< Ezra 3 >

1 Nígbà tí ó di oṣù keje tí àwọn ọmọ Israẹli sì ti wà nínú àwọn ìlú wọn, àwọn ènìyàn péjọpọ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹnìkan ní Jerusalẹmu.
Da den syvende måned kom, og Israels barn bodde i sine byer, samlet folket sig som en mann i Jerusalem.
2 Nígbà náà ni Jeṣua ọmọ Josadaki àti àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli àti àwọn ènìyàn rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí ní kọ́ pẹpẹ Ọlọ́run Israẹli láti rú ẹbọ sísun níbẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìlànà tí a ti kọ sínú ìwé òfin Mose ènìyàn Ọlọ́run.
Og Josva, Josadaks sønn, og hans brødre prestene og Serubabel, Sealtiels sønn, og hans brødre tok til å bygge alteret for Israels Gud for å ofre brennoffere på det, som skrevet står i den Guds mann Moses' lov.
3 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ẹ̀rù àwọn ènìyàn tí ó yí wọn ká ń bà wọ́n síbẹ̀, wọ́n kọ́ pẹpẹ sórí ìpìlẹ̀ rẹ̀, wọ́n sì rú ẹbọ sísun lórí rẹ̀ sí Olúwa, ọrẹ àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́.
De reiste alteret på dets gamle sted, for det var kommet en redsel over dem for de folk som bodde i bygdene rundt omkring; og de ofret på det brennoffere til Herren, både morgen- og aften-brennoffere.
4 Nígbà náà ní ìbámu pẹ̀lú ohun tí a kọ, wọ́n ṣe àjọ àgọ́ ìpàdé pẹ̀lú iye ẹbọ sísun tí a fi lélẹ̀ fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan.
Så holdt de løvsalenes fest, således som det er foreskrevet, og ofret brennoffer hver dag efter det fastsatte tall og på lovbefalt måte, hver dag de offer som var foreskrevet for den dag.
5 Lẹ́yìn náà, wọ́n ṣe ìrúbọ ẹbọ sísun àtìgbàdégbà, ẹbọ oṣù tuntun àti gbogbo àwọn ẹbọ fún gbogbo àpèjẹ tí a yà sọ́tọ̀ fún Olúwa, àti àwọn tí a mú wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ àtinúwá fún Olúwa.
Siden ofret de det daglige brennoffer og de offer som hørte til nymånedagene og alle Herrens hellige høitider, og likeledes hver gang nogen kom med et frivillig offer til Herren.
6 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù keje, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ní rú ẹbọ sísun sí Olúwa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a kò ì tí ì fi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa lélẹ̀.
Fra den første dag i den syvende måned begynte de å ofre brennoffere til Herren, før ennu grunnvollen til Herrens tempel var lagt.
7 Nígbà náà ni wọ́n fún àwọn ọ̀mọ̀lé àti àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà ní owó, wọ́n sì tún fi oúnjẹ, ohun mímu àti òróró fún àwọn ará Sidoni àti Tire, kí wọ́n ba à le è kó igi kedari gba ti orí omi Òkun láti Lebanoni wá sí Joppa, gẹ́gẹ́ bí Kirusi ọba Persia ti pàṣẹ.
Så gav de penger til stenhuggerne og tømmermennene og mat og drikke og olje til sidonierne og tyrierne forat de skulde føre sedertømmer fra Libanon sjøveien til Joppe, efter den fullmakt som kongen i Persia Kyros hadde gitt dem.
8 Ní oṣù kejì ọdún kejì lẹ́yìn tí wọ́n ti padà dé sí ilé Ọlọ́run ní Jerusalẹmu, Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Jeṣua ọmọ Josadaki àti àwọn arákùnrin yòókù (àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi àti gbogbo àwọn tí ó ti ìgbèkùn dé sí Jerusalẹmu) bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ náà. Wọ́n sì yan àwọn ọmọ Lefi tí ó tó ọmọ-ogun ọdún sókè láti máa bojútó kíkọ́ ilé Olúwa.
I det annet år efterat de var kommet til Guds hus i Jerusalem i den annen måned, tok de fatt på verket, Serubabel, Sealtiels sønn, og Josva, Josadaks sønn, med deres andre brødre, prestene og levittene, og alle de som fra fangenskapet var kommet til Jerusalem. De satte levittene fra tyveårsalderen og opover til å føre tilsyn med arbeidet på Herrens hus.
9 Jeṣua àti àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ àti Kadmieli àti àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn ọmọ Juda (àwọn ìran Hodafiah) àti àwọn ọmọ Henadadi àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn arákùnrin wọn—gbogbo ará Lefi—parapọ̀ láti bojútó àwọn òṣìṣẹ́ náà tí wọ́n ń ṣiṣẹ́ lórí í kíkọ́ ilé Ọlọ́run.
Og Josva med sine sønner og brødre og Kadmiel med sine sønner, Hodavjas efterkommere, stod alle som én og hadde tilsyn med dem som utførte arbeidet på Guds hus; og det samme gjorde Henadads efterkommere med sine sønner og brødre, som også hørte til levittene.
10 Nígbà tí àwọn ọ̀mọ̀lé gbé ìpìlẹ̀ ilé Olúwa kalẹ̀, àwọn àlùfáà nínú aṣọ iṣẹ́ àlùfáà wọn pẹ̀lú fèrè, àti àwọn ará Lefi (àwọn ọmọ Asafu) pẹ̀lú símbálì, dúró ní ipò wọn láti yin Olúwa, bí Dafidi ọba Israẹli ti fi lélẹ̀.
Og da bygningsmennene la grunnvollen til Herrens tempel, blev prestene stilt op i embedsskrud med trompeter, og de levitter som var Asafs efterkommere, med cymbler, for å prise Herren, således som Israels konge David hadde foreskrevet.
11 Pẹ̀lú ìyìn àti ọpẹ́ ni wọ́n kọrin sí Olúwa: “Ó dára; ìfẹ́ rẹ̀ sí Israẹli dúró títí láé.” Gbogbo àwọn ènìyàn sì fi ohùn ariwo ńlá yin Olúwa, nítorí tí a ti fi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa lélẹ̀.
Og de sang Herrens lov og pris, fordi han er god, og hans miskunnhet mot Israel varer evindelig; og alt folket brøt ut i et stort fryderop og priste Herren fordi grunnvollen var lagt til Herrens hus.
12 Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ lára àwọn àgbà àlùfáà àti àwọn ará Lefi àti àwọn olórí ìdílé, tí ó ti rí tẹmpili Olúwa ti tẹ́lẹ̀, wọ́n sọkún kíkorò nígbà tí wọ́n rí ìpìlẹ̀ tẹmpili Olúwa yìí tí wọ́n fi lélẹ̀, nígbà tí ọ̀pọ̀ kígbe fún ayọ̀.
Men mange av prestene og levittene og familiehodene - de gamle som hadde sett det første hus, gråt høit da de så dette hus bli grunnlagt, mens mange jublet høit av glede.
13 Kò sí ẹni tí ó le mọ ìyàtọ̀ láàrín igbe ayọ̀ àti ẹkún, nítorí tí ariwo àwọn ènìyàn náà pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́. Wọ́n sì gbọ́ igbe náà ní ọ̀nà jíjìn réré.
Folket kunde ikke skjelne lyden av gledesjubelen fra lyden av folkets gråt; for folket jublet så høit at det hørtes lang vei.

< Ezra 3 >