< Ezra 2 >

1 Lákòókò náà, wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn agbègbè Juda tí ó gòkè wá láti ìgbèkùn láàrín àwọn tí a kó lọ, ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti fi agbára mú ní ìgbèkùn lọ sí Babeli (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀.
Esta es una lista de los exiliados judíos de la provincia que regresaron del cautiverio después de que el rey Nabucodonosor se los llevara a Babilonia. Volvieron a Jerusalén y a sus propias ciudades en Judá.
2 Àwọn wọ̀nyí bá Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordekai, Bilṣani, Mispari, Bigfai, Rehumu àti Baanah wá). Iye àwọn ọkùnrin àwọn ènìyàn Israẹli.
Sus líderes eran Zorobabel, Jesúa, Nehemías, Seraías, Reelaías, Mardoqueo, Bilsán, Mispar, Bigvai, Rehum y Baana. Este es el número de los hombres del pueblo de Israel:
3 Àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
los hijos de Paros, 2.172;
4 Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
los hijos de Sefatías, 372;
5 Arah jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n
los hijos de Ara, 775;
6 Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ àwọn ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì àti ẹgbẹ̀rin lé méjìlá
los hijos de Pahat-moab (hijos de Jesúa y Joab), 2.812;
7 Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
los hijos de Elam, 1.254;
8 Sattu jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rún ó lé márùn-ún
los hijos de Zatu, 945;
9 Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
los hijos de Zacai, 760;
10 Bani jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì
los hijos de Bani, 642;
11 Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mẹ́tàlélógún
los hijos de Bebai, 623
12 Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé méjìlélógún
los hijos de Azgad, 1.222;
13 Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà
los hijos de Adonicam, 666;
14 Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
los hijos de Bigvai, 2.056;
15 Adini jẹ́ àádọ́ta lé ní irinwó ó lé mẹ́rin
los hijos de Adin, 454;
16 Ateri (nípasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́run
los hijos de Ater, (hijos de Ezequías), 98;
17 Besai jẹ́ ọrùndínnírinwó ó lé mẹ́ta
los hijos de Bezai, 323;
18 Jora jẹ́ méjìléláàádọ́fà
los hijos de Jora, 112;
19 Haṣumu jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
los hijos de Hasum, 223;
20 Gibbari jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
los hijos de Gibar, 95;
21 Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
el pueblo de Belén, 123;
22 Netofa jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
el pueblo de Netofa, 56;
23 Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
el pueblo de Anatot, 128;
24 Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
el pueblo de Bet-azmavet, 42;
25 Kiriati-Jearimu, Kefira àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
el pueblo de Quiriat-jearim, Cafira y Beerot, 743;
26 Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
el pueblo de Ramá y Geba, 621;
27 Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
el pueblo de Micmas, 122
28 Beteli àti Ai jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
el pueblo de Betel y de Hai, 223;
29 Nebo jẹ́ méjìléláàádọ́ta
los hijos de Nebo, 52;
30 Magbiṣi jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́jọ
los hijos de Magbis, 156;
31 Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
los hijos de Elam, 1.254;
32 Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó.
los hijos de Harim, 320;
33 Lodi, Hadidi àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
los hijos de Lod, Hadid y Ono, 725;
34 Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún
los hijos de Jericó, 345;
35 Senaa jẹ́ egbèji dín lógún ó lé ọgbọ̀n.
los hijos de Senaa, 3.630.
36 Àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
Este es el número de los sacerdotes: los hijos de Jedaías (por la familia de Jesúa), 973;
37 Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
los hijos de Imer, 1.052;
38 Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
los hijos de Pasur, 1.247;
39 Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
los hijos de Harim, 1.017.
40 Àwọn ọmọ Lefi. Àwọn ọmọ Jeṣua àti Kadmieli (ti ìdílé Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
Este es el número de los levitas: los hijos de Jesúa y Cadmiel (hijos de Hodavías), 74;
41 Àwọn akọrin. Àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádóje.
los cantores de los hijos de Asaf, 128;
42 Àwọn aṣọ́bodè. Àwọn ará Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita àti Ṣobai jẹ́ mọ́kàndínlógóje.
los porteros de las familias de Salum, Ater, Talmón, Acub, Hatita y Sobai, 139.
43 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ. Siha, Hasufa, Tabboati,
Los descendientes de estos servidores del Templo: Ziha, Hasufa, Tabaot,
44 Kerosi, Siaha, Padoni,
Queros, Siaha, Padón,
45 Lebana, Hagaba, Akkubu,
Lebana, Hagaba, Acub,
46 Hagabu, Ṣalmai, Hanani,
Hagab, Salmai, Hanán,
47 Giddeli, Gahari, Reaiah,
Gidel, Gahar, Reaía,
48 Resini, Nekoda, Gassamu,
Rezín, Necoda, Gazam,
49 Ussa, Pasea, Besai,
Uza, Paseah, Besai,
50 Asna, Mehuni, Nefisimu,
Asena, Mehunim, Nefusim,
51 Bakbu, Hakufa, Harhuri.
Bacbuc, Hacufa, Harhur,
52 Basluti, Mehida, Harṣa,
Bazlut, Mehída, Harsa,
53 Barkosi, Sisera, Tema,
Barcos, Sísara, Tema,
54 Nesia àti Hatifa.
Nezía, y Hatifa.
55 Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni. Àwọn ọmọ Sotai, Sofereti, Peruda,
Los descendientes de los siervos del rey Salomón: Sotai, Hasoferet, Peruda,
56 Jaala, Darkoni, Giddeli,
Jaala, Darcón, Gidel,
57 Ṣefatia, àwọn ọmọ Hattili, Pokereti ti Haṣebaimu àti àwọn ọmọ Ami.
Sefatías, Hatil, Poqueret-hazebaim, y Ami.
58 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
El total de los siervos del Templo y de los descendientes de los siervos de Salomón era de 392.
59 Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
Los que procedían de las ciudades de Tel-mela, Tel-Harsa, Querub, Addán e Imer no podían demostrar su genealogía familiar, ni siquiera que eran descendientes de Israel.
60 Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
Entre ellos estaban las familias de Delaía, Tobías y Necoda, 652 en total.
61 Àti nínú àwọn ọmọ àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ: Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi a sì ń fi orúkọ náà pè é).
Además había tres familias sacerdotales, hijos de Habaía, Cos y Barzilai. (Barzilai se había casado con una mujer que descendía de Barzilai de Galaad, y se llamaba así).
62 Àwọn wọ̀nyí wá ìwé ìrántí ìdílé wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni a kò kà wọ́n kún ara àlùfáà nítorí, a kà wọ́n sí aláìmọ́.
Se buscó un registro de ellos en las genealogías, pero no se encontraron sus nombres, por lo que se les prohibió servir como sacerdotes.
63 Baálẹ̀ pa á láṣẹ fún wọn pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ nínú oúnjẹ mímọ́ jùlọ títí tí àlùfáà kan yóò fi ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu.
El gobernador les ordenó que no comieran nada de los sacrificios del santuario hasta que un sacerdote pudiera consular con el Señor sobre el asunto a través del Urim y el Tumim.
64 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó.
El total de personas que regresaron fue de 42.360.
65 Yàtọ̀ sí ẹgbẹ̀rin dín lẹ́gbàárin ó dín mẹ́tàlélọ́gọ́ta ìránṣẹ́ ọkùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin; wọ́n ní igba akọrin ọkùnrin àti obìnrin.
Además había 7.337 sirvientes y 200 cantores y cantoras.
66 Wọ́n ní ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin ẹṣin; ìbáaka òjìlélúgba ó lé márùn-ún,
Tenían 736 caballos, 245 mulas,
67 ràkunmí jẹ́ irinwó ó lé márùndínlógójì àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rin lé lọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
435 camellos y 6.720 asnos.
68 Ní ìgbà tí wọ́n dé ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, díẹ̀ nínú àwọn olórí àwọn ìdílé fi ọrẹ àtinúwá sílẹ̀ fún ṣíṣe àtúnkọ́ ilé Ọlọ́run ní ààyè rẹ̀.
Cuando llegaron al Templo del Señor en Jerusalén, algunos de los jefes de familia hicieron contribuciones voluntarias para reconstruir el Templo de Dios en el lugar donde antes estaba.
69 Gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, wọ́n fún ilé ìṣúra fún iṣẹ́ yìí ní ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ́gbẹ̀rún ìwọ̀n dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún márùn-ún fàdákà àti ọgọ́rùn-ún ẹ̀wù àlùfáà.
Dieron según lo que tenían, poniendo su donativo en el tesoro. El total ascendió a 61.000 dáricos de oro, 5.000 minas de plata y 100 túnicas para los sacerdotes.
70 Àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́bodè àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa ṣe àtìpó sínú àwọn ìlú wọn, pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn, àti ìyókù àwọn ọmọ Israẹli ṣe àtìpó sínú ìlú u wọn.
Los sacerdotes, los levitas, los cantores, los porteros y los servidores del Templo, así como parte del pueblo, volvieron a vivir en sus pueblos específicos. Los demás regresaron a sus propias ciudades en todo Israel.

< Ezra 2 >