< Ezra 3 >

1 Nígbà tí ó di oṣù keje tí àwọn ọmọ Israẹli sì ti wà nínú àwọn ìlú wọn, àwọn ènìyàn péjọpọ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹnìkan ní Jerusalẹmu.
Lorsque le septième mois fut arrivé, et que les enfants d'Israël furent dans les villes, le peuple se rassembla comme un seul homme à Jérusalem.
2 Nígbà náà ni Jeṣua ọmọ Josadaki àti àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli àti àwọn ènìyàn rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí ní kọ́ pẹpẹ Ọlọ́run Israẹli láti rú ẹbọ sísun níbẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìlànà tí a ti kọ sínú ìwé òfin Mose ènìyàn Ọlọ́run.
Alors Josué, fils de Jotsadak, se leva avec ses frères les prêtres et Zorobabel, fils de Shealtiel, et ses proches, et ils bâtirent l'autel du Dieu d'Israël, pour y offrir des holocaustes, comme il est écrit dans la loi de Moïse, homme de Dieu.
3 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ẹ̀rù àwọn ènìyàn tí ó yí wọn ká ń bà wọ́n síbẹ̀, wọ́n kọ́ pẹpẹ sórí ìpìlẹ̀ rẹ̀, wọ́n sì rú ẹbọ sísun lórí rẹ̀ sí Olúwa, ọrẹ àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́.
Malgré la crainte qu'ils éprouvaient à cause des peuples des contrées voisines, ils posèrent l'autel sur sa base, et ils offrirent sur lui des holocaustes à l'Éternel, des holocaustes matin et soir.
4 Nígbà náà ní ìbámu pẹ̀lú ohun tí a kọ, wọ́n ṣe àjọ àgọ́ ìpàdé pẹ̀lú iye ẹbọ sísun tí a fi lélẹ̀ fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan.
Ils célébrèrent la fête des tabernacles, comme il est écrit, et offrirent les holocaustes quotidiens en nombre, selon les prescriptions, comme l'exigeait le devoir de chaque jour;
5 Lẹ́yìn náà, wọ́n ṣe ìrúbọ ẹbọ sísun àtìgbàdégbà, ẹbọ oṣù tuntun àti gbogbo àwọn ẹbọ fún gbogbo àpèjẹ tí a yà sọ́tọ̀ fún Olúwa, àti àwọn tí a mú wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ àtinúwá fún Olúwa.
puis l'holocauste perpétuel, les offrandes des nouvelles lunes, de toutes les fêtes de l'Éternel qui étaient consacrées, et de tous ceux qui offraient volontairement une offrande à l'Éternel.
6 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù keje, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ní rú ẹbọ sísun sí Olúwa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a kò ì tí ì fi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa lélẹ̀.
Dès le premier jour du septième mois, ils commencèrent à offrir des holocaustes à l'Éternel, mais les fondations du temple de l'Éternel n'étaient pas encore posées.
7 Nígbà náà ni wọ́n fún àwọn ọ̀mọ̀lé àti àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà ní owó, wọ́n sì tún fi oúnjẹ, ohun mímu àti òróró fún àwọn ará Sidoni àti Tire, kí wọ́n ba à le è kó igi kedari gba ti orí omi Òkun láti Lebanoni wá sí Joppa, gẹ́gẹ́ bí Kirusi ọba Persia ti pàṣẹ.
Ils donnaient aussi de l'argent aux maçons et aux charpentiers. Ils donnèrent aussi de la nourriture, des boissons et de l'huile aux habitants de Sidon et de Tyr pour qu'ils apportent des cèdres du Liban jusqu'à la mer, à Joppé, selon la concession qu'ils avaient reçue de Cyrus, roi de Perse.
8 Ní oṣù kejì ọdún kejì lẹ́yìn tí wọ́n ti padà dé sí ilé Ọlọ́run ní Jerusalẹmu, Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Jeṣua ọmọ Josadaki àti àwọn arákùnrin yòókù (àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi àti gbogbo àwọn tí ó ti ìgbèkùn dé sí Jerusalẹmu) bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ náà. Wọ́n sì yan àwọn ọmọ Lefi tí ó tó ọmọ-ogun ọdún sókè láti máa bojútó kíkọ́ ilé Olúwa.
Or, la deuxième année de leur arrivée à la maison de Dieu à Jérusalem, au deuxième mois, Zorobabel, fils de Shealthiel, Josué, fils de Jotsadak, et le reste de leurs frères, les prêtres et les lévites, et tous ceux qui étaient venus de la captivité à Jérusalem, commencèrent le travail et désignèrent les lévites, depuis l'âge de vingt ans et au-dessus, pour surveiller l'ouvrage de la maison de Yahvé.
9 Jeṣua àti àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ àti Kadmieli àti àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn ọmọ Juda (àwọn ìran Hodafiah) àti àwọn ọmọ Henadadi àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn arákùnrin wọn—gbogbo ará Lefi—parapọ̀ láti bojútó àwọn òṣìṣẹ́ náà tí wọ́n ń ṣiṣẹ́ lórí í kíkọ́ ilé Ọlọ́run.
Alors Josué se tint avec ses fils et ses frères, Kadmiel et ses fils, les fils de Juda, ensemble pour avoir la surveillance des ouvriers de la maison de Dieu: les fils de Henadad, avec leurs fils et leurs frères les Lévites.
10 Nígbà tí àwọn ọ̀mọ̀lé gbé ìpìlẹ̀ ilé Olúwa kalẹ̀, àwọn àlùfáà nínú aṣọ iṣẹ́ àlùfáà wọn pẹ̀lú fèrè, àti àwọn ará Lefi (àwọn ọmọ Asafu) pẹ̀lú símbálì, dúró ní ipò wọn láti yin Olúwa, bí Dafidi ọba Israẹli ti fi lélẹ̀.
Lorsque les bâtisseurs posèrent les fondations du temple de Yahvé, ils mirent les prêtres en tenue avec des trompettes, et les lévites, fils d'Asaph, avec des cymbales, pour louer Yahvé, selon les instructions de David, roi d'Israël.
11 Pẹ̀lú ìyìn àti ọpẹ́ ni wọ́n kọrin sí Olúwa: “Ó dára; ìfẹ́ rẹ̀ sí Israẹli dúró títí láé.” Gbogbo àwọn ènìyàn sì fi ohùn ariwo ńlá yin Olúwa, nítorí tí a ti fi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa lélẹ̀.
Ils chantaient l'un après l'autre en louant et en remerciant Yahvé: « Car il est bon, car sa bonté dure à jamais envers Israël. » Tout le peuple poussa de grands cris en louant Yahvé, car les fondements de la maison de Yahvé avaient été posés.
12 Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ lára àwọn àgbà àlùfáà àti àwọn ará Lefi àti àwọn olórí ìdílé, tí ó ti rí tẹmpili Olúwa ti tẹ́lẹ̀, wọ́n sọkún kíkorò nígbà tí wọ́n rí ìpìlẹ̀ tẹmpili Olúwa yìí tí wọ́n fi lélẹ̀, nígbà tí ọ̀pọ̀ kígbe fún ayọ̀.
Mais beaucoup de sacrificateurs, de lévites et de chefs de famille, de vieillards qui avaient vu la première maison, lorsque les fondements de cette maison furent posés sous leurs yeux, pleurèrent à haute voix. Beaucoup aussi poussaient des cris de joie à haute voix,
13 Kò sí ẹni tí ó le mọ ìyàtọ̀ láàrín igbe ayọ̀ àti ẹkún, nítorí tí ariwo àwọn ènìyàn náà pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́. Wọ́n sì gbọ́ igbe náà ní ọ̀nà jíjìn réré.
si bien que le peuple ne pouvait distinguer le bruit des cris de joie du bruit des pleurs du peuple; car le peuple poussait de grands cris, et le bruit était entendu au loin.

< Ezra 3 >