< Ezra 2 >
1 Lákòókò náà, wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn agbègbè Juda tí ó gòkè wá láti ìgbèkùn láàrín àwọn tí a kó lọ, ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti fi agbára mú ní ìgbèkùn lọ sí Babeli (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀.
Estas son las personas de las divisiones del reino, entre los que fueron hechos prisioneros por Nabucodonosor, rey de Babilonia, y llevados a Babilonia, quienes regresaron a Jerusalén y Judá, todos a su pueblo;
2 Àwọn wọ̀nyí bá Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordekai, Bilṣani, Mispari, Bigfai, Rehumu àti Baanah wá). Iye àwọn ọkùnrin àwọn ènìyàn Israẹli.
Que fueron con Zorobabel, Josué, Nehemías, Seraías, Reelaias, Mardoqueo, Bilsan, Mispar, Bigvai, Rehum, Baana, el número de los hombres del pueblo de Israel:
3 Àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
Los hijos de Paros, dos mil ciento setenta y dos.
4 Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
Los hijos de Sefatías, trescientos setenta y dos.
5 Arah jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n
Los hijos de Ara, setecientos setenta y cinco.
6 Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ àwọn ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì àti ẹgbẹ̀rin lé méjìlá
Los hijos de Pahat-moab, de los hijos de Josué y Joab, dos mil ochocientos doce.
7 Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
Los hijos de Elam, mil doscientos cincuenta y cuatro.
8 Sattu jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rún ó lé márùn-ún
Los hijos de Zatu, novecientos cuarenta y cinco.
9 Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
Los hijos de Zacai, setecientos sesenta.
10 Bani jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì
Los hijos de Binuy, seiscientos cuarenta y dos.
11 Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mẹ́tàlélógún
Los hijos de Bebai, seiscientos veintitrés.
12 Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé méjìlélógún
Los hijos de Azgad, mil doscientos veintidos.
13 Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà
Los hijos de Adonicam, seiscientos sesenta y seis.
14 Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
Los hijos de Bigvai, dos mil cincuenta y seis.
15 Adini jẹ́ àádọ́ta lé ní irinwó ó lé mẹ́rin
Los hijos de Adín, cuatrocientos cincuenta y cuatro.
16 Ateri (nípasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́run
Los hijos de Ater, de Ezequías, noventa y ocho.
17 Besai jẹ́ ọrùndínnírinwó ó lé mẹ́ta
Los hijos de Bezai, trescientos veintitrés.
18 Jora jẹ́ méjìléláàádọ́fà
Los hijos de Jora, ciento doce.
19 Haṣumu jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
Los hijos de Hasum, doscientos veintitrés.
20 Gibbari jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
Los hijos de Gibbar, noventa y cinco.
21 Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
Los hijos de Belén, ciento veintitrés.
22 Netofa jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
Los hombres de Netofa, cincuenta y seis.
23 Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
Los varones de Anatot, ciento veintiocho;
24 Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
Los hijos de Azmavet, cuarenta y dos.
25 Kiriati-Jearimu, Kefira àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
Los hijos de Quiriat-arim, Cafira y Beerot, setecientos cuarenta y tres.
26 Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
Los hijos de Ramá y Geba, seiscientos veintiuno.
27 Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
Los varones de Micmas, ciento veintidós;
28 Beteli àti Ai jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
Los hombres de Betel y Hai, doscientos veintitrés.
29 Nebo jẹ́ méjìléláàádọ́ta
Los hijos de Nebo, cincuenta y dos.
30 Magbiṣi jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́jọ
Los hijos de Magbis, ciento cincuenta y seis.
31 Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
Los hijos de la otra Elam, mil doscientos cincuenta y cuatro.
32 Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó.
Los hijos de Harim, trescientos veinte.
33 Lodi, Hadidi àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
Los hijos de Lod, Hadid y Ono, setecientos veinticinco.
34 Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún
Los hijos de Jericó, trescientos cuarenta y cinco.
35 Senaa jẹ́ egbèji dín lógún ó lé ọgbọ̀n.
Los hijos de Senaa, tres mil seiscientos treinta.
36 Àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
Los sacerdotes: los hijos de Jedaías, de la casa de Josué, novecientos setenta y tres.
37 Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
Los hijos de Imer, mil cincuenta y dos.
38 Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
Los hijos de Pasur, mil doscientos cuarenta y siete.
39 Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
Los hijos de Harim, mil diecisiete.
40 Àwọn ọmọ Lefi. Àwọn ọmọ Jeṣua àti Kadmieli (ti ìdílé Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
Los levitas: los hijos de Josué y Cadmiel, de los hijos de Hodavias, setenta y cuatro.
41 Àwọn akọrin. Àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádóje.
Los creadores de música: los hijos de Asaf, ciento veintiocho.
42 Àwọn aṣọ́bodè. Àwọn ará Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita àti Ṣobai jẹ́ mọ́kàndínlógóje.
Los hijos de los guardias de la puerta: los hijos de Salum, los hijos de Ater, los hijos de Talmon, los hijos de Acub, los hijos de Hatita, los hijos de Sobai, ciento treinta y nueve.
43 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ. Siha, Hasufa, Tabboati,
Los sirvientes del templo: los hijos de Ziha, los hijos de Hasufa, los hijos de Tabaot,
44 Kerosi, Siaha, Padoni,
Los hijos de Queros, los hijos de Siaha, los hijos de Padon,
45 Lebana, Hagaba, Akkubu,
Los hijos de Lebana, los hijos de Hagaba, los hijos de Acub,
46 Hagabu, Ṣalmai, Hanani,
Los hijos de Hagab, los hijos de Salmai, los hijos de Hanán,
47 Giddeli, Gahari, Reaiah,
Los hijos de Gidel, los hijos de Gahar, los hijos de Reaia,
48 Resini, Nekoda, Gassamu,
Los hijos de Rezín, los hijos de Necoda, los hijos de Gazam,
Los hijos de Uza, los hijos de Paseah, los hijos de Besai,
50 Asna, Mehuni, Nefisimu,
Los hijos de Asena, los hijos de Meunim, los hijos de Nefusim,
51 Bakbu, Hakufa, Harhuri.
Los hijos de Bacbuc, los hijos de Hacufa, los hijos de Harhur,
52 Basluti, Mehida, Harṣa,
Los hijos de Bazlut, los hijos de Mehida, los hijos de Harsa,
53 Barkosi, Sisera, Tema,
Los hijos de Barcos, los hijos de Sísara, los hijos de Tema,
Los hijos de Nezía, los hijos de Hatifa.
55 Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni. Àwọn ọmọ Sotai, Sofereti, Peruda,
Los hijos de los siervos de Salomón: los hijos de Sotai, los hijos de soferet, los hijos de Peruda,
56 Jaala, Darkoni, Giddeli,
Los hijos de Jaala, los hijos de Darcón, los hijos de Gidel,
57 Ṣefatia, àwọn ọmọ Hattili, Pokereti ti Haṣebaimu àti àwọn ọmọ Ami.
Los hijos de Sefatías, los hijos de Hattil, los hijos de Pochereth-hazzebaim, los hijos de Ami.
58 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
Todos los Sirvientes y los hijos de los siervos de Salomón eran trescientos noventa y dos.
59 Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
Y estas fueron las personas que subieron de Tel-mela, Tel-harsa, Querub, Adón e Imer. Pero como no tenían conocimiento de las familias de sus padres ni de sus descendientes, no era seguro que fueran israelitas;
60 Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
Los hijos de Delaía, los hijos de Tobías, los hijos de Necoda, seiscientos cincuenta y dos.
61 Àti nínú àwọn ọmọ àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ: Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi a sì ń fi orúkọ náà pè é).
Y de los hijos de los sacerdotes: los hijos de Habaía, los hijos de Cos, los hijos de Barzilai, que estaba casado con una de las hijas de Barzilai de Galaad, y tomaron su nombre.
62 Àwọn wọ̀nyí wá ìwé ìrántí ìdílé wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni a kò kà wọ́n kún ara àlùfáà nítorí, a kà wọ́n sí aláìmọ́.
Hicieron una búsqueda de su registro entre las listas de familias, pero sus nombres no estaban a la vista; por eso fueron vistos como impuros y fueron excluidos como sacerdotes.
63 Baálẹ̀ pa á láṣẹ fún wọn pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ nínú oúnjẹ mímọ́ jùlọ títí tí àlùfáà kan yóò fi ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu.
Y el gobernador dijo que no debían tener las cosas más sagradas para su alimento, hasta que un sacerdote viniera a dar una decisión por Urim y Tumim.
64 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó.
El número de todas las personas juntas fue cuarenta y dos mil trescientos sesenta.
65 Yàtọ̀ sí ẹgbẹ̀rin dín lẹ́gbàárin ó dín mẹ́tàlélọ́gọ́ta ìránṣẹ́ ọkùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin; wọ́n ní igba akọrin ọkùnrin àti obìnrin.
Así como sus siervos y sus siervas, de los cuales había siete mil trescientos treinta y siete; y tenían doscientos hombres y mujeres para hacer música.
66 Wọ́n ní ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin ẹṣin; ìbáaka òjìlélúgba ó lé márùn-ún,
Tenían setecientos treinta y seis caballos, doscientos cuarenta y cinco bestias de transporte,
67 ràkunmí jẹ́ irinwó ó lé márùndínlógójì àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rin lé lọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
Cuatrocientos treinta y cinco camellos, seis mil setecientos veinte asnos.
68 Ní ìgbà tí wọ́n dé ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, díẹ̀ nínú àwọn olórí àwọn ìdílé fi ọrẹ àtinúwá sílẹ̀ fún ṣíṣe àtúnkọ́ ilé Ọlọ́run ní ààyè rẹ̀.
Y algunos de los jefes de familia, cuando llegaron a la casa del Señor que está en Jerusalén, dieron libremente sus riquezas para la reconstrucción del templo de Dios en su lugar:
69 Gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, wọ́n fún ilé ìṣúra fún iṣẹ́ yìí ní ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ́gbẹ̀rún ìwọ̀n dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún márùn-ún fàdákà àti ọgọ́rùn-ún ẹ̀wù àlùfáà.
Cada uno, como pudo, dio para el trabajo sesenta y un mil dracmas de oro, cinco mil libras de plata y cien túnicas sacerdotales.
70 Àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́bodè àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa ṣe àtìpó sínú àwọn ìlú wọn, pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn, àti ìyókù àwọn ọmọ Israẹli ṣe àtìpó sínú ìlú u wọn.
Así que los sacerdotes y los levitas y la gente y los cantores y los encargados de las puertas y los sirvientes, tomaron sus lugares en sus pueblos; todo Israel en sus propios pueblos.