< Ezra 4 >
1 Nígbà tí àwọn ọ̀tá Juda àti Benjamini gbọ́ wí pé àwọn ìgbèkùn tí ó padà dé ń kọ́ tẹmpili fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli,
Agora quando os adversários de Judá e Benjamim ouviram que os filhos do cativeiro estavam construindo um templo para Javé, o Deus de Israel,
2 wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Serubbabeli àti sí ọ̀dọ̀ àwọn olórí àwọn ìdílé, wọ́n sì wí pé, “Jẹ́ kí a bá a yín kọ́ nítorí pé, bí i tiyín, a ń wá Ọlọ́run yín, a sì ti ń rú ẹbọ sí i láti ìgbà Esarhadoni ọba Asiria, tí ó mú wa wá sí ibi yìí.”
eles se aproximaram de Zorobabel, e dos chefes de família dos pais, e lhes disseram: “Construamos com vocês, pois buscamos seu Deus como vocês; e temos feito sacrifícios a ele desde os dias de Esar Haddon, rei da Assíria, que nos trouxe até aqui”.
3 Ṣùgbọ́n Serubbabeli, Jeṣua àti ìyókù àwọn olórí àwọn ìdílé Israẹli dáhùn pé, “Ẹ kò ní ohunkóhun pẹ̀lú wa ní kíkọ́ ilé fún Ọlọ́run wa. Àwa nìkan yóò kọ́ ọ fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, bí Kirusi, ọba Persia, ti pàṣẹ fún wa.”
Mas Zerubabel, Jeshua e os demais chefes de família dos pais de Israel lhes disseram: “Vocês não têm nada a ver conosco na construção de uma casa para nosso Deus; mas nós mesmos juntos construiremos para Javé, o Deus de Israel, como nos ordenou o rei Ciro, o rei da Pérsia”.
4 Nígbà náà ni àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà mú ọwọ́ àwọn ènìyàn Juda rọ, wọ́n sì dẹ́rùbà wọ́n ní ti kíkọ́ ilé náà.
Então o povo da terra enfraqueceu as mãos do povo de Judá, e os perturbou na construção.
5 Wọ́n gba àwọn olùdámọ̀ràn láti ṣiṣẹ́ lòdì sí wọn àti láti sọ ète wọn di asán ní gbogbo àsìkò ìjọba Kirusi ọba Persia àti títí dé ìgbà ìjọba Dariusi ọba Persia.
Contrataram conselheiros contra eles para frustrar seu propósito durante todos os dias de Ciro, rei da Pérsia, mesmo até o reinado de Dario, rei da Pérsia.
6 Ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Ahaswerusi wọ́n fi ẹ̀sùn kan àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu.
No reinado de Assuero, no início de seu reinado, eles escreveram uma acusação contra os habitantes de Judá e Jerusalém.
7 Àti ní àkókò ìjọba Artasasta ọba Persia, Biṣilami, Mitredati, Tabeli àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ yòókù kọ̀wé sí Artasasta. A kọ ìwé náà ní ìlànà ìkọ̀wé Aramaiki èdè Aramaiki sì ní a fi kọ ọ́.
Nos dias de Artaxerxes, Bishlam, Mithredath, Tabeel e o resto de seus companheiros escreveram a Artaxerxes rei da Pérsia; e a redação da carta foi escrita em sírio e entregue na língua síria.
8 Rehumu balógun àti Ṣimṣai akọ̀wé jùmọ̀ kọ́ ìwé láti dojúkọ Jerusalẹmu sí Artasasta ọba báyìí:
Reum o chanceler e Shimshai o escriba escreveram uma carta contra Jerusalém para Artaxerxes, o rei, como se segue.
9 Rehumu balógun àti Ṣimṣai akọ̀wé, pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn tókù—àwọn ará Dina, ti Afarsatki, ti Tarpeli, ti Afarsi, Ereki àti Babeli, àwọn ará Elamu ti Susa,
Então Rehum o chanceler, Shimshai o escriba, e o resto de seus companheiros, os dinaítas, e os afarsatitas, os tarpelitas, os afarsitas, os arqueólogos, os babilônios, os shushanchitas, os dehaítas, os elamitas,
10 pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn tí ẹni ọlá àti ẹni ọ̀wọ̀ Asnappari kó jáde, tí ó sì tẹ̀ wọ́n dó sí ìlú Samaria àti níbòmíràn ní agbègbè e Eufurate.
e o resto das nações que o grande e nobre Osnappar trouxe e estabeleceu na cidade de Samaria, e no resto do país além do rio, e assim por diante, escreveu.
11 (Èyí ni ẹ̀dà ìwé tí wọ́n fi ránṣẹ́ sí i.) Sí ọba Artasasta, láti ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọkùnrin agbègbè Eufurate.
Esta é a cópia da carta que eles enviaram: Ao Rei Artaxerxes, de seus servos, o povo além do rio.
12 Ọba gbọdọ̀ mọ̀ pé àwọn ará Júù tí ó gòkè wá sọ́dọ̀ wa láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ti lọ sí Jerusalẹmu wọ́n sì ń tún ìlú búburú àti ìlú ọlọ̀tẹ̀ ẹ nì kọ́. Wọ́n ń tún àwọn ògiri náà kọ́, wọ́n sì ń tún àwọn ìpìlẹ̀ náà ṣe.
Seja conhecido do rei que os judeus que vieram de você vieram até nós em Jerusalém. Eles estão construindo a cidade rebelde e má, e terminaram os muros e consertaram as fundações.
13 Síwájú sí i, ọba gbọdọ̀ mọ̀ pé tí a bá kọ́ ìlú yìí àti tí a sì tún àwọn ògiri rẹ̀ mọ, kò sí owó orí, owó òde tàbí owó ibodè tí a ó san, owó tí ó sì ń wọlé fún ọba yóò sì dínkù.
Seja agora conhecido do rei que se esta cidade for construída e os muros terminados, eles não pagarão tributo, costume ou pedágio, e no final será prejudicial para os reis.
14 Nísinsin yìí níwọ̀n ìgbà tí a ní ojúṣe sí ààfin ọba, kò sì bójúmu fún wa láti rí ìtàbùkù ọba, àwa ń rán iṣẹ́ yìí láti sọ fún ọba,
Agora porque comemos o sal do palácio e não é apropriado para nós ver a desonra do rei, por isso enviamos e informamos ao rei,
15 kí a bá a lè ṣe ìwádìí ní inú ìwé ìrántí àwọn aṣíwájú rẹ̀. Nínú ìwé ìrántí wọn yìí, ìwọ yóò rí i wí pé, ìlú yìí jẹ́ ìlú aṣọ̀tẹ̀, oníwàhálà sí àwọn ọba àti àwọn ìgbèríko, ibi ìṣọ̀tẹ̀ láti ìgbà àtijọ́. Ìdí ni èyí tí a ṣe pa ìlú yìí run.
que a busca pode ser feita no livro dos registros de seus pais. Você verá no livro dos registros, e saberá que esta cidade é uma cidade rebelde, e prejudicial para os reis e províncias, e que eles iniciaram rebeliões dentro dela no passado. É por isso que esta cidade foi destruída.
16 A fi dá ọba lójú wí pé tí a bá tún ìlú kọ́ àti ti àwọn ògiri rẹ̀ si di mímọ padà, kì yóò sì ohun ti yóò kù ọ́ kù ní agbègbè Eufurate.
Informamos ao rei que se esta cidade for construída e as muralhas terminarem, então não terá posse além do rio. '
17 Ọba fi èsì yìí ránṣẹ́ padà. Sí Rehumu balógun, Ṣimṣai akọ̀wé àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn yòókù tí ń gbé ní Samaria àti ní òpópónà Eufurate. Ìkíni.
Então o rei enviou uma resposta para Rehum, o chanceler, e para Shimshai, o escriba, e para o resto de seus companheiros que vivem em Samaria, e no resto do país além do rio: Paz.
18 A ti ka ìwé tí ẹ fi ránṣẹ́ sí wa, a sì ti túmọ̀ rẹ̀ níwájú mi.
A carta que você nos enviou foi lida claramente antes de mim.
19 Mo pa àṣẹ, a sì ṣe ìwádìí, nínú ìtàn ọjọ́ pípẹ́ àti ti ìsinsin yìí ti ìṣọ̀tẹ̀ sí àwọn ọba pẹ̀lú, ó sì jẹ́ ibi ìṣọ̀tẹ̀ àti ìrúkèrúdò.
Decidi, e a pesquisa foi feita, e foi descoberto que esta cidade fez insurreição contra reis no passado, e que rebeliões e revoltas foram feitas nela.
20 Jerusalẹmu ti ní àwọn ọba alágbára tí ń jẹ ọba lórí gbogbo àwọn agbègbè Eufurate, àti àwọn owó orí, owó òde àti owó ibodè sì ni wọ́n ń san fún wọn.
There também foram poderosos reis sobre Jerusalém, que governaram todo o país além do rio; e tributo, costumes e pedágio foram pagos a eles.
21 Nísinsin yìí pa àṣẹ fún àwọn ọkùnrin yìí láti dá iṣẹ́ dúró, kí a má ṣe tún ìlú náà kọ títí èmi yóò fi pàṣẹ.
Faça agora um decreto para fazer cessar estes homens, e que esta cidade não seja construída até que um decreto seja feito por mim.
22 Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe àìkọbi-ara sí ọ̀rọ̀ yìí. Èéṣe tí ìbàjẹ́ yóò fi pọ̀ sí i, sí ìpalára àwọn ọba?
Tenha cuidado para não ser descuidado ao fazê-lo. Por que os danos devem crescer para a ferida dos reis? '
23 Ní kété tí a ka ẹ̀dà ìwé ọba Artasasta sí Rehumu àti Ṣimṣai akọ̀wé àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn, wọ́n yára lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn Júù ní Jerusalẹmu pẹ̀lú, wọ́n fi agbára mú wọn láti dáwọ́ dúró.
Então, quando a cópia da carta do rei Artaxerxes foi lida antes de Rehum, Shimshai o escriba, e seus companheiros, eles foram apressados a Jerusalém para os judeus, e os obrigaram a cessar pela força das armas.
24 Báyìí, iṣẹ́ lórí ilé Ọlọ́run ní Jerusalẹmu wá sí ìdúró jẹ́ẹ́ títí di ọdún kejì ìjọba Dariusi ọba Persia.
Em seguida, os trabalhos pararam na casa de Deus que fica em Jerusalém. Parou até o segundo ano do reinado de Dario, rei da Pérsia.