< Ezra 3 >
1 Nígbà tí ó di oṣù keje tí àwọn ọmọ Israẹli sì ti wà nínú àwọn ìlú wọn, àwọn ènìyàn péjọpọ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹnìkan ní Jerusalẹmu.
Ie tsatoke ty volam-paha-fito naho fa an-drova’ iareo añe o ana’ Israeleo, le hene nifanontoñe hoe ondaty raike e Ierosalaime ao.
2 Nígbà náà ni Jeṣua ọmọ Josadaki àti àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli àti àwọn ènìyàn rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí ní kọ́ pẹpẹ Ọlọ́run Israẹli láti rú ẹbọ sísun níbẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìlànà tí a ti kọ sínú ìwé òfin Mose ènìyàn Ọlọ́run.
Nitroatse amy zao t’Iesoà ana’ Iotsadake naho o rahalahi’e mpisoroñeo naho i Zerobabele, ana’ i Sealtiele naho o rahalahi’eo vaho nitsene ty kitrelin’ Añahare hañengàñe soroñe ty amy sinokitse amy Hà’ i Mose ‘ndatin’ Añaharey.
3 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ẹ̀rù àwọn ènìyàn tí ó yí wọn ká ń bà wọ́n síbẹ̀, wọ́n kọ́ pẹpẹ sórí ìpìlẹ̀ rẹ̀, wọ́n sì rú ẹbọ sísun lórí rẹ̀ sí Olúwa, ọrẹ àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́.
Natobò’ iereo amo tombo’eo i kitreliy ie nihembañ’ am’ondati’ o fifeheañeo; le nañenga soroñe ama’e amy Iehovà, soroñe maraiñe naho hariva.
4 Nígbà náà ní ìbámu pẹ̀lú ohun tí a kọ, wọ́n ṣe àjọ àgọ́ ìpàdé pẹ̀lú iye ẹbọ sísun tí a fi lélẹ̀ fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan.
Le nambena’ iareo i sabadida-kibohotsey, ty amy pinatetsey naho nañenga soroñe boak’ andro ty amy ia’e nafetsey, ty amy fañè’ey, songa ty amy lili’ i andro’ey;
5 Lẹ́yìn náà, wọ́n ṣe ìrúbọ ẹbọ sísun àtìgbàdégbà, ẹbọ oṣù tuntun àti gbogbo àwọn ẹbọ fún gbogbo àpèjẹ tí a yà sọ́tọ̀ fún Olúwa, àti àwọn tí a mú wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ àtinúwá fún Olúwa.
tovo izay o soroñe nainai’eo naho o soroñe am-pea-bolañeo naho amo andro namantaña’ Iehovà naho navaheñeo, vaho songa nañenga an-tsatrin’ arofo am’ Iehovà ze nazoto.
6 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù keje, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ní rú ẹbọ sísun sí Olúwa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a kò ì tí ì fi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa lélẹ̀.
Boak’ amy andro valoha’ i volam-pahafitoiy ty namotora’ iareo nañenga soroñe am’ Iehovà; fe mboe tsy nioreñe ty mananta’ i anjomba’ Iehovày.
7 Nígbà náà ni wọ́n fún àwọn ọ̀mọ̀lé àti àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà ní owó, wọ́n sì tún fi oúnjẹ, ohun mímu àti òróró fún àwọn ará Sidoni àti Tire, kí wọ́n ba à le è kó igi kedari gba ti orí omi Òkun láti Lebanoni wá sí Joppa, gẹ́gẹ́ bí Kirusi ọba Persia ti pàṣẹ.
Tinolo iareo drala ka o mpihali-vatoo naho o mpandranjio; naho mahakama naho rano naho menak’ amo nte-Tsioneo vaho amo nte-Tsoreo, hañendesañe hatae boake Lebanone mb’ andriake mb’e Iopà añe, amy tolotse niazo’ iareo amy Korese, mpanjaka’ i Parasey.
8 Ní oṣù kejì ọdún kejì lẹ́yìn tí wọ́n ti padà dé sí ilé Ọlọ́run ní Jerusalẹmu, Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Jeṣua ọmọ Josadaki àti àwọn arákùnrin yòókù (àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi àti gbogbo àwọn tí ó ti ìgbèkùn dé sí Jerusalẹmu) bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ náà. Wọ́n sì yan àwọn ọmọ Lefi tí ó tó ọmọ-ogun ọdún sókè láti máa bojútó kíkọ́ ilé Olúwa.
Ie amy taom-paha-roe nivotraha’ iareo añ’ anjomban’ Añahare e Ierosalaimey; amy volam-paharoe’ey ty niorota’ i Zerobabele ana’ i Sealtiele naho Iesoa ana’ Iotsadake naho o sehangan-droahalahi’e mpisoroñe naho nte-Levy boak’ am-pandrohizañe añe nimb’e Ierosalaime mb’eoo, ie nanendre o nte-Levio mifototse ami’ty roapolo taoñe mañambone, ty hamototse ty fitoloñañe añ’ anjomba’ Iehovà ao.
9 Jeṣua àti àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ àti Kadmieli àti àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn ọmọ Juda (àwọn ìran Hodafiah) àti àwọn ọmọ Henadadi àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn arákùnrin wọn—gbogbo ará Lefi—parapọ̀ láti bojútó àwọn òṣìṣẹ́ náà tí wọ́n ń ṣiṣẹ́ lórí í kíkọ́ ilé Ọlọ́run.
Niharo niongak’ amy zao t’Iesoa naho o ana’eo naho o rahalahi’eo naho i Kadmiele naho o ana’eo vaho o ana’ Iehodào, hisary o mpitoloñe añ’ anjomban’ Añahareo; teo ka o ana’ i Kenadadeo naho o ana’iareoo vaho o rahalahi’e nte-Levio.
10 Nígbà tí àwọn ọ̀mọ̀lé gbé ìpìlẹ̀ ilé Olúwa kalẹ̀, àwọn àlùfáà nínú aṣọ iṣẹ́ àlùfáà wọn pẹ̀lú fèrè, àti àwọn ará Lefi (àwọn ọmọ Asafu) pẹ̀lú símbálì, dúró ní ipò wọn láti yin Olúwa, bí Dafidi ọba Israẹli ti fi lélẹ̀.
Aa ie naore’ o mpandranjio o mananta’ i anjomba’ Iehovàio, le nampijohañeñe eo an-tsaro’e reketse trompetra o mpisoroñeo naho o nte-Levy ana’ i Asafeo am-pikorintsañe, hisabo am’ Iehovà ty amy fanoroa’ i Davide mpanjaka’ Israeley.
11 Pẹ̀lú ìyìn àti ọpẹ́ ni wọ́n kọrin sí Olúwa: “Ó dára; ìfẹ́ rẹ̀ sí Israẹli dúró títí láé.” Gbogbo àwọn ènìyàn sì fi ohùn ariwo ńlá yin Olúwa, nítorí tí a ti fi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa lélẹ̀.
Le nitakasy iereo, nandrenge naho nañandriañe Iehovà: ami’ty hoe: Ie ro Soa, nainai’e ty fiferenaiña’e am’Israele. Le nandia-taroba am-pàzake ondaty iabio, nandrenge Iehovà ami’ty fañoreñañe o manatan’ anjomba’ Iehovào.
12 Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ lára àwọn àgbà àlùfáà àti àwọn ará Lefi àti àwọn olórí ìdílé, tí ó ti rí tẹmpili Olúwa ti tẹ́lẹ̀, wọ́n sọkún kíkorò nígbà tí wọ́n rí ìpìlẹ̀ tẹmpili Olúwa yìí tí wọ́n fi lélẹ̀, nígbà tí ọ̀pọ̀ kígbe fún ayọ̀.
Fe nangoihoy ty rovetse o mpisoroñeo naho o nte-Levio vaho o talèn’ anjomban-droaeo, o androanavy nahaisake i anjomba valoha’eio, ie nampijadoñeñe añatrefam-pihaino’ iareo eo o mananta’ ty anjomba toio, fe maro ka ty nipazapazak’ an-kaehake;
13 Kò sí ẹni tí ó le mọ ìyàtọ̀ láàrín igbe ayọ̀ àti ẹkún, nítorí tí ariwo àwọn ènìyàn náà pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́. Wọ́n sì gbọ́ igbe náà ní ọ̀nà jíjìn réré.
aa le tsy nahatsikara’ ondatio ty famatsiña’ i fipazapazam-pirebehañey amy fangololoiha’ ondatioy; fa pinoña’ ondatio ty fipazake kanao jinanjiñe tsietoitane añe i hozakozakey.