< Ezra 4 >
1 Nígbà tí àwọn ọ̀tá Juda àti Benjamini gbọ́ wí pé àwọn ìgbèkùn tí ó padà dé ń kọ́ tẹmpili fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli,
Na rĩrĩ, hĩndĩ ĩrĩa thũ cia Juda na Benjamini ciaiguire atĩ andũ arĩa maatahĩtwo nĩmaakagĩra Jehova, Ngai wa Isiraeli, hekarũ-rĩ,
2 wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Serubbabeli àti sí ọ̀dọ̀ àwọn olórí àwọn ìdílé, wọ́n sì wí pé, “Jẹ́ kí a bá a yín kọ́ nítorí pé, bí i tiyín, a ń wá Ọlọ́run yín, a sì ti ń rú ẹbọ sí i láti ìgbà Esarhadoni ọba Asiria, tí ó mú wa wá sí ibi yìí.”
magĩthiĩ kũrĩ Zerubabeli o na kũrĩ atongoria a nyũmba cia andũ, makĩmeera atĩrĩ, “Rekei twake tũrĩ hamwe tondũ o na ithuĩ tũrongoragia Ngai wanyu, na nĩtũkoretwo tũkĩmũrutĩra magongona kuuma hĩndĩ ya Esari-Hadoni mũthamaki wa Ashuri, ũrĩa watũrehire gũkũ.”
3 Ṣùgbọ́n Serubbabeli, Jeṣua àti ìyókù àwọn olórí àwọn ìdílé Israẹli dáhùn pé, “Ẹ kò ní ohunkóhun pẹ̀lú wa ní kíkọ́ ilé fún Ọlọ́run wa. Àwa nìkan yóò kọ́ ọ fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, bí Kirusi, ọba Persia, ti pàṣẹ fún wa.”
No rĩrĩ, Zerubabeli, na Jeshua, na atongoria arĩa angĩ a nyũmba cia Isiraeli makĩmacookeria atĩrĩ, “Mũtirĩ na handũ thĩinĩ witũ ũhoro-inĩ wa gwakĩra Ngai witũ hekarũ. Nĩ ithuĩ ene tũgwakĩra Jehova, Ngai wa Isiraeli, o ta ũrĩa Kurusu mũthamaki wa Perisia aatwathire.”
4 Nígbà náà ni àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà mú ọwọ́ àwọn ènìyàn Juda rọ, wọ́n sì dẹ́rùbà wọ́n ní ti kíkọ́ ilé náà.
Hĩndĩ ĩyo andũ arĩa maamathiũrũrũkĩirie makĩhaarĩria kũũraga andũ a Juda ngoro nĩguo metigĩre gũthiĩ na mbere na gwaka.
5 Wọ́n gba àwọn olùdámọ̀ràn láti ṣiṣẹ́ lòdì sí wọn àti láti sọ ète wọn di asán ní gbogbo àsìkò ìjọba Kirusi ọba Persia àti títí dé ìgbà ìjọba Dariusi ọba Persia.
Nao makĩandĩka ataarani a kũhĩngĩca wĩra wao, na gũthũkia mĩbango yao yothe matukũ mothe ma wathani wa Kurusu mũthamaki wa Perisia, nginya hĩndĩ ya wathani wa Dario mũthamaki wa Perisia.
6 Ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Ahaswerusi wọ́n fi ẹ̀sùn kan àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu.
Kĩambĩrĩria kĩa wathani wa Ahasuerusu, ataarani acio magĩthitanga andũ a Juda na Jerusalemu.
7 Àti ní àkókò ìjọba Artasasta ọba Persia, Biṣilami, Mitredati, Tabeli àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ yòókù kọ̀wé sí Artasasta. A kọ ìwé náà ní ìlànà ìkọ̀wé Aramaiki èdè Aramaiki sì ní a fi kọ ọ́.
Na matukũ ma Mũthamaki Aritashashita wa Perisia, na Bishilamu, na Mithiredathu, na Tabeeli na andũ arĩa angĩ a thiritũ yake makĩandĩkĩra Aritashashita marũa. Marũa macio maandĩkirwo na mwandĩkĩre na rũthiomi rwa andũ a Suriata.
8 Rehumu balógun àti Ṣimṣai akọ̀wé jùmọ̀ kọ́ ìwé láti dojúkọ Jerusalẹmu sí Artasasta ọba báyìí:
Rehumu mũnene wa mbũtũ na Shimushai ũrĩa mwandĩki, nĩmandĩkire marũa ma gũthitanga andũ a Jerusalemu kũrĩ Mũthamaki Aritashashita ta ũũ:
9 Rehumu balógun àti Ṣimṣai akọ̀wé, pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn tókù—àwọn ará Dina, ti Afarsatki, ti Tarpeli, ti Afarsi, Ereki àti Babeli, àwọn ará Elamu ti Susa,
Marũa maya moimĩte kũrĩ niĩ Rehumu mũnene wa mbũtũ, na Shimushai ũrĩa mwandĩki, hamwe na arĩa angĩ a thiritũ yao, na aciirithania, na anene a andũ a Ataripeli, na a Perisia, na a Ereku, na Babuloni, na Aelami a Shushani,
10 pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn tí ẹni ọlá àti ẹni ọ̀wọ̀ Asnappari kó jáde, tí ó sì tẹ̀ wọ́n dó sí ìlú Samaria àti níbòmíràn ní agbègbè e Eufurate.
na andũ arĩa angĩ maacooketio nĩ mũgaathe ũrĩa mũnene Osinapari nĩgeetha matũũre itũũra inene rĩa Samaria, na kũrĩa kũngĩ guothe Mũrĩmo-wa-Farati.
11 (Èyí ni ẹ̀dà ìwé tí wọ́n fi ránṣẹ́ sí i.) Sí ọba Artasasta, láti ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọkùnrin agbègbè Eufurate.
(Ĩno nĩyo kobi ya marũa marĩa aandĩkĩirwo.) Kũrĩ Mũthamaki Aritashashita, Kuuma kũrĩ ndungata ciaku, andũ a bũrũri ũrĩa ũrĩ Mũrĩmo-wa-Farati:
12 Ọba gbọdọ̀ mọ̀ pé àwọn ará Júù tí ó gòkè wá sọ́dọ̀ wa láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ti lọ sí Jerusalẹmu wọ́n sì ń tún ìlú búburú àti ìlú ọlọ̀tẹ̀ ẹ nì kọ́. Wọ́n ń tún àwọn ògiri náà kọ́, wọ́n sì ń tún àwọn ìpìlẹ̀ náà ṣe.
Nĩ kwagĩrĩire mũthamaki amenye atĩ, Ayahudi arĩa mookire kũrĩ ithuĩ moimĩte kũrĩ we nĩmathiĩte Jerusalemu, na nĩmaraaka rĩngĩ itũũra rĩu inene, o rĩu iremi na rĩaganu. Nĩmaracookereria rũthingo na magacookereria mĩthingi.
13 Síwájú sí i, ọba gbọdọ̀ mọ̀ pé tí a bá kọ́ ìlú yìí àti tí a sì tún àwọn ògiri rẹ̀ mọ, kò sí owó orí, owó òde tàbí owó ibodè tí a ó san, owó tí ó sì ń wọlé fún ọba yóò sì dínkù.
Ningĩ nĩ kwagĩrĩire mũthamaki amenye atĩ itũũra rĩĩrĩ inene rĩngĩakwo na thingo ciarĩo icookererio, gũtirĩ igooti, kana maruta ma mũthamaki, o na kana igooti rĩa mĩrigo ĩgĩtoonya bũrũri-inĩ rĩrĩrutagwo. Nakĩo kĩgĩĩna kĩa ũthamaki nĩgĩkũnyiiha.
14 Nísinsin yìí níwọ̀n ìgbà tí a ní ojúṣe sí ààfin ọba, kò sì bójúmu fún wa láti rí ìtàbùkù ọba, àwa ń rán iṣẹ́ yìí láti sọ fún ọba,
Na rĩu tondũ ithuĩ tũrĩ andũ matĩĩte ũthamaki, na ti wega kuona mũthamaki akĩimwo gĩtĩĩo, tũratũma ndũmĩrĩri ĩno tũmenyithie mũthamaki,
15 kí a bá a lè ṣe ìwádìí ní inú ìwé ìrántí àwọn aṣíwájú rẹ̀. Nínú ìwé ìrántí wọn yìí, ìwọ yóò rí i wí pé, ìlú yìí jẹ́ ìlú aṣọ̀tẹ̀, oníwàhálà sí àwọn ọba àti àwọn ìgbèríko, ibi ìṣọ̀tẹ̀ láti ìgbà àtijọ́. Ìdí ni èyí tí a ṣe pa ìlú yìí run.
nĩgeetha ũhoro ũcio ũtuĩrio kuuma maandĩko-inĩ ma tene ma arĩa maarĩ mbere yaku. Maandĩko-inĩ macio nĩũrĩona atĩ itũũra rĩĩrĩ inene nĩ iremi, na rĩa gũthĩĩnia athamaki na mabũrũri, na nĩ kũndũ kwa ũremi kuuma mahinda ma tene. Kĩu nĩkĩo gĩatũmire itũũra rĩĩrĩ inene rĩanangwo.
16 A fi dá ọba lójú wí pé tí a bá tún ìlú kọ́ àti ti àwọn ògiri rẹ̀ si di mímọ padà, kì yóò sì ohun ti yóò kù ọ́ kù ní agbègbè Eufurate.
Tũkũmenyithia mũthamaki atĩ itũũra rĩĩrĩ inene rĩngĩakwo na thingo ciarĩo icookererio, wee ũgũtigwo ũtarĩ kĩndũ Mũrĩmo ũyũ wa Rũũĩ rwa Farati.
17 Ọba fi èsì yìí ránṣẹ́ padà. Sí Rehumu balógun, Ṣimṣai akọ̀wé àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn yòókù tí ń gbé ní Samaria àti ní òpópónà Eufurate. Ìkíni.
Mũthamaki nake agĩcookia macookio atĩrĩ: Kũrĩ Rehumu mũnene wa mbũtũ, na Shimushai ũrĩa mwandĩki, na andũ arĩa angĩ a thiritũ yao arĩa matũũraga Samaria na kũrĩa kũngĩ guothe Mũrĩmo-wa-Farati: Nĩndamũgeithia.
18 A ti ka ìwé tí ẹ fi ránṣẹ́ sí wa, a sì ti túmọ̀ rẹ̀ níwájú mi.
Marũa marĩa mwatũtũmĩire nĩmathomeirwo hau mbere yakwa na ngĩtaũrĩrwo ũhoro wamo.
19 Mo pa àṣẹ, a sì ṣe ìwádìí, nínú ìtàn ọjọ́ pípẹ́ àti ti ìsinsin yìí ti ìṣọ̀tẹ̀ sí àwọn ọba pẹ̀lú, ó sì jẹ́ ibi ìṣọ̀tẹ̀ àti ìrúkèrúdò.
Nĩndarutire watho na ũhoro ũcio ũgĩtuĩrio, na gũkĩoneka atĩ itũũra rĩĩrĩ inene nĩrĩũĩkaine kuuma tene atĩ nĩ rĩa kũregana na watho wa athamaki, na rĩtũũraga rĩrĩ iremi, na nĩ rĩa kũringĩrĩria andũ mookĩrĩre thirikari.
20 Jerusalẹmu ti ní àwọn ọba alágbára tí ń jẹ ọba lórí gbogbo àwọn agbègbè Eufurate, àti àwọn owó orí, owó òde àti owó ibodè sì ni wọ́n ń san fún wọn.
Jerusalemu nĩrĩkoretwo na athamaki a hinya magĩathana Mũrĩmo-wa-Farati wothe, na nĩmarĩhagwo igooti na maruta ma mũthamaki, o na igooti rĩa mĩrigo ĩgĩtoonya bũrũri-inĩ.
21 Nísinsin yìí pa àṣẹ fún àwọn ọkùnrin yìí láti dá iṣẹ́ dúró, kí a má ṣe tún ìlú náà kọ títí èmi yóò fi pàṣẹ.
Na rĩrĩ, ruta watho kũrĩ andũ acio matige wĩra, nĩguo itũũra rĩu inene rĩtigaakwo rĩngĩ, nginya rĩrĩa ngoiga.
22 Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe àìkọbi-ara sí ọ̀rọ̀ yìí. Èéṣe tí ìbàjẹ́ yóò fi pọ̀ sí i, sí ìpalára àwọn ọba?
Menyerera ũndũ ũyũ ndũkaage kũhingio. Mũngĩrekereria ũndũ ũngĩrehe ũgwati na ũthũkie ũthamaki nĩkĩ?
23 Ní kété tí a ka ẹ̀dà ìwé ọba Artasasta sí Rehumu àti Ṣimṣai akọ̀wé àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn, wọ́n yára lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn Júù ní Jerusalẹmu pẹ̀lú, wọ́n fi agbára mú wọn láti dáwọ́ dúró.
Na rĩrĩ, kobi ya marũa ma Mũthamaki Aritashashita maarĩkia gũthomerwo Rehumu na Shimushai ũrĩa mwandĩki, na andũ a thiritũ yao, no gũthiĩ mathiire Jerusalemu kũrĩ Ayahudi, na makĩmatigithia wĩra ũcio na hinya.
24 Báyìí, iṣẹ́ lórí ilé Ọlọ́run ní Jerusalẹmu wá sí ìdúró jẹ́ẹ́ títí di ọdún kejì ìjọba Dariusi ọba Persia.
Nĩ ũndũ ũcio, wĩra wa gwaka nyũmba ya Ngai kũu Jerusalemu ũkĩrũgama nginya mwaka wa keerĩ wa wathani wa Dario mũthamaki wa Perisia.