< Ezra 2 >

1 Lákòókò náà, wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn agbègbè Juda tí ó gòkè wá láti ìgbèkùn láàrín àwọn tí a kó lọ, ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti fi agbára mú ní ìgbèkùn lọ sí Babeli (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀.
Voici les fils de la province qui montèrent dentre les captifs qu’avait transportés à Babylone, Nabuchodonosor, roi de Babylone, et qui retournèrent à Jérusalem et en Juda, chacun dans sa ville.
2 Àwọn wọ̀nyí bá Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordekai, Bilṣani, Mispari, Bigfai, Rehumu àti Baanah wá). Iye àwọn ọkùnrin àwọn ènìyàn Israẹli.
Ceux qui vinrent avec Zorobabel et Josué sont: Néhémias, Saraïa, Rahélaïa, Mardochaï, Belsan, Mesphar, Béguaï, Réhum et Baana. Nombres des hommes du peuple d’Israël;
3 Àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
Les fils de Pharos, deux mille cent soixante-douze;
4 Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
Les fils de Séphatia, trois cent soixante-douze;
5 Arah jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n
Les fils d’Aréa, sept cent soixante-quinze;
6 Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ àwọn ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì àti ẹgbẹ̀rin lé méjìlá
Les fils de Phahath-Moab, des fils de Josué: Joab, deux mille huit cent douze;
7 Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
Les fils d’Elam, mille deux cent cinquante-quatre;
8 Sattu jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rún ó lé márùn-ún
Les fils de Zéthua, neuf cent quarante-cinq;
9 Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
Les fils de Zachaï, sept cent soixante;
10 Bani jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì
Les fils de Bani, six cent quarante-deux;
11 Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mẹ́tàlélógún
Les fils de Bébaï, six cent vingt-trois:
12 Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé méjìlélógún
Les fils d’Azgad, mille deux cent vingt-deux;
13 Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà
Les fils d’Adonicam, six cent soixante-six;
14 Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
Les fils de Béguaï, deux mille cinquante-six;
15 Adini jẹ́ àádọ́ta lé ní irinwó ó lé mẹ́rin
Les fils d’Adin, quatre cent cinquante-quatre;
16 Ateri (nípasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́run
Les fils d’Ather, qui étaient d’Ezéchias, quatre-vingt-dix-huit;
17 Besai jẹ́ ọrùndínnírinwó ó lé mẹ́ta
Les fils de Bésaï, trois cent vingt-trois;
18 Jora jẹ́ méjìléláàádọ́fà
Les fils de Jora, cent douze;
19 Haṣumu jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
Les fils d’Hasum, deux cent vingt-trois;
20 Gibbari jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
Les fils de Gebbar, quatre vingt-quinze;
21 Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
Les fils de Bethléhem, cent vingt-trois;
22 Netofa jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
Les hommes de Nétupha, cinquante-six;
23 Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
Les hommes d’Anathoth, cent vingt-huit;
24 Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
Les fils d’Azmaveth, quarante-deux;
25 Kiriati-Jearimu, Kefira àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
Les fils de Cariathiarim, de Céphira et de Béroth, sept cent quarante-trois;
26 Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
Les fils de Rama et de Gabaa, six cent vingt et un;
27 Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
Les hommes de Machmas, cent vingt-deux;
28 Beteli àti Ai jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
Les hommes de Béthel et de Haï, deux cent vingt-trois;
29 Nebo jẹ́ méjìléláàádọ́ta
Les fils de Nébo, cinquante-deux;
30 Magbiṣi jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́jọ
Les fils de Megbis, cent cinquante-six;
31 Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
Les fils d’un autre Elam, mille deux cent cinquante-quatre;
32 Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó.
Les fils de Harim, trois cent vingt;
33 Lodi, Hadidi àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
Les fils de Lod, de Hadid et d’Ono, sept cent vingt-cinq;
34 Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún
Les fils de Jéricho, trois cent quarante-cinq;
35 Senaa jẹ́ egbèji dín lógún ó lé ọgbọ̀n.
Les fils de Sénaa, trois mille six cent trente.
36 Àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
Les prêtres: Les fils de Jadaïa, dans la maison de Josué, neuf cent soixante-treize;
37 Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
Les fils d’Emmer, mille cinquante-deux;
38 Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
Les fils de Pheshur, mille deux cent quarante-sept;
39 Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
Les fils de Harim, mille dix-sept.
40 Àwọn ọmọ Lefi. Àwọn ọmọ Jeṣua àti Kadmieli (ti ìdílé Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
Les Lévites: Les fils de Josué et de Cedmihel, fils d’Odovia, soixante-quatorze.
41 Àwọn akọrin. Àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádóje.
Les chantres: Les fils d’Asaph, cent vingt-huit.
42 Àwọn aṣọ́bodè. Àwọn ará Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita àti Ṣobai jẹ́ mọ́kàndínlógóje.
Les fils des portiers: Les fils de Sellum, les fils d’Ater, les fils de Telmon, les fils d’Accub, les fils de Hatitha, les fils de Sobaï, tous ensemble, cent trente-neuf.
43 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ. Siha, Hasufa, Tabboati,
Les Nathinéens: Les fils de Siha, les fils de Hasupha, les fils de Tabbaoth,
44 Kerosi, Siaha, Padoni,
Les fils de Céros, les fils de Siaa, les fils de Phadon,
45 Lebana, Hagaba, Akkubu,
Les fils de Lébana, les fils de Hagaba, les fils d’Accub,
46 Hagabu, Ṣalmai, Hanani,
Les fils de Hagab, les fils de Semlaï, les fils de Hanan,
47 Giddeli, Gahari, Reaiah,
Les fils de Gaddel, les fils de Gaher, les fils de Raaïa,
48 Resini, Nekoda, Gassamu,
Les fils de Rasin, les fils de Nécoda, les fils de Gazam,
49 Ussa, Pasea, Besai,
Les fils d’Aza, les fils de Phaséa, les fils de Bésée,
50 Asna, Mehuni, Nefisimu,
Les fils d’Aséna, les fils de Munim, les fils de Néphusim,
51 Bakbu, Hakufa, Harhuri.
Les fils de Bacbuc, les fils de Hacupha, les fils de Harhur,
52 Basluti, Mehida, Harṣa,
Les fils de Besluth, les fils de Mahida, les fils de Harsa,
53 Barkosi, Sisera, Tema,
Les fils de Bercos, les fils de Sisara, les fils de Théma,
54 Nesia àti Hatifa.
Les fils de Nasia, les fils de Hatipha,
55 Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni. Àwọn ọmọ Sotai, Sofereti, Peruda,
Les fils des serviteurs de Salomon, les fils de Sotaï, les fils de Sophéret, les fils de Pharuda,
56 Jaala, Darkoni, Giddeli,
Les fils de Jala, les fils de Dercon, les fils de Geddel,
57 Ṣefatia, àwọn ọmọ Hattili, Pokereti ti Haṣebaimu àti àwọn ọmọ Ami.
Les fils de Saphatia, les fils de Hatil, les fils de Phochéreth, qui étaient d’Asebaïm, les fils d’Ami;
58 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
Tous les Nathinéens et les fils des serviteurs de Salomon, trois cent quatre-vingt-douze.
59 Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
Et ceux qui montèrent de Thelmala, Thelharsa, Chérub, Adon et Emer, et qui ne purent faire connaître la maison de leurs pères et leur race, s’ils étaient d’Israël, sont:
60 Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
Les fils de Dalaïa, les fils de Tobie, les fils de Nécoda, six cent cinquante-deux.
61 Àti nínú àwọn ọmọ àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ: Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi a sì ń fi orúkọ náà pè é).
Et d’entre les fils des prêtres: les fils de Hobia, les fils d’Accos, les fils de Berzellaï, qui prit parmi les filles de Berzellaï, le Galaadite, une femme, et fut appelé de leur nom;
62 Àwọn wọ̀nyí wá ìwé ìrántí ìdílé wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni a kò kà wọ́n kún ara àlùfáà nítorí, a kà wọ́n sí aláìmọ́.
Ceux-ci cherchèrent l’écrit de leur généalogie et ne le trouvèrent pas, et ils furent rejetés du sacerdoce.
63 Baálẹ̀ pa á láṣẹ fún wọn pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ nínú oúnjẹ mímọ́ jùlọ títí tí àlùfáà kan yóò fi ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu.
Et Athersatha leur dit qu’ils ne mangeraient point de ce qui est très saint, jusqu’à ce qu’il s’élevât un prêtre instruit et parfait.
64 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó.
Toute la multitude, comme un seul homme, était du nombre de quarante-deux mille trois cent soixante,
65 Yàtọ̀ sí ẹgbẹ̀rin dín lẹ́gbàárin ó dín mẹ́tàlélọ́gọ́ta ìránṣẹ́ ọkùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin; wọ́n ní igba akọrin ọkùnrin àti obìnrin.
Outre leurs serviteurs et servantes, qui étaient sept mille trois cent trente-sept; et parmi eux les chantres et les chanteuses étaient deux cents;
66 Wọ́n ní ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin ẹṣin; ìbáaka òjìlélúgba ó lé márùn-ún,
Leurs chevaux sept cent trente-six; leurs mulets, deux cent quarante-cinq;
67 ràkunmí jẹ́ irinwó ó lé márùndínlógójì àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rin lé lọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
Leurs chameaux, quatre cent tente-cinq; leurs ânes, six mille sept cent vingt.
68 Ní ìgbà tí wọ́n dé ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, díẹ̀ nínú àwọn olórí àwọn ìdílé fi ọrẹ àtinúwá sílẹ̀ fún ṣíṣe àtúnkọ́ ilé Ọlọ́run ní ààyè rẹ̀.
Et des princes des pères, étant entrés dans le temple du Seigneur, qui est à Jérusalem, firent spontanément les dons dans la maison de Dieu, pour la construire en son lieu.
69 Gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, wọ́n fún ilé ìṣúra fún iṣẹ́ yìí ní ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ́gbẹ̀rún ìwọ̀n dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún márùn-ún fàdákà àti ọgọ́rùn-ún ẹ̀wù àlùfáà.
Ils donnèrent, selon leurs facultés, pour les dépenses de cet ouvrage, soixante et un mille solides d’or, et cinq mille mines d’argent, et cent vêtements sacerdotaux.
70 Àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́bodè àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa ṣe àtìpó sínú àwọn ìlú wọn, pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn, àti ìyókù àwọn ọmọ Israẹli ṣe àtìpó sínú ìlú u wọn.
Les prêtres donc, les Lévites, ceux du peuple, les chantres, les portiers et les Nathinéens, habitèrent dans leurs villes, et tout Israël dans ses cités.

< Ezra 2 >