< Ezra 3 >
1 Nígbà tí ó di oṣù keje tí àwọn ọmọ Israẹli sì ti wà nínú àwọn ìlú wọn, àwọn ènìyàn péjọpọ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹnìkan ní Jerusalẹmu.
Oubi fesu da udui galu, Isala: ili dunu huluane da ilia moilaidafa amo ganodini fi dagoi ba: i. Amalalu, dunu amola uda huluane da Yelusalemega gilisi.
2 Nígbà náà ni Jeṣua ọmọ Josadaki àti àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli àti àwọn ènìyàn rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí ní kọ́ pẹpẹ Ọlọ́run Israẹli láti rú ẹbọ sísun níbẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìlànà tí a ti kọ sínú ìwé òfin Mose ènìyàn Ọlọ́run.
Amola Yosiua (Yihosada: ge egefe), eno gobele salasu dunu amola Selubabele (Sia: diele egefe) amola ea sosogo fi da Isala: ili Hina Gode amo Ea oloda bu gagui. Bai ilia da Gode Ea hawa: hamosu dunu Mousese, amo ea Sema amola hamoma: ne sia: i dedei defele, amo oloda da: iya Godema gobele salasu hamomusa: dawa: i.
3 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ẹ̀rù àwọn ènìyàn tí ó yí wọn ká ń bà wọ́n síbẹ̀, wọ́n kọ́ pẹpẹ sórí ìpìlẹ̀ rẹ̀, wọ́n sì rú ẹbọ sísun lórí rẹ̀ sí Olúwa, ọrẹ àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́.
Musa: mugululi asi dunu buhagi da dunu amo ilia musa: soge ganodini esala amoga beda: i. Be ilia da oloda amo ea musa: sogebi amoga bu gagui. Amalalu, ilia da bu hahabe huluane amola daeya huluane amoga gobele salasu hamosu.
4 Nígbà náà ní ìbámu pẹ̀lú ohun tí a kọ, wọ́n ṣe àjọ àgọ́ ìpàdé pẹ̀lú iye ẹbọ sísun tí a fi lélẹ̀ fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan.
Ilia da Sogega Fasela Diasu Lolo Nabe amo sema defele hamosu. Eso huluane ilia da amo eso ea gobele salasu sema ganodini dedei amo gobei.
5 Lẹ́yìn náà, wọ́n ṣe ìrúbọ ẹbọ sísun àtìgbàdégbà, ẹbọ oṣù tuntun àti gbogbo àwọn ẹbọ fún gbogbo àpèjẹ tí a yà sọ́tọ̀ fún Olúwa, àti àwọn tí a mú wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ àtinúwá fún Olúwa.
Amola ilia eno gobele salasu amo ohe gogo gobesu, Oubi gaheabolo doaga: loba gobele salasu, Godema nodone sia: ne gadosu gilisisu amola Hina Godema hahawane udigili iasu amo huluane ilia da hamosu.
6 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù keje, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ní rú ẹbọ sísun sí Olúwa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a kò ì tí ì fi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa lélẹ̀.
Ilia da Debolo amo bu gagumusa: hame hemoi. Be oubi fesuale gala bisili esoga, ilia da Hina Godema gobele salasu hemosu.
7 Nígbà náà ni wọ́n fún àwọn ọ̀mọ̀lé àti àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà ní owó, wọ́n sì tún fi oúnjẹ, ohun mímu àti òróró fún àwọn ará Sidoni àti Tire, kí wọ́n ba à le è kó igi kedari gba ti orí omi Òkun láti Lebanoni wá sí Joppa, gẹ́gẹ́ bí Kirusi ọba Persia ti pàṣẹ.
Isala: ili dunu da Debolo diasu gagusu dunu (amo da igi hedofasu dunu amola ifa hahamosu dunu) ilima ha: i manu, hano amola olife fage amoea maga: me i. Amo liligi ilia da Daia moilai bai bagade amola Saidone moilai bai bagadega, Lebanone soge dolo ifa bidi lama: ne iasi. Amo ifa da hano wayabo amoga misini, Yoba moilaiga doaga: su. Amo hou da Besia hina bagade Sailase amo ea sia: ga hamoi.
8 Ní oṣù kejì ọdún kejì lẹ́yìn tí wọ́n ti padà dé sí ilé Ọlọ́run ní Jerusalẹmu, Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Jeṣua ọmọ Josadaki àti àwọn arákùnrin yòókù (àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi àti gbogbo àwọn tí ó ti ìgbèkùn dé sí Jerusalẹmu) bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ náà. Wọ́n sì yan àwọn ọmọ Lefi tí ó tó ọmọ-ogun ọdún sókè láti máa bojútó kíkọ́ ilé Olúwa.
Amalalu, oubi ageyadu amo odega fa: no ilia da Debolo ea sogebi Yelusalemega doaga: le, ilia da bisili hawa: hamoi. Selubabele, Yosiua, eno Isala: ili dunu huluane, gobele salasu dunu amola musa: mugululi asi buhagi dunu huluane da gilisili hawa: hamosu. Ilia da Lifai dunu amo ilia esalebe ode 20 gidigi amola amo baligi, amo ilia da Debolo diasu bu gagusu amo ouligima: ne sia: i.
9 Jeṣua àti àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ àti Kadmieli àti àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn ọmọ Juda (àwọn ìran Hodafiah) àti àwọn ọmọ Henadadi àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn arákùnrin wọn—gbogbo ará Lefi—parapọ̀ láti bojútó àwọn òṣìṣẹ́ náà tí wọ́n ń ṣiṣẹ́ lórí í kíkọ́ ilé Ọlọ́run.
Lifai dunu afae amo Yesua, ea dunu mano, ea sosogo fi amola Ga: damiele amola egefe (ilia da Houdafia fi dunu) ilia da gilisili Debolo bu gaguma: ne ouligisu. (Henada: de fi Lifai dunu da ili fidisu.)
10 Nígbà tí àwọn ọ̀mọ̀lé gbé ìpìlẹ̀ ilé Olúwa kalẹ̀, àwọn àlùfáà nínú aṣọ iṣẹ́ àlùfáà wọn pẹ̀lú fèrè, àti àwọn ará Lefi (àwọn ọmọ Asafu) pẹ̀lú símbálì, dúró ní ipò wọn láti yin Olúwa, bí Dafidi ọba Israẹli ti fi lélẹ̀.
Hawa: hamosu dunu ilia Debolo diasu bisili gagubiba: le, gobele salasu dunu ilia abula salawane, dalabede dusu agoai amo ilia loboga gagui, amola A: sa: fe da dadabisu gaguli, dusa lelu. Amola ilia da gilisili Hina Godema nodone gesami hea: su amo da musa: Da: ibidi ea esoga hamoi defele hamosu.
11 Pẹ̀lú ìyìn àti ọpẹ́ ni wọ́n kọrin sí Olúwa: “Ó dára; ìfẹ́ rẹ̀ sí Israẹli dúró títí láé.” Gbogbo àwọn ènìyàn sì fi ohùn ariwo ńlá yin Olúwa, nítorí tí a ti fi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa lélẹ̀.
Ilia da Hina Godema nodone gesami hea: su, ha: giwane hea: i amane, “Hina Gode da defeadafa. Ea Isala: ili dunuma asigidafa hou da Fifi Ahoanusudafa.” Debolo diasu ea bai amo gagusu da wali hemobe ba: i. Amaiba: le ilia da ha: giwane gesami hea: su
12 Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ lára àwọn àgbà àlùfáà àti àwọn ará Lefi àti àwọn olórí ìdílé, tí ó ti rí tẹmpili Olúwa ti tẹ́lẹ̀, wọ́n sọkún kíkorò nígbà tí wọ́n rí ìpìlẹ̀ tẹmpili Olúwa yìí tí wọ́n fi lélẹ̀, nígbà tí ọ̀pọ̀ kígbe fún ayọ̀.
Musa: gobele salasu dunu, musa: Lifai dunu amola fi ouligisu hina dunu, mogili ilia da musa: Debolo diasu ba: i. Ilia da Debolo diasu gaheabolo ea bai gagubi ba: loba, fofagiba: le dinanu. Be eno dunu esalebe da bagadewane nodone halasu.
13 Kò sí ẹni tí ó le mọ ìyàtọ̀ láàrín igbe ayọ̀ àti ẹkún, nítorí tí ariwo àwọn ènìyàn náà pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́. Wọ́n sì gbọ́ igbe náà ní ọ̀nà jíjìn réré.
Ilia Debolo diasu gagusu amo nodoi ba: beba: le, dunu huluane da nodone bagadewane halale wele sia: nanu, badilia fi dunu huluane nabima: ne. Amola, disu amola nodone halasu da afafane afae nabimu hamedeiwane ba: i.