< Ezra 4 >

1 Nígbà tí àwọn ọ̀tá Juda àti Benjamini gbọ́ wí pé àwọn ìgbèkùn tí ó padà dé ń kọ́ tẹmpili fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli,
Now when the adversaries of Judah and Benjamin heard that the children of the exile were building the temple unto the Lord the God of Israel:
2 wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Serubbabeli àti sí ọ̀dọ̀ àwọn olórí àwọn ìdílé, wọ́n sì wí pé, “Jẹ́ kí a bá a yín kọ́ nítorí pé, bí i tiyín, a ń wá Ọlọ́run yín, a sì ti ń rú ẹbọ sí i láti ìgbà Esarhadoni ọba Asiria, tí ó mú wa wá sí ibi yìí.”
Then came they near to Zerubbabel, and to the chiefs of the divisions, and said unto them, Let us build with you; for like you will we seek your God; and unto him do we sacrifice since the days of Essar-chaddon the king of Asshur, who hath brought us up hither.
3 Ṣùgbọ́n Serubbabeli, Jeṣua àti ìyókù àwọn olórí àwọn ìdílé Israẹli dáhùn pé, “Ẹ kò ní ohunkóhun pẹ̀lú wa ní kíkọ́ ilé fún Ọlọ́run wa. Àwa nìkan yóò kọ́ ọ fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, bí Kirusi, ọba Persia, ti pàṣẹ fún wa.”
But Zerubbabel, and Jeshua', and the rest of the of the divisions of Israel, said unto them, It is not obligatory on you and on us to build a house unto our God; but we ourselves together must build unto the Lord the God of Israel, as king Cyrus the king of Persia hath commanded us.
4 Nígbà náà ni àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà mú ọwọ́ àwọn ènìyàn Juda rọ, wọ́n sì dẹ́rùbà wọ́n ní ti kíkọ́ ilé náà.
Then did the people of the land weaken the hands of the people of Judah, and frightened them off from building;
5 Wọ́n gba àwọn olùdámọ̀ràn láti ṣiṣẹ́ lòdì sí wọn àti láti sọ ète wọn di asán ní gbogbo àsìkò ìjọba Kirusi ọba Persia àti títí dé ìgbà ìjọba Dariusi ọba Persia.
And they hired against them counsellors, to frustrate their purpose, all the days of Cyrus the king of Persia, and even until the reign of Darius the king of Persia.
6 Ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Ahaswerusi wọ́n fi ẹ̀sùn kan àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu.
And in the reign of Achashverosh, in the beginning of his reign they wrote an accusation against the inhabitants of Judah and Jerusalem.
7 Àti ní àkókò ìjọba Artasasta ọba Persia, Biṣilami, Mitredati, Tabeli àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ yòókù kọ̀wé sí Artasasta. A kọ ìwé náà ní ìlànà ìkọ̀wé Aramaiki èdè Aramaiki sì ní a fi kọ ọ́.
And in the days of Artaxerxes wrote Bishlam, Mithredath, Tabeel, and the rest of their companions, unto Artaxerxes the king of Persia: and the writing of the letter was written in Aramic, and interpreted in Aramic.
8 Rehumu balógun àti Ṣimṣai akọ̀wé jùmọ̀ kọ́ ìwé láti dojúkọ Jerusalẹmu sí Artasasta ọba báyìí:
Rechum the counsellor and Shimshai the scribe wrote a certain letter against Jerusalem to Artaxerxes the king, as followeth:
9 Rehumu balógun àti Ṣimṣai akọ̀wé, pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn tókù—àwọn ará Dina, ti Afarsatki, ti Tarpeli, ti Afarsi, Ereki àti Babeli, àwọn ará Elamu ti Susa,
Then [wrote] Rechum the counsellor, and Shimshai the scribe, and the rest of their companions, from Din, and Apharsathach, Tarpel, Apharass, Erech, Babylon, Shushan, Dehav, and 'Elam,
10 pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn tí ẹni ọlá àti ẹni ọ̀wọ̀ Asnappari kó jáde, tí ó sì tẹ̀ wọ́n dó sí ìlú Samaria àti níbòmíràn ní agbègbè e Eufurate.
And the rest of the nations whom the great and honored Assnapper had brought into exile, and settled in the cities of Samaria, and the rest that are on this side the river, and so forth.
11 (Èyí ni ẹ̀dà ìwé tí wọ́n fi ránṣẹ́ sí i.) Sí ọba Artasasta, láti ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọkùnrin agbègbè Eufurate.
This is the copy of the letter which they sent unto him, even unto king Artaxerxes: Thy servants the men on this side the river, and so forth.
12 Ọba gbọdọ̀ mọ̀ pé àwọn ará Júù tí ó gòkè wá sọ́dọ̀ wa láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ti lọ sí Jerusalẹmu wọ́n sì ń tún ìlú búburú àti ìlú ọlọ̀tẹ̀ ẹ nì kọ́. Wọ́n ń tún àwọn ògiri náà kọ́, wọ́n sì ń tún àwọn ìpìlẹ̀ náà ṣe.
Be it made known unto the king, that the Jews who removed away from thee are come up to us unto Jerusalem: they are building the rebellious and the bad city, and are completing the walls, and are joining together the foundations.
13 Síwájú sí i, ọba gbọdọ̀ mọ̀ pé tí a bá kọ́ ìlú yìí àti tí a sì tún àwọn ògiri rẹ̀ mọ, kò sí owó orí, owó òde tàbí owó ibodè tí a ó san, owó tí ó sì ń wọlé fún ọba yóò sì dínkù.
Be it now known unto the king, that, if this city be rebuilt, and the walls be completed, they will not give tax, tribute, and toll, and the royal revenues will suffer damage.
14 Nísinsin yìí níwọ̀n ìgbà tí a ní ojúṣe sí ààfin ọba, kò sì bójúmu fún wa láti rí ìtàbùkù ọba, àwa ń rán iṣẹ́ yìí láti sọ fún ọba,
Now because we eat the salt of the palace, and it is not proper for us to see the king's dishonor, therefore have we sent and let the king know this:
15 kí a bá a lè ṣe ìwádìí ní inú ìwé ìrántí àwọn aṣíwájú rẹ̀. Nínú ìwé ìrántí wọn yìí, ìwọ yóò rí i wí pé, ìlú yìí jẹ́ ìlú aṣọ̀tẹ̀, oníwàhálà sí àwọn ọba àti àwọn ìgbèríko, ibi ìṣọ̀tẹ̀ láti ìgbà àtijọ́. Ìdí ni èyí tí a ṣe pa ìlú yìí run.
That search may be made in the book of the memorable events of thy fathers, and thou wilt find in the book of the memorable events, and know that this city is a rebellious city, and hurtful unto kings and provinces, and that they have practised sedition within the same from the most ancient time; for which cause this city was destroyed.
16 A fi dá ọba lójú wí pé tí a bá tún ìlú kọ́ àti ti àwọn ògiri rẹ̀ si di mímọ padà, kì yóò sì ohun ti yóò kù ọ́ kù ní agbègbè Eufurate.
We let the king know that, if this city be rebuilt, and its walls be completed, by this means thou wilt have no more any portion on this side of the river.
17 Ọba fi èsì yìí ránṣẹ́ padà. Sí Rehumu balógun, Ṣimṣai akọ̀wé àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn yòókù tí ń gbé ní Samaria àti ní òpópónà Eufurate. Ìkíni.
Then sent the king a reply unto Rechum the counsellor, and to Shimshai the scribe, and to the rest of their companions that dwell in Samaria, and unto the rest of those beyond the river, Peace, and so forth.
18 A ti ka ìwé tí ẹ fi ránṣẹ́ sí wa, a sì ti túmọ̀ rẹ̀ níwájú mi.
The letter which ye have sent unto us hath been plainly read before me.
19 Mo pa àṣẹ, a sì ṣe ìwádìí, nínú ìtàn ọjọ́ pípẹ́ àti ti ìsinsin yìí ti ìṣọ̀tẹ̀ sí àwọn ọba pẹ̀lú, ó sì jẹ́ ibi ìṣọ̀tẹ̀ àti ìrúkèrúdò.
And an order was given by me, and search was made, and it was found that this city from the most ancient time hath lifted itself up against kings, and that rebellion and sedition have been practised therein.
20 Jerusalẹmu ti ní àwọn ọba alágbára tí ń jẹ ọba lórí gbogbo àwọn agbègbè Eufurate, àti àwọn owó orí, owó òde àti owó ibodè sì ni wọ́n ń san fún wọn.
And that mighty kings have been over Jerusalem, who ruled over all the countries beyond the river; and that tax, tribute, and toll was given unto them.
21 Nísinsin yìí pa àṣẹ fún àwọn ọkùnrin yìí láti dá iṣẹ́ dúró, kí a má ṣe tún ìlú náà kọ títí èmi yóò fi pàṣẹ.
Now give ye the order to stop these men, and this city shall not be built, until the order be given from me.
22 Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe àìkọbi-ara sí ọ̀rọ̀ yìí. Èéṣe tí ìbàjẹ́ yóò fi pọ̀ sí i, sí ìpalára àwọn ọba?
Take heed now that ye commit no error in this: that not any injury may grow [out of this] to the damage of the kings.
23 Ní kété tí a ka ẹ̀dà ìwé ọba Artasasta sí Rehumu àti Ṣimṣai akọ̀wé àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn, wọ́n yára lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn Júù ní Jerusalẹmu pẹ̀lú, wọ́n fi agbára mú wọn láti dáwọ́ dúró.
Thereupon so soon as the copy of king Artaxerxes' letter was read before Rechum, and Shimshai the scribe, and their companions, they did go up in haste to Jerusalem unto the Jews, and stopped them by force and power.
24 Báyìí, iṣẹ́ lórí ilé Ọlọ́run ní Jerusalẹmu wá sí ìdúró jẹ́ẹ́ títí di ọdún kejì ìjọba Dariusi ọba Persia.
Then was stopped the work of the house of God which is at Jerusalem, and it remained interrupted until the second year of the reign of Darius the king of Persia.

< Ezra 4 >