wọ́n lọ́wọ́ lórí iṣẹ́ ilé Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli.
Drželi také slavnost přesnic za sedm dní s veselím, proto že je rozveselil Hospodin, a obrátil srdce krále Assyrského k nim, aby jich posilnil v díle domu Božího, Boha Izraelského.

< Ezra 6 >