< Ezra 6 >

1 Nígbà náà ni ọba Dariusi pàṣẹ, wọ́n sì wá inú ilé ìfí nǹkan pamọ́ sí ní ilé ìṣúra ní Babeli.
Amaiba: le, hina bagade Da: liase da ea fidisu dunu ilia eagene meloa dedei Ba: bilone moilai bai bagade amo ganodini dialu, amo hogoma: ne sia: i.
2 A rí ìwé kíká kan ní Ekbatana ibi kíkó ìwé sí ní ilé olódi agbègbè Media, wọ̀nyí ni ohun tí a kọ sínú rẹ̀. Ìwé ìrántí.
Be ilia da Ba: bilone moilai bai bagade amo ganodini amo meloa dedei hame ba: i. Ilia da Egeba: da: na moilai bai bagade (Midia soge amo ganodini dialu) amoga bioi meloa dialebe ba: i. Amo ganodini, sia: amane dedei dialebe ba: i.
3 Ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba ọba Kirusi, ọba pa àṣẹ kan nípa tẹmpili Ọlọ́run ní Jerusalẹmu. Jẹ́ kí a tún tẹmpili ibi tí a ti ń rú onírúurú ẹbọ kọ́, kí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ ni gíga àti fífẹ̀ rẹ̀ jẹ́ àádọ́rùn-ún ẹsẹ̀ bàtà,
“Hina bagade Sailase da ea ode bisili ouligisu hou amoga, ilia da Yelusalemega Debolo diasu gobele salasu hamomusa: bu gaguma: ne sia: i. Amo Debolo gagusia, ea defei da 27 mida sedade defei amola 27 mida ba: de defei gaguma: ne sia: i.
4 pẹ̀lú ipele òkúta ńlá ńlá mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ àti ipele pákó kan, kí a san owó rẹ̀ láti inú ilé ìṣúra ọba.
E da Debolo dobea agoane gaguma: ne sia: i. Igi dada: lesu udiana hagudu legele bu ifa dada: lesu afae legema. Hawa: hamosu liligi amo bidi lasu muni huluane Besia eagene ilia fawane da imunu.
5 Sì jẹ́ kí wúrà àti àwọn ohun èlò fàdákà ti ilé Ọlọ́run, tí Nebukadnessari kó láti ilé Olúwa ní Jerusalẹmu tí ó sì kó lọ sí Babeli, di dídápadà sí ààyè wọn nínú tẹmpili ní Jerusalẹmu; kí a kó wọn sí inú ilé Ọlọ́run.
Amola gouli amola silifa ofodo, amo musa: Nebiuga: denese da Yelusaleme Debolo diasuga lale, Ba: bilone moilai bai bagadega gaguli asi, amo huluane ilia da amo liligi ea sogebidafa Yelusaleme Debolo amoga bu gaguli masa!” ilia da Sailase ea sia: agoane dedei dialebe ba: i.
6 Nítorí náà, kí ìwọ, Tatenai baálẹ̀ agbègbè Eufurate àti Ṣetar-bosnai àti àwọn ẹlẹgbẹ́ yín, àwọn ìjòyè ti agbègbè náà kúrò níbẹ̀.
Amalalu, Da: liase da Yu dunuma sia: adole iasi, “Na da dili, Da: denai (Iufala: idisi Hano Guma: dini soge eagene ouligisu dunu), Sisabosinai amola dilia na: iyado ouligisu dunu Guma: dini Iufala: idisi soge ganodini esala, dilima meloa dedesa. ‘Debolo diasu gadenene maedafa masa.
7 Ẹ fi iṣẹ́ ilé Ọlọ́run yìí lọ́rùn sílẹ̀ láì dí i lọ́wọ́. Ẹ jẹ́ kí baálẹ̀ àwọn Júù àti àwọn àgbàgbà Júù tún ilé Ọlọ́run yín kọ́ sí ipò rẹ̀.
Amola, Debolo gagusu hou mae migelema. Yuda eagene ouligisu dunu amola Yu fi ouligisu dunu da Gode Ea Debolo diasu amo ea musa: sogebi amoga bu gagumu da defea.
8 Síwájú sí i, mo pàṣẹ ohun tí ẹ gbọdọ̀ ṣe fún àwọn àgbàgbà Júù wọ̀nyí lórí kíkọ́ ilé Ọlọ́run yìí. Gbogbo ìnáwó àwọn ọkùnrin yìí ni kí ẹ san lẹ́kùnrẹ́rẹ́ lára ìṣúra ti ọba, láti ibi àkójọpọ̀ owó ìlú ti agbègbè Eufurate kí iṣẹ́ náà má bà dúró.
Dilia amo dunu Debolo bu gaguma: ne fidima. Amo hawa: hamosu da mae yolele hedolo hehenane hawa: hamoma: ne, ilima muni amo ninia eagene muni Guma: dini Iufala: idisi sogega laha amo ilima hedolo ima.
9 Ohunkóhun tí wọ́n bá fẹ́—àwọn ọ̀dọ́ akọ màlúù, àwọn àgbò, ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun sí Ọlọ́run ọ̀run, àti jéró, iyọ̀, wáìnì àti òróró, bí àwọn àlùfáà ní Jerusalẹmu ti béèrè ni ẹ gbọdọ̀ fún wọn lójoojúmọ́ láìyẹ̀.
Eso huluane, mae fisili, dilia Yelusaleme gobele salasu dunu, ilia hanai dilima adolalu, amo defele ilima ima. Amo da bulamagau mano gawali o sibi o sibi mano Hebene Godema gobele salimusa: o widi o deme o waini o olife susuligi.
10 Kí wọn lè rú àwọn ẹbọ tí ó tẹ́ Ọlọ́run ọ̀run lọ́rùn kí wọ́n sì gbàdúrà fún àlàáfíà ọba àti àwọn ọmọ rẹ̀.
Yu dunu da Hebene Gode Ema gobele salasu Ea hanai defele Ema hamomusa: amola Gode da na amola na dunu mano hahawane dogolegele fidima: ne, ilia da Ema nodone sia: ne gadoma: ne, agoane hamoma.
11 Síwájú sí i, mo pàṣẹ pé tí ẹnikẹ́ni bá yí àṣẹ yìí padà, kí fa igi àjà ilé rẹ̀ yọ jáde, kí a sì gbe dúró, kí a sì fi òun náà kọ́ sí orí rẹ̀ kí ó wo ilé rẹ̀ palẹ̀ a ó sì sọ ọ́ di ààtàn.
Na da sia: eno sia: sa. Nowa dunu da amo sia: hame nabasea, dilia ifa ea diasuga dialu fadegale fasili, amalu agesone, amalu amo dunu ea da: i hagomoa soma. Amola ea diasu go da isu salasu hamoma.
12 Kí Ọlọ́run, tí ó ti jẹ́ kí orúkọ rẹ̀ máa gbé ibẹ̀, kí ó pa gbogbo ọba àti orílẹ̀-èdè rún tí ó bá gbé ọwọ́ sókè láti yí àṣẹ yìí padà tàbí láti wó tẹmpili yìí tí ó wà ní Jerusalẹmu run. Èmi Dariusi n pàṣẹ rẹ̀, jẹ́ kí ó di mímúṣẹ láìyí ohunkóhun padà.
Gode da osobo bagade dunu ilia Ema nodone sia: ne gadoma: ne, Yelusaleme moilai bai bagade amo ilegei dagoi. Amaiba: le, nowa dunu da na sia: dedei amo hame nabasea, o Debolo diasu wadela: musa: dawa: sea, Gode da amo dunu wadela: mu da defea. Na, Da: liase da amo sia: sia: iba: le, dilia amo sia: amoma noga: le fa: no bobogema.’”
13 Nígbà náà, nítorí àṣẹ tí ọba Dariusi pa, Tatenai, baálẹ̀ ti agbègbè Eufurate, àti Ṣetar-bosnai pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn pa á mọ́ láìyí ọ̀kan padà.
Amalalu, Da: denai (eagene hina dunu), Sidabosinai amola ela na: iyado ouligisu dunu, ilia da Da: liase ea sia: defele hamoi.
14 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbàgbà Júù tẹ̀síwájú wọ́n sì ń gbèrú sí i lábẹ́ ìwàásù wòlíì Hagai àti wòlíì Sekariah, ìran Iddo. Wọ́n parí kíkọ́ ilé Olúwa gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Ọlọ́run Israẹli àti àwọn àṣẹ Kirusi, Dariusi àti Artasasta àwọn ọba Persia pọ̀.
Yu ouligisu dunu da Debolo diasu gagusu hehenane hawa: hamonanu. Balofede dunu Ha: ga: iai amola Segalia da ilia dogo denesima: ne fidisu. Amalalu, Isala: ili Gode amola Besia hina bagade dunu udiana amo Sailase, Da: liase amola Adasegesisi, ilia hamoma: ne sia: i defele, Debolo diasu da gagui dagoi ba: i.
15 A parí ilé Olúwa ní ọjọ́ kẹta, oṣù Addari tí í se oṣù kejì ní ọdún kẹfà ti ìjọba ọba Dariusi.
Eso udiana amo oubi ea dio amo Ada, amoga, ilia Debolo diasu gaguli dagoi. Amo ode da Da: liase ea Ba: bilone soge ouligisu ode gafeyale gidigi.
16 Nígbà náà ni àwọn ènìyàn Israẹli—àwọn àlùfáà, àwọn Lefi àti àwọn ìgbèkùn tí ó padà, ṣe ayẹyẹ yíya ilé Ọlọ́run sí mímọ́ pẹ̀lú ayọ̀.
Amalalu, Isala: ili dunu huluane, amo gobele salasu dunu, Lifai dunu amola mugululi asi buhagi dunu huluane da hahawane bagade Debolo diasu Godema sia: ne gadosu hamomusa: , modale ligiagale doasi.
17 Fún yíya ilé Ọlọ́run yìí sí mímọ́, wọ́n pa ọgọ́rùn-ún akọ màlúù, igba àgbò àti irinwó akọ ọ̀dọ́-àgùntàn, àti gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo Israẹli, àgbò méjìlá, ọ̀kọ̀ọ̀kan fún olúkúlùkù àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Amo hou hamoma: ne, ilia da bulamagau 100 agoane, sibi 200 agoane amola sibi mano 400 agoane, gobele salasu hamoma: ne iasu. Amola, Wadela: i Hou Gogolema: ne Olofoma: ne Iasu da goudi fagoyale gala. Amo da goudi afae da Isala: ili fi afae hi gagaia gaguli iasu.
18 Wọ́n sì fi àwọn àlùfáà sí àwọn ìpín wọ́n àti àwọn Lefi sì ẹgbẹẹgbẹ́ wọn fún ìsin ti Ọlọ́run ní Jerusalẹmu, gẹ́gẹ́ bí ohun tí a kọ sínú ìwé Mose.
Amola Mousese ea sema buga ganodini dedei defele, ilia gobele salasu dunu amola Lifai dunu ilima Debolo ouligisu hou Yelusaleme amo ganodini olelei.
19 Ní ọjọ́ kẹrìnlá ti oṣù Nisani, àwọn tí a kó ní ìgbèkùn ṣe ayẹyẹ àjọ ìrékọjá.
Mugululi asi buhagi dunu da eso14 oubi age amoga, amola ode ageyadu amoga ilia da buhagi - amo esoga ilia da Baligisu Lolo mai.
20 Àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì jẹ́ mímọ́. Àwọn ará Lefi pa ọ̀dọ́-àgùntàn ti àjọ ìrékọjá fún gbogbo àwọn tí a kó ní ìgbèkùn, fún àwọn àlùfáà arákùnrin wọn àti fún ara wọn.
Gobele salasu dunu amola Lifai dunu da ilia ledo huluane dodofei amola ilia sema defele ledo hame agoai ba: i. Amola Lifai dunu da ilisu, gobele salasu dunu amola dunu huluane da mugululi asili buhagi, amo huluane ilia gobele salasu hamoma: ne, ohe fi medole legei.
21 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Israẹli tí ó ti dé láti ìgbèkùn jẹ ẹ́ lápapọ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó ti ya ara wọn kúrò nínú gbogbo iṣẹ́ àìmọ́ ti àwọn kèfèrí aládùúgbò wọn láti wá Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
Isala: ili dunu mugululi asi buhagi dunu amola musa: Gode Ea hou hame lalegagui ilia da dunu Isala: ili soge amo ganodini esalu amo ilia musa: hou fisili, Isala: ili Hina Godema nodone sia: ne gadomusa: sinidigi, amo dunu huluane da gobele salasu ha: i manu nasu.
22 Fún ọjọ́ méje, wọ́n ṣe ayẹyẹ àkàrà àìwú pẹ̀lú àjẹtì àkàrà. Nítorí tí Olúwa ti kún wọn pẹ̀lú ayọ̀ nípa yíyí ọkàn ọba Asiria padà, tí ó fi ràn wọ́n lọ́wọ́ lórí iṣẹ́ ilé Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli.
Eso fesuale amoga, ilia da Agi Yisidi Hame Sali Lolo Nabe hahawane hamosu. Hina Gode da fidibiba: le, Asilia hina bagade da ilima asigiba: le, e da ilia Isala: ili Gode Ea Debolo amo bu buga: le gagusu hou fidisu. Amaiba: le, Isala: ili dunu da hahawane bagade ba: i.

< Ezra 6 >