< Ezra 5 >

1 Nígbà náà wòlíì Hagai àti wòlíì Sekariah, láti ìran Iddo, sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí àwọn ará Júù ní Juda àti Jerusalẹmu ní orúkọ Ọlọ́run Israẹli tí ẹ̀mí rẹ̀ ń bẹ lára wọn.
Na rĩrĩ, mũnabii Hagai, na mũnabii Zekaria wa rũciaro rwa Ido, nĩmarathĩire Ayahudi a kũu Juda na Jerusalemu thĩinĩ wa rĩĩtwa rĩa Ngai wa Isiraeli, mũgitĩri wao.
2 Nígbà náà Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli àti Jeṣua ọmọ Josadaki gbáradì fún iṣẹ́ àti tún ilé Ọlọ́run ní Jerusalẹmu kọ́. Àwọn wòlíì Ọlọ́run sì wà pẹ̀lú wọn, tí wọ́n ń ràn wọ́n lọ́wọ́.
Hĩndĩ ĩyo Zerubabeli mũrũ wa Shealitieli, na Jeshua mũrũ wa Jozadaku makĩambĩrĩria wĩra wa gwaka rĩngĩ nyũmba ya Ngai kũu Jerusalemu, na anabii a Ngai maarĩ hamwe nao makĩmateithia.
3 Ní àkókò náà Tatenai, baálẹ̀ ti agbègbè Eufurate àti Ṣetar-bosnai àti àwọn ẹgbẹgbẹ́ wọn lọ sí ọ̀dọ̀ wọn. Wọ́n sì béèrè pé, “Ta ni ó fún un yín ní àṣẹ láti tún tẹmpili yìí kọ́ àti láti tún odi yìí mọ?”
Ihinda rĩu Tatenai, barũthi wa Mũrĩmo-wa-Farati, na Shetharu-Bozenai, hamwe na athiritũ ao magĩthiĩ kũrĩ o, makĩmooria atĩrĩ, “Nũũ wamũheire rũtha rwa gwaka rĩngĩ hekarũ ĩno na gũcookereria mwako ũyũ?”
4 Wọ́n sì tún béèrè pé, “Kí ni orúkọ àwọn ọkùnrin tí ó ń kọ́ ilé yìí?”
Ningĩ makĩũria atĩrĩ, “Andũ arĩa maraaka nyũmba ĩno metagwo atĩa?”
5 Ṣùgbọ́n ojú Ọlọ́run wọn wà lára àwọn àgbàgbà Júù, wọn kò sì dá wọn dúró títí ìròyìn yóò fi dè ọ̀dọ̀ Dariusi kí wọ́n sì gba èsì tí àkọsílẹ̀ láti ọ̀dọ̀ rẹ̀.
No rĩrĩ, Ngai nĩaroraga athuuri acio a Ayahudi, na matiatigithirio wĩra nginya ũhoro ũkinyĩrio Dario, na marũa ma macookio make maamũkĩrwo.
6 Èyí ni ẹ̀dà lẹ́tà tí Tatenai, olórí agbègbè Eufurate àti Ṣetar-bosnai àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn. Àwọn olóyè ti agbègbè Eufurate, fi ránṣẹ́ sí ọba Dariusi.
Ĩno nĩyo kobi ya marũa marĩa maatũmĩirwo Mũthamaki Dario nĩ Tatenai ũrĩa warĩ barũthi wa Mũrĩmo-wa-Farati, marĩ na Shetharu-Bozenai na athiritũ ao, arĩa maarĩ anene a Mũrĩmo-wa-Farati.
7 Ìròyìn tí wọ́n fi ránṣẹ́ sí i kà báyìí pé, Sí ọba Dariusi, Àlàáfíà fún un yín.
Ũhoro ũrĩa maamũtũmĩire watariĩ ũũ: Kũrĩ Mũthamaki Dario: Ngeithi cia thayũ.
8 Kí ọba kí ó mọ̀ pé a lọ sí ẹ̀kún Juda, sí tẹmpili Ọlọ́run tí ó tóbi. Àwọn ènìyàn náà ń kọ́ ọ pẹ̀lú àwọn òkúta ńlá ńlá àti pẹ̀lú fífi àwọn igi sí ara ògiri. Wọ́n ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú àìsimi, ó sì ń ní ìtẹ̀síwájú kíákíá lábẹ́ ìṣàkóso wọn.
Nĩ wega mũthamaki amenye atĩ ithuĩ nĩtwathiire rũgongo rwa Juda, kũu hekarũ-inĩ ya Ngai ũrĩa mũnene. Andũ acio nĩmaraaka hekarũ na mahiga manene, o na magekĩra mbaũ rũthingo-inĩ. Wĩra nĩũrarutwo na kĩyo, na nĩũrathiĩ na mbere mũno ũrĩ moko-inĩ ma arĩa maraũruta.
9 A bi àwọn àgbàgbà, a sì fi ọ̀rọ̀ wá wọn lẹ́nu wò pé, “Ta ni ó fún un yín ní àṣẹ láti tún ilé Olúwa yìí kọ́ àti láti tún odi rẹ̀ mọ?”
Tuoririe athuuri acio atĩrĩ, “Nũũ wamũheire rũtha rwa gwaka rĩngĩ hekarũ ĩno na gũcookereria mwako ũyũ?”
10 A sì tún béèrè orúkọ wọn pẹ̀lú, kí a lè kọ àwọn orúkọ àwọn olórí wọn sílẹ̀ kí ẹ ba à le mọ ọ́n.
Ningĩ nĩtwamoririe marĩĩtwa mao, nĩgeetha twandĩke marĩĩtwa ma atongoria ao, nĩguo tũkũmenyithie.
11 Èyí ni ìdáhùn tí wọ́n fún wa: “Àwa ni ìránṣẹ́ Ọlọ́run ọ̀run àti ayé, àwa sì ń tún tẹmpili ilé Olúwa tí a ti kọ́ ní ọ̀pọ̀ ọdún sẹ́yìn kọ́, èyí tí ọba olókìkí kan ní Israẹli kọ́, tí ó sì parí i rẹ̀.
Ũũ nĩguo maatũcokeirie: “Ithuĩ tũrĩ ndungata cia Ngai wa igũrũ na thĩ, na tũraaka rĩngĩ hekarũ ĩrĩa yakĩtwo mĩaka mĩingĩ mĩthiru, ĩrĩa yakĩtwo na ĩkarĩkio nĩ mũthamaki mũnene wa Isiraeli.
12 Ṣùgbọ́n nítorí tí àwọn baba wa mú Ọlọ́run ọ̀run bínú, ó fi wọ́n lé Nebukadnessari ti Kaldea, ọba Babeli lọ́wọ́, ẹni tí ó run tẹmpili Olúwa yìí tí ó sì kó àwọn ènìyàn náà padà sí Babeli.
No tondũ maithe maitũ nĩmarakaririe Ngai wa igũrũ, nĩamaneanire kũrĩ Nebukadinezaru ũrĩa Mũkalidei, mũthamaki wa Babuloni, ũrĩa wamomorire hekarũ ĩno na agĩthaamĩria andũ bũrũri wa Babuloni.
13 “Ṣùgbọ́n ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba Kirusi ọba Babeli, ọba Kirusi pàṣẹ pé kí a tún ilé Ọlọ́run yìí kọ́.
“No rĩrĩ, mwaka wa mbere wa Kurusu mũthamaki wa Babuloni, mũthamaki nĩathanire atĩ nyũmba ĩno ya Ngai yakwo rĩngĩ.
14 Òun tilẹ̀ kò jáde láti inú tẹmpili ní Babeli fàdákà àti ohun èlò wúrà ilé Ọlọ́run, èyí tí Nebukadnessari kó láti inú tẹmpili ní Jerusalẹmu wá sí inú tẹmpili ní Babeli. Ọba Kirusi kó wọn fún ọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Ṣeṣbassari, ẹni tí ó ti yàn gẹ́gẹ́ bí i baálẹ̀,
O na nĩarutire kuuma hekarũ ĩrĩa yarĩ Babuloni indo cia thahabu na cia betha cia nyũmba ya Ngai, iria Nebukadinezaru aarutĩte hekarũ-inĩ kũu Jerusalemu, agĩcitwara hekarũ-inĩ kũu Babuloni. “Nake Mũthamaki Kurusu agĩcineana kũrĩ mũndũ wetagwo Sheshibazaru, ũrĩa aatuĩte barũthi,
15 ó sì sọ fún un pé, ‘Kó àwọn ohun èlò yìí kí o lọ, kí o sì kó wọn sí inú ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, kí ẹ sì tún ilé Ọlọ́run kọ́ sí ipò o rẹ̀.’
na akĩmwĩra atĩrĩ, ‘Oya indo ici ũcitware na ũciige thĩinĩ wa hekarũ kũu Jerusalemu, na wake rĩngĩ nyũmba ya Ngai o harĩa yarĩ.’
16 “Nígbà náà ni Ṣeṣbassari náà wá, ó sí fi ìpìlẹ̀ ilé Ọlọ́run tí ó wá ní Jerusalẹmu lélẹ̀, láti ìgbà náà àní títí di ìsinsin yìí ni o ti n bẹ ní kíkọ́ ṣùgbọ́n, kò sí tí ì parí tán.”
Nĩ ũndũ ũcio Sheshibazaru agĩũka agĩaka mũthingi wa nyũmba ya Ngai kũu Jerusalemu. Kuuma mwaka ũcio nginya ũmũthĩ mwako ũcio no ũthiiaga na mbere na ndũrĩ warĩĩka.”
17 Nísinsin yìí tí ó bá tẹ́ ọba lọ́rùn, ẹ jẹ́ kí a ṣe ìwádìí nínú ìwé ìrántí ní ilé ìṣúra ọba ní Babeli láti rí bí ọba Kirusi fi àṣẹ lélẹ̀ lóòótọ́ láti tún ilé Ọlọ́run yìí kọ́ ní Jerusalẹmu. Nígbà náà jẹ́ kí ọba kó fi ìpinnu rẹ̀ lórí ọ̀rọ̀ yìí ránṣẹ́ sí wa.
Na rĩrĩ, mũthamaki angĩona kwagĩrĩire-rĩ, nĩgũtuĩrio maandĩko-inĩ ma ũthamaki ma tene ma Babuloni, kuoneke kana Mũthamaki Kurusu ti-itherũ nĩarutĩte watho wa gwaka rĩngĩ nyũmba ĩno ya Ngai gũkũ Jerusalemu. Ningĩ reke mũthamaki atũtũmĩre itua rĩake ũhoro-inĩ ũcio.

< Ezra 5 >