< Ezra 2 >

1 Lákòókò náà, wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn agbègbè Juda tí ó gòkè wá láti ìgbèkùn láàrín àwọn tí a kó lọ, ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti fi agbára mú ní ìgbèkùn lọ sí Babeli (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀.
Or voici ceux de la province qui remontèrent de la captivité, d'entre ceux que Nébucadnetsar, roi de Babylone, avait transportés à Babylone, et qui retournèrent à Jérusalem et en Juda, chacun dans sa ville,
2 Àwọn wọ̀nyí bá Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordekai, Bilṣani, Mispari, Bigfai, Rehumu àti Baanah wá). Iye àwọn ọkùnrin àwọn ènìyàn Israẹli.
Qui vinrent avec Zorobabel, Jéshua, Néhémie, Séraja, Reélaja, Mardochée, Bilshan, Mispar, Bigvaï, Réhum et Baana. Nombre des hommes du peuple d'Israël:
3 Àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
Les enfants de Parosh, deux mille cent soixante-douze;
4 Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
Les enfants de Shéphatia, trois cent soixante-douze;
5 Arah jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n
Les enfants d'Arach, sept cent soixante-quinze;
6 Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ àwọn ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì àti ẹgbẹ̀rin lé méjìlá
Les enfants de Pachath-Moab, des enfants de Jeshua et de Joab, deux mille huit cent douze;
7 Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
Les enfants d'Élam, mille deux cent cinquante-quatre;
8 Sattu jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rún ó lé márùn-ún
Les enfants de Zatthu, neuf cent quarante-cinq;
9 Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
Les enfants de Zaccaï, sept cent soixante;
10 Bani jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì
Les enfants de Bani, six cent quarante-deux;
11 Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mẹ́tàlélógún
Les enfants de Bébaï, six cent vingt-trois;
12 Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé méjìlélógún
Les enfants d'Azgad, mille deux cent vingt-deux;
13 Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà
Les enfants d'Adonikam, six cent soixante-six;
14 Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
Les enfants de Bigvaï, deux mille cinquante-six;
15 Adini jẹ́ àádọ́ta lé ní irinwó ó lé mẹ́rin
Les enfants d'Adin, quatre cent cinquante-quatre;
16 Ateri (nípasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́run
Les enfants d'Ater, de la famille d'Ézéchias, quatre-vingt-dix-huit;
17 Besai jẹ́ ọrùndínnírinwó ó lé mẹ́ta
Les enfants de Betsaï, trois cent vingt-trois;
18 Jora jẹ́ méjìléláàádọ́fà
Les enfants de Jora, cent douze;
19 Haṣumu jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
Les enfants de Hashum, deux cent vingt-trois;
20 Gibbari jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
Les enfants de Guibbar, quatre-vingt-quinze;
21 Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
Les enfants de Bethléhem, cent vingt-trois;
22 Netofa jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
Les gens de Nétopha, cinquante-six;
23 Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
Les gens d'Anathoth, cent vingt-huit;
24 Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
Les enfants d'Azmaveth, quarante-deux;
25 Kiriati-Jearimu, Kefira àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
Les enfants de Kirjath-Arim, de Képhira et de Béeroth, sept cent quarante-trois;
26 Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
Les enfants de Rama et de Guéba, six cent vingt et un;
27 Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
Les gens de Micmas, cent vingt-deux;
28 Beteli àti Ai jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
Les gens de Béthel et d'Aï, deux cent vingt-trois;
29 Nebo jẹ́ méjìléláàádọ́ta
Les enfants de Nébo, cinquante-deux;
30 Magbiṣi jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́jọ
Les enfants de Magbish, cent cinquante-six;
31 Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
Les enfants d'un autre Élam, mille deux cent cinquante-quatre;
32 Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó.
Les enfants de Harim, trois cent vingt;
33 Lodi, Hadidi àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
Les enfants de Lod, de Hadid et d'Ono, sept cent vingt-cinq;
34 Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún
Les enfants de Jérico, trois cent quarante-cinq;
35 Senaa jẹ́ egbèji dín lógún ó lé ọgbọ̀n.
Les enfants de Sénaa, trois mille six cent trente.
36 Àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
Sacrificateurs: les enfants de Jédaeja, de la maison de Jéshua, neuf cent soixante et treize;
37 Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
Les enfants d'Immer, mille cinquante-deux;
38 Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
Les enfants de Pashur, mille deux cent quarante-sept;
39 Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
Les enfants de Harim, mille et dix-sept.
40 Àwọn ọmọ Lefi. Àwọn ọmọ Jeṣua àti Kadmieli (ti ìdílé Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
Lévites: les enfants de Jéshua et de Kadmiel, d'entre les enfants d'Hodavia, soixante et quatorze.
41 Àwọn akọrin. Àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádóje.
Chantres: les enfants d'Asaph, cent vingt-huit.
42 Àwọn aṣọ́bodè. Àwọn ará Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita àti Ṣobai jẹ́ mọ́kàndínlógóje.
Enfants des portiers: les enfants de Shallum, les enfants d'Ater, les enfants de Talmon, les enfants d'Akkub, les enfants de Hatita, les enfants de Shobaï, en tout, cent trente-neuf.
43 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ. Siha, Hasufa, Tabboati,
Néthiniens: les enfants de Tsicha, les enfants de Hasupha, les enfants de Tabbaoth;
44 Kerosi, Siaha, Padoni,
Les enfants de Kéros, les enfants de Siaha, les enfants de Padon;
45 Lebana, Hagaba, Akkubu,
Les enfants de Lébana, les enfants de Hagaba, les enfants d'Akkub;
46 Hagabu, Ṣalmai, Hanani,
Les enfants de Hagab, les enfants de Shamlaï, les enfants de Hanan;
47 Giddeli, Gahari, Reaiah,
Les enfants de Guiddel, les enfants de Gachar, les enfants de Réaja;
48 Resini, Nekoda, Gassamu,
Les enfants de Retsin, les enfants de Nékoda, les enfants de Gazzam;
49 Ussa, Pasea, Besai,
Les enfants d'Uzza, les enfants de Paséach, les enfants de Bésaï;
50 Asna, Mehuni, Nefisimu,
Les enfants d'Asna, les enfants de Méhunim, les enfants de Néphusim;
51 Bakbu, Hakufa, Harhuri.
Les enfants de Bakbuk, les enfants de Hakupha, les enfants de Harhur;
52 Basluti, Mehida, Harṣa,
Les enfants de Batsluth, les enfants de Méhida, les enfants de Harsha;
53 Barkosi, Sisera, Tema,
Les enfants de Barkos, les enfants de Sisra, les enfants de Tamach;
54 Nesia àti Hatifa.
Les enfants de Netsiach, les enfants de Hatipha.
55 Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni. Àwọn ọmọ Sotai, Sofereti, Peruda,
Enfants des serviteurs de Salomon: les enfants de Sotaï, les enfants de Sophéreth, les enfants de Péruda;
56 Jaala, Darkoni, Giddeli,
Les enfants de Jaala, les enfants de Darkon, les enfants de Guiddel;
57 Ṣefatia, àwọn ọmọ Hattili, Pokereti ti Haṣebaimu àti àwọn ọmọ Ami.
Les enfants de Shéphatia, les enfants de Hattil, les enfants de Pokéreth-Hatsébaïm, les enfants d'Ami.
58 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
Total des Néthiniens et des enfants des serviteurs de Salomon: trois cent quatre-vingt-douze.
59 Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
Voici ceux qui montèrent de Thel-Mélach, de Thel-Harsha, de Kérub-Addan, et d'Immer, et qui ne purent indiquer la maison de leurs pères, ni leur race, ni s'ils étaient d'Israël.
60 Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
Les enfants de Délaja, les enfants de Tobija, les enfants de Nékoda, six cent cinquante-deux.
61 Àti nínú àwọn ọmọ àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ: Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi a sì ń fi orúkọ náà pè é).
Des enfants des sacrificateurs: les enfants de Habaja, les enfants de Kots, les enfants de Barzillaï, qui prit pour femme une des filles de Barzillaï, le Galaadite, et fut appelé de leur nom.
62 Àwọn wọ̀nyí wá ìwé ìrántí ìdílé wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni a kò kà wọ́n kún ara àlùfáà nítorí, a kà wọ́n sí aláìmọ́.
Ceux-là cherchèrent leurs titres généalogiques; mais ils ne se retrouvèrent point, et ils furent exclus du sacerdoce.
63 Baálẹ̀ pa á láṣẹ fún wọn pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ nínú oúnjẹ mímọ́ jùlọ títí tí àlùfáà kan yóò fi ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu.
Le gouverneur leur dit qu'ils ne mangeassent point des choses très saintes, jusqu'à ce qu'un sacrificateur pût consulter avec l'Urim et le Thummim.
64 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó.
L'assemblée tout entière était de quarante-deux mille trois cent soixante;
65 Yàtọ̀ sí ẹgbẹ̀rin dín lẹ́gbàárin ó dín mẹ́tàlélọ́gọ́ta ìránṣẹ́ ọkùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin; wọ́n ní igba akọrin ọkùnrin àti obìnrin.
Sans compter leurs serviteurs et leurs servantes, au nombre de sept mille trois cent trente-sept; et ils avaient deux cents chantres et chanteuses.
66 Wọ́n ní ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin ẹṣin; ìbáaka òjìlélúgba ó lé márùn-ún,
Ils avaient sept cent trente-six chevaux, deux cent quarante-cinq mulets,
67 ràkunmí jẹ́ irinwó ó lé márùndínlógójì àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rin lé lọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
Quatre cent trente-cinq chameaux, et six mille sept cent vingt ânes.
68 Ní ìgbà tí wọ́n dé ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, díẹ̀ nínú àwọn olórí àwọn ìdílé fi ọrẹ àtinúwá sílẹ̀ fún ṣíṣe àtúnkọ́ ilé Ọlọ́run ní ààyè rẹ̀.
Et plusieurs des chefs des pères, quand ils vinrent à la maison de l'Éternel qui est à Jérusalem, firent des offrandes volontaires pour la maison de Dieu, afin qu'on la rétablît sur son emplacement.
69 Gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, wọ́n fún ilé ìṣúra fún iṣẹ́ yìí ní ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ́gbẹ̀rún ìwọ̀n dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún márùn-ún fàdákà àti ọgọ́rùn-ún ẹ̀wù àlùfáà.
Ils donnèrent au trésor de l'ouvrage, selon leur pouvoir, soixante et un mille dariques d'or, cinq mille mines d'argent, et cent tuniques de sacrificateurs.
70 Àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́bodè àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa ṣe àtìpó sínú àwọn ìlú wọn, pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn, àti ìyókù àwọn ọmọ Israẹli ṣe àtìpó sínú ìlú u wọn.
Les sacrificateurs, les Lévites, les gens du peuple, les chantres, les portiers et les Néthiniens habitèrent dans leurs villes; tous ceux d'Israël furent aussi dans leurs villes.

< Ezra 2 >