< Ezra 2 >

1 Lákòókò náà, wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn agbègbè Juda tí ó gòkè wá láti ìgbèkùn láàrín àwọn tí a kó lọ, ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti fi agbára mú ní ìgbèkùn lọ sí Babeli (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀.
Estes são os filhos da província que subiram do cativeiro, dos transportados que Nabucodonosor, rei de Babilônia, tinha transportado para a Babilônia, e que voltaram a Jerusalém e a Judá, cada um para sua cidade;
2 Àwọn wọ̀nyí bá Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordekai, Bilṣani, Mispari, Bigfai, Rehumu àti Baanah wá). Iye àwọn ọkùnrin àwọn ènìyàn Israẹli.
Os quais vieram com Zorobabel, Jesua, Neemias, Seraías, Reelaías, Mardoqueu, Bilsã, Mispar, Bigvai, Reum e Baaná. O registro dos homens do povo de Israel:
3 Àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
Os filhos de Parós, dois mil cento e setenta e dois;
4 Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
Os filhos de Sefatias, trezentos e setenta e dois;
5 Arah jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n
Os filhos de Ara, setecentos e setenta e cinco;
6 Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ àwọn ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì àti ẹgbẹ̀rin lé méjìlá
Os filhos de Paate-Moabe, dos descendentes de Jesua e Joabe, dois mil oitocentos e doze;
7 Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
Os filhos de Elão, mil duzentos e cinquenta e quatro;
8 Sattu jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rún ó lé márùn-ún
Os filhos de Zatu, novecentos e quarenta e cinco;
9 Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
Os filhos de Zacai, setecentos e sessenta;
10 Bani jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì
Os filhos de Bani, seiscentos e quarenta e dois;
11 Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mẹ́tàlélógún
Os filhos de Bebai, seiscentos e vinte e três;
12 Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé méjìlélógún
Os filhos de Azgade, mil duzentos e vinte e dois;
13 Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà
Os filhos de Adonicão, seiscentos e sessenta e seis;
14 Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
Os filhos de Bigvai, dois mil e cinquenta e seis;
15 Adini jẹ́ àádọ́ta lé ní irinwó ó lé mẹ́rin
Os filhos de Adim, quatrocentos e cinquenta e quatro;
16 Ateri (nípasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́run
Os filhos de Ater, de Ezequias, noventa e oito;
17 Besai jẹ́ ọrùndínnírinwó ó lé mẹ́ta
Os filhos de Bezai, trezentos e vinte e três;
18 Jora jẹ́ méjìléláàádọ́fà
Os filhos de Jora, cento e doze;
19 Haṣumu jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
Os filhos de Hasum, duzentos e vinte e três;
20 Gibbari jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
Os filhos de Gibar, noventa e cinco;
21 Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
Os filhos de Belém, cento e vinte e três;
22 Netofa jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
Os homens de Netofá, cinquenta e seis;
23 Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
Os homens de Anatote, cento e vinte e oito;
24 Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
Os filhos de Azmavete, quarenta e dois;
25 Kiriati-Jearimu, Kefira àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
Os filhos de Quiriate-Jearim, Quefira, e Beerote, setecentos e quarenta e três;
26 Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
Os filhos de Ramá e Geba, seiscentos e vinte e um;
27 Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
Os homens de Micmás, cento e vinte e dois;
28 Beteli àti Ai jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
Os homens de Betel e Ai, duzentos e vinte e três;
29 Nebo jẹ́ méjìléláàádọ́ta
Os filhos de Nebo, cinquenta e dois;
30 Magbiṣi jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́jọ
Os filhos de Magbis, cento e cinquenta e seis;
31 Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
Os filhos do outro Elão, mil duzentos e cinquenta e quatro;
32 Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó.
Os filhos de Harim, trezentos e vinte;
33 Lodi, Hadidi àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
Os filhos de Lode, Hadide, e Ono, setecentos e vinte e cinco;
34 Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún
Os filhos de de Jericó, trezentos e quarenta e cinco;
35 Senaa jẹ́ egbèji dín lógún ó lé ọgbọ̀n.
Os filhos de Senaá, três mil seiscentos e trinta;
36 Àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
Os sacerdotes: os filhos de Jedaías, da casa de Jesua, novecentos e setenta e três;
37 Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
Os filhos de Imer, mil e cinquenta e dois;
38 Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
Os filhos de Pasur, mil duzentos e quarenta e sete;
39 Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
Os filhos de Harim, mil e dezessete.
40 Àwọn ọmọ Lefi. Àwọn ọmọ Jeṣua àti Kadmieli (ti ìdílé Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
Os Levitas: os filhos de Jesua e de Cadmiel, dos filhos de Hodavias, setenta e quatro.
41 Àwọn akọrin. Àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádóje.
Os cantores: os filhos de Asafe, cento e vinte e oito.
42 Àwọn aṣọ́bodè. Àwọn ará Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita àti Ṣobai jẹ́ mọ́kàndínlógóje.
Os filhos dos porteiros: os filhos de Salum, os filhos de Ater, os filhos de Talmom, os filhos de Acube, os filhos de Hatita, os filhos de Sobai; ao todo, cento e trinta e nove.
43 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ. Siha, Hasufa, Tabboati,
Os servos do templo: os filhos de Zia, os filhos de Hasufa, os filhos de Tabaote,
44 Kerosi, Siaha, Padoni,
Os filhos de Queros, os filhos de Sia, os filhos de Padom;
45 Lebana, Hagaba, Akkubu,
Os filhos de Lebana, os filhos de Hagaba, os filhos de Acube;
46 Hagabu, Ṣalmai, Hanani,
Os filhos de Hagabe, os filhos de Sanlai, os filhos de Hanã;
47 Giddeli, Gahari, Reaiah,
Os filhos de Gidel, os filhos de Gaar, os filhos de Reaías;
48 Resini, Nekoda, Gassamu,
Os filhos de Rezim, os filhos de Necoda, os filhos de Gazão;
49 Ussa, Pasea, Besai,
Os filhos de Uzá, os filhos de Paseia, os filhos de Besai;
50 Asna, Mehuni, Nefisimu,
Os filhos de Asná, os filhos de Meunim, os filhos de Nefusim;
51 Bakbu, Hakufa, Harhuri.
Os filhos de Baquebuque, os filhos de Hacufa, os filhos de Harur;
52 Basluti, Mehida, Harṣa,
Os filhos de Baslute, os filhos de Meída, os filhos de Harsa;
53 Barkosi, Sisera, Tema,
Os filhos de Barcos, os filhos de Sísera, os filhos de Temá;
54 Nesia àti Hatifa.
Os filhos de Nesias, os filhos de Hatifa.
55 Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni. Àwọn ọmọ Sotai, Sofereti, Peruda,
Os filhos dos servos de Salomão: os filhos de Sotai, os filhos de Soferete, os filhos de Peruda;
56 Jaala, Darkoni, Giddeli,
Os filhos de Jaala, o filhos de Darcom, os filhos de Gidel;
57 Ṣefatia, àwọn ọmọ Hattili, Pokereti ti Haṣebaimu àti àwọn ọmọ Ami.
Os filhos de Sefatias, os filhos de Hatil, os filhos de Poquerete-Hazebaim, os filhos de Ami.
58 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
Todos os servos do templo, e filhos dos servos de Salomão, trezentos e noventa e dois.
59 Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
Também estes subiram de Tel-Melá, Tel-Harsa, Querube, Adã, e Imer, porém não puderam mostrar a família de seus pais, nem sua linhagem, se eram de Israel:
60 Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
Os filhos de Delaías, os filhos de Tobias, os filhos de Necoda, seiscentos e cinquenta e dois.
61 Àti nínú àwọn ọmọ àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ: Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi a sì ń fi orúkọ náà pè é).
E dos filhos dos sacerdotes: os filhos de Habaías, os filhos de Coz, os filhos de Barzilai, o qual tomou mulher das filhas de Barzilai gileadita, e foi chamado pelo nome delas.
62 Àwọn wọ̀nyí wá ìwé ìrántí ìdílé wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni a kò kà wọ́n kún ara àlùfáà nítorí, a kà wọ́n sí aláìmọ́.
Estes buscaram seu registro de genealogias, mas não foi achado; por isso foram rejeitados do sacerdócio.
63 Baálẹ̀ pa á láṣẹ fún wọn pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ nínú oúnjẹ mímọ́ jùlọ títí tí àlùfáà kan yóò fi ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu.
E o governador lhes mandou que não comessem das coisas sagradas, até que houvesse sacerdote com Urim e Tumim.
64 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó.
Toda esta congregação junta foi quarenta e dois mil trezentos e sessenta,
65 Yàtọ̀ sí ẹgbẹ̀rin dín lẹ́gbàárin ó dín mẹ́tàlélọ́gọ́ta ìránṣẹ́ ọkùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin; wọ́n ní igba akọrin ọkùnrin àti obìnrin.
Sem seus servos e servas, os quais foram sete mil trezentos trinta e sete; também tinham duzentos cantores e cantoras.
66 Wọ́n ní ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin ẹṣin; ìbáaka òjìlélúgba ó lé márùn-ún,
Seus cavalos foram setecentos e trinta e seis; seus mulos, duzentos e quarenta e cinco;
67 ràkunmí jẹ́ irinwó ó lé márùndínlógójì àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rin lé lọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
Seus camelos, quatrocentos trinta e cinco; asnos, seis mil setecentos e vinte.
68 Ní ìgbà tí wọ́n dé ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, díẹ̀ nínú àwọn olórí àwọn ìdílé fi ọrẹ àtinúwá sílẹ̀ fún ṣíṣe àtúnkọ́ ilé Ọlọ́run ní ààyè rẹ̀.
E [alguns] dos chefes de famílias, quando vieram à casa do SENHOR que estava em Jerusalém, deram ofertas voluntárias para a casa de Deus, para [a] reconstruírem em seu lugar.
69 Gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, wọ́n fún ilé ìṣúra fún iṣẹ́ yìí ní ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ́gbẹ̀rún ìwọ̀n dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún márùn-ún fàdákà àti ọgọ́rùn-ún ẹ̀wù àlùfáà.
Conforme sua capacidade deram ao tesouro da obra sessenta e uma mil dracmas de ouro, cinco mil libras de prata, e cem vestes sacerdotais.
70 Àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́bodè àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa ṣe àtìpó sínú àwọn ìlú wọn, pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn, àti ìyókù àwọn ọmọ Israẹli ṣe àtìpó sínú ìlú u wọn.
E os sacerdotes, os Levitas, os do povo, os cantores, os porteiros e os servos do templo, habitaram em suas cidades; como também todo Israel em suas cidades.

< Ezra 2 >